< Romans 1 >

1 Paulu, ìránṣẹ́ Jesu Kristi, ẹni tí a ti pè láti jẹ́ aposteli, tí a sì ti yà sọ́tọ̀ láti wàásù ìyìnrere Ọlọ́run,
Paweł, sługa Jezusa Chrystusa, powołany apostoł, odłączony do [głoszenia] ewangelii Boga;
2 ìyìnrere tí ó ti ṣe ìlérí tẹ́lẹ̀ rí láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ nínú Ìwé Mímọ́.
(Którą przedtem obiecał przez swoich proroków w Pismach świętych);
3 Ní ti Ọmọ rẹ̀, ẹni tí a bí láti inú irú-ọmọ Dafidi nípa ti ara,
O jego Synu, Jezusie Chrystusie, naszym Panu, który według ciała pochodził z potomstwa Dawida;
4 ẹni tí a pinnu rẹ̀ láti jẹ́ Ọmọ Ọlọ́run nínú agbára gẹ́gẹ́ bí Ẹ̀mí ìwà mímọ́, nípa àjíǹde kúrò nínú òkú, àní Jesu Kristi Olúwa wa.
A pokazał z mocą, że jest Synem Bożym, według Ducha świętości, przez zmartwychwstanie;
5 Láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwa rí oore-ọ̀fẹ́ àti jíjẹ́ aposteli gbà, fún ìgbọ́ràn ìgbàgbọ́ láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè, nítorí orúkọ rẹ̀.
Przez którego otrzymaliśmy łaskę i apostolstwo, [by przywieść] do posłuszeństwa wierze wszystkie narody dla jego imienia;
6 Ẹ̀yin pẹ̀lú si wa lára àwọn tí a pè sọ́dọ̀ Jesu Kristi.
Wśród których jesteście i wy, powołani [przez] Jezusa Chrystusa.
7 Sí gbogbo àwọn àyànfẹ́ Ọlọ́run tí ó wà ní Romu tí a ti pè láti jẹ́ ènìyàn mímọ́: Oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà fún yín láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa àti láti ọ̀dọ̀ Olúwa wa Jesu Kristi.
Wszystkim, którzy jesteście w Rzymie, umiłowanym Boga, powołanym świętym: Łaska wam i pokój od Boga, naszego Ojca, i Pana Jezusa Chrystusa.
8 Ní àkọ́kọ́, mo dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run nípasẹ̀ Jesu Kristi fún gbogbo yín, nítorí a ń ròyìn ìgbàgbọ́ yin káàkiri gbogbo ayé.
Najpierw dziękuję mojemu Bogu przez Jezusa Chrystusa za was wszystkich, że wasza wiara słynie na cały świat.
9 Ọlọ́run ṣá à ni ẹlẹ́rìí mi, ẹni tí èmí ń fi gbogbo ẹ̀mí mi sìn nínú ìyìnrere Ọmọ rẹ̀, bí ó ti ṣe pé ní àìsimi ni èmí ń rántí yín nígbà gbogbo nínú àdúrà mi
Bóg bowiem, któremu służę w moim duchu w ewangelii jego Syna, jest mi świadkiem, że nieustannie czynię wzmiankę o was w moich modlitwach;
10 nínú àdúrà mi ìgbà gbogbo; mo tún ń gbàdúrà wí pé nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run kí ọ̀nà ó ṣí fún mi láti wá sọ́dọ̀ yín.
Zawsze prosząc, żeby wreszcie kiedyś udało mi się za wolą Bożą odbyć podróż do was.
11 Nítorí èmi ń fẹ́ gidigidi láti tọ̀ yín wá, kí èmi lè fún yín ní ẹ̀bùn ẹ̀mí díẹ̀, kí a bá a le sọ yín di alágbára nínú Olúwa,
Pragnę bowiem zobaczyć was, abym wam mógł udzielić jakiegoś daru duchowego dla waszego utwierdzenia;
12 èyí nì ni pé, kí a lè jẹ́ ìwúrí fún ara wa nípa ìgbàgbọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan wa.
To znaczy, abyśmy się wzajemnie pocieszyli obopólną wiarą, waszą i moją.
13 Mo fẹ́ kí ẹ mọ èyí, ẹ̀yin ará mi, pé mo ti gbìyànjú lọ́pọ̀ ìgbà láti tọ̀ yín wá (ṣùgbọ́n ìdíwọ́ wà fún mi), kí èmi ki ó lè jèrè ọkàn díẹ̀ láàrín yín, gẹ́gẹ́ bí mo ti ní láàrín àwọn aláìkọlà yòókù.
