< Ruth 1 >
1 Ní ìgbà tí àwọn onídàájọ́ ń ṣe àkóso ilẹ̀ Israẹli, ìyàn kan mú ní ilẹ̀ náà, ọkùnrin kan láti Bẹtilẹhẹmu ti Juda, òun àti aya rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjì lọ láti máa gbé ní ilẹ̀ Moabu fún ìgbà díẹ̀.
I сталось за ча́су, коли судді судили, то був голод у Краю́. І пішов був чоловік з Юдиного Віфлеєму мешкати в моавських поля́х, він і жінка та двоє синів його.
2 Orúkọ ọkùnrin náà ń jẹ́ Elimeleki, orúkọ ìyàwó rẹ̀ ni Naomi, orúkọ àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì sì ni Maloni àti Kilioni àwọn ará Efrata, ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda. Wọ́n sì lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọ́n ń gbé níbẹ̀.
А ім'я́ тому чоловікові Елімеле́х, а ім'я́ жінці його Ноомі́; і ім'я́ двох синів його — Махлон і Кілйон, ефратяни з Віфлеєму Юдиного. І прийшли вони на моавські поля́, та й залишилися.
3 Ní àsìkò tí wọ́n ń gbé ibẹ̀, Elimeleki, ọkọ Naomi kú, ó sì ku òun pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì.
І помер Елімелех, муж Ноомі́, і зоста́лася вона та два їхні си́ни.
4 Wọ́n sì fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ará Moabu méjì, orúkọ ọ̀kan ń jẹ́ Oripa, èkejì sì ń jẹ́ Rutu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti gbé níbẹ̀ fún bí ọdún mẹ́wàá,
І взяли вони собі за жіно́к моаві́тянок, — ім'я́ одній Орпа́, а ім'я другій Рут. І сиділи вони там близько десяти літ.
5 Maloni àti Kilioni náà sì kú, Naomi sì wà láìsí ọkọ tàbí ọmọ kankan fún un mọ́.
І повмирали й вони обоє, Махлон та Кілйон. І позосталася та жінка по двох ді́тях своїх та по чоловікові своєму.
6 Nígbà tí Naomi gbọ́ ní Moabu tí ó wà wí pé Olúwa ti bẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ wò nípa fífún wọn ní ọ̀pọ̀ oúnjẹ. Ó sì dìde pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì láti padà sí ìlú rẹ̀.
І встала вона та невістки її, і вернулися з моавських піль, бо почула на моавському полі, що Госпо́дь згадав про наро́д Свій, даючи їм хліба.
7 Òun pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì ni wọ́n jọ fi ibi tí ó ń gbé sílẹ̀ tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà sí ilẹ̀ Juda.
І вийшла вона з того місця, де була́ там, та оби́дві невістки з нею, та й пішли дорогою, щоб вернутися до Юдиного кра́ю.
8 Ṣùgbọ́n ní ojú ọ̀nà, Naomi wí fún àwọn aya ọmọ rẹ̀ méjèèjì pé, “Kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín padà sí ilé ìyá rẹ̀. Kí Olúwa ṣe àánú fún yín bí ẹ ti ṣe sí èmi àti àwọn ọkọ yín tí ó kú.
І сказала Ноомі́ до двох своїх невісток: „Ідіть, верніться кожна до дому своєї матері. І нехай Господь зробить із вами милість, як ви зробили з померлими та зо мною.
9 Kí Olúwa kí ó fi yín lọ́kàn balẹ̀ ní ilé ọkọ mìíràn.” Naomi sì fi ẹnu kò wọ́n ní ẹnu wí pé “Ó dìgbà,” wọ́n sì sọkún kíkankíkan.
Нехай Господь дасть вам, — і ви зна́йдете відпочинок кожна в домі свого мужа!“І вона поцілувала їх, а вони підняли́ свій голос та плакали.
10 Wọ́n sì wí fún un pé, “Rárá, a ó bà ọ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.”
І вони сказали до неї: „ Ні, — з тобою ми ве́рнемось до народу твого!“
11 Ṣùgbọ́n Naomi dáhùn wí pé, “Ẹ padà sílé ẹ̀yin ọmọ mi. Nítorí kí ni ẹ fi fẹ́ wá pẹ̀lú mi? Ṣé mo tún le bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn ni, tí ó le ṣe ọkọ yin?
А Ноомі́ сказала: „Вертайтеся, до́чки мої, — чого ви пі́дете зо мною? Чи я маю ще в утро́бі своїй синів, а вони стануть вам за чоловіків?
