< Ruth 2 >

1 Naomi ní ìbátan kan láti ìdílé Elimeleki ọkọ rẹ̀, aláàánú ọlọ́rọ̀, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Boasi.
Vala pedig Naóminak egy rokona az ő férje után, előkelő derék ember Elimélek nemzetségéből; neve Boáz.
2 Rutu ará Moabu sì wí fún Naomi pé, “Jẹ́ kí èmi kí ó lọ sí inú oko láti ṣá ọkà tí àwọn olùkórè fi sílẹ̀ ní ọ̀dọ̀ ẹnikẹ́ni tí èmi yóò bá ojúrere rẹ̀ pàdé.” Naomi sì sọ fún un pé, “Máa lọ, ọmọbìnrin mi.”
És monda a Moábita Ruth Naóminak: Hadd menjek, kérlek, a mezőre, hogy kalászokat szedegessek az után, a kinek szemei előtt kedvességet találok. És az monda: Menj édes leányom.
3 Rutu sì jáde lọ láti ṣá ọkà tí àwọn olùkórè fi sílẹ̀ lẹ́yìn wọn. Ó wá jẹ́ wí pé inú oko Boasi tí ó ti ìdílé Elimeleki wá ni ó lọ láìmọ̀-ọ́n-mọ̀.
Elméne azért és odaérkezék, szedegete a mezőn az aratók után, és történetesen oda talált a Boáz szántóföldjére, a ki Elimélek nemzetségéből való volt.
4 Nígbà náà ni Boasi dé láti Bẹtilẹhẹmu tí ó sì kí àwọn olùkórè wí pé, “Kí Olúwa wà pẹ̀lú yín.” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Kí Olúwa bùkún fún ọ.”
És ímé Boáz kijöve Bethlehemből, és monda az aratóknak: Az Úr legyen veletek! És ők mondának néki: Áldjon meg téged az Úr!
5 Boasi sì béèrè lọ́wọ́ olórí àwọn olùkórè wí pé, “Ti ta ni ọ̀dọ́mọbìnrin yẹn?”
És monda Boáz az ő szolgájának, a ki az aratók felügyelője volt: Kié ez a leányzó?
6 Ìránṣẹ́ tí ó jẹ́ olórí àwọn olùkórè náà sì fèsì pé, “Ọ̀dọ́mọbìnrin ará Moabu tí ó tẹ̀lé Naomi wá láti ilẹ̀ Moabu ni.
És felele a szolga, az aratók felügyelője, és monda: Az a Moábita leányzó ez, a ki Naómival jött a Moáb mezejéről.
7 Ó sọ wí pé, ‘Kí ń jọ̀wọ́ jẹ́ kí òun máa ṣá ọkà lẹ́yìn àwọn olùkórè.’ Ó sì ti ń ṣe iṣẹ́ kárakára láti òwúrọ̀ títí di ìsinsin yìí nínú oko àyàfi ìgbà tí ó lọ láti sinmi fún ìgbà díẹ̀ lábẹ́ ibojì.”
A ki mondá: Hadd szedegessek, kérlek, és hadd tarlózgassak a kévék közt az aratók után. És ide jöve, és itt marada reggeltől fogva mind mostanig: és csak épen most pihent egy keveset a házban.
8 Nígbà náà ni Boasi sọ fún Rutu pé, “Gbọ́ ọmọbìnrin mi, má ṣe lọ sí oko mìíràn láti ṣá ọkà, má sì ṣe kúrò ní ibi. Dúró níbí pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́bìnrin mi.
És mondá Boáz Ruthnak: Ugyan hallod-é édes leányom! Ne menj szedegetni más mezőre és el ne menj innen; hanem menj mindenütt szolgálóim után.
9 Wo ibi tí wọ́n ti ń kórè kí o sì máa tẹ̀lé àwọn obìnrin. Mo ti pàṣẹ fún àwọn ọkùnrin kí wọ́n má ṣe fi ọwọ́ kàn ọ́. Nígbàkígbà tí òǹgbẹ bá sì ń gbẹ ọ́, lọ kí ó sì mu omi nínú àmù èyí tí àwọn ọkùnrin ti pọn omi sí nínú.”
