< Ruth 4 >

1 Nígbà náà ni Boasi gòkè lọ sí ẹnu ibodè ìlú, ó sì jókòó síbẹ̀. Nígbà tí ìbátan tí ó súnmọ́ Elimeleki jùlọ, arákùnrin tí Boasi ti sọ̀rọ̀ rẹ̀ ń kọjá, Boasi pè é wí pé, “Máa bọ̀ wá síbí ìwọ ọ̀rẹ́ mi, kí o sì jókòó.” Ó sì lọ jókòó.
Boaz te vongka la cet tih ngol. Te vaengah aka tlan koi la a thui hlang te ha pawk tih Boaz loh, “Tongmang hela pah lamtah ngol dae lah,” a ti nah. Te dongah phael tih ngol thuk.
2 Boasi sì pe mẹ́wàá nínú àwọn àgbàgbà ìlú, wí pé ki wọn jókòó, wọn sí ṣe bẹ́ẹ̀,
Te phoeiah khopuei kah a hamca rhoek te hlang parha a loh tih, “Hela ngol uh dae,” a ti nah vanbangla amih khaw ngol uh.
3 ó sì sọ fún ìbátan rẹ̀ náà pé, “Arábìnrin Naomi tí ó dé láti ilẹ̀ Moabu fẹ́ ta ilẹ̀, èyí tí ó ṣe ti arákùnrin Elimeleki wa.
Te vaengah aka tlan koi taengah, “Mamih kah manuca Elimelekh khohmuen kah lo aka yoi Naomi tah Moab kho lamkah ha bal coeng.
4 Mó sì rò wí pé ó yẹ kí n mú ọ̀rọ̀ náà wá sí etí ìgbọ́ rẹ, wí pé kí o rà á ní iwájú gbogbo àwọn tí ó jókòó sí ibi yìí. Bí ìwọ yóò bá rà á padà rà á. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ní rà á padà, sọ fún mi, kí èmi ó le è mọ̀. Nítorí pé kò sí ẹlòmíràn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti rà á ju ìwọ lọ, èmi sì ni ẹni tí ó tún kàn lẹ́yìn rẹ̀.” Ọkùnrin náà sì sọ wí pé, “Èmi yóò rà á padà.”
Te dongah kai long tah namah hna ah kan yaak sak dae eh ka ti vanbangla hekah aka ngol rhoek hmai neh ka pilnam khuikah a hamca rhoek hmaiah koep lai laeh ka ti. Na tlan ham atah tlan laeh. Tedae na tlan pawt oeh atah kamah taengah he thui. Te daengah ni nang phoeiah aka tlan ham hlang a om pawt te ka ming khaw ka ming van eh. Tedae kai tah nang hnukkah pueng ni,” a ti nah vaengah, “Kamah loh ka tlan ni,” a ti nah.
5 Nígbà náà ni Boasi sọ wí pé, “Bí ìwọ bá ti ra ilẹ̀ náà lọ́wọ́ Naomi àti lọ́wọ́ Rutu ará Moabu, ìwọ gbọdọ̀ fẹ́ opó ọkùnrin náà, kí orúkọ ọkùnrin tí ó kú náà má ba à parẹ́ pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀ àti kí o le è bímọ ní orúkọ rẹ̀.”
Te vaengah Boaz loh, “Naomi neh aka duek kah a yuu Moab nu Ruth kut lamkah khohmuen he na lai khohnin vaengah aka duek ming te thoh pah ham ni a rho khaw na lai eh,” a ti nah.
6 Nígbà náà ni ọkùnrin náà dáhùn sí èyí pé, “Nípa ti èyí, èmi kò le è rà á padà, nítorí pé, ọmọ rẹ̀, ọkùnrin yóò wá jẹ́ ajogún àwọn ohun ìní mi pẹ̀lú. Rà á fún ara rẹ, èmi kò le ṣe é.”
Tedae aka tlan loh, “Kamah loh ka tlan ham akhaw a tlan ham ka noeng moenih. Ka rho he ka porhak sak ve. Namah ham na tlan mako. Ka tlannah neh tlan ham ka noeng moenih,” a ti nah.
7 Ní ayé ìgbàanì, kí a tó le sọ wí pé ohun ìràpadà tàbí pàṣípàrọ̀ ohun ìní fi ìdí múlẹ̀ ní ilẹ̀ Israẹli, ẹnìkan ni láti yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀ kí ó sì fi fún ẹnìkejì, ó jẹ́ òfin fún ẹni tí ó fẹ́ rà á. Nípa ṣíṣe èyí, àwọn ará Israẹli fihàn wí pé ọ̀rọ̀ náà ti fìdímúlẹ̀.
Hlamat vaengah tah Israel khuikah tlannah ham neh hnothung ham he, ol khat khat neh ana khueng thil uh. Te vaengah hlang pakhat loh a khokhom a dul tih a hui taengla a paek te Israel khuikah ciphuemyuhnah coeng ni.
8 Nítorí náà, nígbà tí ọkùnrin náà sọ fún Boasi wí pé, “Ìwọ rà á fúnra rẹ̀,” ó yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
Te dongah aka tlan tueng loh Boaz taengah, “Namah ham lai laeh,” a ti nah tih a khokhom te a dul.
9 Nígbà náà ni Boasi wí fún àwọn àgbàgbà àti àwọn mìíràn tí ó wà ní ibẹ̀ pé, “Gbogbo yín jẹ́ ẹlẹ́rìí mi ní òní wí pé mo ti ra ohun gbogbo tí í ṣe ti Elimeleki àti àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì: Maloni àti Kilioni lọ́wọ́ Naomi.
