< Ruth 3 >

1 Ní ọjọ́ kan, Naomi, ìyá ọkọ Rutu wí fún un pé, “Ọmọbìnrin mi, ǹjẹ́ kò yẹ kí èmi bá ọ wá ilé ọkọ mìíràn, níbi tí wọn yóò ti le è máa tọ́jú rẹ?
Potem Noemi, jej teściowa, powiedziała do niej: Moja córko, czy nie powinnam ci szukać odpoczynku, abyś się dobrze miała?
2 Wò ó, Boasi ọkùnrin nì tí ìwọ bá àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ ṣiṣẹ́, tí í ṣe ìbátan wa, yóò wá láti fẹ́ ọkà barle ní ilẹ̀ ìpakà rẹ̀ ní àṣálẹ́ yìí.
I czyż Boaz nie jest naszym krewnym, z którego służącymi byłaś? Oto dziś w nocy będzie on przewiewał jęczmień na klepisku.
3 Wẹ̀, kí o sì fi ìpara olóòórùn dídùn pa ara rẹ, kí o sì wọ aṣọ rẹ tí ó dára jùlọ, kí o sì lọ sí ilẹ̀ ìpakà tí ó gbé ń pa ọkà, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí ó mọ̀ pé o wà níbẹ̀ títí tí yóò fi jẹ tí yóò sì mu tán.
Umyj się więc i namaść, nałóż na siebie swoje szaty i zejdź na klepisko, lecz nie daj się poznać temu człowiekowi, dopóki nie skończy jeść i pić.
4 Rí í dájú pé o mọ ibi tí ó sùn sí, lẹ́yìn ìgbà tí ó bá ti sùn, lọ kí o ṣí aṣọ ìbora rẹ̀ níbi ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè kí o sì sùn sí ibi ẹsẹ̀ náà. Òun yóò sì sọ ohun tí ìwọ yóò ṣe fún ọ.”
A gdy położy się spać, upatrz miejsce, na którym się położy, podejdź, odkryj jego nogi i połóż się, a on ci powie, co masz czynić.
5 Rutu sì fèsì pé, “Gbogbo ohun tí ìwọ sọ fún mi ni èmi yóò ṣe.”
I [Rut] powiedziała do niej: Uczynię wszystko, co mi każesz.
6 Bẹ́ẹ̀ ni Rutu lọ sí ilẹ̀ ìpakà tí ó sì ṣe gbogbo ohun tí ìyá ọkọ rẹ̀ sọ fún un, pé kí o ṣe.
Zeszła więc na klepisko i uczyniła to, co jej nakazała teściowa.
7 Nígbà tí Boasi parí jíjẹ àti mímu tán, tí ọkàn rẹ̀ sì kún fún ayọ̀. Ó lọ, ó sì dùbúlẹ̀ ní ẹ̀yìn ọkà tí wọ́n kójọ. Rutu yọ́ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́ lọ sí ibẹ̀, ó ṣí aṣọ ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè, ó sì sùn sí ibi ẹsẹ̀ rẹ̀.
A [gdy] Boaz najadł się i napił, i jego serce się rozweseliło, poszedł położyć się przy stosie zboża. Wtedy ona przyszła po cichu, odkryła jego nogi i położyła się.
8 Ó sì ṣe nígbà tí ọkùnrin náà tají ní àárín òru, ẹ̀rù bà á, ó sì yí ara padà, ó sì ṣàkíyèsí obìnrin kan tí ó sùn sí ibi ẹsẹ̀ rẹ̀.
O północy mężczyzna zląkł się, obrócił, a oto kobieta leżała u jego stóp.
9 Ó sì béèrè pé, “Ta ni ìwọ í ṣe?” Rutu sì fèsì wí pé, “Èmi ni Rutu, ìránṣẹ́bìnrin rẹ. Da etí aṣọ rẹ bò mí, nítorí pé ìwọ ni ìbátan tí ó le è rà mí padà.”
I powiedział: Kto ty jesteś? Odpowiedziała: Jestem Rut, twoja służąca. Rozciągnij swój płaszcz nad swoją służącą, bo jesteś ze mną blisko spokrewniony.
10 Boasi sì wí fún un pé, “Kí Olúwa bùkún fún ọ, ọmọbìnrin mi. Ìfẹ́ tí o fihàn yí ti pọ̀ ju ti àtẹ̀yìnwá lọ, bí ó ti jẹ́ wí pé ìwọ kò lọ láti wá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin bóyá ọlọ́rọ̀ tàbí tálákà.
