< Zechariah 1 >

1 Ní oṣù kẹjọ ọdún kejì ọba Dariusi, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah ọmọ Berekiah, ọmọ Iddo pé:
I KA malama ewalu o ka makahiki elua o Dariu, hiki mai ka olelo a Iehova ia Zekaria, ke keiki a Berekia, ke keiki a Ido, ke kaula, i ka i ana mai,
2 “Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín.
Ua ukiuki loa o Iehova i ko oukou poe kupuna.
3 Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ mi,’ báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Nolaila, e olelo aku oe ia lakou nei, Penei ka Iehova o na kaua i olelo mai nei, E huli mai oukou io'u nei, wahi a Iehova o na kaua, a e huli aku hoi au ia oukou la, wahi a Iehova o na kaua.
4 Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé, báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí.
Mai noho a like oukou me ko oukou poe kupuna, ka poe a ka poe kaula mua i kahea aku ai, i ka i ana, Penei ka Iehova o na kaua i olelo mai ai, E huli no oukou mai ka oukou mau aoao hewa mai, a mai ka oukou hana hewa ana hoi; aole nae lakou i hoolohe mai, aole hoi i malama mai ia'u, wahi a Iehova.
5 Àwọn baba yín, níbo ni wọ́n wà? Àti àwọn wòlíì, wọ́n ha wà títí ayé?
O ko oukou poe kupuna, auhea la lakou? A o ka poe kaula, e ola mau anei lakou?
6 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi àti ìlànà mi, ti mo pa ní àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, kò ha tún bá àwọn baba yín? “Wọ́n sì padà wọ́n wí pé, ‘Gẹ́gẹ́ bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rò láti ṣe sí wa, gẹ́gẹ́ bi ọ̀nà wa, àti gẹ́gẹ́ bí ìṣe wa, bẹ́ẹ̀ ní o ti ṣe sí wa.’”
Aka, o ka'u mau olelo a me ko'u mau kanawai, a'u i kauoha aku ai i ka'u poe kauwa i ka poe kaula, aole anei i hookoia ua mau mea la i na makua o oukou? A ua huli mai lakou me ka olelo ae, Me ka Iehova o na kaua i manao ai e hana mai ia makou ma ko makou mau aoao a ma ka makou mau hana, pela no ia i hana mai ai ia makou.
7 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kọkànlá, tí ó jẹ́, oṣù Sebati, ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah, ọmọ Berekiah ọmọ Iddo wá, pé.
I ka la iwakaluakumamaha o ka umikumamakahi o ka malama, oia ka malama Sebata, i ka lua o ka makahiki o Dariu, hiki mai la ka olelo a Iehova i ke kaula ia Zekaria ke keiki a Berekia, ke keiki a Ido, i ka i ana mai,
8 Mo rí ìran kan ni òru, si wò ó, ọkùnrin kan ń gun ẹṣin pupa kan, òun sì dúró láàrín àwọn igi maritili tí ó wà ní ibi òòji; lẹ́yìn rẹ̀ sì ni ẹṣin pupa, adíkálà, àti funfun gbé wà.
Ua ike au i ka po, aia hoi, he kanaka e noho ana maluna o ka lio ulaula, e ku ana iwaena o na laau mureto ma kahi malumalu, a mahope ona na lio ulaula, kikokiko a keokeo.
9 Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni wọ̀nyí olúwa mi?” Angẹli tí ń ba mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Èmi ó fi ohun tí àwọn wọ̀nyí jẹ́ hàn ọ́.”
A ninau aku la au, Owai la keia poe, e ka Haku? I mai la ka anela e kamailio ana me au, E hoike aku no au ia oe i keia poe.
10 Ọkùnrin tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili sì dáhùn ó sì wí pé, “Wọ̀nyí ní àwọn tí Olúwa ti rán láti máa rìn sókè sódò ni ayé.”
Olelo mai la ke kanaka e ku ana iwaena o na laau mureto, i mai la, O lakou nei ka poe a Iehova i hoouna mai ai e kaahele maluna o ka honua.
11 Wọ́n si dá angẹli Olúwa tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili náà lóhùn pé, “Àwa ti rìn sókè sódò já ayé, àwa sí ti rí i pé gbogbo ayé wà ní ìsinmi àti àlàáfíà.”
Olelo mai la lakou i ka anela o Iehova e ku ana iwaena o na laau mureto, i mai la, Ua kaahele makou i ka honua, aia hoi, ua noho malie, a ua malu hoi ko ka honua a pau.
