< Zechariah 10 >

1 Ẹ béèrè òjò nígbà àrọ̀kúrò ni ọwọ́ Olúwa; Olúwa tí o dá mọ̀nàmọ́ná, tí ó sì fi ọ̀pọ̀ òjò fún ènìyàn, fún olúkúlùkù koríko ní pápá.
Demandez au Seigneur de la pluie selon la saison, le matin et le soir. Le Seigneur a créé des signes manifestes; Il donnera aux hommes les pluies d'hiver, et à chacun de l'herbe en son champ.
2 Nítorí àwọn òrìṣà tí sọ̀rọ̀ asán, àwọn aláfọ̀ṣẹ sì tí rí èké, wọn sì tí rọ àlá èké; wọ́n ń tu ni nínú lásán, nítorí náà àwọn ènìyàn náà ṣáko lọ bí àgùntàn, a ṣẹ wọn níṣẹ̀ẹ́, nítorí Olùṣọ́-àgùntàn kò sí.
Les faux prophètes ont fait des prédictions funestes; les devins ont rapporté des visions fausses et des songes trompeurs; ils ont donné de vaines consolations; à cause de cela, ils ont dépéri comme des brebis abandonnées; ils ont été affligés, parce qu'il n'y avait pas de remède.
3 “Ìbínú mi ru sí àwọn darandaran, èmi o sì jẹ àwọn olórí ní yà nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti bẹ agbo rẹ̀, ilé Juda wò, yóò sì fi wọn ṣe ẹṣin rẹ̀ dáradára ní ogun.
Ma colère s'est enflammée contre les pasteurs, et Je visiterai les agneaux. Et le Seigneur Dieu tout-puissant visitera Son troupeau, la maison de Juda; et Il la formera comme son coursier, prêt aux combats.
4 Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni òkúta igun ilé ti jáde wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni èèkàn àgọ́ tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrún ogun tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn akóniṣiṣẹ́ gbogbo tí wá.
C'est de Lui que vient la visite; de Lui, l'ordre de bataille; de Lui, l'arc de la colère; et aussi tout exacteur sortira de Lui.
5 Gbogbo wọn yóò sì dàbí ọkùnrin alágbára ni ogun tí ń tẹ àwọn ọ̀tá wọn mọ́lẹ̀ ní ìgboro, wọn ó sì jagun, nítorí Olúwa wà pẹ̀lú wọn, wọn ó sì dààmú àwọn tí ń gun ẹṣin.
Et ils seront comme des guerriers, foulant aux pieds la boue des chemins dans la bataille; et ils en viendront aux mains, parce que le Seigneur sera avec eux; et les cavaliers seront confondus.
6 “Èmi o sì mú ilé Juda ní agbára, èmi o sì gba ilé Josẹfu là, èmi ó sì tún mú wọn padà nítorí mo tí ṣàánú fún wọn, ó sì dàbí ẹni pé èmi kò ì tì í ta wọ́n nù; nítorí èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn, èmi o sì gbọ́ tiwọn
Et Je fortifierai la maison de Juda; et Je sauverai la maison de Joseph, et Je les rétablirai, parce que Je les aime; et ils seront comme si Je ne les avais pas répudiés; car Je suis le Seigneur leur Dieu, et Je les exaucerai.
7 Efraimu yóò sì ṣe bí alágbára, ọkàn wọn yóò sì yọ̀ bi ẹni pé nípa ọtí wáìnì: àní àwọn ọmọ wọn yóò rí í, wọn o sì yọ̀, inú wọn ó sì dùn nínú Olúwa.
Et ils seront comme les guerriers d'Éphraïm, et leur cœur se réjouira, comme dans le vin; voilà ce que verront leurs enfants, et ils en seront charmés, et leur âme se réjouira dans le Seigneur.
8 Èmi ó kọ sí wọn, èmi ó sì ṣà wọ́n jọ; nítorí èmi tí rà wọ́n padà; wọn ó sì pọ̀ sí i gẹ́gẹ́ bí wọ́n tí ń pọ̀ sí í rí.
Je leur donnerai le signal et Je les rassemblerai; car Je les affranchirai et les multiplierai, comme lorsqu'ils étaient le plus nombreux.
9 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo tú wọn káàkiri orílẹ̀-èdè: síbẹ̀ wọn ó sì rántí mi ni ilẹ̀ jíjìn; wọn ó sì gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn, wọn ó sì tún padà.
Et Je les disséminerai parmi les peuples, et les plus lointains se souviendront de Moi; ils élèveront leurs enfants, et ils reviendront de captivité.
10 Èmi ó sì tún mú wọn padà kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú, èmi ó sì ṣà wọn jọ kúrò ni ilẹ̀ Asiria. Èmi ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ Gileadi àti Lebanoni; a kì yóò sì rí ààyè fún wọn bí ó ti yẹ.
Et Je les ramènerai de la terre d'Égypte; Je les accueillerai à leur retour de l'Assyrie, et Je les conduirai en Galaad et sur le Liban; et pas un seul d'entre eux ne sera laissé en oubli.
11 Wọn yóò sì la Òkun wàhálà já, yóò sì bori rírú omi nínú Òkun, gbogbo ibú odò ni yóò sì gbẹ, a ó sì rẹ ìgbéraga Asiria sílẹ̀, ọ̀pá aládé Ejibiti yóò sí lọ kúrò.
Et ils traverseront les détroits de la mer, et ils frapperont ses vagues, et le fond des fleuves sera à sec, et tout l'orgueil des Assyriens sera abattu, et le sceptre de l'Égypte sera brisé.
12 Èmi ó sì mú wọn ní agbára nínú Olúwa; wọn ó sì rìn sókè rìn sódò ni orúkọ rẹ̀,” ni Olúwa wí.
Et Je les fortifierai dans le Seigneur leur Dieu; et ils se feront gloire de Son Nom, dit le Seigneur.

< Zechariah 10 >