< Ruth 3 >

1 Ní ọjọ́ kan, Naomi, ìyá ọkọ Rutu wí fún un pé, “Ọmọbìnrin mi, ǹjẹ́ kò yẹ kí èmi bá ọ wá ilé ọkọ mìíràn, níbi tí wọn yóò ti le è máa tọ́jú rẹ?
Forsothe aftir that Ruth turnede ayen to hir modir in lawe, Ruth herde of hir, My douytir, Y schal seke reste to thee, and Y schal purueye that it be wel to thee.
2 Wò ó, Boasi ọkùnrin nì tí ìwọ bá àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ ṣiṣẹ́, tí í ṣe ìbátan wa, yóò wá láti fẹ́ ọkà barle ní ilẹ̀ ìpakà rẹ̀ ní àṣálẹ́ yìí.
This Booz, to whose damesels thou were ioyned in the feeld, is oure kynesman, and in this niyt he wyndewith the corn floor of barli.
3 Wẹ̀, kí o sì fi ìpara olóòórùn dídùn pa ara rẹ, kí o sì wọ aṣọ rẹ tí ó dára jùlọ, kí o sì lọ sí ilẹ̀ ìpakà tí ó gbé ń pa ọkà, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí ó mọ̀ pé o wà níbẹ̀ títí tí yóò fi jẹ tí yóò sì mu tán.
Therfor be thou waischun, and anoyntid, and be thou clothid with onestere clothis, and go doun in to the corn floor; the man, `that is, Booz, se not thee, til he haue endid the mete and drynke.
4 Rí í dájú pé o mọ ibi tí ó sùn sí, lẹ́yìn ìgbà tí ó bá ti sùn, lọ kí o ṣí aṣọ ìbora rẹ̀ níbi ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè kí o sì sùn sí ibi ẹsẹ̀ náà. Òun yóò sì sọ ohun tí ìwọ yóò ṣe fún ọ.”
Forsothe whanne he goth to slepe, marke thou the place `in which he slepith; and thou schalt come and vnhile the cloth, `with which he is hilid, fro the part of the feet, and thou schalt caste thee doun, and thou schalt ly there. Forsothe he schal seie to thee, what thou `owist to do.
5 Rutu sì fèsì pé, “Gbogbo ohun tí ìwọ sọ fún mi ni èmi yóò ṣe.”
Which answeride, What euer thing thou comaundist, Y schal do.
6 Bẹ́ẹ̀ ni Rutu lọ sí ilẹ̀ ìpakà tí ó sì ṣe gbogbo ohun tí ìyá ọkọ rẹ̀ sọ fún un, pé kí o ṣe.
And sche yede doun in to the corn floor, and dide alle thingis whiche hir modir in lawe comaundide to hir.
7 Nígbà tí Boasi parí jíjẹ àti mímu tán, tí ọkàn rẹ̀ sì kún fún ayọ̀. Ó lọ, ó sì dùbúlẹ̀ ní ẹ̀yìn ọkà tí wọ́n kójọ. Rutu yọ́ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́ lọ sí ibẹ̀, ó ṣí aṣọ ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè, ó sì sùn sí ibi ẹsẹ̀ rẹ̀.
And whanne Booz hadde ete and drunke, and was maad gladere, and hadde go to slepe bisidis the `heep of handfuls, sche cam, and hidde hir silf; and whanne the cloth was vnhilid fro `hise feet, sche castide doun hir silf.
8 Ó sì ṣe nígbà tí ọkùnrin náà tají ní àárín òru, ẹ̀rù bà á, ó sì yí ara padà, ó sì ṣàkíyèsí obìnrin kan tí ó sùn sí ibi ẹsẹ̀ rẹ̀.
And lo! now at mydnyyt `the man dredde, and was troblid; and he siy a womman lyggynge at hise feet;
9 Ó sì béèrè pé, “Ta ni ìwọ í ṣe?” Rutu sì fèsì wí pé, “Èmi ni Rutu, ìránṣẹ́bìnrin rẹ. Da etí aṣọ rẹ bò mí, nítorí pé ìwọ ni ìbátan tí ó le è rà mí padà.”
and he seide to hir, Who art thou? Sche answeride, Y am Ruth, thin handmayde; stretche forth thi cloth on thi seruauntesse, for thou art nyy of kyn.
10 Boasi sì wí fún un pé, “Kí Olúwa bùkún fún ọ, ọmọbìnrin mi. Ìfẹ́ tí o fihàn yí ti pọ̀ ju ti àtẹ̀yìnwá lọ, bí ó ti jẹ́ wí pé ìwọ kò lọ láti wá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin bóyá ọlọ́rọ̀ tàbí tálákà.
