< Ruth 1 >

1 Ní ìgbà tí àwọn onídàájọ́ ń ṣe àkóso ilẹ̀ Israẹli, ìyàn kan mú ní ilẹ̀ náà, ọkùnrin kan láti Bẹtilẹhẹmu ti Juda, òun àti aya rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjì lọ láti máa gbé ní ilẹ̀ Moabu fún ìgbà díẹ̀.
I stało się za onych czasów, kiedy sędziowie sądzili, był głód w ziemi; i poszedł niektóry mąż z Betlehem Juda na mieszkanie do ziemi Moabskiej z żoną swoją i z dwoma synami swymi.
2 Orúkọ ọkùnrin náà ń jẹ́ Elimeleki, orúkọ ìyàwó rẹ̀ ni Naomi, orúkọ àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì sì ni Maloni àti Kilioni àwọn ará Efrata, ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda. Wọ́n sì lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọ́n ń gbé níbẹ̀.
A imię męża onego było Elimelech, imię też żony jego Noemi, także imiona dwóch synów jego Mahalon i Chelijon, a ci byli Efratejczykami z Betlehem Juda, którzy zaszedłszy do krainy Moabskiej, mieszkali tam.
3 Ní àsìkò tí wọ́n ń gbé ibẹ̀, Elimeleki, ọkọ Naomi kú, ó sì ku òun pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì.
Potem umarł Elimelech, mąż Noemi, a ona pozostała z dwoma synami swoimi.
4 Wọ́n sì fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ará Moabu méjì, orúkọ ọ̀kan ń jẹ́ Oripa, èkejì sì ń jẹ́ Rutu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti gbé níbẹ̀ fún bí ọdún mẹ́wàá,
I pojęli sobie żony Moabskie; imię jednej Orfa, a drugiej imię Rut; i mieszkali tam około dziesięciu lat.
5 Maloni àti Kilioni náà sì kú, Naomi sì wà láìsí ọkọ tàbí ọmọ kankan fún un mọ́.
Umarli potem i oni oba, Mahalon i Chelijon; i tak ona niewiasta osierociała po obu synach swoich i po mężu swoim.
6 Nígbà tí Naomi gbọ́ ní Moabu tí ó wà wí pé Olúwa ti bẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ wò nípa fífún wọn ní ọ̀pọ̀ oúnjẹ. Ó sì dìde pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì láti padà sí ìlú rẹ̀.
A wezbrawszy się z synowemi swemi wróciła się z ziemi Moabskiej; bo słyszała w krainie Moabskiej, że był nawiedził Pan lud swój, i dał im chleb.
7 Òun pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì ni wọ́n jọ fi ibi tí ó ń gbé sílẹ̀ tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà sí ilẹ̀ Juda.
Tedy wyszła z miejsca, na którem była z onemi dwiema synowemi swemi, a udały się w drogę, aby się wróciły do ziemi Juda.
8 Ṣùgbọ́n ní ojú ọ̀nà, Naomi wí fún àwọn aya ọmọ rẹ̀ méjèèjì pé, “Kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín padà sí ilé ìyá rẹ̀. Kí Olúwa ṣe àánú fún yín bí ẹ ti ṣe sí èmi àti àwọn ọkọ yín tí ó kú.
Zatem rzekła Noemi do dwóch synowych swych: Idźcież, wróćcie się każda do domu matki twojej; niechaj uczyni Pan z wami miłosierdzie, jakoście uczyniły z umarłymi synami moimi i ze mną.
9 Kí Olúwa kí ó fi yín lọ́kàn balẹ̀ ní ilé ọkọ mìíràn.” Naomi sì fi ẹnu kò wọ́n ní ẹnu wí pé “Ó dìgbà,” wọ́n sì sọkún kíkankíkan.
Niech wam da Pan znaleźć odpocznienie, każdej w domu męża swego; i pocałowała je, a one podniósłszy głos swój, płakały,
10 Wọ́n sì wí fún un pé, “Rárá, a ó bà ọ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.”
I mówiły do niej: Raczej się z tobą wrócimy do ludu twojego.
11 Ṣùgbọ́n Naomi dáhùn wí pé, “Ẹ padà sílé ẹ̀yin ọmọ mi. Nítorí kí ni ẹ fi fẹ́ wá pẹ̀lú mi? Ṣé mo tún le bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn ni, tí ó le ṣe ọkọ yin?
A Noemi rzekła: Wróćcież się córki moje; przeczżebyście ze mną iść miały? Azaż ja jeszcze mogę mieć syny, którzyby byli mężami waszymi?
