< Ruth 4 >

1 Nígbà náà ni Boasi gòkè lọ sí ẹnu ibodè ìlú, ó sì jókòó síbẹ̀. Nígbà tí ìbátan tí ó súnmọ́ Elimeleki jùlọ, arákùnrin tí Boasi ti sọ̀rọ̀ rẹ̀ ń kọjá, Boasi pè é wí pé, “Máa bọ̀ wá síbí ìwọ ọ̀rẹ́ mi, kí o sì jókòó.” Ó sì lọ jókòó.
Atunci Boaz a urcat la poartă şi s-a aşezat acolo; şi, iată, răscumpărătorul, de care vorbise Boaz, a trecut pe acolo; şi i-a spus: Tu, cutare, abate-te şi aşază-te aici. Şi s-a abătut şi s-a aşezat.
2 Boasi sì pe mẹ́wàá nínú àwọn àgbàgbà ìlú, wí pé ki wọn jókòó, wọn sí ṣe bẹ́ẹ̀,
Şi a luat zece bărbaţi dintre bătrânii cetăţii şi a spus: Aşezaţi-vă aici. Şi s-au aşezat.
3 ó sì sọ fún ìbátan rẹ̀ náà pé, “Arábìnrin Naomi tí ó dé láti ilẹ̀ Moabu fẹ́ ta ilẹ̀, èyí tí ó ṣe ti arákùnrin Elimeleki wa.
Şi i-a spus răscumpărătorului: Naomi, care a ieşit din ţara Moabului, vinde o parcelă de pământ, care a fost a fratelui nostru Elimelec.
4 Mó sì rò wí pé ó yẹ kí n mú ọ̀rọ̀ náà wá sí etí ìgbọ́ rẹ, wí pé kí o rà á ní iwájú gbogbo àwọn tí ó jókòó sí ibi yìí. Bí ìwọ yóò bá rà á padà rà á. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ní rà á padà, sọ fún mi, kí èmi ó le è mọ̀. Nítorí pé kò sí ẹlòmíràn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti rà á ju ìwọ lọ, èmi sì ni ẹni tí ó tún kàn lẹ́yìn rẹ̀.” Ọkùnrin náà sì sọ wí pé, “Èmi yóò rà á padà.”
Şi m-am gândit să te înştiinţez, spunând: Cumpăr-o înaintea locuitorilor de aici şi înaintea bătrânilor poporului meu. Dacă o răscumperi, răscumpăr-o; iar dacă nu o răscumperi, spune-mi ca să ştiu, fiindcă în afară de tine nu este altul care să o răscumpere şi după tine sunt eu. Iar el a spus: O voi răscumpăra.
5 Nígbà náà ni Boasi sọ wí pé, “Bí ìwọ bá ti ra ilẹ̀ náà lọ́wọ́ Naomi àti lọ́wọ́ Rutu ará Moabu, ìwọ gbọdọ̀ fẹ́ opó ọkùnrin náà, kí orúkọ ọkùnrin tí ó kú náà má ba à parẹ́ pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀ àti kí o le è bímọ ní orúkọ rẹ̀.”
Atunci Boaz a spus: În ziua în care cumperi câmpul din mâna lui Naomi, trebuie să îl cumperi de asemenea şi de la Rut moabita, soţia mortului, pentru a ridica numele mortului peste moştenirea lui.
6 Nígbà náà ni ọkùnrin náà dáhùn sí èyí pé, “Nípa ti èyí, èmi kò le è rà á padà, nítorí pé, ọmọ rẹ̀, ọkùnrin yóò wá jẹ́ ajogún àwọn ohun ìní mi pẹ̀lú. Rà á fún ara rẹ, èmi kò le ṣe é.”
Iar răscumpărătorul a spus: Nu îl pot răscumpăra pentru mine, ca nu cumva să stric moştenirea mea, răscumpără dreptul meu pentru tine, fiindcă eu nu îl pot răscumpăra.
7 Ní ayé ìgbàanì, kí a tó le sọ wí pé ohun ìràpadà tàbí pàṣípàrọ̀ ohun ìní fi ìdí múlẹ̀ ní ilẹ̀ Israẹli, ẹnìkan ni láti yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀ kí ó sì fi fún ẹnìkejì, ó jẹ́ òfin fún ẹni tí ó fẹ́ rà á. Nípa ṣíṣe èyí, àwọn ará Israẹli fihàn wí pé ọ̀rọ̀ náà ti fìdímúlẹ̀.
Acum, acesta era obiceiul în acel timp în Israel, referitor la răscumpărare şi schimb, pentru a confirma toate lucrurile: un bărbat îşi scotea sandala şi o dădea vecinului său şi aceasta era o mărturie în Israel.
8 Nítorí náà, nígbà tí ọkùnrin náà sọ fún Boasi wí pé, “Ìwọ rà á fúnra rẹ̀,” ó yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
De aceea răscumpărătorul i-a spus lui Boaz: Cumpără-l pentru tine. Astfel şi-a scos sandala.