A on odpowiedział: Błogosławiona jesteś przez PANA, moja córko. Większą miłość okazałaś teraz niż na początku, gdyż nie poszłaś za młodzieńcami, czy to ubogimi, czy bogatymi.
11 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ìwọ ọmọbìnrin mi, má bẹ̀rù. Èmi yóò sì ṣe ohun gbogbo tí o béèrè fún ọ. Gbogbo ènìyàn ni ó mọ̀ ọ́n ní obìnrin oníwà rere.
Teraz więc, moja córko, nie bój się. Uczynię wszystko, co powiedziałaś, gdyż całe miasto mego ludu wie, że jesteś cnotliwą kobietą.
12 Nítòótọ́ ni mo wí pé èmi jẹ́ ìbátan tí ó súnmọ́ ọ, ṣùgbọ́n ìbátan kan wà tí ó súnmọ́ ọ ju ti tèmi lọ.
A chociaż to prawda, że jestem z tobą blisko spokrewniony, to jednak bliżej jest z tobą spokrewniony inny ode mnie.
13 Dúró síbí títí ilẹ̀ yóò fi mọ́, bí ó bá sì di òwúrọ̀ tí ọkùnrin náà sì ṣe tan láti ṣe ìràpadà, ó dára kí ó ṣe bẹ́ẹ̀, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, bí Olúwa ti ń bẹ láààyè nígbà náà ni èmi yóò ṣe ìràpadà, sùn sí ìhín títí ilẹ̀ yóò fi mọ́.”
Zostań tu przez noc, a rankiem, jeśli zechce cię on wykupić, dobrze, niech wykupi. Lecz jeśli nie zechce cię wykupić, ja cię wykupię, jak żyje PAN! Śpij tu aż do rana.
14 Ó sì sùn ní ẹsẹ̀ rẹ̀ títí di òwúrọ̀, ṣùgbọ́n ó dìde ní òwúrọ̀ kùtùkùtù kí ẹnìkínní tó le è dá ẹnìkejì mọ̀. Boasi sì sọ fún un wí pé, “Má ṣe jẹ́ kí ó di mí mọ̀ wí pé obìnrin kan wá sí ilẹ̀ ìpakà.”
Spała więc u jego stóp aż do rana. Wstała jednak w porze, gdy człowiek nie jest w stanie rozpoznać drugiego. Mówił bowiem Boaz: Niech nikt się nie dowie, że kobieta przyszła na klepisko.
15 Ó sì tún wí fún un pé, “Mú aṣọ ìborùn rẹ tí o dà bora, kí o tẹ̀ ẹ sílẹ̀.” Rutu sì ṣe bẹ́ẹ̀, Boasi sì wọn òsùwọ̀n ọkà barle mẹ́fà sí i, ó sì gbé e rù ú. Nígbà náà ni ó padà sí ìlú.
I dodał: Daj okrycie, które masz na sobie, i trzymaj je. A [gdy] trzymała je, odmierzył jej sześć [miar] jęczmienia i włożył to na nią. Potem poszła do miasta.
16 Nígbà tí Rutu dé ilé Naomi ìyá ọkọ sì bí léèrè pé, “Báwo ni ó ti rí ọmọbìnrin mi?” Nígbà náà ni ó sì sọ gbogbo ohun tí ọkùnrin náà ṣe fún un fún ìyá ọkọ rẹ̀.
A gdy przyszła do teściowej, ta zapytała ją: Kto ty jesteś, moja córko? I opowiedziała jej wszystko, co ten człowiek uczynił dla niej.
17 Ó fi kún un wí pé, “Ó sọ fún mi wí pé, ‘Má ṣe padà sí ọ̀dọ̀ ìyá ọkọ rẹ ní ọwọ́ òfo, nítorí náà, ó fún mi ní ìwọ̀n ọkà barle mẹ́fà.’”
I dodała: [Oto] dał mi sześć [miar] jęczmienia. Powiedział bowiem do mnie: Nie możesz wrócić z pustymi rękami do swojej teściowej.
18 Naomi sì wí fún un pé, “Dúró, ọmọbìnrin mi títí tí ìwọ yóò fi mọ bí ohun gbogbo yóò ti rí, nítorí pé ọkùnrin náà kò ní sinmi títí tí ọ̀rọ̀ náà yóò fi yanjú lónìí.”
Wtedy Noemi powiedziała: Bądź spokojna, moja córko, aż się dowiesz, jak potoczą się rzeczy, gdyż ten człowiek nie spocznie, dopóki nie zakończy dzisiaj tej sprawy.

< Ruth 3 >