< Ruth 4 >

1 Nígbà náà ni Boasi gòkè lọ sí ẹnu ibodè ìlú, ó sì jókòó síbẹ̀. Nígbà tí ìbátan tí ó súnmọ́ Elimeleki jùlọ, arákùnrin tí Boasi ti sọ̀rọ̀ rẹ̀ ń kọjá, Boasi pè é wí pé, “Máa bọ̀ wá síbí ìwọ ọ̀rẹ́ mi, kí o sì jókòó.” Ó sì lọ jókòó.
A LAILA pii aku la o Boaza i ka puka pa, a noho iho la ilaila; aia hoi, hele ae la ka hoahanau a Boaza i olelo ai. I aku la keia ia ia, E, o mea, e huli mai oe, a e noho iho maanei. Huli mai la ia a noho iho la.
2 Boasi sì pe mẹ́wàá nínú àwọn àgbàgbà ìlú, wí pé ki wọn jókòó, wọn sí ṣe bẹ́ẹ̀,
Lawe ae la ia i na lunakahiko o ke kulanakauhale he umi, i aku la, E noho mai oukou maanei; a noho mai la lakou.
3 ó sì sọ fún ìbátan rẹ̀ náà pé, “Arábìnrin Naomi tí ó dé láti ilẹ̀ Moabu fẹ́ ta ilẹ̀, èyí tí ó ṣe ti arákùnrin Elimeleki wa.
I aku la ia i ka hoahanau, O Naomi, ka mea i hoi mai, mai ka aina i Moaba mai, ke kuai nei oia i ka aina o ke kaikuana o kaua, o Elimeleka.
4 Mó sì rò wí pé ó yẹ kí n mú ọ̀rọ̀ náà wá sí etí ìgbọ́ rẹ, wí pé kí o rà á ní iwájú gbogbo àwọn tí ó jókòó sí ibi yìí. Bí ìwọ yóò bá rà á padà rà á. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ní rà á padà, sọ fún mi, kí èmi ó le è mọ̀. Nítorí pé kò sí ẹlòmíràn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti rà á ju ìwọ lọ, èmi sì ni ẹni tí ó tún kàn lẹ́yìn rẹ̀.” Ọkùnrin náà sì sọ wí pé, “Èmi yóò rà á padà.”
I iho la au, E hai aku no au ma kou pepeiao, me ka i ana aku, E kii aku oe imua o ke alo o na kanaka, a me na lunakahiko o ko'u poe kanaka. Ina i kuai oe, e kuai no, a i ole oe e kuai, e hai mai oe ia'u, i ike au; no ka mea, aole mea e ae nana e kuai, o oe wale no, a owau ka mea mahope ou. I mai la kela, E kuai no au.
5 Nígbà náà ni Boasi sọ wí pé, “Bí ìwọ bá ti ra ilẹ̀ náà lọ́wọ́ Naomi àti lọ́wọ́ Rutu ará Moabu, ìwọ gbọdọ̀ fẹ́ opó ọkùnrin náà, kí orúkọ ọkùnrin tí ó kú náà má ba à parẹ́ pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀ àti kí o le è bímọ ní orúkọ rẹ̀.”
I aku la o Boaza, I ka la au e kuai ai i ka aina ma ka lima o Naomi, ma o Ruta la no kekahi e kuai aku ai, ma ka wahine no Moaba, ka wahine a ka mea i make, i mea e mau ai ka inoa o ka mea i make ma kona hooilina.
6 Nígbà náà ni ọkùnrin náà dáhùn sí èyí pé, “Nípa ti èyí, èmi kò le è rà á padà, nítorí pé, ọmọ rẹ̀, ọkùnrin yóò wá jẹ́ ajogún àwọn ohun ìní mi pẹ̀lú. Rà á fún ara rẹ, èmi kò le ṣe é.”
Olelo mai la ka hoahanau, Aole hiki ia'u ke kuai no'u iho, o hoolilo auanei au i ko'u hooilina. Nau no e kuai i ko'u kuleana nou, no ka mea, aole hiki ia'u ke kuai.
7 Ní ayé ìgbàanì, kí a tó le sọ wí pé ohun ìràpadà tàbí pàṣípàrọ̀ ohun ìní fi ìdí múlẹ̀ ní ilẹ̀ Israẹli, ẹnìkan ni láti yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀ kí ó sì fi fún ẹnìkejì, ó jẹ́ òfin fún ẹni tí ó fẹ́ rà á. Nípa ṣíṣe èyí, àwọn ará Israẹli fihàn wí pé ọ̀rọ̀ náà ti fìdímúlẹ̀.
Eia ko ka aoao kahiko o ka Iseraela ma ke kuai ana, a me ka hoonohonoho hou ana, i paa na mea a pau. Wehe ke kanaka i kona kamaa, a haawi ae la i kona hoalauna, i mea e hoike ai iwaena o ka Iseraela.
8 Nítorí náà, nígbà tí ọkùnrin náà sọ fún Boasi wí pé, “Ìwọ rà á fúnra rẹ̀,” ó yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
Olelo mai la ka hoahanau ia Boaza, E kuai oe nou iho; a wehe ae la ia i kona kamaa.
9 Nígbà náà ni Boasi wí fún àwọn àgbàgbà àti àwọn mìíràn tí ó wà ní ibẹ̀ pé, “Gbogbo yín jẹ́ ẹlẹ́rìí mi ní òní wí pé mo ti ra ohun gbogbo tí í ṣe ti Elimeleki àti àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì: Maloni àti Kilioni lọ́wọ́ Naomi.
