< Ruth 4 >

1 Nígbà náà ni Boasi gòkè lọ sí ẹnu ibodè ìlú, ó sì jókòó síbẹ̀. Nígbà tí ìbátan tí ó súnmọ́ Elimeleki jùlọ, arákùnrin tí Boasi ti sọ̀rọ̀ rẹ̀ ń kọjá, Boasi pè é wí pé, “Máa bọ̀ wá síbí ìwọ ọ̀rẹ́ mi, kí o sì jókòó.” Ó sì lọ jókòó.
Na rĩrĩ, Boazu akĩambata agĩthiĩ nginya kĩhingo-inĩ gĩa itũũra, agĩikara thĩ ho. Rĩrĩa mũndũ ũrĩa wa mbarĩ yao, ũrĩa Boazu aarĩtie ũhoro wake ookire-rĩ, Boazu akĩmwĩra atĩrĩ, “Mũrata wakwa, ũka haha ũikare thĩ.” Nĩ ũndũ ũcio agĩthiĩ hau agĩikara thĩ.
2 Boasi sì pe mẹ́wàá nínú àwọn àgbàgbà ìlú, wí pé ki wọn jókòó, wọn sí ṣe bẹ́ẹ̀,
Boazu agĩĩta athuuri ikũmi a itũũra akĩmeera atĩrĩ, “Ta ikarai thĩ haha!” Nao magĩĩka o ũguo.
3 ó sì sọ fún ìbátan rẹ̀ náà pé, “Arábìnrin Naomi tí ó dé láti ilẹ̀ Moabu fẹ́ ta ilẹ̀, èyí tí ó ṣe ti arákùnrin Elimeleki wa.
Ningĩ akĩĩra mũndũ ũcio wa mbarĩ yao atĩrĩ, “Naomi ũrĩa ũracookire kuuma bũrũri wa Moabi-rĩ, nĩarendia gĩthaka kĩrĩa kĩarĩ kĩa Elimeleku, mũndũ wa mbarĩ ciitũ.
4 Mó sì rò wí pé ó yẹ kí n mú ọ̀rọ̀ náà wá sí etí ìgbọ́ rẹ, wí pé kí o rà á ní iwájú gbogbo àwọn tí ó jókòó sí ibi yìí. Bí ìwọ yóò bá rà á padà rà á. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ní rà á padà, sọ fún mi, kí èmi ó le è mọ̀. Nítorí pé kò sí ẹlòmíràn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti rà á ju ìwọ lọ, èmi sì ni ẹni tí ó tún kàn lẹ́yìn rẹ̀.” Ọkùnrin náà sì sọ wí pé, “Èmi yóò rà á padà.”
Ndagĩĩciiria ngũhe ũhoro ũcio na ngwĩre ũgũre gĩthaka kĩu ũrĩ mbere ya andũ aya maikarĩte haha o na mbere ya athuuri a andũ aitũ. Ũngĩkorwo nĩũgũgĩkũũra, ũgĩkũũre. No angĩkorwo ndũgwĩka ũguo-rĩ, ũnjĩĩre nĩguo menye. Nĩgũkorwo hatirĩ mũndũ ũngĩ ũrĩ na kĩhooto gĩa gwĩka ũguo tiga wee, na niĩ ngagũcooka.” Nake akiuga atĩrĩ, “Nĩngũgĩkũũra.”
5 Nígbà náà ni Boasi sọ wí pé, “Bí ìwọ bá ti ra ilẹ̀ náà lọ́wọ́ Naomi àti lọ́wọ́ Rutu ará Moabu, ìwọ gbọdọ̀ fẹ́ opó ọkùnrin náà, kí orúkọ ọkùnrin tí ó kú náà má ba à parẹ́ pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀ àti kí o le è bímọ ní orúkọ rẹ̀.”
Boazu nake akiuga atĩrĩ, “Mũthenya ũrĩa ũkaagũra gĩthaka kĩu kuuma kũrĩ Naomi, na kuuma kũrĩ Ruthu ũrĩa Mũmoabi, nĩũkahikia mũtumia wa ndigwa wa mũndũ ũcio wakuire, nĩgeetha ũtũũrie rĩĩtwa rĩa ũcio ũkuĩte o hamwe na indo ciake.”
