< Zechariah 10 >
1 Ẹ béèrè òjò nígbà àrọ̀kúrò ni ọwọ́ Olúwa; Olúwa tí o dá mọ̀nàmọ́ná, tí ó sì fi ọ̀pọ̀ òjò fún ènìyàn, fún olúkúlùkù koríko ní pápá.
Pedido de chuva de Yahweh na primavera, Yahweh que faz nuvens de tempestade, e ele dá chuveiros de chuva a todos para as plantas no campo.
2 Nítorí àwọn òrìṣà tí sọ̀rọ̀ asán, àwọn aláfọ̀ṣẹ sì tí rí èké, wọn sì tí rọ àlá èké; wọ́n ń tu ni nínú lásán, nítorí náà àwọn ènìyàn náà ṣáko lọ bí àgùntàn, a ṣẹ wọn níṣẹ̀ẹ́, nítorí Olùṣọ́-àgùntàn kò sí.
Pois os teraphim falaram vaidade, e os adivinhadores viram uma mentira; e eles contaram sonhos falsos. Confortam em vão. Portanto, eles seguem seu caminho como ovelhas. Eles são oprimidos, porque não há pastor.
3 “Ìbínú mi ru sí àwọn darandaran, èmi o sì jẹ àwọn olórí ní yà nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti bẹ agbo rẹ̀, ilé Juda wò, yóò sì fi wọn ṣe ẹṣin rẹ̀ dáradára ní ogun.
Minha raiva é acesa contra os pastores, e castigarei os caprinos machos, pois Javé dos Exércitos visitou seu rebanho, a casa de Judá, e os fará como seu majestoso cavalo na batalha.
4 Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni òkúta igun ilé ti jáde wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni èèkàn àgọ́ tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrún ogun tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn akóniṣiṣẹ́ gbogbo tí wá.
dele virá a pedra angular, dele a cavilha da barraca, dele, o arco de batalha, dele todos os governantes juntos.
5 Gbogbo wọn yóò sì dàbí ọkùnrin alágbára ni ogun tí ń tẹ àwọn ọ̀tá wọn mọ́lẹ̀ ní ìgboro, wọn ó sì jagun, nítorí Olúwa wà pẹ̀lú wọn, wọn ó sì dààmú àwọn tí ń gun ẹṣin.
Eles serão homens tão poderosos, pisando em ruas lamacentas na batalha. Eles vão lutar, porque Yahweh está com eles. Os cavaleiros a cavalo ficarão confusos.
6 “Èmi o sì mú ilé Juda ní agbára, èmi o sì gba ilé Josẹfu là, èmi ó sì tún mú wọn padà nítorí mo tí ṣàánú fún wọn, ó sì dàbí ẹni pé èmi kò ì tì í ta wọ́n nù; nítorí èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn, èmi o sì gbọ́ tiwọn
“Vou fortalecer a casa de Judá, e eu salvarei a casa de José. Eu os trarei de volta, pois eu tenho piedade deles. Eles serão como se eu não os tivesse jogado fora, pois eu sou Yahweh seu Deus, e eu os ouvirei.
7 Efraimu yóò sì ṣe bí alágbára, ọkàn wọn yóò sì yọ̀ bi ẹni pé nípa ọtí wáìnì: àní àwọn ọmọ wọn yóò rí í, wọn o sì yọ̀, inú wọn ó sì dùn nínú Olúwa.
Ephraim será como um homem poderoso, e seu coração se regozijará como pelo vinho. Sim, seus filhos o verão e se regozijarão. Seu coração ficará contente em Yahweh.
8 Èmi ó kọ sí wọn, èmi ó sì ṣà wọ́n jọ; nítorí èmi tí rà wọ́n padà; wọn ó sì pọ̀ sí i gẹ́gẹ́ bí wọ́n tí ń pọ̀ sí í rí.
Eu farei sinal para eles e os recolherei, pois eu os resgatei. Eles vão aumentar como antes.
9 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo tú wọn káàkiri orílẹ̀-èdè: síbẹ̀ wọn ó sì rántí mi ni ilẹ̀ jíjìn; wọn ó sì gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn, wọn ó sì tún padà.
Semeá-las-ei entre os povos. Eles vão se lembrar de mim em países distantes. Eles viverão com seus filhos e voltarão.
10 Èmi ó sì tún mú wọn padà kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú, èmi ó sì ṣà wọn jọ kúrò ni ilẹ̀ Asiria. Èmi ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ Gileadi àti Lebanoni; a kì yóò sì rí ààyè fún wọn bí ó ti yẹ.
Vou trazê-los novamente também para fora da terra do Egito, e os recolhe fora da Assíria. Vou trazê-los para a terra de Gilead e do Líbano; e não haverá espaço suficiente para eles.
11 Wọn yóò sì la Òkun wàhálà já, yóò sì bori rírú omi nínú Òkun, gbogbo ibú odò ni yóò sì gbẹ, a ó sì rẹ ìgbéraga Asiria sílẹ̀, ọ̀pá aládé Ejibiti yóò sí lọ kúrò.
Ele passará pelo mar da aflição, e atingirá as ondas no mar, e todas as profundezas do Nilo secarão; e o orgulho da Assíria será derrubado, e o cetro do Egito irá partir.
12 Èmi ó sì mú wọn ní agbára nínú Olúwa; wọn ó sì rìn sókè rìn sódò ni orúkọ rẹ̀,” ni Olúwa wí.
Vou fortalecê-los em Yahweh. Eles andarão para cima e para baixo em seu nome”, diz Yahweh.