< Ruth 1 >

1 Ní ìgbà tí àwọn onídàájọ́ ń ṣe àkóso ilẹ̀ Israẹli, ìyàn kan mú ní ilẹ̀ náà, ọkùnrin kan láti Bẹtilẹhẹmu ti Juda, òun àti aya rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjì lọ láti máa gbé ní ilẹ̀ Moabu fún ìgbà díẹ̀.
Zdarzyło się, że w czasach, kiedy rządzili sędziowie, nastał głód na ziemi. I [pewien] człowiek z Betlejem judzkiego wyruszył wraz ze swoją żoną i dwoma synami, aby zamieszkać w ziemi Moabu.
2 Orúkọ ọkùnrin náà ń jẹ́ Elimeleki, orúkọ ìyàwó rẹ̀ ni Naomi, orúkọ àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì sì ni Maloni àti Kilioni àwọn ará Efrata, ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda. Wọ́n sì lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọ́n ń gbé níbẹ̀.
Ten człowiek [miał] na imię Elimelech, jego żona – Noemi, a jego dwaj synowie – Machlon i Kilion. [Byli oni] Efratejczykami z Betlejem judzkiego. Przybyli do ziemi Moabu i tam zamieszkali.
3 Ní àsìkò tí wọ́n ń gbé ibẹ̀, Elimeleki, ọkọ Naomi kú, ó sì ku òun pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì.
Potem umarł Elimelech, mąż Noemi, a ona pozostała sama z dwoma synami.
4 Wọ́n sì fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ará Moabu méjì, orúkọ ọ̀kan ń jẹ́ Oripa, èkejì sì ń jẹ́ Rutu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti gbé níbẹ̀ fún bí ọdún mẹ́wàá,
Ci pojęli sobie za żony Moabitki: jedna miała na imię Orfa, a druga – Rut. I mieszkali tam około dziesięciu lat.
5 Maloni àti Kilioni náà sì kú, Naomi sì wà láìsí ọkọ tàbí ọmọ kankan fún un mọ́.
Potem obaj, Machlon i Kilion, również umarli; i tak kobieta ta pozostała sama bez swoich dwóch synów i bez męża.
6 Nígbà tí Naomi gbọ́ ní Moabu tí ó wà wí pé Olúwa ti bẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ wò nípa fífún wọn ní ọ̀pọ̀ oúnjẹ. Ó sì dìde pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì láti padà sí ìlú rẹ̀.
Wtedy powstała wraz ze swoimi synowymi, aby wrócić z ziemi Moabu, gdyż usłyszała w ziemi Moabu, że PAN nawiedził swój lud i dał mu chleb.
7 Òun pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì ni wọ́n jọ fi ibi tí ó ń gbé sílẹ̀ tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà sí ilẹ̀ Juda.
Wyszła więc z miejsca, w którym była, a wraz z nią jej dwie synowe i udały się w drogę powrotną do ziemi Judy.
8 Ṣùgbọ́n ní ojú ọ̀nà, Naomi wí fún àwọn aya ọmọ rẹ̀ méjèèjì pé, “Kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín padà sí ilé ìyá rẹ̀. Kí Olúwa ṣe àánú fún yín bí ẹ ti ṣe sí èmi àti àwọn ọkọ yín tí ó kú.
I powiedziała Noemi do swych dwóch synowych: Idźcie, niech każda z was powróci do domu swojej matki. Niech PAN okaże wam miłosierdzie, tak jak okazałyście [je] zmarłym i mnie.
9 Kí Olúwa kí ó fi yín lọ́kàn balẹ̀ ní ilé ọkọ mìíràn.” Naomi sì fi ẹnu kò wọ́n ní ẹnu wí pé “Ó dìgbà,” wọ́n sì sọkún kíkankíkan.
Niech PAN sprawi, aby każda z was znalazła pokój w domu swego męża. I pocałowała je, a one podniosły głosy i zapłakały.
10 Wọ́n sì wí fún un pé, “Rárá, a ó bà ọ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.”
I mówiły do niej: Wrócimy raczej z tobą do twego ludu.
11 Ṣùgbọ́n Naomi dáhùn wí pé, “Ẹ padà sílé ẹ̀yin ọmọ mi. Nítorí kí ni ẹ fi fẹ́ wá pẹ̀lú mi? Ṣé mo tún le bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn ni, tí ó le ṣe ọkọ yin?
Lecz Noemi odpowiedziała: Zawróćcie, moje córki. Czemu chcecie iść ze mną? Czy mam jeszcze w swoim łonie synów, którzy zostaliby waszymi mężami?
