< Zechariah 1 >

1 Ní oṣù kẹjọ ọdún kejì ọba Dariusi, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah ọmọ Berekiah, ọmọ Iddo pé:
W ósmym miesiącu drugiego roku Dariusza słowo PANA doszło do Zachariasza, syna Berechiasza, syna Iddo proroka, mówiące:
2 “Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín.
PAN bardzo się rozgniewał na waszych ojców.
3 Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ mi,’ báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Dlatego powiedz im: Tak mówi PAN zastępów: Powróćcie do mnie, mówi PAN zastępów, a ja powrócę do was, mówi PAN zastępów.
4 Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé, báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí.
Nie bądźcie jak wasi ojcowie, do których wołali dawni prorocy, mówiąc: Tak mówi PAN zastępów: Odwróćcie się teraz od waszych złych dróg i od waszych złych uczynków. Ale oni nie usłuchali ani nie zważali na mnie, mówi PAN.
5 Àwọn baba yín, níbo ni wọ́n wà? Àti àwọn wòlíì, wọ́n ha wà títí ayé?
Gdzie są wasi ojcowie? A prorocy, czy żyją wiecznie?
6 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi àti ìlànà mi, ti mo pa ní àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, kò ha tún bá àwọn baba yín? “Wọ́n sì padà wọ́n wí pé, ‘Gẹ́gẹ́ bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rò láti ṣe sí wa, gẹ́gẹ́ bi ọ̀nà wa, àti gẹ́gẹ́ bí ìṣe wa, bẹ́ẹ̀ ní o ti ṣe sí wa.’”
Czyż jednak moje słowa i ustawy, które rozkazałem moim sługom, prorokom, nie dotarły do waszych ojców? Powrócili i powiedzieli: Jak PAN zastępów zamierzył uczynić nam według naszych dróg i naszych uczynków, tak nam uczynił.
7 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kọkànlá, tí ó jẹ́, oṣù Sebati, ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah, ọmọ Berekiah ọmọ Iddo wá, pé.
Dnia dwudziestego czwartego, jedenastego miesiąca, czyli w miesiącu Szebat, w drugim roku Dariusza, słowo PANA doszło do Zachariasza, syna Berechiasza, syna proroka Iddo, mówiące:
8 Mo rí ìran kan ni òru, si wò ó, ọkùnrin kan ń gun ẹṣin pupa kan, òun sì dúró láàrín àwọn igi maritili tí ó wà ní ibi òòji; lẹ́yìn rẹ̀ sì ni ẹṣin pupa, adíkálà, àti funfun gbé wà.
Widziałem w nocy, a oto mąż jechał na rudym koniu, który stał wśród mirtów, które [były] na nizinie, a za nim konie rude, pstrokate i białe.
9 Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni wọ̀nyí olúwa mi?” Angẹli tí ń ba mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Èmi ó fi ohun tí àwọn wọ̀nyí jẹ́ hàn ọ́.”
Wtedy zapytałem: Kim oni [są], mój panie? I Anioł, który rozmawiał ze mną, odpowiedział mi: Ja ci pokażę, kim oni są.
10 Ọkùnrin tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili sì dáhùn ó sì wí pé, “Wọ̀nyí ní àwọn tí Olúwa ti rán láti máa rìn sókè sódò ni ayé.”
I mąż, który stał wśród mirtów, odpowiedział: To są ci, których PAN posłał, aby obeszli ziemię.
11 Wọ́n si dá angẹli Olúwa tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili náà lóhùn pé, “Àwa ti rìn sókè sódò já ayé, àwa sí ti rí i pé gbogbo ayé wà ní ìsinmi àti àlàáfíà.”
I odpowiedzieli Aniołowi PANA stojącemu wśród mirtów: Obeszliśmy ziemię, a oto cała ziemia żyje bezpiecznie i zażywa pokoju.
12 Nígbà náà ni angẹli Olúwa náà dáhùn ó sì wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ kì yóò fi ṣàánú fún Jerusalẹmu, àti fún àwọn ìlú ńlá Juda, ti ìwọ ti bínú sí ni àádọ́rin ọdún wọ̀nyí?”
Wtedy Anioł PANA odpowiedział: PANIE zastępów, jak długo jeszcze nie będziesz się litował nad Jerozolimą i nad miastami Judy, na które się gniewasz już siedemdziesiąt lat?
13 Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ rere àti ọ̀rọ̀ ìtùnú dá angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ lóhùn.
PAN odpowiedział Aniołowi, który rozmawiał ze mną, słowami dobrymi, słowami pociechy.
14 Angẹli ti ń bá mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Ìwọ kígbe wí pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi ń fi ìjowú ńlá jowú fún Jerusalẹmu àti fún Sioni.
Potem Anioł, który rozmawiał ze mną, powiedział: Wołaj i mów: Tak mówi PAN zastępów: Zapłonąłem wielką gorliwością o Jerozolimę i o Syjon.
15 Èmi sì bínú púpọ̀púpọ̀ si àwọn orílẹ̀-èdè tí ó rò wí pé òun ní ààbò. Nítorí nígbà tí mo bínú díẹ̀, wọ́n ran ìparun lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú.’
A bardzo się gniewam na te narody, które zażywają pokoju, bo [gdy] się trochę gniewałem, one wtedy przyczyniły się do nieszczęścia.
16 “Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: ‘Mo padà tọ Jerusalẹmu wá pẹ̀lú àánú; ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, a ó kọ́ ilé mi sínú rẹ̀, a o sí ta okùn ìwọ̀n kan jáde sórí Jerusalẹmu.’
Dlatego tak mówi PAN: Zwróciłem się do Jerozolimy w miłosierdziu, mój dom zostanie w niej zbudowany, mówi PAN zastępów, i sznur [będzie] rozciągnięty nad Jerozolimą.
17 “Máa ké síbẹ̀ pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘A o máa fi ìre kún ìlú ńlá mi síbẹ̀; Olúwa yóò sì máa tu Sioni nínú síbẹ̀, yóò sì yan Jerusalẹmu síbẹ̀.’”
Wołaj jeszcze: Tak mówi PAN zastępów: Moje miasta jeszcze się rozciągną z powodu [obfitości] dobra, PAN jeszcze pocieszy Syjon i jeszcze wybierze Jerozolimę.
18 Mo si gbé ojú sókè, mo sì rí, sì kíyèsi i, ìwo mẹ́rin.
Wtedy podniosłem swe oczy i spojrzałem, a oto cztery rogi.
19 Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?” Ó si dà mí lóhùn pé, “Àwọn ìwo wọ̀nyí ni ó tí tú Juda, Israẹli, àti Jerusalẹmu ká.”
I zapytałem Anioła, który rozmawiał ze mną: Cóż to jest? I odpowiedział mi: To są rogi, które rozproszyły Judę, Izraela i Jerozolimę.
20 Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí.
Następnie PAN ukazał mi czterech kowali.
21 Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?” O sì sọ wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìwo tí ó ti tú Juda ká, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò fi gbé orí rẹ̀ sókè? Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí wá láti dẹ́rùbà wọ́n, láti lé ìwo àwọn orílẹ̀-èdè jáde, ti wọ́n gbé ìwo wọn sórí ilẹ̀ Juda láti tú ènìyàn rẹ̀ ká.”
I zapytałem: Co oni przyszli czynić? I odpowiedział: To są rogi, które rozproszyły Judę, tak że nikt nie mógł podnieść swojej głowy. Dlatego oni przyszli, aby je przestraszyć i strącić rogi tych narodów, [które] podniosły swoje rogi przeciwko ziemi Judy, aby ją rozproszyć.

< Zechariah 1 >