< Titus 3 >

1 Rán àwọn ènìyàn náà létí láti máa tẹríba fún ìjọba àti àwọn aláṣẹ. Kí wọn ṣe ìgbọ́ràn nígbà gbogbo, kí wọn sì múra fún iṣẹ́ rere gbogbo.
ⲁ̅ⲙⲁ⳿ⲫⲙⲉⲩⲓ ⲛⲱⲟⲩ ⲉⲑⲣⲟⲩϭⲛⲉϫⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓⲁⲣⲭⲏ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲉⲝⲟⲩⲥⲓⲁ ⲉⲩⲟⲓ ⳿ⲛⲣⲉϥϯⲙⲁϯ ⳿ⲛⲥⲉϣⲱⲡⲓ ⲉⲩⲥⲉⲃⲧⲱⲧ ⳿ⲉϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲑⲛⲁⲛⲉⲩ.
2 Wọn kò gbọdọ̀ sọ̀rọ̀ ẹnikẹ́ni ní ibi, kí wọn jẹ́ ẹni àlàáfíà àti ẹni pẹ̀lẹ́, kí wọn sì máa fi ìwà tútù gbogbo hàn sí gbogbo ènìyàn.
ⲃ̅⳿ⲛⲥⲉϫⲉⲟⲩ⳿ⲁ ⳿ⲉ⳿ϩⲗⲓ ⲁⲛ ⳿ⲛⲥⲉⲟⲓ ⳿ⲛⲣⲉϥ⳿ⲙⲗⲁϧ ⲁⲛ ⲉⲩⲟⲓ ⳿ⲛⲉⲡⲓⲕⲏⲥ ⲉⲩⲟⲩⲱⲛϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲉⲧⲣⲉⲙⲣⲁⲩϣ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲛⲉⲙ ⲣⲱⲙⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
3 Nígbà kan rí, àwa pàápàá jẹ́ òpè àti aláìgbọ́ràn, àti tàn wá jẹ, a sì ti sọ wá di ẹrú fún onírúurú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti adùn ayé. À ń gbé ìgbé ayé àrankàn àti owú kíkorò, a jẹ́ ẹni ìríra, a sì ń kórìíra ọmọ ẹnìkejì wa pẹ̀lú.
ⲅ̅ⲛⲁⲛⲟⲓ ⲅⲁⲣ ϩⲱⲛ ⲡⲉ ⳿ⲛⲁⲧ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲥⲏⲟⲩ ⲉⲛⲟⲓ ⳿ⲛⲁⲧϯⲙⲁϯ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲛⲥⲟⲣⲉⲙ ⲉⲛⲟⲓ ⳿ⲙⲃⲱⲕ ⳿ⲛϩⲁⲛⲉⲡⲓⲑⲩⲙⲓⲁ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛϩⲩⲇⲟⲛⲏ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛⲣⲏϯ ⲉⲛⲙⲟϣⲓ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲕⲁⲕⲓⲁ ⲛⲉⲙ ⲟⲩ⳿ⲫⲑⲟⲛⲟⲥ ⲉⲛ⳿ⲙ⳿ⲡϣⲁ ⳿ⲙⲙⲉⲥⲧⲱⲛ ⲉⲛⲙⲟⲥϯ ⳿ⲛⲛⲉⲛⲉⲣⲏ ⲟⲩ.
4 Ṣùgbọ́n nígbà tí inú rere àti ìfẹ́ Ọlọ́run Olùgbàlà wa farahàn,
ⲇ̅ϩⲟⲧⲉ ⲇⲉ ⲉⲧⲁⲥⲟⲩⲟⲛϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϫⲉ ϯ ⲙⲉⲧⲭ͞ⲣⲥ̅ ⲛⲉⲙ ϯⲙⲉⲧⲙⲁⲓⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲡⲉⲛⲥⲱⲧⲏⲣ.
5 o gbà wá là. Kì í ṣe nípa iṣẹ́ tí àwa ṣe nínú òdodo bí kò ṣe nítorí àánú rẹ̀. Ó gbà wá là, nípasẹ̀ ìwẹ̀nù àtúnbí àti ìsọdọ̀tun ti Ẹ̀mí Mímọ́,
ⲉ̅ⲛⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲉⲛ⳿ϩⲃⲏⲟⲩ⳿ⲓ ⲁⲛ ⲉⲧⲁⲛⲁⲓⲧⲟⲩ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲑⲙⲏⲓ ⲁⲗⲗⲁ ⲕⲁⲧⲁ ⲡⲉϥⲛⲁⲓ ⲁϥⲛⲁϩⲙⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲡⲓϫⲱⲕⲉⲙ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲟⲩⲁϩⲉⲙⲙⲓⲥⲓ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲟⲩⲁϩⲉⲙⲃⲉⲣⲓ.
