< Romans 9 >

1 Òtítọ́ ni èmi ń sọ nínú Kristi, èmi kò ṣèké, ọkàn mi sì ń jẹ́ mi ní ẹ̀rí nínú Ẹ̀mí Mímọ́.
I am telling you the truth as a Christian man--it is no falsehood, for my conscience enlightened, as it is, by the Holy Spirit adds its testimony to mine--
2 Pé mo ní ìbìnújẹ́ púpọ̀, àti ìkáàánú ìgbà gbogbo ni ọkàn mi.
when I declare that I have deep grief and unceasing anguish of heart.
3 Nítorí mo fẹ́rẹ lè gbàdúrà pé kí èmi tìkára mi kúrò lọ́dọ̀ Kristi nítorí àwọn ará mi, àwọn ìbátan mi nípa ti ara.
For I could pray to be accursed from Christ on behalf of my brethren, my human kinsfolk--for such the Israelites are.
4 Àwọn ẹni tí i ṣe Israẹli; tí àwọn ẹni tí ìsọdọmọ í ṣe, àti ògo, àti májẹ̀mú, àti ìfúnilófin, àti ìsìn Ọlọ́run, àti àwọn ìlérí.
To them belongs recognition as God's sons, and they have His glorious Presence and the Covenants, and the giving of the Law, and the Temple service, and the ancient Promises.
5 Tí ẹni tí àwọn Baba í ṣe, àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ẹni tí Kristi ti wá nípa ti ara, ẹni tí ó borí ohun gbogbo, Ọlọ́run olùbùkún láéláé. Àmín. (aiōn g165)
To them the Patriarchs belong, and from them in respect of His human lineage came the Christ, who is exalted above all, God blessed throughout the Ages. Amen. (aiōn g165)
6 Ṣùgbọ́n kì í ṣe pé nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run di asán. Kì í sá í ṣe gbogbo àwọn tí ó ti inú Israẹli wá, àwọn ni Israẹli.
Not however that God's word has failed; for all who have sprung from Israel do not count as Israel,
7 Bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe pé, nítorí wọ́n jẹ́ irú-ọmọ Abrahamu, gbogbo wọn ni ọmọ. Ní ọ̀nà mìíràn, “Nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.”
nor because they are Abraham's true children. But the promise was "Through Isaac shall your posterity be reckoned."
8 Èyí nì ni pé, kì í ṣe àwọn ọmọ nípa ti ara ni ọmọ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ìlérí ni a kà ní irú-ọmọ.
In other words, it is not the children by natural descent who count as God's children, but the children made such by the promise are regarded as Abraham's posterity.
9 Nítorí ọ̀rọ̀ ìlérí ni èyí: “Ní ìwòyí àmọ́dún ni èmi yóò wá, Sara yóò sì ní ọmọ ọkùnrin.”
For the words are the language of promise and run thus, "About this time next year I will come, and Sarah shall have a son."
10 Kì í sì í ṣe kìkì èyí, ṣùgbọ́n nígbà tí Rebeka pẹ̀lú lóyún fún ẹnìkan, fún Isaaki baba wa.
Nor is that all: later on there was Rebecca too. She was soon to bear two children to her husband, our forefather Isaac--
11 Nítorí nígbà tí kò tí ì bí àwọn ọmọ náà, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tí ì ṣe rere tàbí búburú—kí ìpinnu Ọlọ́run nípa ti ìyànfẹ́ kí ó lè dúró,
and even then, though they were not then born and had not done anything either good or evil, yet in order that God's electing purpose might not be frustrated, based, as it was, not on their actions but on the will of Him who called them, she was told,
12 kì í ṣe nípa ti iṣẹ́, bí kò ṣe ti ẹni tí ń peni—a ti sọ fún un pé, “Ẹ̀gbọ́n ni yóò máa sin àbúrò.”
"The elder of them will be bondservant to the younger."
13 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Jakọbu ni mo fẹ́ràn, ṣùgbọ́n Esau ni mo kórìíra.”
This agrees with the other Scripture which says, "Jacob I have loved, but Esau I have hated."
14 Ǹjẹ́ àwa yóò ha ti wí? Àìṣòdodo ha wà lọ́dọ̀ Ọlọ́run bí? Kí a má ri!
What then are we to infer? That there is injustice in God?
15 Nítorí ó wí fún Mose pé, “Èmi ó ṣàánú fún ẹni tí èmi yóò ṣàánú fún, èmi yóò sì ṣe ìyọ́nú fún ẹni tí èmi yóò ṣe ìyọ́nú fún.”
No, indeed; the solution is found in His words to Moses, "Wherever I show mercy it shall be nothing but mercy, and wherever I show compassion it shall be simply compassion."
16 Ǹjẹ́ bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe ti ẹni tí ó fẹ́, kì í sì í ṣe ti ẹni tí ń sáré, bí kò ṣe ti Ọlọ́run tí ń ṣàánú.
And from this we learn that everything is dependent not on man's will or endeavour, but upon God who has mercy. For the Scripture said to Pharaoh,
17 Nítorí ìwé mímọ́ wí fún Farao pé, “Nítorí èyí náà ni mo ṣe gbé ọ dìde, kí èmi kí ó le fi agbára mi hàn lára rẹ, àti kí a bá à le máa ròyìn orúkọ mi ká gbogbo ayé.”
"It is for this very purpose that I have lifted you so high--that I may make manifest in you My power, and that My name may be proclaimed far and wide in all the earth."
18 Nítorí náà ni ó ṣe ń ṣàánú fún ẹni tí ó wù ú, ẹni tí ó wù ú a sì mú ní ọkàn le.
This is a proof that wherever He chooses He shows mercy, and wherever he chooses He hardens the heart.
