< Ruth 4 >

1 Nígbà náà ni Boasi gòkè lọ sí ẹnu ibodè ìlú, ó sì jókòó síbẹ̀. Nígbà tí ìbátan tí ó súnmọ́ Elimeleki jùlọ, arákùnrin tí Boasi ti sọ̀rọ̀ rẹ̀ ń kọjá, Boasi pè é wí pé, “Máa bọ̀ wá síbí ìwọ ọ̀rẹ́ mi, kí o sì jókòó.” Ó sì lọ jókòó.
Boaz xǝⱨǝr dǝrwazisiƣa qiⱪip, xu yǝrdǝ olturdi. Mana, u waⱪitta Boaz eytⱪan ⱨeliⱪi ⱨǝmjǝmǝtlik ⱨoⱪuⱪiƣa igǝ kixi keliwatatti. Boaz uningƣa: — Əy buradǝr, kelip bu yǝrdǝ olturƣin, dewidi, u kelip olturdi.
2 Boasi sì pe mẹ́wàá nínú àwọn àgbàgbà ìlú, wí pé ki wọn jókòó, wọn sí ṣe bẹ́ẹ̀,
Andin Boaz xǝⱨǝrning aⱪsaⱪalliridin on adǝmni qaⱪirip, ularƣimu: — Bu yǝrdǝ olturunglar, dedi. Ular olturƣanda
3 ó sì sọ fún ìbátan rẹ̀ náà pé, “Arábìnrin Naomi tí ó dé láti ilẹ̀ Moabu fẹ́ ta ilẹ̀, èyí tí ó ṣe ti arákùnrin Elimeleki wa.
u ⱨǝmjǝmǝtlik ⱨoⱪuⱪiƣa igǝ kixigǝ: — Moabning sǝⱨrasidin yenip kǝlgǝn Naomi ⱪerindiximiz Əlimǝlǝkkǝ tǝwǝ xu zeminni satmaⱪqi boluwatidu.
4 Mó sì rò wí pé ó yẹ kí n mú ọ̀rọ̀ náà wá sí etí ìgbọ́ rẹ, wí pé kí o rà á ní iwájú gbogbo àwọn tí ó jókòó sí ibi yìí. Bí ìwọ yóò bá rà á padà rà á. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ní rà á padà, sọ fún mi, kí èmi ó le è mọ̀. Nítorí pé kò sí ẹlòmíràn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti rà á ju ìwọ lọ, èmi sì ni ẹni tí ó tún kàn lẹ́yìn rẹ̀.” Ọkùnrin náà sì sọ wí pé, “Èmi yóò rà á padà.”
Xunga mǝn muxu ixni sanga hǝwǝrlǝndürmǝkqi idim, xundaⱪla muxu yǝrdǝ olturƣanlarning aldida wǝ hǝlⱪimning aⱪsaⱪallirining aldida «Buni setiwalƣin» demǝkqimǝn. Sǝn ǝgǝr ⱨǝmjǝmǝtlik ⱨoⱪuⱪiƣa asasǝn alay desǝng, alƣin; ⱨǝmjǝmǝtlik ⱪilmay, almaymǝn desǝng, manga eytⱪin, mǝn buni bilǝy; qünki sǝndin [awwal] baxⱪisining ⱨǝmjǝmǝtlik ⱨoⱪuⱪi bolmaydu; andin sǝndin keyin mening ⱨoⱪuⱪum bar, dedi. U kixi: — Ⱨǝmjǝmǝtlik ⱪilip uni alimǝn, dedi.
5 Nígbà náà ni Boasi sọ wí pé, “Bí ìwọ bá ti ra ilẹ̀ náà lọ́wọ́ Naomi àti lọ́wọ́ Rutu ará Moabu, ìwọ gbọdọ̀ fẹ́ opó ọkùnrin náà, kí orúkọ ọkùnrin tí ó kú náà má ba à parẹ́ pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀ àti kí o le è bímọ ní orúkọ rẹ̀.”
Boaz uningƣa: — Undaⱪta yǝrni Naomining ⱪolidin alƣan künidǝ mǝrⱨumning mirasiƣa uning nami bilǝn atalƣan birǝr ǝwladi ⱪalduruluxi üqün mǝrⱨumning ayali, Moab ⱪizi Rutnimu elixing kerǝk, — dedi.
