< Zechariah 11 >

1 Ṣí àwọn ìlẹ̀kùn rẹ sílẹ̀, ìwọ Lebanoni, kí iná bá lè jẹ igi kedari rẹ run.
Otwórz swe wrota, Libanie, niech ogień strawi twoje cedry.
2 Hu, igi junifa; nítorí igi kedari ṣubú, nítorí tí a ba àwọn igi tí o lógo jẹ́: hu, ẹ̀yin igi óákù tí Baṣani, nítorí gé igbó àjàrà lulẹ̀.
Zawódź, jodło, bo upadł cedr, bo wielcy są spustoszeni. Zawódźcie, dęby Baszanu, bo niedostępny las został wycięty.
3 Gbọ́ ohun igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn; ògo wọn bàjẹ́; gbọ́ ohùn bíbú àwọn ọmọ kìnnìún nítorí ògo Jordani bàjẹ́.
[Słychać] głos narzekania pasterzy, bo ich wspaniałość została zburzona; [słychać] głos ryku lwiąt, bo pycha Jordanu jest zburzona.
4 Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run mi wí: “Bọ́ ọ̀wọ́ ẹran àbọ́pa.
Tak mówi PAN, mój Bóg: Paś owce przeznaczone na rzeź;
5 Tí àwọn olúwa wọn ń pa wọ́n, tí wọn kò sì ka ara wọn sí pé wọn jẹ̀bi: àti àwọn tí ń tà wọ́n wí pé, ‘Ìbùkún ni fún Olúwa, nítorí tí mo dí ọlọ́rọ̀!’ Àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn kò sì ṣàánú wọn.
Które kupcy zabijają, a nie czują się winni, a sprzedający je mówią: Błogosławiony PAN, że się wzbogaciłem. A ich pasterze nie mają dla nich litości.
6 Nítorí èmi kì yóò ṣàánú fún àwọn ara ilẹ̀ náà mọ́,” ni Olúwa wí, “Ṣí kíyèsi í, èmi yóò fi olúkúlùkù ènìyàn lé aládùúgbò rẹ̀ lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ ọba rẹ̀, wọn yóò sì fọ́ ilẹ̀ náà, èmi kì yóò sì gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn.”
Dlatego już nie będę miał litości dla mieszkańców tej ziemi, mówi PAN. Oto wydam tych ludzi, każdego z nich, w ręce jego bliźniego i w ręce jego króla. I zniszczą ziemię, a nikogo nie wyrwę z ich rąk.
7 Èmi yóò sì bọ́ ẹran àbọ́pa, àní ẹ̀yin òtòṣì nínú ọ̀wọ́ ẹran. Mo sì mu ọ̀pá méjì sọ́dọ̀; mo pè ọ̀kan ni Oore-ọ̀fẹ́, mo pè èkejì ni Àmùrè; mo sì bọ́ ọ̀wọ́ ẹran náà.
Będę więc pasł owce przeznaczone na rzeź, was, [mówię], biedne owce! Wziąłem sobie dwie laski, jedną nazwałem Piękno, a drugą nazwałem Więzy, i pasłem te [owce].
8 Olùṣọ́-àgùntàn mẹ́ta ni mo sì gé kúrò ní oṣù kan. Ọkàn mi sì kórìíra wọn, ọkàn wọn pẹ̀lú sì kórìíra mi.
Zgładziłem trzech pasterzy w jednym miesiącu; i moja dusza czuła niechęć do nich, a ich dusza też brzydziła się mną.
9 Mo sì wí pé, “Èmi kì yóò bọ́ yin: èyí ti ń ku lọ, jẹ́ kí òkú o kú; èyí tí a o ba sì gé kúrò, jẹ́ kí a gé e kúrò; ki olúkúlùkù nínú àwọn ìyókù jẹ́ ẹran-ara ẹnìkejì rẹ̀.”
Wtedy powiedziałem: Nie będę was pasł. Co umiera, niech umrze, a co ma być zgładzone, niech będzie zgładzone, a ci, [co] pozostaną, niech każdy pożera ciało drugiego.