12 Ẹ padà sílé, ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí èmi ti di arúgbó jù láti ní ọkọ mìíràn. Bí èmí wí pé, èmí ní ìrètí, bí èmí tilẹ̀ ní ọkọ mìíràn ní alẹ́ yìí, tí èmí sì bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn,
Верніться, до́чки мої, ідіть, бо я занадто стара́, щоб бути для мужа. А коли б я й сказала: Маю надію, і коли б цієї ночі була з мужем, і також породила синів, —
13 ẹ̀yin ha le è dúró dìgbà tí wọ́n yóò fi dàgbà? Ẹ̀yin ó le è dúró dè wọ́n láì fẹ́ ọkọ mìíràn? Rárá, ẹ̀yin ọmọbìnrin mi, nítorí pé inú mi bàjẹ́ gidigidi ju tiyín lọ, nítorí tí ọwọ́ Olúwa fi jáde sí mi!”
чи ж ви чекали б їх, аж поки повироста́ють? Чи ж ви зв'язалися б з ними, щоб не бути замужем? Ні, до́чки мої, бо мені значно гірше, як вам, — бо Господня рука знайшла мене“.
14 Wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì tún sọkún. Nígbà náà ní Oripa fi ẹnu ko ìyá ọkọ rẹ̀ ní ẹnu wí pé ó dìgbà, ṣùgbọ́n Rutu dì mọ́ ọn síbẹ̀.
І підняли́ вони голос свій, і заплакали ще. І поцілувала Орпа свою свекру́ху, а Рут пригорну́лася до неї.
15 Naomi wí pé, “Wò ó, arábìnrin rẹ ti padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀ àti òrìṣà rẹ̀, ìwọ náà padà pẹ̀lú rẹ̀.”
І сказала Ноомі: „Ось зови́ця твоя вернулася до наро́ду свого та до богів своїх, — вернися й ти за зови́цею своєю!“
16 Ṣùgbọ́n Rutu dáhùn wí pé, “Má ṣe rọ̀ mí láti fi ọ́ sílẹ̀ tàbí láti padà lẹ́yìn rẹ. Ibi tí ìwọ bá lọ ní èmi yóò lọ, ibi ti ìwọ bá dúró ni èmi yóò dúró, àwọn ènìyàn rẹ ni yóò jẹ́ ènìyàn mi, Ọlọ́run rẹ ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run mi.
А Рут відказала: „Не силуй мене, щоб я покинула тебе, щоб я вернулася від тебе, бо куди пі́деш ти, туди піду́ й я, а де житимеш ти, там житиму й я. Наро́д твій буде мій народ, а Бог твій — мій Бог.
17 Níbi tí ìwọ bá kú sí ni èmi yóò kú sí, níbẹ̀ ni wọn yóò sì sin mí sí. Kí Olúwa jẹ mí ní ìyà tí ó lágbára, bí ohunkóhun bí kò ṣe ikú bá yà wá.”
Де помреш ти, там помру й я, і там буду похована. Нехай Господь зробить мені так, і так нехай додасть, і тільки смерть розлучить мене з тобою“.
18 Nígbà tí Naomi rí i wí pé Rutu ti pinnu láti tẹ̀lé òun kò rọ̀ láti padà mọ́.
І побачила Ноомі́, що вона настоює йти за нею, і перестала вговорювати її.
19 Àwọn méjèèjì sì ń lọ títí wọ́n fi dé ìlú Bẹtilẹhẹmu. Nígbà tí wọ́n dé ibẹ̀, ariwo ìpadàbọ̀ wọn gba ìlú kan, àwọn obìnrin ibẹ̀ sì kígbe ní ohùn rara wí pé, “Naomi ni èyí bí?”
І пішли вони вдвох, аж прийшли до Віфлеєму. І сталося, коли вони вхо́дили до Віфлеєму, то зашуміло все місто про них, і говорили: „Чи це Ноомі́?“
20 Naomi sì dáhùn wí pé, “Ẹ má ṣe pè mí ní Naomi mọ́, ẹ pè mí ní Mara, nítorí wí pé Olódùmarè ti mú kí ayé mi di kíkorò.
А вона сказала їм: „Не кличте мене: Ноомі́, — кличте мене: Мара́, бо велику гірко́ту зробив мені Всемогу́тній.
21 Mo jáde ní kíkún, ṣùgbọ́n Olúwa mú mi padà ní òfo. Nítorí náà kín ló dé tí ẹ fi ń pè mí ní Naomi, nígbà tí Olódùmarè ti kọ̀ mí sílẹ̀, tí ó sì mú ìdààmú bá mi?”
Я замо́жною пішла була, та порожньою вернув мене Господь. Чого кличете мене: Ноомі́, коли Господь свідчив проти мене, а Всемогутній послав мені горе?“
22 Báyìí ni Naomi ṣe padà láti Moabu pẹ̀lú Rutu, ará Moabu ìyàwó ọmọ rẹ̀. Wọ́n gúnlẹ̀ sí Bẹtilẹhẹmu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè ọkà barle.
І вернулася Ноомі́ та з нею моавітянка Рут, невістка її, що верталася з моавських піль. І прийшли вони до Віфлеєму на початку жнив ячме́ню.