A nie chcę, abyście i wy, bracia, nie wiedzieli, że często zamierzałem przybyć do was (ale byłem dotąd zatrzymywany), abym miał jakiś owoc zarówno wśród was, jak i wśród innych pogan.
14 Nítorí mo jẹ́ ajigbèsè sí Giriki àti sí àwọn aláìgbédè tí kì í ṣe Giriki, sí àwọn ọlọ́gbọ́n àti sí àwọn aṣiwèrè.
Jestem dłużnikiem zarówno Greków, jak i barbarzyńców, zarówno mądrych, jak i niemądrych;
15 Nítorí ìdí èyí ni mo ṣe ń làkàkà láti wá sí Romu àti láti fi gbogbo agbára mi wàásù ìyìnrere Ọlọ́run sí i yín.
Tak że na ile mogę, jestem gotowy i wam, którzy jesteście w Rzymie, głosić ewangelię.
16 Èmi kò tijú ìyìnrere Jesu, nítorí agbára Ọlọ́run ní ín ṣe láti gba gbogbo àwọn tí ó bá gbàgbọ́ là, ọ̀rọ̀ yìí ni a kọ́kọ́ wàásù sí àwọn Júù nìkan, ṣùgbọ́n nísinsin yìí fún àwọn Helleni pẹ̀lú.
Nie wstydzę się bowiem ewangelii Chrystusa, ponieważ jest [ona] mocą Boga ku zbawieniu dla każdego, kto uwierzy, najpierw Żyda, [potem] i Greka.
17 Nítorí nínú ìyìnrere ni òdodo Ọlọ́run ti farahàn, òdodo Ọlọ́run nípa ìgbàgbọ́ láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú Ìwé Mímọ́ pé, “Olódodo yóò yè nípa ìgbàgbọ́ rẹ̀.”
W niej bowiem objawia się sprawiedliwość Boga z wiary w wiarę, jak jest napisane: Sprawiedliwy będzie żył z wiary.
18 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run fi ìbínú rẹ̀ hàn láti ọ̀run wá sí gbogbo àìwà-bí-Ọlọ́run àti gbogbo àìṣòdodo ènìyàn, àwọn tí ń fi ìwà búburú dènà ìmọ̀ òtítọ́ lọ́dọ̀ ènìyàn.
Gniew Boży bowiem objawia się z nieba przeciwko wszelkiej bezbożności i niesprawiedliwości ludzi, którzy zatrzymują prawdę w niesprawiedliwości.
19 Nítorí pé, nǹkan gbogbo tí a lè mọ nípa Ọlọ́run ni a ti fihàn fún wọn, nítorí Ọlọ́run ti fi í hàn fún wọn.
Ponieważ to, co można wiedzieć o Bogu, jest dla nich jawne, gdyż Bóg im to objawił.
20 Nítorí pé láti ìgbà dídá ayé, gbogbo ohun àìlèfojúrí rẹ̀, bí agbára ayérayé àti ìwà-bí-Ọlọ́run rẹ̀ ni a rí gbangba tí a sì ń fi òye ohun tí a dá mọ̀ ọ́n kí ènìyàn má ba à wá àwáwí. (aïdios g126)
[To bowiem, co] niewidzialne, to znaczy jego wieczna moc i bóstwo, są widzialne od stworzenia świata przez to, co stworzone, po to, aby oni byli bez wymówki. (aïdios g126)
21 Lóòótọ́, wọn ní òye nípa Ọlọ́run dáradára, ṣùgbọ́n wọn kò yìn ín lógo bí Ọlọ́run, wọ́n kò sí dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀; wọ́n ń ro èrò asán, ọkàn aṣiwèrè wọn sì ṣókùnkùn.
Dlatego że poznawszy Boga, nie chwalili [go] jako Boga ani [mu] nie dziękowali, lecz znikczemnieli w swoich myślach i zaćmiło się ich bezrozumne serce.
22 Níwọ́n bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n pe ara wọn ní ọlọ́gbọ́n ṣùgbọ́n wọ́n di òmùgọ̀ pátápátá,
Podając się za mądrych, zgłupieli;
23 wọ́n sì yí ògo Ọlọ́run tí kì í díbàjẹ́ sí àwọn àwòrán ère bí i ti ènìyàn tí í díbàjẹ́ àti ti ẹyẹ, àti ti ẹranko ẹlẹ́sẹ̀ mẹ́rin àti ti ẹranko afàyàfà.
