< Zechariah 12 >
1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa fún Israẹli ni. Olúwa wí, ẹni tí ó na àwọn ọ̀run, tí ó sì fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, tí ó sì da ẹ̀mí ènìyàn tí ń bẹ ni inú rẹ̀,
Brzemię słowa PANA nad Izraelem. [Tak] mówi PAN, który rozpostarł niebiosa, założył fundamenty ziemi i stwarza ducha człowieka w jego wnętrzu:
2 “Kíyèsi í, èmi yóò sọ Jerusalẹmu dí àgọ́ ìwárìrì sí gbogbo ènìyàn yíká, nígbà tí wọn yóò dó ti Juda àti Jerusalẹmu.
Oto uczynię Jerozolimę kielichem odurzenia dla wszystkich okolicznych narodów, gdy nastanie oblężenie przeciwko Judzie i przeciwko Jerozolimie.
3 Ní ọjọ́ náà, nígbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè ayé bá parapọ̀ sí i, ni èmi yóò sọ Jerusalẹmu di òkúta ti ko ṣe yí kúrò fún gbogbo ènìyàn, gbogbo àwọn tí ó bá sì fẹ́ yí i ni a ó gé sí wẹ́wẹ́,
W tym dniu uczynię Jerozolimę ciężkim kamieniem dla wszystkich narodów. Wszyscy, którzy będą go dźwigać, bardzo się zranią, choćby się zgromadziły przeciwko niemu wszystkie narody ziemi.
4 ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí, “Ni èmi yóò fi ìdágìrì lu gbogbo ẹṣin, àti fi òmùgọ̀ kọlu ẹni tí ń gun un; èmi yóò sì ṣí ojú mi sí ilé Juda, èmi yóò sì bu ìfọ́jú lu gbogbo ẹṣin tí orílẹ̀-èdè.
Tego dnia, mówi PAN, każdego konia porażę trwogą i jego jeźdźca – szaleństwem; ale nad domem Judy otworzę swoje oczy, a każdego konia narodów porażę ślepotą.
5 Àti àwọn baálẹ̀ Juda yóò sì wí ni ọkàn wọn pé, ‘Àwọn ara Jerusalẹmu ni agbára mi nípa Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ọlọ́run wọn.’
I przywódcy Judy powiedzą w swoim sercu: Mieszkańcy Jerozolimy będą naszą siłą w PANU zastępów, swoim Bogu.
6 “Ní ọjọ́ náà, ni èmi yóò ṣe àwọn baálẹ̀ Juda bí ààrò iná kan láàrín igi, àti bi ẹ̀fúùfù iná láàrín ìtí; wọn yóò sì jẹ gbogbo àwọn ènìyàn run yíká lápá ọ̀tún àti lápá òsì, a ó sì tún máa gbé inú Jerusalẹmu ní ipò rẹ̀.
W tym dniu uczynię przywódców Judy jak węgle ogniste wśród drwa i jak płonącą pochodnię pośród snopów; i pożrą wszystkie okoliczne narody na prawo i na lewo. I Jerozolima pozostanie na swoim miejscu, w Jerozolimie.
7 “Olúwa pẹ̀lú yóò kọ́ tètè gba àgọ́ Juda là ná, kí ògo ilé Dafidi àti ògo àwọn ara Jerusalẹmu má ba gbé ara wọn ga sí Juda.
I najpierw PAN wybawi namioty Judy, aby chwała domu Dawida i chwała mieszkańców Jerozolimy nie wywyższały się przeciwko Judzie.
8 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò dáàbò bò àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu; ẹni tí ó bá sì ṣe àìlera nínú wọn ní ọjọ́ náà, yóò dàbí Dafidi; ilé Dafidi yóò sì dàbí Ọlọ́run, bí angẹli Olúwa níwájú wọn.
W tym dniu PAN będzie bronił mieszkańców Jerozolimy, a najsłabszy pośród nich stanie się tego dnia podobny do Dawida, a dom Dawida podobny do Boga, podobny do Anioła PANA na ich czele.
9 Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, èmi yóò wá láti pa gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè run tí ó wá kọjú ìjà sí Jerusalẹmu.”
I stanie się w tym dniu, że będę zmierzać do zniszczenia wszystkich narodów, które wyruszą przeciwko Jerozolimie.
10 “Èmi ó sì tu ẹ̀mí oore-ọ̀fẹ́ àti ẹ̀bẹ̀ sórí ilé Dafidi àti sórí Jerusalẹmu, wọn ó sì máa wo ẹni tí wọn tí gún ni ọ̀kọ̀, wọn ó sì máa ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, bí ẹnìkan ti ń ṣọ̀fọ̀ fún ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo àti gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí wọn yóò sì wà ni ìbànújẹ́, bí ẹni tí ń banújẹ́ fún àkọ́bí rẹ̀.
I wyleję na dom Dawida i na mieszkańców Jerozolimy ducha łaski i modlitwy. Będą patrzyć na mnie, którego przebili, i będą go opłakiwać, jak się opłakuje jedynaka; będą gorzko płakać nad nim, jak się płacze gorzko nad pierworodnym.
11 Ní ọjọ́ náà ni ẹkún, ńlá ńlá yóò wà ni Jerusalẹmu, gẹ́gẹ́ bí ọ̀fọ̀ Hadadi Rimoni ni àfonífojì Megido.
W tym dniu będzie wielki lament w Jerozolimie, jak lament w Hadad-Rimmon na równinie Megiddo.
12 Ilẹ̀ náà yóò ṣọ̀fọ̀, ìdílé, kọ̀ọ̀kan fun ara rẹ, lọ́tọ̀ọ̀tọ̀; ìdílé Dafidi lọ́tọ̀; àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀; ìdílé Natani lọ́tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ́.
Ziemia będzie lamentować, każdy ród osobno: ród domu Dawida osobno i jego kobiety osobno; ród domu Natana osobno i jego kobiety osobno;
13 Ìdílé Lefi lọ́tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀; ìdílé Ṣimei lọ́tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀.
Ród domu Lewiego osobno i jego kobiety osobno; ród Szimejego osobno i jego kobiety osobno;
14 Gbogbo àwọn ìdílé tí o kù, ìdílé, ìdílé, lọ́tọ̀ọ̀tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀ọ̀tọ̀.
Wszystkie pozostałe rody, każdy ród osobno i ich kobiety osobno.