6 èyí tí tú lé wa lórí ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ nípasẹ̀ Jesu Kristi Olùgbàlà wá.
ⲋ̅ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲁϥϫⲟϣϥ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲱⲛ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲧⲣⲁⲙⲁ⳿ⲟ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲡⲉⲛⲥⲱⲧⲏ ⲣ.
7 Tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́ tí ó jẹ́ wí pé lẹ́hìn tí a tí dá wa láre nípasẹ̀ oore-ọ̀fẹ́, kí a lè jẹ́ àjùmọ̀jogún ìrètí ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios g166)
ⲍ̅ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲛⲙⲁⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫⲏ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲛⲧⲉⲛϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛ⳿ⲕⲗⲏⲣⲟⲛⲟⲙⲟⲥ ⲕⲁⲧⲁ ⲟⲩϩⲉⲗⲡⲓⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩⲱⲛϧ ⳿ⲛⲉⲛⲉϩ. (aiōnios g166)
8 Òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ wọ̀nyí. Mo sì fẹ́ kí ó ṣe ìtẹnumọ́ rẹ̀ gidigidi, kí àwọn tí wọ́n ti gbàgbọ́ nínú Ọlọ́run le kíyèsi láti máa fi ara wọn jì fún iṣẹ́ rere. Nǹkan wọ̀nyí dára, wọ́n sì jẹ́ èrè fún gbogbo ènìyàn.
ⲏ̅⳿ϥⲉⲛϩⲟⲧ ⳿ⲛϫⲉ ⳿ⲡⲥⲁϫⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲑⲃⲉ ⲛⲁⲓⲕⲉⲭ ⲱⲟⲩⲛⲓ ϯⲟⲩⲱϣ ⲉⲑⲣⲉⲕⲧⲁϫⲣⲟⲕ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲥⲉϥⲓ⳿ⲫⲣⲱⲟⲩϣ ⳿ⲉϯⲧⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓ⳿ϩⲃⲏⲟⲩⲓ ⲉⲑⲛⲁⲛⲉⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲏⲉⲧⲁⲩⲛⲁϩϯ ⳿ⲉⲫϯ ⲛⲁⲓ ⲛⲁⲛⲉⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲥⲉⲟⲓ ⳿ⲛϩⲏⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓⲣⲱⲙⲓ.
9 Ṣùgbọ́n yẹra kúrò nínú àwọn ìbéèrè òmùgọ̀, àti ìtàn ìran, àti àríyànjiyàn àti ìjà nípa ti òfin, nítorí pé àwọn nǹkan báyìí jẹ́ aláìlérè àti asán.
ⲑ̅ⲛⲓⲕⲱϯ ⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲥⲟϫ ⲛⲉⲙ ⲛⲓϫⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲓ⳿ϣϭⲛⲏⲛ ⲛⲉⲙ ⲛⲓ⳿ⲙⲗⲁϧ ⳿ⲛⲛⲟⲙⲓⲕⲟⲛ ϩⲉⲛⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲛⲁⲓ ⲅⲁⲣ ϩⲁⲛⲁⲧ ϯϩⲏⲟⲩ ⲛⲉ ⲟⲩⲟϩ ϩⲁⲛⲉⲫⲗⲏⲟⲩ ⲛⲉ.
10 Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ dá ìyapa sílẹ̀ láàrín yín, ẹ bá a wí lẹ́ẹ̀kínní àti lẹ́ẹ̀kejì. Lẹ́yìn náà, ẹ má ṣe ní ohunkóhun í ṣe pẹ̀lú rẹ̀.