12 Ẹ padà sílé, ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí èmi ti di arúgbó jù láti ní ọkọ mìíràn. Bí èmí wí pé, èmí ní ìrètí, bí èmí tilẹ̀ ní ọkọ mìíràn ní alẹ́ yìí, tí èmí sì bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn,
Wróćcież się córki moje, a idźcie, bom się już zstarzała, a nie mogę iść za mąż. Choćbym też rzekła, jeszcze mam nadzieję, albo choćbym też dobrze tej nocy była za mężem choćbym też nawet i porodziła syny;
13 ẹ̀yin ha le è dúró dìgbà tí wọ́n yóò fi dàgbà? Ẹ̀yin ó le è dúró dè wọ́n láì fẹ́ ọkọ mìíràn? Rárá, ẹ̀yin ọmọbìnrin mi, nítorí pé inú mi bàjẹ́ gidigidi ju tiyín lọ, nítorí tí ọwọ́ Olúwa fi jáde sí mi!”
Izali wy ich czekać będziecie, ażby dorośli? zaż się dla tego zatrzymacie, abyście nie szły za mąż? Nie tak córki moje; bo żałość moja większa jest niźli wasza, gdyż się obróciła przeciwko mnie ręka Pańska.
14 Wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì tún sọkún. Nígbà náà ní Oripa fi ẹnu ko ìyá ọkọ rẹ̀ ní ẹnu wí pé ó dìgbà, ṣùgbọ́n Rutu dì mọ́ ọn síbẹ̀.
Ale one podniósłszy głos swój, znowu płakały. I pocałowała Orfa świekrę swoję; a Ruta została przy niej.
15 Naomi wí pé, “Wò ó, arábìnrin rẹ ti padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀ àti òrìṣà rẹ̀, ìwọ náà padà pẹ̀lú rẹ̀.”
Do której Noemi rzekła: Oto się wróciła powinna twoja do ludu swego, i do bogów swoich, wróćże się i ty za powinną swoją.
16 Ṣùgbọ́n Rutu dáhùn wí pé, “Má ṣe rọ̀ mí láti fi ọ́ sílẹ̀ tàbí láti padà lẹ́yìn rẹ. Ibi tí ìwọ bá lọ ní èmi yóò lọ, ibi ti ìwọ bá dúró ni èmi yóò dúró, àwọn ènìyàn rẹ ni yóò jẹ́ ènìyàn mi, Ọlọ́run rẹ ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run mi.
Na co jej odpowiedziała Ruta: Nie wiedź mię do tego, abym cię opuścić i od ciebie odejść miała; owszem gdziekolwiek pójdziesz, z tobą pójdę, a gdziekolwiek mieszkać będziesz, z tobą mieszkać będę; lud twój lud mój, a Bóg twój Bóg mój.
17 Níbi tí ìwọ bá kú sí ni èmi yóò kú sí, níbẹ̀ ni wọn yóò sì sin mí sí. Kí Olúwa jẹ mí ní ìyà tí ó lágbára, bí ohunkóhun bí kò ṣe ikú bá yà wá.”
Gdzie umrzesz, tam i ja umrę, i tam pogrzebiona będę. To mi niech uczyni Pan, i to niech przepuści na mię, że tylko śmierć rozłączy mię z tobą.
18 Nígbà tí Naomi rí i wí pé Rutu ti pinnu láti tẹ̀lé òun kò rọ̀ láti padà mọ́.
A tak ona widząc, że się na to uparła, aby z nią szła, przestała jej odradzać.
19 Àwọn méjèèjì sì ń lọ títí wọ́n fi dé ìlú Bẹtilẹhẹmu. Nígbà tí wọ́n dé ibẹ̀, ariwo ìpadàbọ̀ wọn gba ìlú kan, àwọn obìnrin ibẹ̀ sì kígbe ní ohùn rara wí pé, “Naomi ni èyí bí?”
I szły obie pospołu, aż przyszły do Betlehem. I stało się, gdy przyszły do Betlehem, wzruszyło się wszystko miasto dla nich, mówiąc: Izaż nie ta jest Noemi?
20 Naomi sì dáhùn wí pé, “Ẹ má ṣe pè mí ní Naomi mọ́, ẹ pè mí ní Mara, nítorí wí pé Olódùmarè ti mú kí ayé mi di kíkorò.
Ale ona mówiła do nich: Nie nazywajcie mię Noemi, ale mię zowcie Mara; albowiem mię gorzkościę wielką Wszechmogący napełnił.
21 Mo jáde ní kíkún, ṣùgbọ́n Olúwa mú mi padà ní òfo. Nítorí náà kín ló dé tí ẹ fi ń pè mí ní Naomi, nígbà tí Olódùmarè ti kọ̀ mí sílẹ̀, tí ó sì mú ìdààmú bá mi?”
Wyszłam stąd obfitą a próżną mię przywrócił Pan. Przeczże mię tedy zowiecie Noemi, gdyż mię Pan utrapił, a Wszechmogący złe na mię dopuścił?
22 Báyìí ni Naomi ṣe padà láti Moabu pẹ̀lú Rutu, ará Moabu ìyàwó ọmọ rẹ̀. Wọ́n gúnlẹ̀ sí Bẹtilẹhẹmu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè ọkà barle.
A tak wróciła się Noemi i Rut Moabitka, synowa jej, z nią; wróciła się z krainy Moabskiej, i przyszły do Betlehem na początku żniwa jęczmiennego.

< Ruth 1 >