And he seide, Douytir, thou art blessid of the Lord, and thou hast ouercome the formere mercy with the lattere; for thou `suedist not yonge men, pore ethir riche.
11 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ìwọ ọmọbìnrin mi, má bẹ̀rù. Èmi yóò sì ṣe ohun gbogbo tí o béèrè fún ọ. Gbogbo ènìyàn ni ó mọ̀ ọ́n ní obìnrin oníwà rere.
Therfor `nyle thou drede, but what euer thing thou schalt seie to me, Y schal do to thee; for al the puple that dwellith with ynne the yatis of my cytee woot, that thou art a womman of vertu.
12 Nítòótọ́ ni mo wí pé èmi jẹ́ ìbátan tí ó súnmọ́ ọ, ṣùgbọ́n ìbátan kan wà tí ó súnmọ́ ọ ju ti tèmi lọ.
And Y forsake not, that Y am of nyy kyn, but another man is neer than Y;
13 Dúró síbí títí ilẹ̀ yóò fi mọ́, bí ó bá sì di òwúrọ̀ tí ọkùnrin náà sì ṣe tan láti ṣe ìràpadà, ó dára kí ó ṣe bẹ́ẹ̀, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, bí Olúwa ti ń bẹ láààyè nígbà náà ni èmi yóò ṣe ìràpadà, sùn sí ìhín títí ilẹ̀ yóò fi mọ́.”
reste thou in this nyyt, and whanne the morewtid is maad, if he wole holde thee bi riyt of nyy kyn, the thing is wel doon; forsothe if he nyle, Y schal take thee with outen ony doute, the Lord lyueth, `that is, bi the Lord lyuynge; slepe thou til the morewtid.
14 Ó sì sùn ní ẹsẹ̀ rẹ̀ títí di òwúrọ̀, ṣùgbọ́n ó dìde ní òwúrọ̀ kùtùkùtù kí ẹnìkínní tó le è dá ẹnìkejì mọ̀. Boasi sì sọ fún un wí pé, “Má ṣe jẹ́ kí ó di mí mọ̀ wí pé obìnrin kan wá sí ilẹ̀ ìpakà.”
Therfore sche slepte at `hise feet til to the goyng awey of nyyt, and so sche roos bifor that men knewen `hem silf togidere. And Booz seide to hir, Be thou war lest ony man knowe, that thou camest hidir.
15 Ó sì tún wí fún un pé, “Mú aṣọ ìborùn rẹ tí o dà bora, kí o tẹ̀ ẹ sílẹ̀.” Rutu sì ṣe bẹ́ẹ̀, Boasi sì wọn òsùwọ̀n ọkà barle mẹ́fà sí i, ó sì gbé e rù ú. Nígbà náà ni ó padà sí ìlú.
And eft he seide, Stretche forth thi mentil `with which thou `art hilid, and holde thou with euer either hond. And while sche stretchide forth and helde, he mete sixe buyschels of barly, and `puttide on hir; and sche bar, and entride in to the citee,
16 Nígbà tí Rutu dé ilé Naomi ìyá ọkọ sì bí léèrè pé, “Báwo ni ó ti rí ọmọbìnrin mi?” Nígbà náà ni ó sì sọ gbogbo ohun tí ọkùnrin náà ṣe fún un fún ìyá ọkọ rẹ̀.
and cam to hir modir in lawe. Which seide to Ruth, What hast thou do, douyter? And Ruth telde to hir alle thingis, whyche `the man hadde do to hir.
17 Ó fi kún un wí pé, “Ó sọ fún mi wí pé, ‘Má ṣe padà sí ọ̀dọ̀ ìyá ọkọ rẹ ní ọwọ́ òfo, nítorí náà, ó fún mi ní ìwọ̀n ọkà barle mẹ́fà.’”
And Ruth seide, Lo! he yaf to me sixe buyschels of barly; and he seide, Y nyle that thou turne ayen voide to thi modir in lawe.
18 Naomi sì wí fún un pé, “Dúró, ọmọbìnrin mi títí tí ìwọ yóò fi mọ bí ohun gbogbo yóò ti rí, nítorí pé ọkùnrin náà kò ní sinmi títí tí ọ̀rọ̀ náà yóò fi yanjú lónìí.”
And Noemy seide, Abide, douytir, til we sien what issu the thing schal haue; for the man schal not ceesse, no but he fille tho thingis whiche he spak.

< Ruth 3 >