6 Nígbà náà ni ọkùnrin náà dáhùn sí èyí pé, “Nípa ti èyí, èmi kò le è rà á padà, nítorí pé, ọmọ rẹ̀, ọkùnrin yóò wá jẹ́ ajogún àwọn ohun ìní mi pẹ̀lú. Rà á fún ara rẹ, èmi kò le ṣe é.”
Ⱨǝmjǝmǝt kixi: — Undaⱪ bolsa ⱨǝmjǝmǝtlik ⱨoⱪuⱪumni ixlitip [etizni] alsam bolmiƣudǝk; alsam ɵz mirasimƣa ziyan yǝtküzgüdǝkmǝn. Ⱨǝmjǝmǝtlik ⱨoⱪuⱪini sǝn ɵzüng ixlitip, yǝrni setiwalƣin; mǝn ixlitǝlmǝymǝn, dedi.
7 Ní ayé ìgbàanì, kí a tó le sọ wí pé ohun ìràpadà tàbí pàṣípàrọ̀ ohun ìní fi ìdí múlẹ̀ ní ilẹ̀ Israẹli, ẹnìkan ni láti yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀ kí ó sì fi fún ẹnìkejì, ó jẹ́ òfin fún ẹni tí ó fẹ́ rà á. Nípa ṣíṣe èyí, àwọn ará Israẹli fihàn wí pé ọ̀rọ̀ náà ti fìdímúlẹ̀.
Ⱪǝdimki waⱪitlarda Israilda ⱨǝmjǝmǝtlik ⱨoⱪuⱪiƣa yaki almaxturux-tegixix ixiƣa munasiwǝtlik mundaⱪ bir rǝsim-ⱪaidǝ bar idi: — ixni kǝsmǝk üqün bir tǝrǝp ɵz kǝxini selip, ikkinqi tǝrǝpkǝ berǝtti. Israilda soda-setiⱪni bekitixtǝ mana muxundaⱪ bir usul bar idi.
8 Nítorí náà, nígbà tí ọkùnrin náà sọ fún Boasi wí pé, “Ìwọ rà á fúnra rẹ̀,” ó yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
Xunga ⱨǝmjǝmǝt ⱨoⱪuⱪiƣa igǝ kixi Boazƣa: — Sǝn uni alƣin, dǝp, ɵz kǝxini seliwǝtti.
9 Nígbà náà ni Boasi wí fún àwọn àgbàgbà àti àwọn mìíràn tí ó wà ní ibẹ̀ pé, “Gbogbo yín jẹ́ ẹlẹ́rìí mi ní òní wí pé mo ti ra ohun gbogbo tí í ṣe ti Elimeleki àti àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì: Maloni àti Kilioni lọ́wọ́ Naomi.
Boaz aⱪsaⱪallarƣa wǝ kɵpqilikkǝ: — Silǝr bügün mening Əlimǝlǝk kǝ tǝwǝ bolƣan ⱨǝmmini, xundaⱪla Kilyon bilǝn Maⱨlonƣa tǝwǝ bolƣan ⱨǝmmini Naomining ⱪolidin alƣinimƣa guwaⱨtursilǝr.
10 Ní àfikún, mo ra Rutu ará Moabu opó Maloni padà láti di aya mi. Èyí tí yóò mú kí orúkọ ọkùnrin òkú náà wà pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, kí ìran rẹ̀ má ba à lè parẹ́ láàrín àwọn ẹbí rẹ̀ àti ìlú rẹ̀. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ní òní.”
Uning üstigǝ mǝrⱨumning nami ⱪerindaxliri arisidin wǝ xǝⱨirining dǝrwazisidin ɵqürülmǝsliki üqün mǝrⱨumning mirasiƣa uning nami bolƣan [birǝr ǝwladi] ⱪaldurulsun üqün Maⱨlonning ayali, Moab ⱪizi Rutni hotunluⱪⱪa aldim. Silǝr bügün buningƣa guwaⱨtursilǝr, dedi.
11 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí, kí Olúwa jẹ́ kí obìnrin tí ó ń bọ̀ wá sí inú ilẹ̀ rẹ dàbí Rakeli àti Lea láti ara àwọn ẹni tí gbogbo ìdílé Israẹli ti jáde wá. Kí ìwọ sì di ọlọ́rọ̀ ní ìran Efrata àti olókìkí ní ìlú Bẹtilẹhẹmu.
