< Ruth 4 >

1 Nígbà náà ni Boasi gòkè lọ sí ẹnu ibodè ìlú, ó sì jókòó síbẹ̀. Nígbà tí ìbátan tí ó súnmọ́ Elimeleki jùlọ, arákùnrin tí Boasi ti sọ̀rọ̀ rẹ̀ ń kọjá, Boasi pè é wí pé, “Máa bọ̀ wá síbí ìwọ ọ̀rẹ́ mi, kí o sì jókòó.” Ó sì lọ jókòó.
Potem je Boaz odšel k velikim vratom in se tam usedel in glej, sorodnik, o katerem je Boaz govoril, je prišel mimo, kateremu je rekel: »Hej, ti oné! Kreni sem in sedi tukaj.« In ta je krenil tja ter se usedel.
2 Boasi sì pe mẹ́wàá nínú àwọn àgbàgbà ìlú, wí pé ki wọn jókòó, wọn sí ṣe bẹ́ẹ̀,
Vzel je deset mož izmed starešin mesta ter rekel: »Sedite tukaj.« In oni so se usedli.
3 ó sì sọ fún ìbátan rẹ̀ náà pé, “Arábìnrin Naomi tí ó dé láti ilẹ̀ Moabu fẹ́ ta ilẹ̀, èyí tí ó ṣe ti arákùnrin Elimeleki wa.
Sorodniku je rekel: »Naomí, ki je ponovno prišla iz moábske dežele, prodaja posest dežele, ki je bila od najinega brata Eliméleha
4 Mó sì rò wí pé ó yẹ kí n mú ọ̀rọ̀ náà wá sí etí ìgbọ́ rẹ, wí pé kí o rà á ní iwájú gbogbo àwọn tí ó jókòó sí ibi yìí. Bí ìwọ yóò bá rà á padà rà á. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ní rà á padà, sọ fún mi, kí èmi ó le è mọ̀. Nítorí pé kò sí ẹlòmíràn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti rà á ju ìwọ lọ, èmi sì ni ẹni tí ó tún kàn lẹ́yìn rẹ̀.” Ọkùnrin náà sì sọ wí pé, “Èmi yóò rà á padà.”
in mislil sem, da ti oznanim, rekoč: ›Kupi to pred prebivalci in pred starešinami mojega ljudstva. Če hočeš to odkupiti, to odkupi, toda če ti tega nočeš odkupiti, potem mi povej, da bom lahko vedel, kajti poleg tebe ni nikogar, da to odkupi, jaz pa sem za teboj.‹« In ta je rekel: » To bom odkupil.«
5 Nígbà náà ni Boasi sọ wí pé, “Bí ìwọ bá ti ra ilẹ̀ náà lọ́wọ́ Naomi àti lọ́wọ́ Rutu ará Moabu, ìwọ gbọdọ̀ fẹ́ opó ọkùnrin náà, kí orúkọ ọkùnrin tí ó kú náà má ba à parẹ́ pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀ àti kí o le è bímọ ní orúkọ rẹ̀.”
Potem je Boaz rekel: »Tisti dan, ko kupiš polje iz Naomíne roke, moraš to kupiti tudi od Moábke Rute, žene umrlega, da obudiš ime mrtvega na njegovi dediščini.«
6 Nígbà náà ni ọkùnrin náà dáhùn sí èyí pé, “Nípa ti èyí, èmi kò le è rà á padà, nítorí pé, ọmọ rẹ̀, ọkùnrin yóò wá jẹ́ ajogún àwọn ohun ìní mi pẹ̀lú. Rà á fún ara rẹ, èmi kò le ṣe é.”
Sorodnik je rekel: » Tega ne morem odkupiti zase, da ne bi oškodoval svoje lastne dediščine. Ti odkupi mojo pravico k sebi, kajti jaz tega ne morem odkupiti.«
7 Ní ayé ìgbàanì, kí a tó le sọ wí pé ohun ìràpadà tàbí pàṣípàrọ̀ ohun ìní fi ìdí múlẹ̀ ní ilẹ̀ Israẹli, ẹnìkan ni láti yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀ kí ó sì fi fún ẹnìkejì, ó jẹ́ òfin fún ẹni tí ó fẹ́ rà á. Nípa ṣíṣe èyí, àwọn ará Israẹli fihàn wí pé ọ̀rọ̀ náà ti fìdímúlẹ̀.
Torej to je bil običaj v prejšnjem času v Izraelu, glede odkupitve in glede zamenjave, za potrditev vseh stvari. Človek je sezul svoj čevelj in tega dal svojemu bližnjemu in to je bilo pričevanje v Izraelu.
8 Nítorí náà, nígbà tí ọkùnrin náà sọ fún Boasi wí pé, “Ìwọ rà á fúnra rẹ̀,” ó yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
Zato je sorodnik Boazu rekel: » To si kupi zase.« Tako je sezul svoj čevelj.