Szemeid legyenek a mezőn, a melyet aratnak, és járj utánok. Ímé meghagytam a szolgáknak, hogy ne bántsanak téged, és ha megszomjúhozol, menj az edényekhez és igyál abból, a mit a szolgák merítenek.
10 Rutu wólẹ̀, ó sì wí fún Boasi pé, “Èéṣe tí èmi fi bá ojúrere rẹ pàdé tó báyìí, tí o sì kíyèsi mi, èmi àjèjì àti àlejò?”
Akkor ez arczra borula és meghajtá magát a földig, és monda néki: Hogy-hogy találtam ilyen kedvességet a te szemeid előtt, hogy rám tekintettél, holott én idegen vagyok?
11 Boasi sì fèsì wí pé, “Èmi ti gbọ́ gbogbo bí o ti ń ṣe sí ìyá ọkọ ọ̀ rẹ láti ìgbà tí ọkọ rẹ ti kú àti bí o ti ṣe fi baba àti ìyá rẹ àti ilẹ̀ rẹ sílẹ̀, tí o sì wá láti gbé láàrín àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ̀ tẹ́lẹ̀ rí.
Boáz pedig felele, és monda néki: Bizony elmondtak nékem mindent, amit cselekedtél a te napaddal, férjed halála után, hogy elhagytad a te atyádat és a te anyádat és a te születésednek földét, és jöttél ahhoz a néphez, a melyet nem ismertél azelőtt.
12 Kí Olúwa kí ó san ẹ̀san ohun tí ìwọ ṣe fún ọ. Kí o sì gba èrè kíkún láti ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, abẹ́ ìyẹ́ ẹni tí ìwọ sá wá fún ààbò.”
Fizessen meg az Úr a te cselekedetedért, és legyen teljes a te jutalmad az Úrtól, Izráelnek Istenétől, a kinek szárnyai alatt oltalmat keresni jöttél.
13 Rutu sì fèsì wí pé, “Kí èmi kí ó máa rí ojúrere láti ọ̀dọ̀ rẹ síwájú sí i olúwa mi. Ìwọ ti tù mí nínú nípa sísọ ọ̀rọ̀ rere sí ìránṣẹ́bìnrin rẹ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò tó ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ.”
Ez pedig monda: Találjak kedvességet a te szemeid előtt uram, mert megvigasztaltál engem, és mert a te szolgálódnak szívéhez szóltál, holott én nem vagyok a te szolgálóleányaid közül.
14 Nígbà tí àkókò oúnjẹ sì tó, Boasi sọ fún Rutu pé, “Wá gba ìwọ̀n àkàrà yìí kí o sì fi run wáìnì kíkan.” Òun sì jókòó pẹ̀lú àwọn olùkórè, Boasi sì fún un ní ọkà yíyan. Òun sì jẹ́, ó yó, ó sì tún ṣẹ́kù.
És az evésnek idejekor szóla néki Boáz: Jer ide, és egyél a kenyérből, és mártsd be a te falatodat az eczetes lébe. És ő leüle az aratók mellé. És pergelt gabonát nyújtott néki, és evett, s jóllakott, sőt még hagyott is.
15 Nígbà tí ó sì dìde láti máa ṣá ọkà, Boasi pàṣẹ fún àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀ wí pé, “Bí ó tilẹ̀ ń ṣà láàrín oko ọkà pàápàá, ẹ má ṣe dí i lọ́wọ́.
Azután felállott, hogy szedegessen és Boáz megparancsolta az ő szolgáinak, mondván: A kévék között is hadd szedegessen, és meg ne pirongassátok őt.
16 Bí kò ṣe pé kí ẹ mú lára àwọn ìtí sílẹ̀ fún láti ṣá, kí ẹ má sì ṣe ba a wí.”
Sőt húzogassatok ki néki a kévékből is, és hagyogassatok el, hogy szedje fel, és meg ne dorgáljátok őt.