12 Nígbà náà ni angẹli Olúwa náà dáhùn ó sì wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ kì yóò fi ṣàánú fún Jerusalẹmu, àti fún àwọn ìlú ńlá Juda, ti ìwọ ti bínú sí ni àádọ́rin ọdún wọ̀nyí?”
Alaila, olelo mai la ka anela o Iehova, i mai la, E Iehova o na kaua, Pehea la ka loihi o kou aloha ole mai ia Ierusalema, a me na kulanakauhale o Iuda, au i huhu mai ai i neia mau makahiki he kanahiku?
13 Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ rere àti ọ̀rọ̀ ìtùnú dá angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ lóhùn.
Olelo mai la o Iehova i ka anela i kamailio me au i na olelo aloha, a me na olelo hooluolu.
14 Angẹli ti ń bá mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Ìwọ kígbe wí pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi ń fi ìjowú ńlá jowú fún Jerusalẹmu àti fún Sioni.
A o ka anela i kamailio me au, i mai la oia ia'u, penei, E kahea aku oe, i ka i ana aku, Penei ka Iehova o na kaua i olelo mai ai, ua aloha no au ia Ierusalema a ia Ziona i ke aloha nui.
15 Èmi sì bínú púpọ̀púpọ̀ si àwọn orílẹ̀-èdè tí ó rò wí pé òun ní ààbò. Nítorí nígbà tí mo bínú díẹ̀, wọ́n ran ìparun lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú.’
A ua huhu loa au i ko na aina e e noho nanea ana; a i kuu wa i huhu uuku ai, kokua aku la lakou i ka hoopilikia ana.
16 “Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: ‘Mo padà tọ Jerusalẹmu wá pẹ̀lú àánú; ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, a ó kọ́ ilé mi sínú rẹ̀, a o sí ta okùn ìwọ̀n kan jáde sórí Jerusalẹmu.’
Nolaila, ke i mai nei o Iehova, Ua hoi hou mai nei au i Ierusalema me ke aloha; e kukuluia ko'u hale iloko ona, wahi a Iehova o na kaua; a e kauia ke kaula-ana maluna o Ierusalema.
17 “Máa ké síbẹ̀ pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘A o máa fi ìre kún ìlú ńlá mi síbẹ̀; Olúwa yóò sì máa tu Sioni nínú síbẹ̀, yóò sì yan Jerusalẹmu síbẹ̀.’”
E kahea aku hoi, i ka i ana, Penei ka Iehova o na kaua i olelo ai; Ma ia hope e hoopiha la ia ko'u mau kulanakauhale i ka lokomaikai; a ma ia hope hoi e hooluolu o Iehova ia Ziona, a e wae hoi ia Ierusalema.
18 Mo si gbé ojú sókè, mo sì rí, sì kíyèsi i, ìwo mẹ́rin.
Alaila alawa ae la ko'u mau maka iluna, ike aku la au, aia hoi, he mau pepeiaohao eha.
19 Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?” Ó si dà mí lóhùn pé, “Àwọn ìwo wọ̀nyí ni ó tí tú Juda, Israẹli, àti Jerusalẹmu ká.”
Alaila, i aku la au i ka anela i kamailio me au, Heaha keia mau mea? I mai la kela ia'u, Eia na pepeiaohao I hooauhee aku i ka Iuda, i ka Iseraela a me ko Ierusalema.
20 Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí.
A hoike mai la o Iehova ia'u i na kamena eha.
21 Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?” O sì sọ wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìwo tí ó ti tú Juda ká, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò fi gbé orí rẹ̀ sókè? Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí wá láti dẹ́rùbà wọ́n, láti lé ìwo àwọn orílẹ̀-èdè jáde, ti wọ́n gbé ìwo wọn sórí ilẹ̀ Juda láti tú ènìyàn rẹ̀ ká.”
I aku la au, Heaha ka lakou nei e hana'i? I mai la kela, penei, O keia no na pepeiaohao, nana i hooauhee ia Iuda, i hookiekie ole ai kekahi i kona poo; a ua hele mai keia poe e hoomakau ia lakou, a e kipaku aku i na pepeiaohao o ko na aina e, o ka poe hookiekie i ka pepeiaohao maluna o ka aina o ka Iuda e hooauhee aku ai ia ia.

< Zechariah 1 >