9 Nígbà náà ni Boasi wí fún àwọn àgbàgbà àti àwọn mìíràn tí ó wà ní ibẹ̀ pé, “Gbogbo yín jẹ́ ẹlẹ́rìí mi ní òní wí pé mo ti ra ohun gbogbo tí í ṣe ti Elimeleki àti àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì: Maloni àti Kilioni lọ́wọ́ Naomi.
Boaz je rekel starešinam in vsemu ljudstvu: »Vi ste priče ta dan, da sem kupil vse, kar je bilo Elimélehovo in vse, kar je bilo Mahlónovo in Kiljónovo iz Naomíne roke.
10 Ní àfikún, mo ra Rutu ará Moabu opó Maloni padà láti di aya mi. Èyí tí yóò mú kí orúkọ ọkùnrin òkú náà wà pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, kí ìran rẹ̀ má ba à lè parẹ́ láàrín àwọn ẹbí rẹ̀ àti ìlú rẹ̀. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ní òní.”
Poleg tega sem kupil Moábko Ruto, Mahlónovo ženo, da postane moja žena, da obudim ime mrtvega na njegovi dediščini, da ime mrtvega ne bo iztrebljeno izmed njegovih bratov in od velikih vrat tega kraja. Vi ste priče ta dan.«
11 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí, kí Olúwa jẹ́ kí obìnrin tí ó ń bọ̀ wá sí inú ilẹ̀ rẹ dàbí Rakeli àti Lea láti ara àwọn ẹni tí gbogbo ìdílé Israẹli ti jáde wá. Kí ìwọ sì di ọlọ́rọ̀ ní ìran Efrata àti olókìkí ní ìlú Bẹtilẹhẹmu.
Vse ljudstvo, ki je bilo v velikih vratih, in starešine, so rekli: » Mi smo priče. Gospod naj naredi žensko, ki je prišla v tvojo hišo, kakor Rahelo in kakor Lejo, ki sta zgradili Izraelovo hišo. Ti pa delaj plemenito v Efráti in bodi slaven v Betlehemu.
12 Kí Olúwa fún ọ ní ọmọ tí yóò mú ìdílé rẹ dàbí ti Peresi ọmọkùnrin tí Tamari bí fún Juda láti ipasẹ̀ ọ̀dọ́mọbìnrin yìí.”
Tvoja hiša naj bo podobna Parecovi hiši, katerega je Tamara rodila Judu, od semena, ki ti ga bo Gospod dal od te mlade ženske.«
13 Báyìí ni Boasi ṣe mú Rutu, tí ó sì di aya rẹ̀. Nígbà náà ni ó wọlé tọ aya rẹ̀, Olúwa sì mú kí ó lóyún, ó sì bí ọmọ ọkùnrin kan.
Tako je Boaz vzel Ruto in bila je njegova žena in ko je šel noter k njej, ji je Gospod dal spočetje in rodila je sina.
14 Àwọn obìnrin sì wí fún Naomi pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí kò fi ọ sílẹ̀ ní òní yìí láìní ìbátan, Olùràpadà. Kí ọmọ náà di olókìkí ní Israẹli.
Ženske so rekle Naomí: »Blagoslovljen bodi Gospod, ki te ta dan ni pustil brez sorodnika, da bo njegovo ime lahko slavno v Izraelu.
15 Yóò tún ayé rẹ ṣe, yóò sì dáàbò bò ọ́ ní ọjọ́ ogbó rẹ. Nítorí pé ìyàwó ọmọ rẹ, èyí tí ó sàn fún ọ ju ọmọkùnrin méje lọ, tí ó sì fẹ́ràn rẹ ni ó bí ọmọ yìí fún.”
On ti bo obnovitelj tvojega življenja in hranitelj tvoje starosti, kajti rodila ga je tvoja snaha, ki te ima rada, ki ti je boljša kakor sedem sinov.«
16 Naomi sì gbé ọmọ náà lé orí ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì ń tọ́jú rẹ̀.
Naomí je vzela otroka in ga položila v svoje naročje in mu postala pestunja.
17 Àwọn obìnrin àdúgbò sì wí pé, “A bí ọmọkùnrin kan fún Naomi.” Wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Obedi. Òun sì ni baba Jese tí í ṣe baba Dafidi.
Ženske, njene sosede, so mu dale ime, rekoč: »Naomí je rojen sin« in njegovo ime so imenovale Obéd. On je oče Davidovega očeta Jeseja.
18 Èyí ni ìran Peresi: Peresi ni baba Hesroni,
Torej to so Parecovi rodovi: Parec je zaplodil Hecróna,
19 Hesroni ni baba Ramu, Ramu ni baba Amminadabu
Hecrón je zaplodil Rama, Ram je zaplodil Aminadába,
20 Amminadabu ni baba Nahiṣoni, Nahiṣoni ni baba Salmoni,
Aminadáb je zaplodil Nahšóna, Nahšón je zaplodil Salmóna,
21 Salmoni ni baba Boasi, Boasi ni baba Obedi,
Salmón je zaplodil Boaza, Boaz je zaplodil Obéda,
22 Obedi ní baba Jese, Jese ni baba Dafidi.
Obéd je zaplodil Jeseja in Jese je zaplodil Davida.

< Ruth 4 >