< Ruth 1 >

1 Ní ìgbà tí àwọn onídàájọ́ ń ṣe àkóso ilẹ̀ Israẹli, ìyàn kan mú ní ilẹ̀ náà, ọkùnrin kan láti Bẹtilẹhẹmu ti Juda, òun àti aya rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjì lọ láti máa gbé ní ilẹ̀ Moabu fún ìgbà díẹ̀.
És lőn azon napokban, a mikor a bírák bíráskodának, éhség lőn a földön. És elméne egy férfi a Júda Bethleheméből, hogy Moáb mezején tartózkodjék; ő meg a felesége, és a két fia.
2 Orúkọ ọkùnrin náà ń jẹ́ Elimeleki, orúkọ ìyàwó rẹ̀ ni Naomi, orúkọ àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì sì ni Maloni àti Kilioni àwọn ará Efrata, ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda. Wọ́n sì lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọ́n ń gbé níbẹ̀.
A férfi neve Elimélek és felesége neve Naómi; két fiok neve pedig Mahlon és Kiljon; efrataiak, a Júda Bethleheméből valók. És eljutának Moáb mezejére, és ott valának.
3 Ní àsìkò tí wọ́n ń gbé ibẹ̀, Elimeleki, ọkọ Naomi kú, ó sì ku òun pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì.
Meghala pedig Elimélek a Naómi férje, és marada ő és az ő két fia.
4 Wọ́n sì fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ará Moabu méjì, orúkọ ọ̀kan ń jẹ́ Oripa, èkejì sì ń jẹ́ Rutu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti gbé níbẹ̀ fún bí ọdún mẹ́wàá,
A kik Moábita leányokat vőnek feleségül; az egyiknek neve Orpa, és a másiknak neve Ruth. És ott lakozának közel tíz esztendeig.
5 Maloni àti Kilioni náà sì kú, Naomi sì wà láìsí ọkọ tàbí ọmọ kankan fún un mọ́.
Meghalának ők is mind a ketten, Mahlon is, Kiljon is, és marada az asszony az ő két fia és férje nélkül.
6 Nígbà tí Naomi gbọ́ ní Moabu tí ó wà wí pé Olúwa ti bẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ wò nípa fífún wọn ní ọ̀pọ̀ oúnjẹ. Ó sì dìde pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì láti padà sí ìlú rẹ̀.
Felkele azért ő és az ő menyei, és ő visszatére Moáb mezejéről; mert hallotta vala Moáb mezején, hogy meglátogatta az Úr az ő népét, hogy adjon nékik kenyeret.
7 Òun pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì ni wọ́n jọ fi ibi tí ó ń gbé sílẹ̀ tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà sí ilẹ̀ Juda.
És kiméne arról a helyről, a hol volt, és vele a két menye. És menének az úton, hogy visszatérjenek Júda földére,
8 Ṣùgbọ́n ní ojú ọ̀nà, Naomi wí fún àwọn aya ọmọ rẹ̀ méjèèjì pé, “Kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín padà sí ilé ìyá rẹ̀. Kí Olúwa ṣe àánú fún yín bí ẹ ti ṣe sí èmi àti àwọn ọkọ yín tí ó kú.
És monda Naómi az ő két menyének: Menjetek, térjetek vissza, kiki az ő anyjának házához. Cselekedjék az Úr irgalmasságot veletek, a miképen ti cselekedtetek a megholtakkal és én velem!
9 Kí Olúwa kí ó fi yín lọ́kàn balẹ̀ ní ilé ọkọ mìíràn.” Naomi sì fi ẹnu kò wọ́n ní ẹnu wí pé “Ó dìgbà,” wọ́n sì sọkún kíkankíkan.
Adja az Úr tinéktek, hogy találjatok nyugodalmat, kiki az ő férje házában. És megcsókolá őket; és ők nagy felszóval sírának.
10 Wọ́n sì wí fún un pé, “Rárá, a ó bà ọ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.”
És mondák néki: Bizony mi veled együtt térünk a te népedhez!
11 Ṣùgbọ́n Naomi dáhùn wí pé, “Ẹ padà sílé ẹ̀yin ọmọ mi. Nítorí kí ni ẹ fi fẹ́ wá pẹ̀lú mi? Ṣé mo tún le bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn ni, tí ó le ṣe ọkọ yin?
Naómi pedig mondá: Térjetek vissza leányaim! Miért jönnétek én velem? Hát ugyan vannak-é még fiak az én méhemben, a kik férjeitek lehetnének?
