< Ruth 1 >

1 Ní ìgbà tí àwọn onídàájọ́ ń ṣe àkóso ilẹ̀ Israẹli, ìyàn kan mú ní ilẹ̀ náà, ọkùnrin kan láti Bẹtilẹhẹmu ti Juda, òun àti aya rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjì lọ láti máa gbé ní ilẹ̀ Moabu fún ìgbà díẹ̀.
Pripetilo se je torej v dneh, ko so vladali sodniki, da je bila v deželi lakota. In nek mož iz Judovega Betlehema je odšel, da začasno prebiva v moábski deželi, on in njegova žena in njegova dva sinova.
2 Orúkọ ọkùnrin náà ń jẹ́ Elimeleki, orúkọ ìyàwó rẹ̀ ni Naomi, orúkọ àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì sì ni Maloni àti Kilioni àwọn ará Efrata, ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda. Wọ́n sì lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọ́n ń gbé níbẹ̀.
Ime moža je bilo Eliméleh, ime njegove žene pa Naomí in ime njegovih dveh sinov Mahlón in Kiljón, Efrátejci iz Judovega Betlehema. Prišli so v moábsko deželo in tam ostali.
3 Ní àsìkò tí wọ́n ń gbé ibẹ̀, Elimeleki, ọkọ Naomi kú, ó sì ku òun pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì.
Naomín soprog Eliméleh je umrl in bila je zapuščena in njena dva sinova.
4 Wọ́n sì fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ará Moabu méjì, orúkọ ọ̀kan ń jẹ́ Oripa, èkejì sì ń jẹ́ Rutu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti gbé níbẹ̀ fún bí ọdún mẹ́wàá,
In vzela sta si ženi izmed moábskih žensk. Ime ene je bilo Orpa, ime druge pa je bilo Ruta. In tam so prebivali okoli deset let.
5 Maloni àti Kilioni náà sì kú, Naomi sì wà láìsí ọkọ tàbí ọmọ kankan fún un mọ́.
Tudi Mahlón in Kiljón, oba izmed njiju, sta umrla. In ženska je bila zapuščena od svojih dveh sinov in od svojega soproga.
6 Nígbà tí Naomi gbọ́ ní Moabu tí ó wà wí pé Olúwa ti bẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ wò nípa fífún wọn ní ọ̀pọ̀ oúnjẹ. Ó sì dìde pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì láti padà sí ìlú rẹ̀.
Potem je vstala s svojima snahama, da bi se lahko vrnila iz moábske dežele, kajti v moábski deželi je slišala, kako je Gospod obiskal svoje ljudstvo, ko jim je dajal kruh.
7 Òun pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì ni wọ́n jọ fi ibi tí ó ń gbé sílẹ̀ tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà sí ilẹ̀ Juda.
Zato je odšla iz kraja, kjer je bila in njeni dve snahi z njo in odšle so na pot, da se vrnejo v Judovo deželo.
8 Ṣùgbọ́n ní ojú ọ̀nà, Naomi wí fún àwọn aya ọmọ rẹ̀ méjèèjì pé, “Kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín padà sí ilé ìyá rẹ̀. Kí Olúwa ṣe àánú fún yín bí ẹ ti ṣe sí èmi àti àwọn ọkọ yín tí ó kú.
Naomí je svojima dvema snahama rekla: »Pojdita, vrnita se vsaka k hiši svoje matere. Gospod naj prijazno postopa z vama, kakor sta vidve postopali z mrtvima in z menoj.
9 Kí Olúwa kí ó fi yín lọ́kàn balẹ̀ ní ilé ọkọ mìíràn.” Naomi sì fi ẹnu kò wọ́n ní ẹnu wí pé “Ó dìgbà,” wọ́n sì sọkún kíkankíkan.
Gospod naj vama zagotovi, da bosta lahko našli počitek, vsaka izmed vaju, v hiši svojega soproga.« Potem ju je poljubila. Oni pa sta povzdignili svoj glas in zajokali.
10 Wọ́n sì wí fún un pé, “Rárá, a ó bà ọ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.”
Rekli sta ji: »Zagotovo se bova s teboj vrnili k tvojemu ljudstvu.«
11 Ṣùgbọ́n Naomi dáhùn wí pé, “Ẹ padà sílé ẹ̀yin ọmọ mi. Nítorí kí ni ẹ fi fẹ́ wá pẹ̀lú mi? Ṣé mo tún le bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn ni, tí ó le ṣe ọkọ yin?
Naomí je rekla: »Obrnita se, moji hčeri. Čemu hočeta iti z menoj? Mar je v moji maternici vendar še kaj sinov, da bi bili vajini soprogi?