Olelo ae la o Boaza i na lunakahiko, a i na kanaka a pau, He poe ike oukou i keia la, ua kuai au ma ka lima o Naomi i na mea a pau o Elimeleka a me na mea a pau o Kiliona, a me Mahelona.
10 Ní àfikún, mo ra Rutu ará Moabu opó Maloni padà láti di aya mi. Èyí tí yóò mú kí orúkọ ọkùnrin òkú náà wà pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, kí ìran rẹ̀ má ba à lè parẹ́ láàrín àwọn ẹbí rẹ̀ àti ìlú rẹ̀. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ní òní.”
A o Ruta no hoi, no Moaba ka wahine a Mahelona, ka'u i kuai nei, i wahine na'u, i mea e paa ai ka inoa o ka mea i make ma kona hoilina, i mea hoi e hooki ole ia'i ka inoa o ka mea i make, mai kona hoahanau aku, a mai kona wahi aku. He poe ike oukou i keia la.
11 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí, kí Olúwa jẹ́ kí obìnrin tí ó ń bọ̀ wá sí inú ilẹ̀ rẹ dàbí Rakeli àti Lea láti ara àwọn ẹni tí gbogbo ìdílé Israẹli ti jáde wá. Kí ìwọ sì di ọlọ́rọ̀ ní ìran Efrata àti olókìkí ní ìlú Bẹtilẹhẹmu.
I mai la na kanaka a pau, ma ka puka pa, a me na lunakahiko, He poe ike makou. Na Iehova no e hoolilo mai i ka wahine i hele mai iloko o kou hale e like me Rahela a me Lea, na laua elua i kukulu i ka hale o ka Iseraela, a e waiwai hoi oe ma Eperata, a e kaulana no kou inoa ma Betelehema.
12 Kí Olúwa fún ọ ní ọmọ tí yóò mú ìdílé rẹ dàbí ti Peresi ọmọkùnrin tí Tamari bí fún Juda láti ipasẹ̀ ọ̀dọ́mọbìnrin yìí.”
E like hoi kou hale me ka hale o Pareza, ka mea a Tamara i hanau ai na Iuda, ma ke kauhua a Iehova e haawi mai ai ia oe na keia kaikamahine.
13 Báyìí ni Boasi ṣe mú Rutu, tí ó sì di aya rẹ̀. Nígbà náà ni ó wọlé tọ aya rẹ̀, Olúwa sì mú kí ó lóyún, ó sì bí ọmọ ọkùnrin kan.
Lawe ae la o Boaza ia Ruta, a lilo mai ia i wahine nana. A i kona komo ana io na la, na Iehova i haawi mai i ka hapai ana, a hanau mai la ia, he keikikane.
14 Àwọn obìnrin sì wí fún Naomi pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí kò fi ọ sílẹ̀ ní òní yìí láìní ìbátan, Olùràpadà. Kí ọmọ náà di olókìkí ní Israẹli.
I aku la na wahine ia Naomi, Ua pomaikai oe ia Iehova, ka mea i hoonele ole ia oe i ka hoahanau nou, i keia la, i kaulana kona inoa iloko o ka Iseraela.
15 Yóò tún ayé rẹ ṣe, yóò sì dáàbò bò ọ́ ní ọjọ́ ogbó rẹ. Nítorí pé ìyàwó ọmọ rẹ, èyí tí ó sàn fún ọ ju ọmọkùnrin méje lọ, tí ó sì fẹ́ràn rẹ ni ó bí ọmọ yìí fún.”
Nana no e hoola hou aku ia oe, i kona malama ana ia oe, i kou wa e poohina ai; no ka mea, o kau hunonawahine, i hanau mai ia ia, nana oe i aloha aku, a ua oi aku kona maikai nou, mamua o na keikikane ehiku.
16 Naomi sì gbé ọmọ náà lé orí ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì ń tọ́jú rẹ̀.
Lawe ae la o Naomi i ua keiki la, a waiho iho la ma kona poli, a lilo iho la ia i kahu nona.
17 Àwọn obìnrin àdúgbò sì wí pé, “A bí ọmọkùnrin kan fún Naomi.” Wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Obedi. Òun sì ni baba Jese tí í ṣe baba Dafidi.
Kapa aku la kona poe hoalauna wahine i kona inoa, i ae la, Ua hanauia ke keikikane na Naomi; a kapa aku lakou i kona inoa, o Obeda; oia ka makuakane o Iese, o ka makuakane o Davida.
18 Èyí ni ìran Peresi: Peresi ni baba Hesroni,
Eia na hanauna o Pareza; na Pareza o Hezerona,
19 Hesroni ni baba Ramu, Ramu ni baba Amminadabu
Na Hezerona o Rama, na Rama o Aminadaba,
20 Amminadabu ni baba Nahiṣoni, Nahiṣoni ni baba Salmoni,
Na Aminadaba o Nahasona, a na Nahasona o Salemona,
21 Salmoni ni baba Boasi, Boasi ni baba Obedi,
Na Salemona o Boaza, a na Boaza o Obeda,
22 Obedi ní baba Jese, Jese ni baba Dafidi.
Na Obeda o Iese, na Iese o Davida.

< Ruth 4 >