< Zechariah 11 >

1 Ṣí àwọn ìlẹ̀kùn rẹ sílẹ̀, ìwọ Lebanoni, kí iná bá lè jẹ igi kedari rẹ run.
Ouvrez vos portes, Liban, pour que le feu dévore vos cèdres.
2 Hu, igi junifa; nítorí igi kedari ṣubú, nítorí tí a ba àwọn igi tí o lógo jẹ́: hu, ẹ̀yin igi óákù tí Baṣani, nítorí gé igbó àjàrà lulẹ̀.
Gémis, cyprès, car le cèdre est tombé, parce que les majestueux sont détruits. Gémissez, chênes de Bashan, car la forêt forte est tombée.
3 Gbọ́ ohun igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn; ògo wọn bàjẹ́; gbọ́ ohùn bíbú àwọn ọmọ kìnnìún nítorí ògo Jordani bàjẹ́.
La voix des pleurs des bergers! Car leur gloire est détruite - une voix qui ressemble au rugissement de jeunes lions! Car la fierté du Jourdain est ruinée.
4 Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run mi wí: “Bọ́ ọ̀wọ́ ẹran àbọ́pa.
Yahvé, mon Dieu, dit: « Paisez le troupeau de la boucherie.
5 Tí àwọn olúwa wọn ń pa wọ́n, tí wọn kò sì ka ara wọn sí pé wọn jẹ̀bi: àti àwọn tí ń tà wọ́n wí pé, ‘Ìbùkún ni fún Olúwa, nítorí tí mo dí ọlọ́rọ̀!’ Àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn kò sì ṣàánú wọn.
Leurs acheteurs les égorgent et restent impunis. Ceux qui les vendent disent: « Béni soit Yahvé, car je suis riche », et leurs propres bergers n'ont pas pitié d'eux.
6 Nítorí èmi kì yóò ṣàánú fún àwọn ara ilẹ̀ náà mọ́,” ni Olúwa wí, “Ṣí kíyèsi í, èmi yóò fi olúkúlùkù ènìyàn lé aládùúgbò rẹ̀ lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ ọba rẹ̀, wọn yóò sì fọ́ ilẹ̀ náà, èmi kì yóò sì gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn.”
Car je n'aurai plus pitié des habitants du pays, dit l'Éternel, mais voici que je livrerai chacun de ces hommes entre les mains de son prochain et entre les mains de son roi. Ils frapperont le pays, et de leur main je ne les délivrerai pas. »
7 Èmi yóò sì bọ́ ẹran àbọ́pa, àní ẹ̀yin òtòṣì nínú ọ̀wọ́ ẹran. Mo sì mu ọ̀pá méjì sọ́dọ̀; mo pè ọ̀kan ni Oore-ọ̀fẹ́, mo pè èkejì ni Àmùrè; mo sì bọ́ ọ̀wọ́ ẹran náà.
J'ai donc nourri le troupeau à abattre, surtout les opprimés du troupeau. Je pris pour moi deux bâtons. J'appelai l'un « faveur » et l'autre « union », et je fis paître le troupeau.
8 Olùṣọ́-àgùntàn mẹ́ta ni mo sì gé kúrò ní oṣù kan. Ọkàn mi sì kórìíra wọn, ọkàn wọn pẹ̀lú sì kórìíra mi.
J'exterminai les trois bergers en un mois, car mon âme était lasse d'eux, et leur âme aussi me haïssait.
9 Mo sì wí pé, “Èmi kì yóò bọ́ yin: èyí ti ń ku lọ, jẹ́ kí òkú o kú; èyí tí a o ba sì gé kúrò, jẹ́ kí a gé e kúrò; ki olúkúlùkù nínú àwọn ìyókù jẹ́ ẹran-ara ẹnìkejì rẹ̀.”
