< Zechariah 10 >

1 Ẹ béèrè òjò nígbà àrọ̀kúrò ni ọwọ́ Olúwa; Olúwa tí o dá mọ̀nàmọ́ná, tí ó sì fi ọ̀pọ̀ òjò fún ènìyàn, fún olúkúlùkù koríko ní pápá.
Anokaat Herralta ehtoo sadetta, niin Herra tekee pilven, ja antaa teille kyllä sataa, kaikelle kedon kasvulle.
2 Nítorí àwọn òrìṣà tí sọ̀rọ̀ asán, àwọn aláfọ̀ṣẹ sì tí rí èké, wọn sì tí rọ àlá èké; wọ́n ń tu ni nínú lásán, nítorí náà àwọn ènìyàn náà ṣáko lọ bí àgùntàn, a ṣẹ wọn níṣẹ̀ẹ́, nítorí Olùṣọ́-àgùntàn kò sí.
Sillä epäjumalat puhuvat turhuutta, ja aavistajat näkevät valheen; ja puhuvat turhia unia, ja heidän lohdutuksensa ei ole mitään: sentähden he käyvät eksyksissä niinkuin lampaat, ja nääntyvät, ettei heillä ole yhtään paimenta.
3 “Ìbínú mi ru sí àwọn darandaran, èmi o sì jẹ àwọn olórí ní yà nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti bẹ agbo rẹ̀, ilé Juda wò, yóò sì fi wọn ṣe ẹṣin rẹ̀ dáradára ní ogun.
Minun vihani on julmistunut paimenten päälle, ja minä tahdon kauriit etsiä; sillä Herran Zebaot on etsivä laumansa, Juudan huoneen, ja valmistaa heitä niinkuin hankituita sotahevosia.
4 Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni òkúta igun ilé ti jáde wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni èèkàn àgọ́ tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrún ogun tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn akóniṣiṣẹ́ gbogbo tí wá.
Häneltä ovat nurkat, häneltä naulat, häneltä sotajoutsi, häneltä myös ynnä kaikki vaatiat tulleet.
5 Gbogbo wọn yóò sì dàbí ọkùnrin alágbára ni ogun tí ń tẹ àwọn ọ̀tá wọn mọ́lẹ̀ ní ìgboro, wọn ó sì jagun, nítorí Olúwa wà pẹ̀lú wọn, wọn ó sì dààmú àwọn tí ń gun ẹṣin.
Ja heidän pitää kuitenkin oleman niinkuin sankarit, jotka loan tallaavat kaduilla sodassa, ja pitää sotiman, sillä Herra on heidän kanssansa, että ratsasmiehet häpiään tulevat.
6 “Èmi o sì mú ilé Juda ní agbára, èmi o sì gba ilé Josẹfu là, èmi ó sì tún mú wọn padà nítorí mo tí ṣàánú fún wọn, ó sì dàbí ẹni pé èmi kò ì tì í ta wọ́n nù; nítorí èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn, èmi o sì gbọ́ tiwọn
Ja minä tahdon vahvistaa Juudan huoneen, ja varjella Josephin huonetta, ja tahdon heitä asettaa jälleen sijoillensa; sillä minä armahdan heitä; ja he ovat niinkuin he ennenkin olivat, kuin minä heidät sysäsin pois; sillä minä Herra heidän Jumalansa tahdon heitä kuulla.
7 Efraimu yóò sì ṣe bí alágbára, ọkàn wọn yóò sì yọ̀ bi ẹni pé nípa ọtí wáìnì: àní àwọn ọmọ wọn yóò rí í, wọn o sì yọ̀, inú wọn ó sì dùn nínú Olúwa.
Ja Ephraim on oleva niinkuin sankari, ja heidän sydämensä on iloitseva niinkuin viinasta; ja heidän lapsensa saavat myös sen nähdä, ja riemuitsevat, että heidän sydämensä on iloinen Herrassa.
8 Èmi ó kọ sí wọn, èmi ó sì ṣà wọ́n jọ; nítorí èmi tí rà wọ́n padà; wọn ó sì pọ̀ sí i gẹ́gẹ́ bí wọ́n tí ń pọ̀ sí í rí.
Minä tahdon heille viheltää, ja koota heitä, sillä minä tahdon heitä lunastaa; ja he lisääntyvät niinkuin he ennenkin olleet olivat.
9 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo tú wọn káàkiri orílẹ̀-èdè: síbẹ̀ wọn ó sì rántí mi ni ilẹ̀ jíjìn; wọn ó sì gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn, wọn ó sì tún padà.
Ja tahdon kylvää heitä kansain sekaan, että he muistaisivat minua kaukaisissa maakunnissa, ja eläisivät lastensa kanssa ja palajaisivat.
10 Èmi ó sì tún mú wọn padà kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú, èmi ó sì ṣà wọn jọ kúrò ni ilẹ̀ Asiria. Èmi ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ Gileadi àti Lebanoni; a kì yóò sì rí ààyè fún wọn bí ó ti yẹ.
Sillä minä tahdon heitä tuoda jälleen Egyptin maalta, ja koota heitä Assyriasta, ja saattaa heitä Gileadin maahan ja Libanoniin, ja ei siinäkään pidä heillä kyllä oleman.
11 Wọn yóò sì la Òkun wàhálà já, yóò sì bori rírú omi nínú Òkun, gbogbo ibú odò ni yóò sì gbẹ, a ó sì rẹ ìgbéraga Asiria sílẹ̀, ọ̀pá aládé Ejibiti yóò sí lọ kúrò.
Ja hänen pitää käymän sen ahtaan meren lävitse, ja meren aaltoja lyömän, että kaikki ojain syvyydet kuivuisivat; silloin Assyrian ylpeys alennetaan, ja Egyptin valtikka lakkaa.
12 Èmi ó sì mú wọn ní agbára nínú Olúwa; wọn ó sì rìn sókè rìn sódò ni orúkọ rẹ̀,” ni Olúwa wí.
Minä tahdon heitä vahvistaa Herrassa, ja heidän pitää vaeltaman hänen nimeensä, sanoo Herra.

< Zechariah 10 >