ⲓ̅ⲟⲩⲉⲣⲉⲧⲓⲕⲟⲥ ⳿ⲛⲣⲱⲙⲓ ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⲟⲩⲥⲟⲡ ⲛⲉⲙ ⲃ̅ ⳿ⲛϯ⳿ⲥⲃⲱ ⲛⲁϥ ⲁⲣⲓⲡⲁⲣⲁⲧⲓⲥⲑⲉ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
11 Kí ó dá ọ lójú wí pé irú ẹni bẹ́ẹ̀ ti yapa, ó jẹ́ ẹlẹ́ṣẹ̀, ó sì dá ara rẹ̀ lẹ́bi.
ⲓ̅ⲁ̅ⲉⲕ⳿ⲉⲙⲓ ϫⲉ ⲁϥⲫⲱⲛϩ ⳿ⲛϫⲉ ⲫⲁⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲟⲩⲟϩ ⳿ϥⲉⲣⲛⲟⲃⲓ ⳿ⲉⲁϥϩⲓⲧϥ ⳿ⲙⲡⲓϩⲁⲡ ⳿ⲙⲙⲁⲩⲁⲧϥ.
12 Ní kété tí mo bá ti rán Artema tàbí Tikiku sí ọ, sa gbogbo ipá rẹ láti tọ̀ mí wá ní Nikopoli, nítorí mo ti pinnu láti lo ìgbà òtútù mi níbẹ̀.
ⲓ̅ⲃ̅ⲉϣⲱⲡ ⲁⲛϣⲁⲛⲟⲩⲱⲣⲡ ⳿ⲛⲁⲣⲧⲉⲙⲁ ϩⲁⲣⲟⲕ ⲓⲉ ⲧⲓⲭⲓⲕⲟⲥ ⲓⲏⲥ ⳿ⲙⲙⲟⲕ ⳿ⲉ⳿ⲓ ϩⲁⲣⲟⲓ ⳿ⲉⲛⲓⲕⲟⲡⲟⲗⲓⲥ ⲁⲓⲑⲱϣ ⲅⲁⲣ ⳿ⲉⲉⲣϯ⳿ⲫⲣⲱ ⳿ⲙⲙⲁⲩ.
13 Sa gbogbo agbára rẹ láti ran Senasi amòfin àti Apollo lọ́wọ́ nínú ìrìnàjò wọn. Rí i dájú pé wọ́n ní ohun gbogbo tí wọn nílò.
ⲓ̅ⲅ̅ⲍⲏⲛⲁⲥ ⲡⲓⲛⲟⲙⲓⲕⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲁⲡⲟⲗⲗⲱ ⲟⲩⲟⲣⲡⲟⲩ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲓⲏⲥ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲥⲉ⳿ϣⲧⲉⲙϭⲣⲟϩ ⳿ⲛ⳿ϩⲗⲓ.
14 Àwọn ènìyàn nílò láti kọ́ bí a tí ń fi ara ẹni jì sí iṣẹ́ rere kí wọn ba à le pèsè ohun kòsémánìí fún ara wọn, nípa èyí, wọn kì yóò jẹ́ aláìléso.
ⲓ̅ⲇ̅ⲙⲁⲣⲟⲩⲥⲁⲃⲟ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲏⲉⲧⲉⲛⲟⲩⲛ ⳿ⲉϥⲓ⳿ⲫⲣⲱⲟⲩϣ ⳿ⲛϩⲁⲛ⳿ϩⲃⲏⲟⲩ⳿ⲓ ⲉⲑⲛⲁⲛⲉⲩ ⳿ⲉⲛⲓⲁⲛⲁⲅⲕⲉⲟⲛ ⳿ⲛ⳿ⲭⲣⲓⲁ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲥⲉ⳿ϣⲧⲉⲙϣⲱⲡⲓ ⲉⲩⲟⲓ ⳿ⲛⲁⲧⲟⲩⲧⲁϩ.
15 Gbogbo àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ mi kí ọ. Bá mi kí àwọn tí ó fẹ́ wa nínú ìgbàgbọ́. Kí oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú gbogbo yín.
ⲓ̅ⲉ̅ⲥⲉϣⲓⲛⲓ ⳿ⲉⲣⲟⲕ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲏⲉⲑⲛⲉⲙⲏⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ϣⲓⲛⲓ ⳿ⲉⲛⲏⲉⲑⲙⲉⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲛⲁϩϯ ⳿ⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲛⲉⲙⲱⲧⲉⲛ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⳿ⲡⲣⲟⲥ ⲧⲟⲧⲟⲥ ⲁⲩ⳿ⲥϧⲏⲧⲥ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲕⲟⲡⲟⲗⲓⲥ ⲁϥⲉⲣⲉⲡⲓⲥⲕⲟⲡⲟⲥ ⳿ⲛϯⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲑⲙⲁⲕⲉⲇⲟⲛⲓⲁ

< Titus 3 >