17 Rutu sì ń ṣá ọkà títí ó fi di ìrọ̀lẹ́, nígbà tí ó sì pa ọkà barle tí ó rí ṣà, tí ó sì fẹ́ ẹ tán, èyí tí ó rí sì tó ìwọ̀n garawa kan (lita méjìlélógún).
És ő szedegete a mezőn mind estiglen, és kicsépelé, a mit szedegetett, és lett abból szinte egy efa árpa.
18 Ó sì gbé e, ó sì lọ sí ìlú, ìyá ọkọ rẹ sì rí ọkà tí ó rí ṣà bi o tí pọ̀ tó, Rutu sì mú oúnjẹ tí ó jẹ kù lẹ́yìn tí ó ti yó tan fún ìyá ọkọ rẹ̀.
És felvevé és beméne a városba, és napaasszonya látá, a mit ő szedegetett. Aztán elővevé és odaadá néki, a mit meghagyott, minekutána jóllakott vala.
19 Ìyá ọkọ rẹ̀ sì bi í léèrè wí pé, “Níbo ni ìwọ ti ṣá ọkà lónìí? Àti wí pé oko ta ni ìwọ gbé ṣiṣẹ́? Alábùkún fún ni ọkùnrin náà tí ó bojú wò ọ.” Rutu sì sọ ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ti ṣiṣẹ́ fún ìyá ọkọ rẹ̀ pé, “Ní oko ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Boasi ni mo ti ṣiṣẹ́ lónìí.”
És monda néki az ő napaasszonya: Hol szedegettél ma, és hol munkálkodtál? Áldott legyen, a ki rád tekintett. És elbeszélte az ő napaasszonyának, hogy kinél munkálkodott, és monda: Annak a férfiúnak a neve, a kinél ma munkálkodtam: Boáz.
20 Naomi sì wí fún un pé, “Kí Olúwa, kí ó bùkún fún ọkùnrin náà. Ọlọ́run kò dáwọ́ oore àti àánú ṣíṣe sí àwọn alààyè àti òkú dúró.” Naomi sì sọ síwájú sí i wí pé, “Ìbátan tí ó súnmọ́ wa pẹ́kípẹ́kí ni ọkùnrin náà ń ṣe, ó sì jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti ra ohun ìní ìdílé padà.”
És monda Naómi az ő menyének: Áldott legyen ő az Úrtól, a ki nem vonta meg irgalmasságát az élőktől és a megholtaktól! És Naómi monda néki: Közel valónk nékünk az a férfiú; legközelebbi rokonaink közül való ő.
21 Rutu, ará Moabu sì wí pé, “Ju gbogbo rẹ̀ lọ, ó sọ fún mi pé, ‘Kí ń máa ṣá ọkà pẹ̀lú àwọn òṣìṣẹ́ òun, títí wọn yóò fi parí ìkórè.’”
És szóla a Moábita Ruth: Még azt is mondta ő nékem: Menj mindenütt az én munkásaim után, a míg csak el nem végzik az én egész aratásomat.
22 Naomi sì sọ fún Rutu, ìyàwó ọmọ rẹ̀ pé, “Ìbá dára bí ó bá le bá àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ ṣiṣẹ́. Nítorí pé wọ́n le è dà ọ́ láàmú bí o bá lọ sí oko ẹlòmíràn.”
És monda Naómi Ruthnak, az ő menyének: Jó, édes leányom, hogy az ő szolgálóival jársz, ne is találjanak téged más mezőn.
23 Rutu sì bá àwọn ìránṣẹ́bìnrin Boasi ṣiṣẹ́ títí tí wọ́n fi parí ìkórè ọkà barle àti ti jéró. Ó sì ń gbé pẹ̀lú ìyá ọkọ rẹ̀.
Így járt ő mindenütt a Boáz szolgálói után, szedegetve, míg az árpaaratás és búzaaratás bevégződött; és az ő napaasszonyával lakott.

< Ruth 2 >