Alors je dis: « Je ne vous ferai pas paître. Ce qui meurt, qu'il meure; et ce qui doit être retranché, qu'il soit retranché; et que ceux qui restent mangent la chair les uns des autres. »
10 Mo sì mu ọ̀pá mi, ti a ń pè ní Oore-ọ̀fẹ́, mo ṣẹ́ si méjì, ki èmi bá lè da májẹ̀mú mi tí mo tí bá gbogbo àwọn ènìyàn náà dá.
Je pris mon bâton Favor et je le taillai en pièces, afin de rompre l'alliance que j'avais conclue avec tous les peuples.
11 Ó sì dá ni ọjọ́ náà, bẹ́ẹ̀ ni àwọn òtòṣì nínú ọ̀wọ́ ẹran náà tí ó dúró tì mí mọ̀ pé, ọ̀rọ̀ Olúwa ni.
Elle fut rompue ce jour-là, et les pauvres du troupeau qui m'écoutaient surent que c'était la parole de Yahvé.
12 Mo sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá dára ní ojú yin, ẹ fún mi ni owó ọ̀yà mi; bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ mú un lọ́wọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọn ọgbọ̀n owó fàdákà fún iye owó ọ̀yà mi.
Je leur dis: « Si vous le jugez bon, donnez-moi mon salaire; sinon, gardez-le. » Ils pesèrent donc pour mon salaire trente pièces d'argent.
13 Olúwa sì wí fún mi pé, “Sọ ọ sí amọ̀kòkò.” Iye dáradára náà, tí wọn yọ owó mi sí. Mo sì mu ọgbọ̀n owó fàdákà náà, mo sì sọ wọ́n sí àpótí ìṣúra ní ilé Olúwa.
L'Éternel me dit: « Jette-les au potier, c'est le beau prix auquel ils m'ont estimé. » J'ai pris les trente pièces d'argent et je les ai jetées au potier dans la maison de l'Éternel.
14 Mo sì ṣẹ́ ọ̀pá mi kejì, àní Àmùrè, sí méjì, kí èmi lè ya ìbátan tí ó wà láàrín Juda àti láàrín Israẹli.
Puis j'ai coupé mon autre bâton, l'Union, afin de rompre la fraternité entre Juda et Israël.
15 Olúwa sì wí fún mi pé, “Tún mú ohun èlò aṣiwèrè olùṣọ́-àgùntàn kan sọ́dọ̀ rẹ̀.
L'Éternel me dit: « Prends encore pour toi l'équipement d'un berger insensé.
16 Nítorí Èmi o gbé Olùṣọ́-àgùntàn kan dìde ni ilẹ̀ náà, tí kí yóò bẹ àwọn tí ó ṣègbé wò, ti kì yóò sì wá èyí tí ó yapa; tí kì yóò ṣe ìtọ́jú èyí tí a pa lára tàbí kí ó bọ́ àwọn tí ara wọn dá pépé: Ṣùgbọ́n òun yóò jẹ ẹran èyí tí ó ni ọ̀rá, àwọn èyí tiwọn fi èékánná wọn ya ara wọn pẹ́rẹpẹ̀rẹ.
Car voici que je vais susciter dans le pays un berger qui ne visitera pas ceux qui sont retranchés, ne cherchera pas ceux qui sont dispersés, ne guérira pas ceux qui sont brisés et ne nourrira pas ceux qui sont sains; mais il mangera la viande des brebis grasses et mettra leurs sabots en pièces.
17 “Ègbé ni fún olùṣọ́-àgùntàn asán náà, tí ó fi ọ̀wọ́ ẹran sílẹ̀! Idà yóò gé apá rẹ̀ àti ojú ọ̀tún rẹ̀: apá rẹ̀ yóò gbẹ pátápátá, ojú ọ̀tún rẹ̀ yóò sì fọ́ pátápátá!”
Malheur au berger sans valeur qui abandonne le troupeau! L'épée frappera son bras et son œil droit. Son bras sera complètement desséché, et son œil droit sera complètement aveuglé! ».

< Zechariah 11 >