10 Mo sì mu ọ̀pá mi, ti a ń pè ní Oore-ọ̀fẹ́, mo ṣẹ́ si méjì, ki èmi bá lè da májẹ̀mú mi tí mo tí bá gbogbo àwọn ènìyàn náà dá.
Wziąłem więc swoją laskę, Piękno, i złamałem ją, aby zerwać swoje przymierze, które zawarłem z całym ludem.
11 Ó sì dá ni ọjọ́ náà, bẹ́ẹ̀ ni àwọn òtòṣì nínú ọ̀wọ́ ẹran náà tí ó dúró tì mí mọ̀ pé, ọ̀rọ̀ Olúwa ni.
I zostało zerwane w tym dniu, a biedni spośród trzody, którzy przyglądali się mnie, poznali, że [to] słowo PANA.
12 Mo sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá dára ní ojú yin, ẹ fún mi ni owó ọ̀yà mi; bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ mú un lọ́wọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọn ọgbọ̀n owó fàdákà fún iye owó ọ̀yà mi.
Potem powiedziałem do nich: Jeśli to jest dobre w waszych oczach, dajcie mi moją zapłatę, a jeśli nie, zaniechajcie [jej]. Odważyli więc moją zapłatę: trzydzieści srebrników.
13 Olúwa sì wí fún mi pé, “Sọ ọ sí amọ̀kòkò.” Iye dáradára náà, tí wọn yọ owó mi sí. Mo sì mu ọgbọ̀n owó fàdákà náà, mo sì sọ wọ́n sí àpótí ìṣúra ní ilé Olúwa.
Potem PAN powiedział do mnie: Rzuć je przed garncarza. Wspaniała to zapłata, na jaką mnie tak drogo oszacowali! Wziąłem więc trzydzieści srebrników i rzuciłem je przed garncarza w domu PANA.
14 Mo sì ṣẹ́ ọ̀pá mi kejì, àní Àmùrè, sí méjì, kí èmi lè ya ìbátan tí ó wà láàrín Juda àti láàrín Israẹli.
Potem złamałem swoją drugą laskę, Więzy, aby zerwać braterstwo między Judą a Izraelem.
15 Olúwa sì wí fún mi pé, “Tún mú ohun èlò aṣiwèrè olùṣọ́-àgùntàn kan sọ́dọ̀ rẹ̀.
I PAN powiedział do mnie: Weź sobie jeszcze narzędzie głupiego pasterza.
16 Nítorí Èmi o gbé Olùṣọ́-àgùntàn kan dìde ni ilẹ̀ náà, tí kí yóò bẹ àwọn tí ó ṣègbé wò, ti kì yóò sì wá èyí tí ó yapa; tí kì yóò ṣe ìtọ́jú èyí tí a pa lára tàbí kí ó bọ́ àwọn tí ara wọn dá pépé: Ṣùgbọ́n òun yóò jẹ ẹran èyí tí ó ni ọ̀rá, àwọn èyí tiwọn fi èékánná wọn ya ara wọn pẹ́rẹpẹ̀rẹ.
Oto bowiem wzbudzę pasterza w tej ziemi, [który] nie będzie troszczył się o zaginione, nie będzie szukał jagniątek, nie będzie leczyć okaleczonych i tego, co stoi, nie będzie karmił. Ale będzie jeść mięso tucznych, a ich kopyta oberwie.
17 “Ègbé ni fún olùṣọ́-àgùntàn asán náà, tí ó fi ọ̀wọ́ ẹran sílẹ̀! Idà yóò gé apá rẹ̀ àti ojú ọ̀tún rẹ̀: apá rẹ̀ yóò gbẹ pátápátá, ojú ọ̀tún rẹ̀ yóò sì fọ́ pátápátá!”
Biada pasterzowi nieużytecznemu, który opuszcza trzodę! Niech spadnie miecz na jego ramię i na jego prawe oko. Jego ramię całkiem uschnie, a jego prawe oko całkiem oślepnie.

< Zechariah 11 >