19 Ìwọ ó sì wí fún mi pé, “Kín ni ó ha tún bá ni wí sí? Nítorí ta ni ó ń de ìfẹ́ rẹ lọ́nà?”
"Why then does God still find fault?" you will ask; "for who is resisting His will?"
20 Bẹ́ẹ̀ kọ́, ìwọ ènìyàn, tà ni ìwọ tí ń dá Ọlọ́run lóhùn? “Ohun tí a mọ, a ha máa wí fún ẹni tí ó mọ ọ́n pé, ‘Èéṣe tí ìwọ fi mọ mi báyìí?’”
Nay, but who are you, a mere man, that you should cavil against GOD? Shall the thing moulded say to him who moulded it, "Why have you made me thus?"
21 Amọ̀kòkò kò ha ni agbára lórí amọ̀, nínú ìṣù kan náà láti ṣe apá kan nínú ohun èlò sí ọlá, àti apá kan nínú ohun èlò sí àìlọ́lá?
Or has not the potter rightful power over the clay to make out of the same lump one vessel for more honourable and another for less honourable uses?
22 Ǹjẹ́ bí Ọlọ́run bá fẹ́ fi ìbínú rẹ̀ hàn ń kọ́? Tí ó sì fẹ́ sọ agbára rẹ̀ di mí mọ̀, tí ó sì mú sùúrù púpọ̀ fún àwọn ohun èlò ìbínú tí a ṣe fún ìparun.
And what if God, while choosing to make manifest the terrors of His anger and to show what is possible with Him, has yet borne with long-forbearing patience with the subjects of His anger who stand ready for destruction,
23 Àti kí ó lè sọ ọ̀rọ̀ ògo rẹ̀ di mí mọ̀ lára àwọn ohun èlò àánú tí ó ti pèsè ṣáájú fún ògo.
in order to make known His infinite goodness towards the subjects of His mercy whom He has prepared beforehand for glory,
24 Àní àwa, tí ó ti pè, kì í ṣe nínú àwọn Júù nìkan, ṣùgbọ́n nínú àwọn Kèfèrí pẹ̀lú?
even towards us whom He has called not only from among the Jews but also from among the Gentiles?
25 Bí ó ti wí pẹ̀lú ní Hosea pé, “Èmi ó pe àwọn tí kì í ṣe ènìyàn mi, ní ‘ènìyàn mi’, àti ẹni tí kí í ṣe àyànfẹ́ ní ‘àyànfẹ́.’”
So also in Hosea He says, "I will call that nation My People which was not My People, and I will call her beloved who was not beloved.
26 Yóò sì ṣe, “Ní ibi ti a gbé ti sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó gbé pè wọ́n ní ‘ọmọ Ọlọ́run alààyè.’”
And in the place where it was said to them, 'No people of Mine are you,' there shall they be called sons of the everliving God."
27 Isaiah sì kígbe nítorí Israẹli pé: “Bí iye àwọn ọmọ Israẹli bá rí bí iyanrìn Òkun, apá kan ni ó gbàlà.
And Isaiah cries aloud concerning Israel, "Though the number of the sons of Israel be like the sands of the sea, only a remnant of them shall be saved;
28 Nítorí Olúwa yóò mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ lórí ilẹ̀ ayé, yóò parí rẹ̀, yóò sì ké e kúrò ní òdodo.”
for the Lord will hold a reckoning upon the earth, making it efficacious and brief."
29 Àti bí Isaiah ti wí tẹ́lẹ̀: “Bí kò ṣe bí Olúwa àwọn Ọmọ-ogun ti fi irú-ọmọ sílẹ̀ fún wa, àwa ìbá ti dàbí Sodomu, a bá sì ti sọ wá dàbí Gomorra.”
Even as Isaiah says in an earlier place, "Were it not that the Lord, the God of Hosts, had left us some few descendants, we should have become like Sodom, and have come to resemble Gomorrah."
30 Ǹjẹ́ kí ni àwa ó ha wí? Pé àwọn Kèfèrí, tí kò lépa òdodo, ọwọ́ wọn tẹ òdodo, ṣùgbọ́n òdodo tí ó ti inú ìgbàlà wá ni.
To what conclusion does this bring us? Why, that the Gentiles, who were not in pursuit of righteousness, have overtaken it--a righteousness, however, which arises from faith;
31 Ṣùgbọ́n Israẹli ti ń lépa òfin òdodo, ọwọ́ wọn kò tẹ òfin òdodo.
while the descendants of Israel, who were in pursuit of a Law that could give righteousness, have not arrived at one.
32 Nítorí kí ni? Nítorí wọn kò wá a nípa ìgbàgbọ́, ṣùgbọ́n bí ẹni pé nípa iṣẹ́ òfin. Nítorí wọn kọsẹ̀ lára òkúta ìkọ̀sẹ̀ ni.
And why? Because they were pursuing a righteousness which should arise not from faith, but from what they regarded as merit. They stuck their foot against the stone which lay in their way;
33 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Kíyèsi, mo gbé òkúta ìkọ̀sẹ̀ kalẹ̀ ní Sioni àti àpáta tí ó mú wọn ṣubú, ẹnikẹ́ni ti ó bá sì gbà a gbọ́, ojú kì yóò tì í.”
in agreement with the statement of Scripture, "See, I am placing on Mount Zion a stone for people to stumble at, and a rock for them to trip over, and yet he whose faith rests upon it shall never have reason to feel ashamed."

< Romans 9 >