12 Ẹ padà sílé, ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí èmi ti di arúgbó jù láti ní ọkọ mìíràn. Bí èmí wí pé, èmí ní ìrètí, bí èmí tilẹ̀ ní ọkọ mìíràn ní alẹ́ yìí, tí èmí sì bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn,
Zawróćcie, moje córki, idźcie, bo jestem zbyt stara, aby wyjść za mąż. A nawet gdybym powiedziała: mam jeszcze nadzieję, to choćbym tej nocy wyszła za mąż i również urodziła synów;
13 ẹ̀yin ha le è dúró dìgbà tí wọ́n yóò fi dàgbà? Ẹ̀yin ó le è dúró dè wọ́n láì fẹ́ ọkọ mìíràn? Rárá, ẹ̀yin ọmọbìnrin mi, nítorí pé inú mi bàjẹ́ gidigidi ju tiyín lọ, nítorí tí ọwọ́ Olúwa fi jáde sí mi!”
Czy czekałybyście na nich, aż dorosną? Czy ze względu na nich pozostałybyście bez męża? Nie, moje córki. Odczuwam bowiem wielką gorycz ze względu na was, gdyż ręka PANA obróciła się przeciwko mnie.
14 Wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì tún sọkún. Nígbà náà ní Oripa fi ẹnu ko ìyá ọkọ rẹ̀ ní ẹnu wí pé ó dìgbà, ṣùgbọ́n Rutu dì mọ́ ọn síbẹ̀.
A [one] znowu podniosły głosy i zaczęły płakać. I Orfa pocałowała swoją teściową, ale Rut pozostała przy niej.
15 Naomi wí pé, “Wò ó, arábìnrin rẹ ti padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀ àti òrìṣà rẹ̀, ìwọ náà padà pẹ̀lú rẹ̀.”
Wtedy [Noemi] powiedziała do niej: Oto twoja szwagierka wróciła do swego ludu i do swoich bogów. Wróć [także] ty za swoją szwagierką.
16 Ṣùgbọ́n Rutu dáhùn wí pé, “Má ṣe rọ̀ mí láti fi ọ́ sílẹ̀ tàbí láti padà lẹ́yìn rẹ. Ibi tí ìwọ bá lọ ní èmi yóò lọ, ibi ti ìwọ bá dúró ni èmi yóò dúró, àwọn ènìyàn rẹ ni yóò jẹ́ ènìyàn mi, Ọlọ́run rẹ ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run mi.
Rut jednak odpowiedziała: Nie nalegaj na mnie, abym cię opuściła i odeszła od ciebie. Gdziekolwiek bowiem pójdziesz i ja pójdę, a gdziekolwiek zamieszkasz i ja zamieszkam. Twój lud będzie moim ludem, a twój Bóg będzie moim Bogiem.
17 Níbi tí ìwọ bá kú sí ni èmi yóò kú sí, níbẹ̀ ni wọn yóò sì sin mí sí. Kí Olúwa jẹ mí ní ìyà tí ó lágbára, bí ohunkóhun bí kò ṣe ikú bá yà wá.”
Gdzie ty umrzesz, [tam i] ja umrę, i tam będę pogrzebana. Niech mi to PAN uczyni i niech do tego dorzuci, jeśli coś innego niż śmierć oddzieli mnie od ciebie.
18 Nígbà tí Naomi rí i wí pé Rutu ti pinnu láti tẹ̀lé òun kò rọ̀ láti padà mọ́.
A gdy [Noemi] widziała, że uparła się, aby z nią iść, przestała jej odradzać.
19 Àwọn méjèèjì sì ń lọ títí wọ́n fi dé ìlú Bẹtilẹhẹmu. Nígbà tí wọ́n dé ibẹ̀, ariwo ìpadàbọ̀ wọn gba ìlú kan, àwọn obìnrin ibẹ̀ sì kígbe ní ohùn rara wí pé, “Naomi ni èyí bí?”
I szły obie razem, aż przyszły do Betlejem. A gdy przybyły do Betlejem, całe miasto ogarnęło poruszenie z ich powodu i mówiono: Czy to jest Noemi?
20 Naomi sì dáhùn wí pé, “Ẹ má ṣe pè mí ní Naomi mọ́, ẹ pè mí ní Mara, nítorí wí pé Olódùmarè ti mú kí ayé mi di kíkorò.
Lecz ona powiedziała do nich: Nie nazywajcie mnie Noemi, lecz nazywajcie mnie Mara, ponieważ Wszechmogący napełnił mnie wielką goryczą.
21 Mo jáde ní kíkún, ṣùgbọ́n Olúwa mú mi padà ní òfo. Nítorí náà kín ló dé tí ẹ fi ń pè mí ní Naomi, nígbà tí Olódùmarè ti kọ̀ mí sílẹ̀, tí ó sì mú ìdààmú bá mi?”
Wyszłam [stąd] pełna, a PAN sprowadził mnie pustą. Czemu nazywacie mnie Noemi, skoro PAN wystąpił przeciwko mnie i Wszechmogący sprowadził na mnie nieszczęście?
22 Báyìí ni Naomi ṣe padà láti Moabu pẹ̀lú Rutu, ará Moabu ìyàwó ọmọ rẹ̀. Wọ́n gúnlẹ̀ sí Bẹtilẹhẹmu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè ọkà barle.
Wróciła więc Noemi, a z nią Rut Moabitka, jej synowa, która wróciła z krainy Moabu. A przyszły do Betlejem na początku żniw jęczmienia.

< Ruth 1 >