12 Ẹ padà sílé, ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí èmi ti di arúgbó jù láti ní ọkọ mìíràn. Bí èmí wí pé, èmí ní ìrètí, bí èmí tilẹ̀ ní ọkọ mìíràn ní alẹ́ yìí, tí èmí sì bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn,
Térjetek vissza leányaim! menjetek, mert én már vénebb vagyok, semhogy férjhez mehetnék. Még ha azt mondanám is, hogy van reménységem; még ha ez éjjel férjhez mennék is és szülnék is fiakat:
13 ẹ̀yin ha le è dúró dìgbà tí wọ́n yóò fi dàgbà? Ẹ̀yin ó le è dúró dè wọ́n láì fẹ́ ọkọ mìíràn? Rárá, ẹ̀yin ọmọbìnrin mi, nítorí pé inú mi bàjẹ́ gidigidi ju tiyín lọ, nítorí tí ọwọ́ Olúwa fi jáde sí mi!”
Ugyan megvárhatnátok-é őket, a míg felnőnek? Ugyan megtartóztatnátok-é magatokat miattok, hogy férjhez ne menjetek? Ne, édes leányaim! Mert nagyobb az én keserüségem, mint a tietek, mert engem talált az Úrnak keze.
14 Wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì tún sọkún. Nígbà náà ní Oripa fi ẹnu ko ìyá ọkọ rẹ̀ ní ẹnu wí pé ó dìgbà, ṣùgbọ́n Rutu dì mọ́ ọn síbẹ̀.
Azok pedig nagy felszóval tovább sírának. És Orpa megcsókolá az ő napát; Ruth azonban ragaszkodék hozzá.
15 Naomi wí pé, “Wò ó, arábìnrin rẹ ti padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀ àti òrìṣà rẹ̀, ìwọ náà padà pẹ̀lú rẹ̀.”
Ő pedig monda: Ímé a te sógorasszonyod visszatért az ő népéhez, és az ő isteneihez, térj vissza te is a te sógorasszonyod után.
16 Ṣùgbọ́n Rutu dáhùn wí pé, “Má ṣe rọ̀ mí láti fi ọ́ sílẹ̀ tàbí láti padà lẹ́yìn rẹ. Ibi tí ìwọ bá lọ ní èmi yóò lọ, ibi ti ìwọ bá dúró ni èmi yóò dúró, àwọn ènìyàn rẹ ni yóò jẹ́ ènìyàn mi, Ọlọ́run rẹ ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run mi.
Ruth pedig monda: Ne unszolj, hogy elhagyjalak, hogy visszaforduljak tőled. Mert a hova te mégy, oda megyek, és a hol te megszállsz, ott szállok meg; néped az én népem, és Istened az én Istenem.
17 Níbi tí ìwọ bá kú sí ni èmi yóò kú sí, níbẹ̀ ni wọn yóò sì sin mí sí. Kí Olúwa jẹ mí ní ìyà tí ó lágbára, bí ohunkóhun bí kò ṣe ikú bá yà wá.”
A hol te meghalsz, ott halok meg, ott temessenek el engem is. Úgy tegyen velem az Úr akármit, hogy csak a halál választ el engem tőled.
18 Nígbà tí Naomi rí i wí pé Rutu ti pinnu láti tẹ̀lé òun kò rọ̀ láti padà mọ́.
Mikor pedig látá, hogy erősködik vele menni, nem szóla néki többet.
19 Àwọn méjèèjì sì ń lọ títí wọ́n fi dé ìlú Bẹtilẹhẹmu. Nígbà tí wọ́n dé ibẹ̀, ariwo ìpadàbọ̀ wọn gba ìlú kan, àwọn obìnrin ibẹ̀ sì kígbe ní ohùn rara wí pé, “Naomi ni èyí bí?”
És menének mind a ketten, míglen Bethlehembe érkezének. És lőn, hogy mikor Bethlehembe érkezének, megmozdult az egész város miattok, és mondák: Nemde nem Naómi ez?
20 Naomi sì dáhùn wí pé, “Ẹ má ṣe pè mí ní Naomi mọ́, ẹ pè mí ní Mara, nítorí wí pé Olódùmarè ti mú kí ayé mi di kíkorò.
És ő monda nékik: Ne hívjatok engem Naóminak, hívjatok inkább Márának, mert nagy keserűséggel illetett engem a Mindenható.
21 Mo jáde ní kíkún, ṣùgbọ́n Olúwa mú mi padà ní òfo. Nítorí náà kín ló dé tí ẹ fi ń pè mí ní Naomi, nígbà tí Olódùmarè ti kọ̀ mí sílẹ̀, tí ó sì mú ìdààmú bá mi?”
Többed magammal mentem el, és elárvultan hozott vissza engemet az Úr; miért hívnátok hát engem Naóminak, holott az Úr ellenem fordult, és a Mindenható nyomorúsággal illetett engemet?
22 Báyìí ni Naomi ṣe padà láti Moabu pẹ̀lú Rutu, ará Moabu ìyàwó ọmọ rẹ̀. Wọ́n gúnlẹ̀ sí Bẹtilẹhẹmu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè ọkà barle.
Így tért vissza Naómi, és vele a Moábita Ruth, az ő menye, a ki hazatért Moáb mezejéről. Megérkezének pedig Bethlehembe az árpaaratás kezdetén.

< Ruth 1 >