9 Nígbà náà ni Boasi wí fún àwọn àgbàgbà àti àwọn mìíràn tí ó wà ní ibẹ̀ pé, “Gbogbo yín jẹ́ ẹlẹ́rìí mi ní òní wí pé mo ti ra ohun gbogbo tí í ṣe ti Elimeleki àti àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì: Maloni àti Kilioni lọ́wọ́ Naomi.
Şi Boaz a spus bătrânilor şi întregului popor: Voi sunteţi martori astăzi, că am cumpărat tot ce a fost a lui Elimelec şi tot ce a fost a lui Chilion şi a lui Mahlon, din mâna lui Naomi.
10 Ní àfikún, mo ra Rutu ará Moabu opó Maloni padà láti di aya mi. Èyí tí yóò mú kí orúkọ ọkùnrin òkú náà wà pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, kí ìran rẹ̀ má ba à lè parẹ́ láàrín àwọn ẹbí rẹ̀ àti ìlú rẹ̀. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ní òní.”
Mai mult, pe Rut moabita, soţia lui Mahlon, am cumpărat-o să fie soţia mea, pentru a ridica numele mortului peste moştenirea lui, pentru ca numele mortului să nu fie stârpit dintre fraţii săi şi de la poarta locului său; voi sunteţi martori astăzi.
11 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí, kí Olúwa jẹ́ kí obìnrin tí ó ń bọ̀ wá sí inú ilẹ̀ rẹ dàbí Rakeli àti Lea láti ara àwọn ẹni tí gbogbo ìdílé Israẹli ti jáde wá. Kí ìwọ sì di ọlọ́rọ̀ ní ìran Efrata àti olókìkí ní ìlú Bẹtilẹhẹmu.
Şi toţi oamenii care au fost la poartă, şi bătrânii, au spus: Suntem martori. DOMNUL să facă pe femeia care a intrat în casa ta, ca pe Rahela şi ca pe Leea, care au ridicat, amândouă, casa lui Israel, şi fă ce este demn în Efrata şi fii faimos în Betleem;
12 Kí Olúwa fún ọ ní ọmọ tí yóò mú ìdílé rẹ dàbí ti Peresi ọmọkùnrin tí Tamari bí fún Juda láti ipasẹ̀ ọ̀dọ́mọbìnrin yìí.”
Şi să fie casa ta ca şi casa lui Farez, pe care l-a născut Tamar lui Iuda, din sămânţa pe care DOMNUL ţi-o va da din această tânără.
13 Báyìí ni Boasi ṣe mú Rutu, tí ó sì di aya rẹ̀. Nígbà náà ni ó wọlé tọ aya rẹ̀, Olúwa sì mú kí ó lóyún, ó sì bí ọmọ ọkùnrin kan.
Astfel că Boaz a luat-o pe Rut, şi ea a fost soţia lui; şi când a intrat la ea, DOMNUL i-a dat să rămână însărcinată şi a născut un fiu.
14 Àwọn obìnrin sì wí fún Naomi pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí kò fi ọ sílẹ̀ ní òní yìí láìní ìbátan, Olùràpadà. Kí ọmọ náà di olókìkí ní Israẹli.
Şi femeile i-au spus lui Naomi: Binecuvântat fie DOMNUL, care nu te-a lăsat astăzi fără un răscumpărător, ca numele lui să fie faimos în Israel.
15 Yóò tún ayé rẹ ṣe, yóò sì dáàbò bò ọ́ ní ọjọ́ ogbó rẹ. Nítorí pé ìyàwó ọmọ rẹ, èyí tí ó sàn fún ọ ju ọmọkùnrin méje lọ, tí ó sì fẹ́ràn rẹ ni ó bí ọmọ yìí fún.”
Şi el îţi va fi un restaurator al vieţii tale şi un îngrijitor al bătrâneţii tale; fiindcă nora ta, care te iubeşte, care îţi este mai bună decât şapte fii, l-a născut.
16 Naomi sì gbé ọmọ náà lé orí ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì ń tọ́jú rẹ̀.
Şi Naomi a luat copilul şi l-a aşezat pe sânul ei şi i-a devenit dădacă.
17 Àwọn obìnrin àdúgbò sì wí pé, “A bí ọmọkùnrin kan fún Naomi.” Wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Obedi. Òun sì ni baba Jese tí í ṣe baba Dafidi.
Şi vecinele ei, i-au dat nume, spunând: Un fiu i s-a născut lui Naomi şi i-au pus numele Obed, el este tatăl lui Isai, tatăl lui David.
18 Èyí ni ìran Peresi: Peresi ni baba Hesroni,
Acestea sunt acum generaţiile lui Farez: Farez a născut pe Heţron;
19 Hesroni ni baba Ramu, Ramu ni baba Amminadabu
Şi Heţron a născut pe Ram; şi Ram a născut pe Aminadab;
20 Amminadabu ni baba Nahiṣoni, Nahiṣoni ni baba Salmoni,
Şi Aminadab a născut pe Naşon; şi Naşon a născut pe Salmon;
21 Salmoni ni baba Boasi, Boasi ni baba Obedi,
Şi Salmon a născut pe Boaz; şi Boaz a născut pe Obed;
22 Obedi ní baba Jese, Jese ni baba Dafidi.
Şi Obed a născut pe Isai; şi Isai a născut pe David.

< Ruth 4 >