< Ruth 4 >

1 Nígbà náà ni Boasi gòkè lọ sí ẹnu ibodè ìlú, ó sì jókòó síbẹ̀. Nígbà tí ìbátan tí ó súnmọ́ Elimeleki jùlọ, arákùnrin tí Boasi ti sọ̀rọ̀ rẹ̀ ń kọjá, Boasi pè é wí pé, “Máa bọ̀ wá síbí ìwọ ọ̀rẹ́ mi, kí o sì jókòó.” Ó sì lọ jókòó.
و بوعز به دروازه آمده، آنجا نشست و اینک آن ولی که بوعز درباره او سخن گفته بود می‌گذشت، و به او گفت: «ای فلان! به اینجابرگشته، بنشین.» و او برگشته، نشست.۱
2 Boasi sì pe mẹ́wàá nínú àwọn àgbàgbà ìlú, wí pé ki wọn jókòó, wọn sí ṣe bẹ́ẹ̀,
و ده نفراز مشایخ شهر را برداشته، به ایشان گفت: «اینجابنشینید.» و ایشان نشستند.۲
3 ó sì sọ fún ìbátan rẹ̀ náà pé, “Arábìnrin Naomi tí ó dé láti ilẹ̀ Moabu fẹ́ ta ilẹ̀, èyí tí ó ṣe ti arákùnrin Elimeleki wa.
و به آن ولی گفت: «نعومی که از بلاد موآب برگشته است قطعه زمینی را که از برادر ما الیملک بود، می‌فروشد.۳
4 Mó sì rò wí pé ó yẹ kí n mú ọ̀rọ̀ náà wá sí etí ìgbọ́ rẹ, wí pé kí o rà á ní iwájú gbogbo àwọn tí ó jókòó sí ibi yìí. Bí ìwọ yóò bá rà á padà rà á. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ní rà á padà, sọ fún mi, kí èmi ó le è mọ̀. Nítorí pé kò sí ẹlòmíràn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti rà á ju ìwọ lọ, èmi sì ni ẹni tí ó tún kàn lẹ́yìn rẹ̀.” Ọkùnrin náà sì sọ wí pé, “Èmi yóò rà á padà.”
ومن مصلحت دیدم که تو را اطلاع داده، بگویم که آن را به حضور این مجلس و مشایخ قوم من بخر، پس اگر انفکاک می‌کنی، بکن، و اگر انفکاک نمی کنی مرا خبر بده تا بدانم، زیرا غیر از تو کسی نیست که انفکاک کند، و من بعد از تو هستم.» اوگفت: «من انفکاک می‌کنم.»۴
5 Nígbà náà ni Boasi sọ wí pé, “Bí ìwọ bá ti ra ilẹ̀ náà lọ́wọ́ Naomi àti lọ́wọ́ Rutu ará Moabu, ìwọ gbọdọ̀ fẹ́ opó ọkùnrin náà, kí orúkọ ọkùnrin tí ó kú náà má ba à parẹ́ pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀ àti kí o le è bímọ ní orúkọ rẹ̀.”
بوعز گفت: «درروزی که زمین را از دست نعومی می‌خری، ازروت موآبیه، زن متوفی نیز باید خرید، تا نام متوفی را بر میراثش برانگیزانی.»۵
6 Nígbà náà ni ọkùnrin náà dáhùn sí èyí pé, “Nípa ti èyí, èmi kò le è rà á padà, nítorí pé, ọmọ rẹ̀, ọkùnrin yóò wá jẹ́ ajogún àwọn ohun ìní mi pẹ̀lú. Rà á fún ara rẹ, èmi kò le ṣe é.”
آن ولی گفت: «نمی توانم برای خود انفکاک کنم مبادا میراث خود را فاسد کنم، پس تو حق انفکاک مرا بر ذمه خود بگیر زیرا نمی توانم انفکاک نمایم.»۶
7 Ní ayé ìgbàanì, kí a tó le sọ wí pé ohun ìràpadà tàbí pàṣípàrọ̀ ohun ìní fi ìdí múlẹ̀ ní ilẹ̀ Israẹli, ẹnìkan ni láti yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀ kí ó sì fi fún ẹnìkejì, ó jẹ́ òfin fún ẹni tí ó fẹ́ rà á. Nípa ṣíṣe èyí, àwọn ará Israẹli fihàn wí pé ọ̀rọ̀ náà ti fìdímúlẹ̀.
و رسم انفکاک و مبادلت در ایام قدیم دراسرائیل به جهت اثبات هر امر این بود که شخص کفش خود را بیرون کرده، به همسایه خود می‌داد. و این در اسرائیل قانون شده است.۷
8 Nítorí náà, nígbà tí ọkùnrin náà sọ fún Boasi wí pé, “Ìwọ rà á fúnra rẹ̀,” ó yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
پس آن ولی به بوعز گفت: «آن را برای خود بخر.» و کفش خود را بیرون کرد.۸
9 Nígbà náà ni Boasi wí fún àwọn àgbàgbà àti àwọn mìíràn tí ó wà ní ibẹ̀ pé, “Gbogbo yín jẹ́ ẹlẹ́rìí mi ní òní wí pé mo ti ra ohun gbogbo tí í ṣe ti Elimeleki àti àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì: Maloni àti Kilioni lọ́wọ́ Naomi.
