< Zechariah 10 >
1 Ẹ béèrè òjò nígbà àrọ̀kúrò ni ọwọ́ Olúwa; Olúwa tí o dá mọ̀nàmọ́ná, tí ó sì fi ọ̀pọ̀ òjò fún ènìyàn, fún olúkúlùkù koríko ní pápá.
Ask ye of Jehovah rain in the time of the latter rain! It is Jehovah that maketh the lightning; And he will give you abundant showers, To every one the herb of the field.
2 Nítorí àwọn òrìṣà tí sọ̀rọ̀ asán, àwọn aláfọ̀ṣẹ sì tí rí èké, wọn sì tí rọ àlá èké; wọ́n ń tu ni nínú lásán, nítorí náà àwọn ènìyàn náà ṣáko lọ bí àgùntàn, a ṣẹ wọn níṣẹ̀ẹ́, nítorí Olùṣọ́-àgùntàn kò sí.
For the teraphim speak falsehood, And the diviners see a lie, And the dreams speak falsehood; Vain are their consolations. Therefore they wander as a flock; They are in distress, because there is no shepherd.
3 “Ìbínú mi ru sí àwọn darandaran, èmi o sì jẹ àwọn olórí ní yà nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti bẹ agbo rẹ̀, ilé Juda wò, yóò sì fi wọn ṣe ẹṣin rẹ̀ dáradára ní ogun.
My anger is kindled against the shepherds, And the bucks will I punish; For Jehovah of hosts will visit his flock, the house of Judah, And make them as his goodly horse in battle.
4 Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni òkúta igun ilé ti jáde wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni èèkàn àgọ́ tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrún ogun tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn akóniṣiṣẹ́ gbogbo tí wá.
From him shall come forth the corner-stone, From him the nail, From him the battle-bow; From him shall every leader come forth.
5 Gbogbo wọn yóò sì dàbí ọkùnrin alágbára ni ogun tí ń tẹ àwọn ọ̀tá wọn mọ́lẹ̀ ní ìgboro, wọn ó sì jagun, nítorí Olúwa wà pẹ̀lú wọn, wọn ó sì dààmú àwọn tí ń gun ẹṣin.
And they shall be as mighty men, Who tread down their enemies in battle as the mire of the streets, And they shall fight, because Jehovah is with them, So that the riders on horses shall be confounded.
6 “Èmi o sì mú ilé Juda ní agbára, èmi o sì gba ilé Josẹfu là, èmi ó sì tún mú wọn padà nítorí mo tí ṣàánú fún wọn, ó sì dàbí ẹni pé èmi kò ì tì í ta wọ́n nù; nítorí èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn, èmi o sì gbọ́ tiwọn
And I will strengthen the house of Judah, And give victory to the house of Joseph, And I will set them in their dwellings, because I have compassion upon them; And they shall be as though I had not cast them off; For I am Jehovah, their God, and I will hear them.
7 Efraimu yóò sì ṣe bí alágbára, ọkàn wọn yóò sì yọ̀ bi ẹni pé nípa ọtí wáìnì: àní àwọn ọmọ wọn yóò rí í, wọn o sì yọ̀, inú wọn ó sì dùn nínú Olúwa.
And Ephraim shall be as a mighty man, And their heart shall rejoice, as through wine; And their sons shall see it and rejoice, Their hearts shall rejoice in Jehovah.
8 Èmi ó kọ sí wọn, èmi ó sì ṣà wọ́n jọ; nítorí èmi tí rà wọ́n padà; wọn ó sì pọ̀ sí i gẹ́gẹ́ bí wọ́n tí ń pọ̀ sí í rí.
I will whistle for them, and will gather them; for I have redeemed them; And they shall increase as they increased before.
9 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo tú wọn káàkiri orílẹ̀-èdè: síbẹ̀ wọn ó sì rántí mi ni ilẹ̀ jíjìn; wọn ó sì gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn, wọn ó sì tún padà.
Though I scatter them among the nations, Yet in far countries will they remember me; And they shall live with their children, and shall return.
10 Èmi ó sì tún mú wọn padà kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú, èmi ó sì ṣà wọn jọ kúrò ni ilẹ̀ Asiria. Èmi ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ Gileadi àti Lebanoni; a kì yóò sì rí ààyè fún wọn bí ó ti yẹ.
And I will bring them back from the land of Egypt, And from Assyria will I gather them; And I will bring them into the land of Gilead and of Lebanon, And there shall not be room enough for them.
11 Wọn yóò sì la Òkun wàhálà já, yóò sì bori rírú omi nínú Òkun, gbogbo ibú odò ni yóò sì gbẹ, a ó sì rẹ ìgbéraga Asiria sílẹ̀, ọ̀pá aládé Ejibiti yóò sí lọ kúrò.
And he shall pass through the sea of distress, And he shall smite the sea of waves, And all the depths of the river shall be dried up; And the pride of Assyria shall be brought down, And the sceptre of Egypt shall depart.
12 Èmi ó sì mú wọn ní agbára nínú Olúwa; wọn ó sì rìn sókè rìn sódò ni orúkọ rẹ̀,” ni Olúwa wí.
And I will strengthen them through Jehovah, And in his name shall they walk, saith Jehovah.