6 Nígbà náà ni ọkùnrin náà dáhùn sí èyí pé, “Nípa ti èyí, èmi kò le è rà á padà, nítorí pé, ọmọ rẹ̀, ọkùnrin yóò wá jẹ́ ajogún àwọn ohun ìní mi pẹ̀lú. Rà á fún ara rẹ, èmi kò le ṣe é.”
Na rĩrĩa mũndũ ũcio wa mbarĩ yao aiguire ũguo-rĩ, akiuga atĩrĩ, “Ndikũhota gũgĩkũũra, nĩ ũndũ ndahota gwĩthũkĩria ũgai wakwa niĩ mwene. Gĩgĩkũũre arĩ we. Niĩ ndingĩhota gwĩka ũguo.”
7 Ní ayé ìgbàanì, kí a tó le sọ wí pé ohun ìràpadà tàbí pàṣípàrọ̀ ohun ìní fi ìdí múlẹ̀ ní ilẹ̀ Israẹli, ẹnìkan ni láti yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀ kí ó sì fi fún ẹnìkejì, ó jẹ́ òfin fún ẹni tí ó fẹ́ rà á. Nípa ṣíṣe èyí, àwọn ará Israẹli fihàn wí pé ọ̀rọ̀ náà ti fìdímúlẹ̀.
(Matukũ-inĩ ma tene thĩinĩ wa Isiraeli-rĩ, mũtugo wa gũkũũra kana gũkũũrania indo nĩguo maũndũ mothe marĩkio wega, mũndũ ũmwe wa eene ũhoro aarutaga kĩraatũ gĩake agakĩnengera mũndũ ũcio ũngĩ. Kũu Isiraeli ĩno nĩyo yarĩ njĩra ya gwĩkĩra ũira atĩ ũndũ ũrĩa mũiguanĩre nĩwarĩĩkĩrĩra wega biũ.)
8 Nítorí náà, nígbà tí ọkùnrin náà sọ fún Boasi wí pé, “Ìwọ rà á fúnra rẹ̀,” ó yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
Nĩ ũndũ ũcio mũndũ ũcio wa mbarĩ yao akĩĩra Boazu atĩrĩ, “Kĩgũre wee mwene.” Na akĩruta kĩraatũ gĩake, akĩmũnengera.
9 Nígbà náà ni Boasi wí fún àwọn àgbàgbà àti àwọn mìíràn tí ó wà ní ibẹ̀ pé, “Gbogbo yín jẹ́ ẹlẹ́rìí mi ní òní wí pé mo ti ra ohun gbogbo tí í ṣe ti Elimeleki àti àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì: Maloni àti Kilioni lọ́wọ́ Naomi.
Hĩndĩ ĩyo Boazu akĩĩra athuuri acio na andũ othe atĩrĩ, “Ũmũthĩ mũrĩ aira akwa atĩ nĩndagũra indo ciothe cia Elimeleku, na cia Kilioni, na cia Mahaloni kuuma kũrĩ Naomi.
10 Ní àfikún, mo ra Rutu ará Moabu opó Maloni padà láti di aya mi. Èyí tí yóò mú kí orúkọ ọkùnrin òkú náà wà pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, kí ìran rẹ̀ má ba à lè parẹ́ láàrín àwọn ẹbí rẹ̀ àti ìlú rẹ̀. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ní òní.”
Ningĩ nĩndahikia Ruthu ũrĩa Mũmoabi, mũtumia wa ndigwa wa Mahaloni, atuĩke mũtumia wakwa, nĩguo ndũũrie rĩĩtwa rĩa ũcio ũkuĩte hamwe na indo ciake, nĩguo rĩĩtwa rĩake rĩtikaanoore nyũmba-inĩ yao, kana rĩehere maandĩko-inĩ marĩa maigĩtwo ma itũũra. Ũmũthĩ nĩmwatuĩka aira!”
11 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí, kí Olúwa jẹ́ kí obìnrin tí ó ń bọ̀ wá sí inú ilẹ̀ rẹ dàbí Rakeli àti Lea láti ara àwọn ẹni tí gbogbo ìdílé Israẹli ti jáde wá. Kí ìwọ sì di ọlọ́rọ̀ ní ìran Efrata àti olókìkí ní ìlú Bẹtilẹhẹmu.
