< Ruth 4 >

1 Nígbà náà ni Boasi gòkè lọ sí ẹnu ibodè ìlú, ó sì jókòó síbẹ̀. Nígbà tí ìbátan tí ó súnmọ́ Elimeleki jùlọ, arákùnrin tí Boasi ti sọ̀rọ̀ rẹ̀ ń kọjá, Boasi pè é wí pé, “Máa bọ̀ wá síbí ìwọ ọ̀rẹ́ mi, kí o sì jókòó.” Ó sì lọ jókòó.
Boasi'a marerino ana kumate kasante umani'ne. Anante Boasi'a keana, Rutima asmino kva huntegahie hu'nea ne' egeno, anage hu'ne, Nenfuga amare enka emanio, higeno anante emani'ne.
2 Boasi sì pe mẹ́wàá nínú àwọn àgbàgbà ìlú, wí pé ki wọn jókòó, wọn sí ṣe bẹ́ẹ̀,
Ana hutegeno Boasi'a 10ni'a ranra kuma kva vahe, zamare atru huno anage hu'ne, amare emaniho hige'za zamagra emani'naze.
3 ó sì sọ fún ìbátan rẹ̀ náà pé, “Arábìnrin Naomi tí ó dé láti ilẹ̀ Moabu fẹ́ ta ilẹ̀, èyí tí ó ṣe ti arákùnrin Elimeleki wa.
Anante Boasi amanage huno ana nera asami'ne, Naomi'a Moabu mopareti e'neno, tagri vahe'mofo Elimeleki mopa mizante atrenaku nehige'na negasmue.
4 Mó sì rò wí pé ó yẹ kí n mú ọ̀rọ̀ náà wá sí etí ìgbọ́ rẹ, wí pé kí o rà á ní iwájú gbogbo àwọn tí ó jókòó sí ibi yìí. Bí ìwọ yóò bá rà á padà rà á. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ní rà á padà, sọ fún mi, kí èmi ó le è mọ̀. Nítorí pé kò sí ẹlòmíràn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti rà á ju ìwọ lọ, èmi sì ni ẹni tí ó tún kàn lẹ́yìn rẹ̀.” Ọkùnrin náà sì sọ wí pé, “Èmi yóò rà á padà.”
Hige'na nagra tamage kazigati kasami fatgo hunaku nagesa nentahue. Amama mani'naza vahe'ene, ranra kva vahe'nimokizmi zamufi, kagrama miza sena aza hugahue hanunka, amne ana huo. Hagi ana osugahue hanunka, nasmige'na antahi'neno. Na'ankure kagra kagota hanke'na, nagra kagri kamage hu'noe. Ana ne'mo'a kenona huno, Nagra mizasena aza hugahue huno hu'ne.
5 Nígbà náà ni Boasi sọ wí pé, “Bí ìwọ bá ti ra ilẹ̀ náà lọ́wọ́ Naomi àti lọ́wọ́ Rutu ará Moabu, ìwọ gbọdọ̀ fẹ́ opó ọkùnrin náà, kí orúkọ ọkùnrin tí ó kú náà má ba à parẹ́ pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀ àti kí o le è bímọ ní orúkọ rẹ̀.”
Higeno Boasi'a anage hu'ne, Ana mopa Naomi azampinti miza sesana zupa, Moabuti a'ma fri'nemofo kento a' Rutina nafa'aza hunenka, fri'nea ne'mofo naga zamagima erifore hananke'za, ana naga'mo'za ana mopa erigahaze.
6 Nígbà náà ni ọkùnrin náà dáhùn sí èyí pé, “Nípa ti èyí, èmi kò le è rà á padà, nítorí pé, ọmọ rẹ̀, ọkùnrin yóò wá jẹ́ ajogún àwọn ohun ìní mi pẹ̀lú. Rà á fún ara rẹ, èmi kò le ṣe é.”
Avate korama kvama huntega ne'mo'a anage hu'ne, Nagra mizase'na azahuga osu'noe. Na'ankure e'ina hanu'na nenfa'ma namige'na erisanti hare'noa zana eri haviza hugahue. E'ina hu'negu nagrama huga'zana kagra huo. Na'ankure nagra mizase'na azahuga osu'noe.
7 Ní ayé ìgbàanì, kí a tó le sọ wí pé ohun ìràpadà tàbí pàṣípàrọ̀ ohun ìní fi ìdí múlẹ̀ ní ilẹ̀ Israẹli, ẹnìkan ni láti yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀ kí ó sì fi fún ẹnìkejì, ó jẹ́ òfin fún ẹni tí ó fẹ́ rà á. Nípa ṣíṣe èyí, àwọn ará Israẹli fihàn wí pé ọ̀rọ̀ náà ti fìdímúlẹ̀.
Hagi amanahu avu'avara, korapa knafi'na Israeli vahepi me'neane. Mago vahemo'ma mago'zama mizasekuro, azahukura, mago agia ano zafino mago'mofo nemia zane. Higeno amanahu antahi'zamo'a mani'zamofo kankamu erifore huno Israeli vahera aza nehia zane.
8 Nítorí náà, nígbà tí ọkùnrin náà sọ fún Boasi wí pé, “Ìwọ rà á fúnra rẹ̀,” ó yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
Ana higeno, Rutima kegava huntega ne'mo'a, Boasinku anage hu'ne, Kagraka'a suza miza'so, nehuno aga nona zafi'ne.
9 Nígbà náà ni Boasi wí fún àwọn àgbàgbà àti àwọn mìíràn tí ó wà ní ibẹ̀ pé, “Gbogbo yín jẹ́ ẹlẹ́rìí mi ní òní wí pé mo ti ra ohun gbogbo tí í ṣe ti Elimeleki àti àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì: Maloni àti Kilioni lọ́wọ́ Naomi.
