< Zechariah 1 >
1 Ní oṣù kẹjọ ọdún kejì ọba Dariusi, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah ọmọ Berekiah, ọmọ Iddo pé:
A nyolczadik hónapban, Darjáves második évében, lett az Örökkévaló igéje Zekarjához, Berekja, Iddó fia fiához, a prófétához, mondván:
2 “Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín.
Haraggal haragudott az Örökkévaló őseitekre.
3 Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ mi,’ báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Szólj hozzájuk: Így szól az Örökkévaló, a seregek ura: térjetek vissza hozzám, úgymond az Örökkévaló, a seregek ura s visszatérek tihozzátok, mondja az Örökkévaló, a seregek ura.
4 Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé, báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí.
Ne legyetek olyanok mint, őseitek, a kiknek hirdették vala az előbbi próféták, mondván Így szól az Úr az Örökkévaló, a seregek ura: térjetek csak vissza rossz utaitokról és rossz cselekedeteitektől; de nem hallgattak és nem figyeltek reám, úgymond az Örökkévaló.
5 Àwọn baba yín, níbo ni wọ́n wà? Àti àwọn wòlíì, wọ́n ha wà títí ayé?
Őseitek hol vannak? S a próféták örökké élnek-e?
6 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi àti ìlànà mi, ti mo pa ní àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, kò ha tún bá àwọn baba yín? “Wọ́n sì padà wọ́n wí pé, ‘Gẹ́gẹ́ bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rò láti ṣe sí wa, gẹ́gẹ́ bi ọ̀nà wa, àti gẹ́gẹ́ bí ìṣe wa, bẹ́ẹ̀ ní o ti ṣe sí wa.’”
Ámde szavaim és törvényeim, melyeket parancsoltam szolgáimnak, a prófétáknak, nemde utolérték őseiteket? Akkor megtértek és mondtaik: amint szándékozott velünk tenni az Örökkévaló, a seregek Ura, utjaink és cselekedeteink szerint, úgy tett rajtunk.
7 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kọkànlá, tí ó jẹ́, oṣù Sebati, ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah, ọmọ Berekiah ọmọ Iddo wá, pé.
Huszonnegyedik napján a tizenegyedik hónapnak, Sebát hónap az, Darjáves második évében, lett az Örökkévaló igéje Zekarjához, Berekjáhú, Iddó fia fiához, a prófétához, mondván:
8 Mo rí ìran kan ni òru, si wò ó, ọkùnrin kan ń gun ẹṣin pupa kan, òun sì dúró láàrín àwọn igi maritili tí ó wà ní ibi òòji; lẹ́yìn rẹ̀ sì ni ẹṣin pupa, adíkálà, àti funfun gbé wà.
Láttam az éjjel és íme, egy férfi rajta ül egy vörös lovon és ő állt a mély völgyben levő mirthusok között, mögötte vörös, fakó és fehér lovak.
9 Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni wọ̀nyí olúwa mi?” Angẹli tí ń ba mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Èmi ó fi ohun tí àwọn wọ̀nyí jẹ́ hàn ọ́.”
Mondtam: Mik ezek uram? És szólt hozzám az angyal, a ki velem beszélt Én megmutatom majd néked, mik ezek.
10 Ọkùnrin tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili sì dáhùn ó sì wí pé, “Wọ̀nyí ní àwọn tí Olúwa ti rán láti máa rìn sókè sódò ni ayé.”
Erre megszólalt a mirthusok között álló férfi és mondta: Ezek azok, akiket küldött az Örökkévaló, hogy bejárják a földet!
11 Wọ́n si dá angẹli Olúwa tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili náà lóhùn pé, “Àwa ti rìn sókè sódò já ayé, àwa sí ti rí i pé gbogbo ayé wà ní ìsinmi àti àlàáfíà.”
És feleltek az Örökkévaló angyalának, ki a mirthusok között állt és mondták: Bejártuk a földet, s íme az egész föld csendes és nyugodt.