Te dongah a hamca rhoek taeng neh pilnam boeih taengah Boaz loh, “Elimelekh kah a koe boeih khaw, Kilion neh Mahlon koe boeih khaw Naomi kut lamkah ka lai coeng tila tihnin ah laipai la na om uh coeng.
10 Ní àfikún, mo ra Rutu ará Moabu opó Maloni padà láti di aya mi. Èyí tí yóò mú kí orúkọ ọkùnrin òkú náà wà pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, kí ìran rẹ̀ má ba à lè parẹ́ láàrín àwọn ẹbí rẹ̀ àti ìlú rẹ̀. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ní òní.”
Te dongah amah koe neh aka duek ming thoh pah ham ni Mahlon yurho, Moab nu Ruth khaw ka yuu la ka lai coeng. Te phoeiah aka duek kah a ming te a pacaboeina khui lamkah neh te hmuen vongka lamloh a muei pawt ham khaw tihnin ah laipai la na om uh coeng,” a ti nah.
11 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí, kí Olúwa jẹ́ kí obìnrin tí ó ń bọ̀ wá sí inú ilẹ̀ rẹ dàbí Rakeli àti Lea láti ara àwọn ẹni tí gbogbo ìdílé Israẹli ti jáde wá. Kí ìwọ sì di ọlọ́rọ̀ ní ìran Efrata àti olókìkí ní ìlú Bẹtilẹhẹmu.
Te vaengah vongka kah pilnam boeih neh a hamca rhoek loh, “Laipai la ka om uh coeng. Na im khuila aka kun huta tah, BOEIPA loh Israel imkhui aka thoh rhoi Rakhel neh Leah bangla khueh saeh. Epharath ah thadueng la om saeh lamtah Bethlehem ah a ming om saeh.
12 Kí Olúwa fún ọ ní ọmọ tí yóò mú ìdílé rẹ dàbí ti Peresi ọmọkùnrin tí Tamari bí fún Juda láti ipasẹ̀ ọ̀dọ́mọbìnrin yìí.”
Hekah hula dongah BOEIPA loh nang m'paek na tii na ngan lamloh na imkhui khaw Tamar loh Judah ham a sak Perez imkhui bangla om saeh,” a ti na uh.
13 Báyìí ni Boasi ṣe mú Rutu, tí ó sì di aya rẹ̀. Nígbà náà ni ó wọlé tọ aya rẹ̀, Olúwa sì mú kí ó lóyún, ó sì bí ọmọ ọkùnrin kan.
Boaz loh Ruth te a loh tih a yuu la coeng. Ruth taengla a kun vaengah rhumpum ham khaw BOEIPA loh a paek coeng dongah capa a cun.
14 Àwọn obìnrin sì wí fún Naomi pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí kò fi ọ sílẹ̀ ní òní yìí láìní ìbátan, Olùràpadà. Kí ọmọ náà di olókìkí ní Israẹli.
Te vaengah Naomi te huta rhoek loh, “Tihnin ah nang aka tlan ham te aka pat sak pawh BOEIPA te a yoethen pai saeh. A ming khaw Israel lakli ah thang pai saeh.
15 Yóò tún ayé rẹ ṣe, yóò sì dáàbò bò ọ́ ní ọjọ́ ogbó rẹ. Nítorí pé ìyàwó ọmọ rẹ, èyí tí ó sàn fún ọ ju ọmọkùnrin méje lọ, tí ó sì fẹ́ràn rẹ ni ó bí ọmọ yìí fún.”
Nang hamla na hinglu aka hlawt tih na sampok vaengah aka cangbam la om ni. Na langa loh nang n'lungnah tih anih a sak coeng. Anih pakhat he nang ham tah ca tongpa parhih lakah khaw then coeng,” a ti na uh.
16 Naomi sì gbé ọmọ náà lé orí ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì ń tọ́jú rẹ̀.
Camoe te Naomi loh a loh tih a rhang dongah a poem. Te dongah anih te camoe aka poeh la om.
17 Àwọn obìnrin àdúgbò sì wí pé, “A bí ọmọkùnrin kan fún Naomi.” Wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Obedi. Òun sì ni baba Jese tí í ṣe baba Dafidi.
Imben rhoek long khaw, “Naomi ham ca tongpa om coeng,” a ti uh tih camoe te a ming a sak pa uh. Te dongah a ming te Obed a sak pa uh. Anih tah Jesse napa tih, Jesse tah David napa la om.
18 Èyí ni ìran Peresi: Peresi ni baba Hesroni,
Te dongah Perez kah a rhuirhong rhoek la Perez loh Khetsron a sak.
19 Hesroni ni baba Ramu, Ramu ni baba Amminadabu
Khetsron loh Ram a sak tih Ram loh Amminadab a sak.
20 Amminadabu ni baba Nahiṣoni, Nahiṣoni ni baba Salmoni,
Amminadab loh Nahshon a sak tih Nahshon loh Salmon a sak.
21 Salmoni ni baba Boasi, Boasi ni baba Obedi,
Salmon loh Boaz a sak tih Boaz loh Obed a sak.
22 Obedi ní baba Jese, Jese ni baba Dafidi.
Obed loh Jesse a sak tih Jesse loh David a sak.

< Ruth 4 >