Anante Boasi'a ranra vaheku'ene, mika vaheku anage hu'ne, Tamagra negesage'na tamagri tamufi menina Naomi azampintira, Elimelekima, Kilioni'ma, Maloni zantamima me'neana, nagra miza segahue.
10 Ní àfikún, mo ra Rutu ará Moabu opó Maloni padà láti di aya mi. Èyí tí yóò mú kí orúkọ ọkùnrin òkú náà wà pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, kí ìran rẹ̀ má ba à lè parẹ́ láàrín àwọn ẹbí rẹ̀ àti ìlú rẹ̀. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ní òní.”
Nagra ana zanke hu'na, Moaputi a' Rutina azeri nafa'a nehue, Maloni kento a'mo nagri a' mani'neno, fri'nea ne'mofo agi fanane hu'zanku zamagia erifore hanige'za ana mopare ene, vahe'afine, kuma'afinena fanane osugahie. Mika vahe'mota menina amazana tamufinti negaze,
11 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí, kí Olúwa jẹ́ kí obìnrin tí ó ń bọ̀ wá sí inú ilẹ̀ rẹ dàbí Rakeli àti Lea láti ara àwọn ẹni tí gbogbo ìdílé Israẹli ti jáde wá. Kí ìwọ sì di ọlọ́rọ̀ ní ìran Efrata àti olókìkí ní ìlú Bẹtilẹhẹmu.
huno higeno ana kumamofo kasante mani'naza vahe'ene, kumate ranra vahe'ene mika'moza hu'za, Tagra negone, Ra Anumzamo azeri so'e hanigeno nonka'afima esnia a'mo'a, Resoli'ene, Liakema, Israeli vahe kse hakare huna'a kna hugahie. Hanigenka kagra Efrati naga nofipi ra kagi erinka Betlehemia feno ne' manigahane.
12 Kí Olúwa fún ọ ní ọmọ tí yóò mú ìdílé rẹ dàbí ti Peresi ọmọkùnrin tí Tamari bí fún Juda láti ipasẹ̀ ọ̀dọ́mọbìnrin yìí.”
Mago'ene nagakamo'za, Peresi naga kna huza, Judanteti Tamari'ma kasente'nea ne'mofo nagapinti, Ra Anumzamo ama a'pinti mofavre zaga kamigahie.
13 Báyìí ni Boasi ṣe mú Rutu, tí ó sì di aya rẹ̀. Nígbà náà ni ó wọlé tọ aya rẹ̀, Olúwa sì mú kí ó lóyún, ó sì bí ọmọ ọkùnrin kan.
Higeno Boasi'a, Ruti a' avregeno nenaro'za higeno, anteno mase'ne. Ramo azeri knare huntegeno agra amu'ene huno ne'mofavre ksente'ne.
14 Àwọn obìnrin sì wí fún Naomi pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí kò fi ọ sílẹ̀ ní òní yìí láìní ìbátan, Olùràpadà. Kí ọmọ náà di olókìkí ní Israẹli.
Anante a'nemo'za Naominku anage hu'naze, Ra Anumzamofo agi'a erisga hanune, na'ankure meni ama knafina kzahu vahera omani'ne huno onkatre'ne. Ama mofavremo Israeli vahe motafina ragi erigahie.
15 Yóò tún ayé rẹ ṣe, yóò sì dáàbò bò ọ́ ní ọjọ́ ogbó rẹ. Nítorí pé ìyàwó ọmọ rẹ, èyí tí ó sàn fún ọ ju ọmọkùnrin méje lọ, tí ó sì fẹ́ràn rẹ ni ó bí ọmọ yìí fún.”
Agra nomani zanka'a kzeri muse nehuno tavava'ma resankeno'a knare huno kegava hugantegahie, na'ankure neganofero'a, seveni'a ne'mofavre zaga zamagatere'no, agra avesi kantega'hie!
16 Naomi sì gbé ọmọ náà lé orí ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì ń tọ́jú rẹ̀.
Anante Naomi'a ana mofavre avreno, agra'a asumpi anukino kegava hu'ne.
17 Àwọn obìnrin àdúgbò sì wí pé, “A bí ọmọkùnrin kan fún Naomi.” Wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Obedi. Òun sì ni baba Jese tí í ṣe baba Dafidi.
Magopi nemaniza a'nemo'za, anage hu'naze, Mago ne'mofavre Naomi'na fore humie! Obeti'e hu'za agi'a antemi'naze. Obeti'a raseno Jesi ksentegeno, Jesi'a, Deviti nefaza hu'ne!
18 Èyí ni ìran Peresi: Peresi ni baba Hesroni,
Ama'ne e'i Peresi naga'nofimokizmi zamagi'e, Peresi'a, Hesroni ksente'ne,
19 Hesroni ni baba Ramu, Ramu ni baba Amminadabu
Hesroni'a, Rami ksentegeno, Rami'a, Aminadabu ksente'ne.
20 Amminadabu ni baba Nahiṣoni, Nahiṣoni ni baba Salmoni,
Aminadabu'a, Nasoni ksentegeno, Nasoni'a, Salmoni ksente'ne.
21 Salmoni ni baba Boasi, Boasi ni baba Obedi,
Salmoni'a, Boasi ksentegeno Boasi'a, Obeti ksente'ne.
22 Obedi ní baba Jese, Jese ni baba Dafidi.
Obeti'a, Jesi ksentegeno, Jesi'a, Deviti ksente'ne.

< Ruth 4 >