< Zechariah 12 >

1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa fún Israẹli ni. Olúwa wí, ẹni tí ó na àwọn ọ̀run, tí ó sì fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, tí ó sì da ẹ̀mí ènìyàn tí ń bẹ ni inú rẹ̀,
The burden of the word of the Lord upon Israel. The Lord, stretching forth the heavens and founding the earth and forming the spirit of man within him, says:
2 “Kíyèsi í, èmi yóò sọ Jerusalẹmu dí àgọ́ ìwárìrì sí gbogbo ènìyàn yíká, nígbà tí wọn yóò dó ti Juda àti Jerusalẹmu.
Behold, I will set Jerusalem as a lintel of the effects of drunkenness to all the surrounding peoples, yet even Judah will be in the blockade against Jerusalem.
3 Ní ọjọ́ náà, nígbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè ayé bá parapọ̀ sí i, ni èmi yóò sọ Jerusalẹmu di òkúta ti ko ṣe yí kúrò fún gbogbo ènìyàn, gbogbo àwọn tí ó bá sì fẹ́ yí i ni a ó gé sí wẹ́wẹ́,
And this shall be: In that day, I will set Jerusalem as a burdensome stone to every people. All who will lift it up will be torn to pieces. And all the kingdoms of the earth will be gathered together against her.
4 ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí, “Ni èmi yóò fi ìdágìrì lu gbogbo ẹṣin, àti fi òmùgọ̀ kọlu ẹni tí ń gun un; èmi yóò sì ṣí ojú mi sí ilé Juda, èmi yóò sì bu ìfọ́jú lu gbogbo ẹṣin tí orílẹ̀-èdè.
In that day, says the Lord, I will strike every horse with stupor and his rider with madness. And I will open my eyes upon the house of Judah, and I will strike every horse of the people with blindness.
5 Àti àwọn baálẹ̀ Juda yóò sì wí ni ọkàn wọn pé, ‘Àwọn ara Jerusalẹmu ni agbára mi nípa Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ọlọ́run wọn.’
And the governors of Judah will say in their heart, “Let the inhabitants of Jerusalem be strengthened for me, in the Lord of hosts, their God.”
6 “Ní ọjọ́ náà, ni èmi yóò ṣe àwọn baálẹ̀ Juda bí ààrò iná kan láàrín igi, àti bi ẹ̀fúùfù iná láàrín ìtí; wọn yóò sì jẹ gbogbo àwọn ènìyàn run yíká lápá ọ̀tún àti lápá òsì, a ó sì tún máa gbé inú Jerusalẹmu ní ipò rẹ̀.
In that day, I will set the governors of Judah like a flaming furnace among wood, and like a flaming torch among hay. And they will devour, to the right and to the left, all the surrounding peoples. And Jerusalem will be inhabited again, in her own place, in Jerusalem.
7 “Olúwa pẹ̀lú yóò kọ́ tètè gba àgọ́ Juda là ná, kí ògo ilé Dafidi àti ògo àwọn ara Jerusalẹmu má ba gbé ara wọn ga sí Juda.
And the Lord will save the tabernacles of Judah, just as in the beginning, so that the house of David and the glory of the inhabitants of Jerusalem may not glorify themselves boastfully against Judah.
8 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò dáàbò bò àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu; ẹni tí ó bá sì ṣe àìlera nínú wọn ní ọjọ́ náà, yóò dàbí Dafidi; ilé Dafidi yóò sì dàbí Ọlọ́run, bí angẹli Olúwa níwájú wọn.
In that day, the Lord will protect the inhabitants of Jerusalem, and even he who will have offended from them, in that day, will be like David, and the house of David will be like that of God, just like an angel of the Lord in their sight.
9 Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, èmi yóò wá láti pa gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè run tí ó wá kọjú ìjà sí Jerusalẹmu.”
And this shall be in that day: I will seek to crush all the Gentiles that come against Jerusalem.
10 “Èmi ó sì tu ẹ̀mí oore-ọ̀fẹ́ àti ẹ̀bẹ̀ sórí ilé Dafidi àti sórí Jerusalẹmu, wọn ó sì máa wo ẹni tí wọn tí gún ni ọ̀kọ̀, wọn ó sì máa ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, bí ẹnìkan ti ń ṣọ̀fọ̀ fún ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo àti gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí wọn yóò sì wà ni ìbànújẹ́, bí ẹni tí ń banújẹ́ fún àkọ́bí rẹ̀.
And I will pour out upon the house of David and upon the inhabitants of Jerusalem, the spirit of grace and of prayers. And they will look upon me, whom they have pierced, and they will mourn for him as one mourns for an only son, and they will feel sorrow over him, as one would be sorrowful at the death of a firstborn.
11 Ní ọjọ́ náà ni ẹkún, ńlá ńlá yóò wà ni Jerusalẹmu, gẹ́gẹ́ bí ọ̀fọ̀ Hadadi Rimoni ni àfonífojì Megido.
In that day, there will be a great lamentation in Jerusalem, like the lamentation of Hadadrimmon in the plain of Megiddo.
12 Ilẹ̀ náà yóò ṣọ̀fọ̀, ìdílé, kọ̀ọ̀kan fun ara rẹ, lọ́tọ̀ọ̀tọ̀; ìdílé Dafidi lọ́tọ̀; àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀; ìdílé Natani lọ́tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ́.
And the earth will mourn: families and families separately; the families of the house of David separately, and their women separately;
13 Ìdílé Lefi lọ́tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀; ìdílé Ṣimei lọ́tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀.
the families of the house of Nathan separately, and their women separately; the families of the house of Levi separately, and their women separately; the families of Shimei separately, and their women separately;
14 Gbogbo àwọn ìdílé tí o kù, ìdílé, ìdílé, lọ́tọ̀ọ̀tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀ọ̀tọ̀.
all the rest of the families, families and families separately, and their women separately.

< Zechariah 12 >