I zamienili chwałę niezniszczalnego Boga na podobieństwo obrazu zniszczalnego człowieka, ptaków, czworonożnych [zwierząt] i gadów.
24 Nítorí náà Ọlọ́run fà wọ́n lé ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ọkàn wọn lọ́wọ́ láti máa ṣe ohun ìríra pẹ̀lú ara wọn èyí tí kò tọ́.
Dlatego też Bóg wydał ich nieczystości przez pożądliwości ich serc, aby hańbili swoje ciała między sobą.
25 Wọ́n yí òtítọ́ Ọlọ́run sí èké, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ láti máa sin ẹ̀dá dípò ẹlẹ́dàá—ẹni tí ìyìn tọ́ sí láéláé. Àmín. (aiōn g165)
[Oni to] zamienili prawdę Bożą w kłamstwo i czcili stworzenie, i służyli [jemu] raczej niż Stwórcy, który jest błogosławiony na wieki. Amen. (aiōn g165)
26 Nítorí èyí yìí ni Ọlọ́run ṣe fi wọ́n fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, nítorí àwọn obìnrin wọn tilẹ̀ ń yí ìṣẹ̀dá ìbáṣepọ̀ tí ó tọ̀nà, sí èyí tí kò tọ̀nà.
Dlatego wydał ich Bóg haniebnym namiętnościom, gdyż nawet ich kobiety zamieniły naturalne współżycie na przeciwne naturze.
27 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin pẹ̀lú, wọn a máa fi ìbálòpọ̀ obìnrin nípa ti ẹ̀dá sílẹ̀, wọn a máa fẹ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ara wọn, ọkùnrin ń bá ọkùnrin ṣe èyí tí kò yẹ, wọ́n sì ǹ jẹ èrè ìṣìnà wọn nínú ara wọn bí ó ti yẹ sí.
Także mężczyźni, opuściwszy naturalne współżycie z kobietą, zapałali w swej pożądliwości jedni ku drugim, mężczyzna z mężczyzną, popełniając haniebne czyny i ponosząc na sobie samych należną za swój błąd zapłatę.
28 Àti gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti kọ̀ láti gba Ọlọ́run nínú ìmọ̀ tí ó tọ́, Ọlọ́run fi wọ́n fún iyè ríra láti ṣe ohun tí kò tọ́ fún wọn láti ṣe.
A skoro im się nie spodobało zachowanie poznania Boga, wydał ich Bóg [na pastwę] wypaczonego umysłu, aby robili to, co nie wypada;
29 Wọ́n kún fún onírúurú àìṣòdodo gbogbo, àgbèrè, ìkà, ojúkòkòrò, àrankàn; wọ́n kún fún ìlara, ìpànìyàn, ìjà, ìtànjẹ, ìwà búburú; wọ́n jẹ́ afọ̀rọ̀kẹ́lẹ́ ba ni jẹ́.
Będąc napełnieni wszelką nieprawością, nierządem, przewrotnością, chciwością, złośliwością; pełni zazdrości, morderstwa, sporu, podstępu, złych obyczajów;
30 Asọ̀rọ̀ ẹni lẹ́yìn, akórìíra Ọlọ́run, aláfojúdi, agbéraga, ahalẹ̀, aláròṣe ohun búburú, aṣàìgbọràn sí òbí,
Plotkarze, oszczercy, nienawidzący Boga, zuchwali, pyszni, chełpliwi, wynalazcy złych rzeczy, nieposłuszni rodzicom;
31 aláìníyè nínú, ọ̀dàlẹ̀, aláìnígbàgbọ́, ọ̀dájú, aláìláàánú.
Bezrozumni, niedotrzymujący słowa, bez naturalnej miłości, nieprzejednani [i] bez miłosierdzia.
32 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n mọ ìlànà Ọlọ́run pé, ẹni tí ó bá ṣe irú nǹkan wọ̀nyí yẹ sí ikú, wọn kò ní inú dídùn sí àwọn nǹkan wọ̀nyí nìkan ṣùgbọ́n wọ́n ní inú dídùn sí àwọn tí ń ṣe wọ́n.
Oni to, poznawszy wyrok Boga, że ci, którzy robią takie [rzeczy], są godni śmierci, nie tylko sami je robią, ale też pochwalają tych, którzy tak postępują.

< Romans 1 >