< Zechariah 13 >

1 “Ní ọjọ́ náà ìsun kan yóò ṣí sílẹ̀ fún ilé Dafidi àti fún àwọn ará Jerusalẹmu, láti wẹ̀ wọ́n mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àti àìmọ́ wọn.
To na niah loe zaehaih ciim ai pongah, David imthung takoh hoi Jerusalem ah kaom kaminawk khaeah tui ka pueksak han.
2 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ni èmi ó gé orúkọ àwọn òrìṣà kúrò ni ilẹ̀ náà, a kì yóò sì rántí wọn mọ́, àti pẹ̀lú èmi ó mú àwọn wòlíì èké àti àwọn ẹ̀mí àìmọ́ kúrò ni ilẹ̀ náà.
To na niah loe prae thung hoiah krang ih ahminnawk to ka phraek han, nihcae mah to ahminnawk to panoek o mak ai boeh: tahmaanawk hoi kaciim ai muithla to prae thung hoi ka haek han, tiah misatuh kaminawk ih Angraeng mah thuih.
3 Yóò sì ṣe, nígbà tí ẹnìkan yóò sọtẹ́lẹ̀ síbẹ̀, ni baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ tí ó bí í yóò wí fún un pé, ‘Ìwọ ki yóò yè, nítorí ìwọ ń sọ ọ̀rọ̀ èké ni orúkọ Olúwa.’ Àti baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ tí o bí í yóò gun un ni àgúnpa nígbà tí ó bá sọtẹ́lẹ̀.
To naah lokthui tahmaanawk om o vop nahaeloe, anih cunkung amno hoi ampa mah anih khaeah, Angraeng ih ahmin hoi amsawnlok na thuih pongah, na hing han om ai, tiah naa tih. Tahmaanawk mah lokthuih o naah, anih cunkung amno hoi ampa mah to tahmaanawk to sumsen hoiah thun o tih.
4 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ojú yóò tí àwọn wòlíì èké olúkúlùkù nítorí ìran rẹ̀, nígbà tí òun ba tí sọtẹ́lẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò sì wọ aṣọ wòlíì onírun rẹ̀ tí o fi ń tan ní jẹ.
To na niah tahmaanawk mah a hnuk o ih hmuen kawng thuih o naah, azat o tih; kami aling hanah moihin khukbuen to angkhuk mak ai boeh.
5 Ṣùgbọ́n òun o wí pé, ‘Èmi kí í ṣe wòlíì, àgbẹ̀ ni èmi; nítorí tí a ti fi mí ṣe ìránṣẹ́ láti ìgbà èwe mi wá.’
Toe anih mah, Kai loe tahmaa na ai ni, kai loe lawkphrawk kami ni; nawkta nathuem hoi boeh ni kami maeto mah maitaw toep hanah ang patuk, tiah thui tih.
6 Ẹnìkan ó sì wí fún un pé, ‘Ọgbẹ́ kín ní wọ̀nyí ni ẹ̀yìn rẹ?’ Òun o sì dáhùn pé, ‘Wọ̀nyí ni ibi tí a ti sá mi ní ilé àwọn ọ̀rẹ́ mi.’
Kami mah, Tipongah na ban ah ahma oh loe? tiah dueng o naah, Kam puinawk ih im ah ahma ka caak, tiah thui tih.
7 “Dìde, ìwọ idà, sí Olùṣọ́-àgùntàn mi, àti sí ẹni tí í ṣe ẹnìkejì mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Kọlu Olùṣọ́-àgùntàn, àwọn àgùntàn a sì túká: èmi o sì yí ọwọ́ mi sí àwọn kéékèèké.
Aw sumsen, kai ih tuutoep kami hoi kai ih ampui to tuk hanah, angthawk ah, tiah misatuh kaminawk ih Angraeng mah thuih: tuutoep kami hum naah loe tuunawk ampraek o phang tih: to tuucaanawk nuiah ban ka phok han.
8 Yóò sì ṣe, ni gbogbo ilẹ̀,” ni Olúwa wí, “a ó gé apá méjì nínú rẹ̀ kúrò yóò sì kú; ṣùgbọ́n apá kẹta yóò kù nínú rẹ̀.
Prae thung boih ah, thumto thungah hnetto hum o ueloe dueh o tih; toe thumto thungah maeto loe anghmat tih.
9 Èmi ó sì mú apá kẹta náà la àárín iná, èmi yóò sì yọ́ wọn bí a ti yọ́ fàdákà, èmi yóò sì dán wọn wò, bi a tí ń dán wúrà wò: wọn yóò sì pé orúkọ mi, èmi yóò sì dá wọn lóhùn: èmi yóò wí pé, ‘Àwọn ènìyàn mi ni,’ àwọn yóò sì wí pé, ‘Olúwa ni Ọlọ́run wa.’”
Sum kanglung hmai hoi atui pacii baktih, sui loe hmai hoiah tanoek ah oh baktih toengah, thumto haih to hmai thungah ka vah han: nihcae mah ka hmin to kawk o tih, to naah nihcae to ka pathim han: to naah kai mah, nihcae loe kai ih kami ni, tiah ka thuih han; nihcae mah doeh, Angraeng loe kai ih Sithaw ni, tiah thui o toeng tih, tiah Angraeng mah thuih.

< Zechariah 13 >