< Ruth 3 >

1 Ní ọjọ́ kan, Naomi, ìyá ọkọ Rutu wí fún un pé, “Ọmọbìnrin mi, ǹjẹ́ kò yẹ kí èmi bá ọ wá ilé ọkọ mìíràn, níbi tí wọn yóò ti le è máa tọ́jú rẹ?
Mũthenya ũmwe-rĩ, Naomi, nyaciarawe wa Ruthu, akĩmwĩra atĩrĩ, “Mwarĩ wakwa, githĩ ndiagĩrĩirwo ngũcarĩrie mũciĩ waku, kũrĩa wee ũngĩona maũndũ mega?
2 Wò ó, Boasi ọkùnrin nì tí ìwọ bá àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ ṣiṣẹ́, tí í ṣe ìbátan wa, yóò wá láti fẹ́ ọkà barle ní ilẹ̀ ìpakà rẹ̀ ní àṣálẹ́ yìí.
Githĩ Boazu ũcio wee ũkoretwo na ndungata ciake cia airĩtu ti mũndũ wa rũrĩra rwitũ? Ũtukũ ũyũ nĩguo ekũhuha cairi kĩhuhĩro-inĩ.
3 Wẹ̀, kí o sì fi ìpara olóòórùn dídùn pa ara rẹ, kí o sì wọ aṣọ rẹ tí ó dára jùlọ, kí o sì lọ sí ilẹ̀ ìpakà tí ó gbé ń pa ọkà, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí ó mọ̀ pé o wà níbẹ̀ títí tí yóò fi jẹ tí yóò sì mu tán.
Wĩthambe na wĩhake maguta mekũnunga wega, ningĩ wĩhumbe nguo ciaku iria njega mũno. Ũcooke ũikũrũke ũkinye kĩhuhĩro-inĩ, no ndũkeyonithie mũndũ ũcio nginya arĩkie kũrĩa na kũnyua.
4 Rí í dájú pé o mọ ibi tí ó sùn sí, lẹ́yìn ìgbà tí ó bá ti sùn, lọ kí o ṣí aṣọ ìbora rẹ̀ níbi ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè kí o sì sùn sí ibi ẹsẹ̀ náà. Òun yóò sì sọ ohun tí ìwọ yóò ṣe fún ọ.”
Rĩrĩa arĩkoma, wone harĩa akoma. Ningĩ ũthiĩ ho na ũhumbũrie magũrũ make, ũkome ho. Nake nĩegũkwĩra ũrĩa wagĩrĩirwo nĩ gwĩka.”
5 Rutu sì fèsì pé, “Gbogbo ohun tí ìwọ sọ fún mi ni èmi yóò ṣe.”
Ruthu akĩmũcookeria, akĩmwĩra atĩrĩ, “Maũndũ macio mothe wanjĩĩra no mo ngwĩka.”
6 Bẹ́ẹ̀ ni Rutu lọ sí ilẹ̀ ìpakà tí ó sì ṣe gbogbo ohun tí ìyá ọkọ rẹ̀ sọ fún un, pé kí o ṣe.
Nĩ ũndũ ũcio agĩikũrũka agĩkinya kĩhuhĩro-inĩ kĩu, na agĩĩka ũrĩa wothe nyaciarawe aamwĩrĩte eeke.
7 Nígbà tí Boasi parí jíjẹ àti mímu tán, tí ọkàn rẹ̀ sì kún fún ayọ̀. Ó lọ, ó sì dùbúlẹ̀ ní ẹ̀yìn ọkà tí wọ́n kójọ. Rutu yọ́ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́ lọ sí ibẹ̀, ó ṣí aṣọ ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè, ó sì sùn sí ibi ẹsẹ̀ rẹ̀.
Na rĩrĩa Boazu aarĩkirie kũrĩa na kũnyua, na agĩkorwo arĩ mũkenu, agĩthiĩ agĩkoma mũthia-inĩ biũ wa hĩba ya cairi. Nake Ruthu agĩthiĩ acemete, akĩmũhumbũria magũrũ, agĩkoma ho.
8 Ó sì ṣe nígbà tí ọkùnrin náà tají ní àárín òru, ẹ̀rù bà á, ó sì yí ara padà, ó sì ṣàkíyèsí obìnrin kan tí ó sùn sí ibi ẹsẹ̀ rẹ̀.
Ũtukũ gatagatĩ, kĩndũ gĩkĩhahũra Boazu, nake egarũra, agĩkora nĩ mũndũ-wa-nja wakomete magũrũ-inĩ make.
9 Ó sì béèrè pé, “Ta ni ìwọ í ṣe?” Rutu sì fèsì wí pé, “Èmi ni Rutu, ìránṣẹ́bìnrin rẹ. Da etí aṣọ rẹ bò mí, nítorí pé ìwọ ni ìbátan tí ó le è rà mí padà.”
Akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩwe ũ?” Nake akĩmũcookeria atĩrĩ, “Nĩ niĩ ndungata yaku Ruthu. Tambũrũkia gĩcurĩ kĩa nguo yaku ũũhumbĩre, nĩ ũndũ wee nĩwe ũngĩtũmenyerera.”
10 Boasi sì wí fún un pé, “Kí Olúwa bùkún fún ọ, ọmọbìnrin mi. Ìfẹ́ tí o fihàn yí ti pọ̀ ju ti àtẹ̀yìnwá lọ, bí ó ti jẹ́ wí pé ìwọ kò lọ láti wá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin bóyá ọlọ́rọ̀ tàbí tálákà.