و بوعز به مشایخ و به تمامی قوم گفت: «شما امروز شاهد باشید که تمامی مایملک الیملک و تمامی مایملک کلیون ومحلون را از دست نعومی خریدم.۹
10 Ní àfikún, mo ra Rutu ará Moabu opó Maloni padà láti di aya mi. Èyí tí yóò mú kí orúkọ ọkùnrin òkú náà wà pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, kí ìran rẹ̀ má ba à lè parẹ́ láàrín àwọn ẹbí rẹ̀ àti ìlú rẹ̀. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ní òní.”
و هم روت موآبیه زن محلون را به زنی خود خریدم تا نام متوفی را بر میراثش برانگیزانم، و نام متوفی ازمیان برادرانش و از دروازه محله‌اش منقطع نشود، شما امروز شاهد باشید.»۱۰
11 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí, kí Olúwa jẹ́ kí obìnrin tí ó ń bọ̀ wá sí inú ilẹ̀ rẹ dàbí Rakeli àti Lea láti ara àwọn ẹni tí gbogbo ìdílé Israẹli ti jáde wá. Kí ìwọ sì di ọlọ́rọ̀ ní ìran Efrata àti olókìkí ní ìlú Bẹtilẹhẹmu.
و تمامی قوم که نزد دروازه بودند و مشایخ گفتند: «شاهد هستیم و خداوند این زن را که به خانه تو درآمد، مثل راحیل و لیه گرداند که خانه اسرائیل را بنا کردند، و تو در افراته کامیاب شو، ودر بیت لحم نامور باش.۱۱
12 Kí Olúwa fún ọ ní ọmọ tí yóò mú ìdílé rẹ dàbí ti Peresi ọmọkùnrin tí Tamari bí fún Juda láti ipasẹ̀ ọ̀dọ́mọbìnrin yìí.”
و خانه تو مثل خانه فارص باشد که تامار برای یهودا زایید، ازاولادی که خداوند تو را از این دختر، خواهدبخشید.»۱۲
13 Báyìí ni Boasi ṣe mú Rutu, tí ó sì di aya rẹ̀. Nígbà náà ni ó wọlé tọ aya rẹ̀, Olúwa sì mú kí ó lóyún, ó sì bí ọmọ ọkùnrin kan.
پس بوعز روت را گرفت و او زن وی شد وبه او درآمد و خداوند او را حمل داد که پسری زایید.۱۳
14 Àwọn obìnrin sì wí fún Naomi pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí kò fi ọ sílẹ̀ ní òní yìí láìní ìbátan, Olùràpadà. Kí ọmọ náà di olókìkí ní Israẹli.
و زنان به نعومی گفتند: «متبارک بادخداوند که تو را امروز بی‌ولی نگذاشته است و نام او در اسرائیل بلند شود.۱۴
15 Yóò tún ayé rẹ ṣe, yóò sì dáàbò bò ọ́ ní ọjọ́ ogbó rẹ. Nítorí pé ìyàwó ọmọ rẹ, èyí tí ó sàn fún ọ ju ọmọkùnrin méje lọ, tí ó sì fẹ́ràn rẹ ni ó bí ọmọ yìí fún.”
و او برایت تازه کننده جان و پرورنده پیری تو باشد، زیرا که عروست که تو را دوست می‌دارد و برایت از هفت پسر بهتراست، او را زایید.»۱۵
16 Naomi sì gbé ọmọ náà lé orí ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì ń tọ́jú rẹ̀.
و نعومی پسر را گرفته، در آغوش خود گذاشت و دایه او شد.۱۶
17 Àwọn obìnrin àdúgbò sì wí pé, “A bí ọmọkùnrin kan fún Naomi.” Wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Obedi. Òun sì ni baba Jese tí í ṣe baba Dafidi.
و زنان همسایه‌اش، او را نام نهاده، گفتند برای نعومی پسری زاییده شد، و نام اورا عوبید خواندند و او پدر یسی پدر داوداست.۱۷
18 Èyí ni ìran Peresi: Peresi ni baba Hesroni,
این است پیدایش فارص: فارص حصرون را آورد؛۱۸
19 Hesroni ni baba Ramu, Ramu ni baba Amminadabu
و حصرون، رام را آورد؛ و رام، عمیناداب را آورد؛۱۹
20 Amminadabu ni baba Nahiṣoni, Nahiṣoni ni baba Salmoni,
و عمیناداب نحشون راآورد؛ و نحشون سلمون را آورد؛۲۰
21 Salmoni ni baba Boasi, Boasi ni baba Obedi,
و سلمون بوعز را آورد؛ و بوعز عوبید را آورد؛۲۱
22 Obedi ní baba Jese, Jese ni baba Dafidi.
و عوبیدیسی را آورد؛ و یسی داود را آورد.۲۲

< Ruth 4 >