12 Ẹ padà sílé, ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí èmi ti di arúgbó jù láti ní ọkọ mìíràn. Bí èmí wí pé, èmí ní ìrètí, bí èmí tilẹ̀ ní ọkọ mìíràn ní alẹ́ yìí, tí èmí sì bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn,
Ponovno se obrnita, moji hčeri, pojdita svojo pot, kajti prestara sem, da bi imela soproga. Če bi rekla, imam upanje, če bi tudi nocoj imela soproga in bi mu tudi rodila sinove,
13 ẹ̀yin ha le è dúró dìgbà tí wọ́n yóò fi dàgbà? Ẹ̀yin ó le è dúró dè wọ́n láì fẹ́ ọkọ mìíràn? Rárá, ẹ̀yin ọmọbìnrin mi, nítorí pé inú mi bàjẹ́ gidigidi ju tiyín lọ, nítorí tí ọwọ́ Olúwa fi jáde sí mi!”
bi se zadrževali zanju dokler ne bi odrasla? Bi ostali zanju, da ne bi imeli soprogov? Ne, moji hčeri, kajti to me zelo žalosti zaradi vaju, da se je Gospodova roka iztegnila zoper mene.«
14 Wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì tún sọkún. Nígbà náà ní Oripa fi ẹnu ko ìyá ọkọ rẹ̀ ní ẹnu wí pé ó dìgbà, ṣùgbọ́n Rutu dì mọ́ ọn síbẹ̀.
Povzdignili sta glas in ponovno zajokali. Orpa je poljubila svojo taščo, toda Ruta se je trdno pridružila k njej.
15 Naomi wí pé, “Wò ó, arábìnrin rẹ ti padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀ àti òrìṣà rẹ̀, ìwọ náà padà pẹ̀lú rẹ̀.”
Rekla je: »Glej, tvoja svakinja je odšla nazaj k svojemu ljudstvu in k svojim bogovom. Vrni se za svojo svakinjo.«
16 Ṣùgbọ́n Rutu dáhùn wí pé, “Má ṣe rọ̀ mí láti fi ọ́ sílẹ̀ tàbí láti padà lẹ́yìn rẹ. Ibi tí ìwọ bá lọ ní èmi yóò lọ, ibi ti ìwọ bá dúró ni èmi yóò dúró, àwọn ènìyàn rẹ ni yóò jẹ́ ènìyàn mi, Ọlọ́run rẹ ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run mi.
Ruta pa je rekla: »Ne zahtevaj, da te zapustim ali da se vrnem od sledenja za teboj, kajti kamor greš ti, bom šla jaz. In kjer ti prenočuješ, bom prenočevala jaz. Tvoje ljudstvo bo moje ljudstvo in tvoj Bog [bo] moj Bog.
17 Níbi tí ìwọ bá kú sí ni èmi yóò kú sí, níbẹ̀ ni wọn yóò sì sin mí sí. Kí Olúwa jẹ mí ní ìyà tí ó lágbára, bí ohunkóhun bí kò ṣe ikú bá yà wá.”
Kjer ti umreš, bom umrla jaz in tam bom pokopana. Gospod naj mi tako stori in še več, če bi karkoli razen smrti, ločilo tebe in mene.«
18 Nígbà tí Naomi rí i wí pé Rutu ti pinnu láti tẹ̀lé òun kò rọ̀ láti padà mọ́.
Ko je videla, da je bila neomajnega mišljenja, da gre z njo, potem je opustila, da ji prigovarja.
19 Àwọn méjèèjì sì ń lọ títí wọ́n fi dé ìlú Bẹtilẹhẹmu. Nígbà tí wọ́n dé ibẹ̀, ariwo ìpadàbọ̀ wọn gba ìlú kan, àwọn obìnrin ibẹ̀ sì kígbe ní ohùn rara wí pé, “Naomi ni èyí bí?”
Tako sta obe odšli, dokler nista prišli v Betlehem. Pripetilo se je, ko sta prišli v Betlehem, da je bilo vse mesto vznemirjeno glede njiju in rekli so: » Ali ni to Naomí?«
20 Naomi sì dáhùn wí pé, “Ẹ má ṣe pè mí ní Naomi mọ́, ẹ pè mí ní Mara, nítorí wí pé Olódùmarè ti mú kí ayé mi di kíkorò.
Odgovorila jim je: »Ne imenujte me Naomí, imenujte me Mara, kajti Vsemogočni je zelo grenko postopal z menoj.
21 Mo jáde ní kíkún, ṣùgbọ́n Olúwa mú mi padà ní òfo. Nítorí náà kín ló dé tí ẹ fi ń pè mí ní Naomi, nígbà tí Olódùmarè ti kọ̀ mí sílẹ̀, tí ó sì mú ìdààmú bá mi?”
Odšla sem polna, Gospod pa me je ponovno privedel domov prazno. Zakaj me torej imenujete Naomí, glede na to, da je Gospod pričeval zoper mene in me je Vsemogočni prizadel?«
22 Báyìí ni Naomi ṣe padà láti Moabu pẹ̀lú Rutu, ará Moabu ìyàwó ọmọ rẹ̀. Wọ́n gúnlẹ̀ sí Bẹtilẹhẹmu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè ọkà barle.
Tako se je Naomí vrnila in z njo njena snaha Moábka Ruta, ki sta se vrnili iz moábske dežele. V Betlehem sta prišli ob začetku ječmenove žetve.

< Ruth 1 >