Dǝrwazida turƣan ⱨǝmmǝ hǝlⱪ bilǝn aⱪsaⱪallar: — Biz guwaⱨturmiz. Pǝrwǝrdigar sening ɵyünggǝ kirgǝn ayalni Israilning jǝmǝtini bǝrpa ⱪilƣan Raⱨilǝ bilǝn Leyaⱨ ikkisidǝk ⱪilƣay; sǝn ɵzüng Əfrataⱨ jǝmǝti iqidǝ bayaxat bolup, Bǝyt-Lǝⱨǝmdǝ nam-izziting ziyadǝ bolƣay;
12 Kí Olúwa fún ọ ní ọmọ tí yóò mú ìdílé rẹ dàbí ti Peresi ọmọkùnrin tí Tamari bí fún Juda láti ipasẹ̀ ọ̀dọ́mọbìnrin yìí.”
Pǝrwǝrdigar sanga bu yax qokandin tapⱪuzidiƣan nǝsling tüpǝylidin sening jǝmǝting Tamar Yǝⱨudaƣa tuƣup bǝrgǝn Pǝrǝzning jǝmǝtidǝk bolƣay! — dedi.
13 Báyìí ni Boasi ṣe mú Rutu, tí ó sì di aya rẹ̀. Nígbà náà ni ó wọlé tọ aya rẹ̀, Olúwa sì mú kí ó lóyún, ó sì bí ọmọ ọkùnrin kan.
Andin Boaz Rutni ǝmrigǝ elip, uningƣa yeⱪinliⱪ ⱪildi. Pǝrwǝrdigar uningƣa xapaǝt ⱪilip, u ⱨamilidar bolup bir oƣul tuƣdi.
14 Àwọn obìnrin sì wí fún Naomi pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí kò fi ọ sílẹ̀ ní òní yìí láìní ìbátan, Olùràpadà. Kí ọmọ náà di olókìkí ní Israẹli.
Ⱪiz-ayallar Naomiƣa: — Israilning arisida sanga ⱨǝmjǝmǝt-nijatkar nǝslini üzüp ⱪoymiƣan Pǝrwǝrdigarƣa tǝxǝkkür-mǝdⱨiyǝ ⱪayturulsun! Xu nǝslingning nami Israilda izzǝt-abruyluⱪ bolƣay!
15 Yóò tún ayé rẹ ṣe, yóò sì dáàbò bò ọ́ ní ọjọ́ ogbó rẹ. Nítorí pé ìyàwó ọmọ rẹ, èyí tí ó sàn fún ọ ju ọmọkùnrin méje lọ, tí ó sì fẹ́ràn rẹ ni ó bí ọmọ yìí fún.”
U sanga jeningni yengiliƣuqi ⱨǝm ⱪeriƣiningda seni ǝzizliƣuqi bolidu; qünki seni sɵyidiƣan, sanga yǝttǝ oƣuldin ǝwzǝl bolƣan kelining uni tuƣdi, — dedi.
16 Naomi sì gbé ọmọ náà lé orí ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì ń tọ́jú rẹ̀.
Naomi balini elip, baƣriƣa basti wǝ uningƣa baⱪⱪuqi ana boldi.
17 Àwọn obìnrin àdúgbò sì wí pé, “A bí ọmọkùnrin kan fún Naomi.” Wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Obedi. Òun sì ni baba Jese tí í ṣe baba Dafidi.
Uningƣa ⱪoxna bolƣan ayallar «Naomiƣa bir bala tuƣuldi» dǝp, uningƣa isim ⱪoydi. Ular uningƣa «Obǝd» dǝp at ⱪoydi. U Yǝssǝning atisi boldi, Yǝssǝ Dawutning atisi boldi.
18 Èyí ni ìran Peresi: Peresi ni baba Hesroni,
Pǝrǝzning nǝsǝbnamisi tɵwǝndikidǝktur: — Pǝrǝzdin Ⱨǝzron tɵrǝldi,
19 Hesroni ni baba Ramu, Ramu ni baba Amminadabu
Ⱨǝzrondin Ram tɵrǝldi, Ramdin Amminadab tɵrǝldi,
20 Amminadabu ni baba Nahiṣoni, Nahiṣoni ni baba Salmoni,
Amminadabtin Naⱨxon tɵrǝldi, Naⱨxondin Salmon tɵrǝldi,
21 Salmoni ni baba Boasi, Boasi ni baba Obedi,
Salmondin Boaz tɵrǝldi, Boazdin Obǝd tɵrǝldi,
22 Obedi ní baba Jese, Jese ni baba Dafidi.
Obǝdtin Yǝssǝ tɵrǝldi wǝ Yǝssǝdin Dawut tɵrǝldi.

< Ruth 4 >