Nake akĩmwĩra atĩrĩ, “Jehova arokũrathima mwarĩ wakwa. Ũtugi ũrĩa wonania nĩũkĩrĩte ũrĩa wonanirie kĩambĩrĩria-inĩ, nĩ ũndũ ndũnenda kũrũmanĩrĩra na aanake, marĩ athĩĩni kana marĩ itonga.
11 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ìwọ ọmọbìnrin mi, má bẹ̀rù. Èmi yóò sì ṣe ohun gbogbo tí o béèrè fún ọ. Gbogbo ènìyàn ni ó mọ̀ ọ́n ní obìnrin oníwà rere.
Na rĩrĩ, mwarĩ wakwa, ndũgetigĩre. Nĩngũgwĩkĩra ũrĩa wothe ũkũũhooya. Andũ othe a itũũra rĩĩrĩ riitũ nĩmooĩ atĩ wee ũrĩ mũndũ-wa-nja ngatha.
12 Nítòótọ́ ni mo wí pé èmi jẹ́ ìbátan tí ó súnmọ́ ọ, ṣùgbọ́n ìbátan kan wà tí ó súnmọ́ ọ ju ti tèmi lọ.
O na gũtuĩka ndĩ ũmwe wa arĩa mangĩkũmenyerera-rĩ, nĩ harĩ mũndũ ũngĩ ũngĩkũmenyerera wa hakuhĩ kũngĩra.
13 Dúró síbí títí ilẹ̀ yóò fi mọ́, bí ó bá sì di òwúrọ̀ tí ọkùnrin náà sì ṣe tan láti ṣe ìràpadà, ó dára kí ó ṣe bẹ́ẹ̀, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, bí Olúwa ti ń bẹ láààyè nígbà náà ni èmi yóò ṣe ìràpadà, sùn sí ìhín títí ilẹ̀ yóò fi mọ́.”
Rĩu kĩraare haha ũtukũ ũyũ, na rũciinĩ gwakĩa angĩkorwo nĩekwenda gũkũmenyerera, nĩ wega; nĩagakũmenyerera. No angĩkorwo ndekwenda, o ta ũrĩa Jehova atũũraga muoyo, nĩngakũmenyerera. Kĩraare haha nginya rũciũ rũciinĩ.”
14 Ó sì sùn ní ẹsẹ̀ rẹ̀ títí di òwúrọ̀, ṣùgbọ́n ó dìde ní òwúrọ̀ kùtùkùtù kí ẹnìkínní tó le è dá ẹnìkejì mọ̀. Boasi sì sọ fún un wí pé, “Má ṣe jẹ́ kí ó di mí mọ̀ wí pé obìnrin kan wá sí ilẹ̀ ìpakà.”
Nĩ ũndũ ũcio Ruthu agĩkoma hau magũrũ-inĩ make nginya rũciinĩ, no akĩroka gũũkĩra rũciinĩ tene kũrĩ mairia, nake Boazu akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndũkareke kũmenyeke atĩ nĩ kũrĩ mũndũ-wa-nja ũrokĩte kĩhuhĩro-inĩ.”
15 Ó sì tún wí fún un pé, “Mú aṣọ ìborùn rẹ tí o dà bora, kí o tẹ̀ ẹ sílẹ̀.” Rutu sì ṣe bẹ́ẹ̀, Boasi sì wọn òsùwọ̀n ọkà barle mẹ́fà sí i, ó sì gbé e rù ú. Nígbà náà ni ó padà sí ìlú.
Ningĩ akĩmwĩra atĩrĩ, “Rehe nguo ĩyo wĩigĩrĩire wanĩrĩrie.” Rĩrĩa eekire ũguo, Boazu agĩitĩrĩra ibaba ithathatũ cia cairi, akĩmũigĩrĩra. Nake Ruthu agĩcooka itũũra-inĩ.
16 Nígbà tí Rutu dé ilé Naomi ìyá ọkọ sì bí léèrè pé, “Báwo ni ó ti rí ọmọbìnrin mi?” Nígbà náà ni ó sì sọ gbogbo ohun tí ọkùnrin náà ṣe fún un fún ìyá ọkọ rẹ̀.
Na rĩrĩa Ruthu aacookire kũrĩ nyaciarawe-rĩ, Naomi akĩmũũria atĩrĩ, “Mwarĩ wakwa, kũraathiire atĩa?” Nake akĩmwĩra maũndũ marĩa mothe Boazu aamwĩkĩire.
17 Ó fi kún un wí pé, “Ó sọ fún mi wí pé, ‘Má ṣe padà sí ọ̀dọ̀ ìyá ọkọ rẹ ní ọwọ́ òfo, nítorí náà, ó fún mi ní ìwọ̀n ọkà barle mẹ́fà.’”
Ningĩ agĩcooka akĩmwĩra atĩrĩ, “Ibaba ici ithathatũ cia cairi nĩwe ũũheire, na anjĩĩra atĩrĩ, ‘Tiga kũinũkĩra nyaciaraguo moko matheri.’”
18 Naomi sì wí fún un pé, “Dúró, ọmọbìnrin mi títí tí ìwọ yóò fi mọ bí ohun gbogbo yóò ti rí, nítorí pé ọkùnrin náà kò ní sinmi títí tí ọ̀rọ̀ náà yóò fi yanjú lónìí.”
Nake Naomi akĩmwĩra atĩrĩ, “Eterera o ro ũguo, mwarĩ wakwa, nginya ũmenye ũrĩa ũhoro ũcio ũgũthiĩ, nĩgũkorwo mũndũ ũcio ndangĩhurũka nginya rĩrĩa aniine ũhoro ũcio ũmũthĩ.”

< Ruth 3 >