12 Nígbà náà ni angẹli Olúwa náà dáhùn ó sì wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ kì yóò fi ṣàánú fún Jerusalẹmu, àti fún àwọn ìlú ńlá Juda, ti ìwọ ti bínú sí ni àádọ́rin ọdún wọ̀nyí?”
Erre megszólalt az Örökkévaló angyala és mondta: Örökkévaló, seregek ura, meddig nem irgalmazol te Jeruzsálemnek és Jehúda városainak, amelyekre haragszol immár hetven éve?
13 Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ rere àti ọ̀rọ̀ ìtùnú dá angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ lóhùn.
Felelt az Örökkévaló az angyalnak, ki velem beszélt, jóságos szavakkal, vigasztaló szavakkal.
14 Angẹli ti ń bá mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Ìwọ kígbe wí pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi ń fi ìjowú ńlá jowú fún Jerusalẹmu àti fún Sioni.
És szólt hozzám az angyal, ki velem beszélt: Hirdesd, mondván: így szól az Örökkévaló, a seregek ura: Buzgólkodtam Jeruzsálemért és Cziónért, nagy buzgalommal.
15 Èmi sì bínú púpọ̀púpọ̀ si àwọn orílẹ̀-èdè tí ó rò wí pé òun ní ààbò. Nítorí nígbà tí mo bínú díẹ̀, wọ́n ran ìparun lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú.’
És nagy haraggal haragszom a gondtalan nemzetekre, mivel én keveset haragudtam, de ők bajra segédkeztek.
16 “Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: ‘Mo padà tọ Jerusalẹmu wá pẹ̀lú àánú; ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, a ó kọ́ ilé mi sínú rẹ̀, a o sí ta okùn ìwọ̀n kan jáde sórí Jerusalẹmu.’
Azért így szól az Örökkévaló: Visszatértem Jeruzsálemhez irgalommal; házam fölépül benne, úgymond az Örökkévaló, a seregek ura, és mérőzsinór feszíttetik ki Jeruzsálemen.
17 “Máa ké síbẹ̀ pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘A o máa fi ìre kún ìlú ńlá mi síbẹ̀; Olúwa yóò sì máa tu Sioni nínú síbẹ̀, yóò sì yan Jerusalẹmu síbẹ̀.’”
Még hirdesd, mondván: Így szól az Örökkévaló, a seregek ura még bővülni fognak városaim a jótól, megvigasztalja még az Örökkévaló Cziónt és még kiválasztja Jeruzsálemet!
18 Mo si gbé ojú sókè, mo sì rí, sì kíyèsi i, ìwo mẹ́rin.
Fölemeltem szemeimet és láttam: íme négy szarv.
19 Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?” Ó si dà mí lóhùn pé, “Àwọn ìwo wọ̀nyí ni ó tí tú Juda, Israẹli, àti Jerusalẹmu ká.”
És szóltam az angyalhoz, ki velem beszélt: Mik ezek? Szólt hozzám: Ezek a szarvak, melyek szétszórták Jehúdát, Izraélt és Jeruzsálemet.
20 Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí.
Erre láttatott velem az Örökkévaló négy kovácsot.
21 Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?” O sì sọ wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìwo tí ó ti tú Juda ká, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò fi gbé orí rẹ̀ sókè? Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí wá láti dẹ́rùbà wọ́n, láti lé ìwo àwọn orílẹ̀-èdè jáde, ti wọ́n gbé ìwo wọn sórí ilẹ̀ Juda láti tú ènìyàn rẹ̀ ká.”
Mondtam: Mit jönnek ezek tenni? És szólt, mondván: Ezek a szarvak, melyek szétszórták Jehúdát annyiban, hogy senki nem emelhette fel a fejét, jöttek tehát ezek, hogy elriasszák azokat, leütvén a szarvait ama nemzeteknek, melyek szarvat emeltek vala Jehúda országa ellen, hogy szétszórják.