Ningĩ athuuri acio, o na andũ arĩa othe maikarĩte hau kĩhingo-inĩ, makiuga atĩrĩ, “Tũrĩ aira. Jehova arotũma mũndũ-wa-nja ũcio ũroka gwaku mũciĩ atuĩke o ta Rakeli na Lea, andũ-a-nja arĩa eerĩ maakire nyũmba ya Isiraeli. Ũromenyeka kũu Efiratha, na ũgĩe igweta inene kũu Bethilehemu.
12 Kí Olúwa fún ọ ní ọmọ tí yóò mú ìdílé rẹ dàbí ti Peresi ọmọkùnrin tí Tamari bí fún Juda láti ipasẹ̀ ọ̀dọ́mọbìnrin yìí.”
Ciana iria Jehova egũkũhe kuuma kũrĩ mũirĩtu ũcio irotũma nyũmba yaku ĩhaane ta ya Perezu, ũrĩa Tamaru aaciarĩire Juda.”
13 Báyìí ni Boasi ṣe mú Rutu, tí ó sì di aya rẹ̀. Nígbà náà ni ó wọlé tọ aya rẹ̀, Olúwa sì mú kí ó lóyún, ó sì bí ọmọ ọkùnrin kan.
Nĩ ũndũ ũcio Boazu akĩhikia Ruthu, agĩtuĩka mũtumia wake. Ningĩ aakoma nake, Jehova agĩtũma Ruthu agĩe nda, na agĩciara kahĩĩ.
14 Àwọn obìnrin sì wí fún Naomi pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí kò fi ọ sílẹ̀ ní òní yìí láìní ìbátan, Olùràpadà. Kí ọmọ náà di olókìkí ní Israẹli.
Nao andũ-a-nja makĩĩra Naomi atĩrĩ, “Jehova arogoocwo, ũrĩa ũtagũtigĩte ũtarĩ na mũkũmenyereri. Kahĩĩ kau karogĩa ngumo njega Isiraeli guothe!
15 Yóò tún ayé rẹ ṣe, yóò sì dáàbò bò ọ́ ní ọjọ́ ogbó rẹ. Nítorí pé ìyàwó ọmọ rẹ, èyí tí ó sàn fún ọ ju ọmọkùnrin méje lọ, tí ó sì fẹ́ràn rẹ ni ó bí ọmọ yìí fún.”
Kau nĩko gakerũhia mũtũũrĩre waku, na gagũtũũrie ũkũrũ-inĩ waku. Nĩ ũndũ mũtumia wa mũrũguo, ũrĩa ũkwendete na wa bata harĩ we gũkĩra aanake mũgwanja, nĩwe ũgaciarĩte.”
16 Naomi sì gbé ọmọ náà lé orí ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì ń tọ́jú rẹ̀.
Nake Naomi akĩoya kaana kau, agĩkaigĩrĩra ciero-inĩ ciake, agĩkarera.
17 Àwọn obìnrin àdúgbò sì wí pé, “A bí ọmọkùnrin kan fún Naomi.” Wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Obedi. Òun sì ni baba Jese tí í ṣe baba Dafidi.
Nao andũ-a-nja arĩa maatũũraga kũu makiuga atĩrĩ, “Naomi arĩ na kahĩĩ.” Nao magĩgatua Obedi. Nake nĩwe warĩ ithe wa Jesii, ũrĩa warĩ ithe wa Daudi.
18 Èyí ni ìran Peresi: Peresi ni baba Hesroni,
Ici nacio nĩcio njiaro cia Perezu: Perezu nĩwe warĩ ithe wa Hezironi,
19 Hesroni ni baba Ramu, Ramu ni baba Amminadabu
nake Hezironi aarĩ ithe wa Ramu,
20 Amminadabu ni baba Nahiṣoni, Nahiṣoni ni baba Salmoni,
nake Ramu aarĩ ithe wa Aminadabu, nake Aminadabu aarĩ ithe wa Nahashoni, nake Nahashoni aarĩ ithe wa Salimoni,
21 Salmoni ni baba Boasi, Boasi ni baba Obedi,
nake Salimoni aarĩ ithe wa Boazu, nake Boazu aarĩ ithe wa Obedi.
22 Obedi ní baba Jese, Jese ni baba Dafidi.
nake Obedi aarĩ ithe wa Jesii, nake Jesii aarĩ ithe wa Daudi.

< Ruth 4 >