< Romans 9 >

1 Òtítọ́ ni èmi ń sọ nínú Kristi, èmi kò ṣèké, ọkàn mi sì ń jẹ́ mi ní ẹ̀rí nínú Ẹ̀mí Mímọ́.
ⲁ̅ⲐⲘⲎⲒ ⲠⲈϮϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϦⲈⲚⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲚϮϪⲈⲘⲈⲐⲚⲞⲨϪ ⲀⲚ ⲈⲤⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ⲈⲢⲞⲒ ⲚⲈⲘⲎⲒ ⲚϪⲈⲦⲀⲤⲨⲚⲎⲆⲈⲤⲒⲤ ϦⲈⲚⲞⲨⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈϤⲞⲨⲀⲂ.
2 Pé mo ní ìbìnújẹ́ púpọ̀, àti ìkáàánú ìgbà gbogbo ni ọkàn mi.
ⲃ̅ϪⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚⲘⲔⲀϨ ⲚϨⲎⲦ ⲚⲈⲘⲎ ⲒⲚⲈⲘ ⲞⲨϢⲈⲚϨⲎⲦ ⲘⲠⲀϤⲘⲞⲨⲚⲔ ϦⲈⲚⲠⲀϨⲎ Ⲧ.
3 Nítorí mo fẹ́rẹ lè gbàdúrà pé kí èmi tìkára mi kúrò lọ́dọ̀ Kristi nítorí àwọn ará mi, àwọn ìbátan mi nípa ti ara.
ⲅ̅ⲚⲀⲒⲦⲰⲂϨ ⲄⲀⲢ ⲀⲚⲞⲔ ⲈⲈⲢⲀⲚⲀⲐⲎⲘⲀ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲀ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲈϪⲈⲚ ⲚⲀⲤⲚⲎⲞⲨ ⲚⲀⲤⲨⲚⲄⲈⲚⲎⲤ ⲔⲀⲦⲀ ⲤⲀⲢⲜ
4 Àwọn ẹni tí i ṣe Israẹli; tí àwọn ẹni tí ìsọdọmọ í ṣe, àti ògo, àti májẹ̀mú, àti ìfúnilófin, àti ìsìn Ọlọ́run, àti àwọn ìlérí.
ⲇ̅ⲈⲦⲈ ⲚⲒⲤⲢⲀⲎⲖⲒⲦⲎⲤ ⲚⲈⲚⲎ ⲈⲦⲈ ⲐⲰⲞⲨ ⲦⲈ ϮⲘⲈⲦϢⲎⲢⲒ ⲚⲈⲘ ⲠⲒⲰⲞⲨ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲆⲒⲀⲐⲎⲔⲎ ⲚⲈⲘ ⲠⲒⲤⲈⲘⲚⲈ ⲚⲞⲘⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲠⲒϢⲈⲘϢⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲰϢ.
5 Tí ẹni tí àwọn Baba í ṣe, àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ẹni tí Kristi ti wá nípa ti ara, ẹni tí ó borí ohun gbogbo, Ọlọ́run olùbùkún láéláé. Àmín. (aiōn g165)
ⲉ̅ⲚⲎ ⲈⲦⲈ ⲚⲞⲨⲞⲨ ⲚⲈⲚⲒⲒⲞϮ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲐⲰⲞⲨ ⲞⲚ ⲀⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲒⲈⲂⲞⲖ ⲚϦⲎⲦⲞⲨ ⲔⲀⲦⲀ ⲤⲀⲢⲜ ⲪⲎ ⲈⲦⲬⲎ ϨⲒϪⲈⲚ ⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲦⲤⲘⲀⲢⲰⲞⲨⲦ ϢⲀ ⲈⲚⲈϨ ⲀⲘⲎⲚ. (aiōn g165)
6 Ṣùgbọ́n kì í ṣe pé nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run di asán. Kì í sá í ṣe gbogbo àwọn tí ó ti inú Israẹli wá, àwọn ni Israẹli.
ⲋ̅ⲠⲀⲒⲢⲎϮ ⲆⲈ ⲘⲠⲈ ⲠⲒⲤⲀϪⲒ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ϨⲈⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨ ⲄⲀⲢ ⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲀⲚ ⲈⲦⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲒⲤⲖ ⲚⲀⲒ ⲚⲈⲠⲒⲤⲖ.
7 Bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe pé, nítorí wọ́n jẹ́ irú-ọmọ Abrahamu, gbogbo wọn ni ọmọ. Ní ọ̀nà mìíràn, “Nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.”
ⲍ̅ⲞⲨⲆⲈ ϪⲈ ϨⲀⲚϪⲢⲞϪ ⲚⲦⲈⲀⲂⲢⲀⲀⲘ ⲚⲈϨⲀⲚϢⲎⲢⲒ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲚⲈⲀⲖⲖⲀ ϦⲈⲚⲒⲤⲀⲀⲔ ⲈⲨⲈⲐⲀϨⲈⲘ ⲞⲨϪⲢⲞϪ ⲚⲀⲔ.
8 Èyí nì ni pé, kì í ṣe àwọn ọmọ nípa ti ara ni ọmọ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ìlérí ni a kà ní irú-ọmọ.
ⲏ̅ⲈⲦⲈ ⲪⲀⲒ ⲠⲈ ϪⲈ ⲚⲒϢⲎⲢⲒ ⲚⲦⲈⲦⲤⲀⲢⲜ ⲀⲚ ⲚⲀⲒ ⲚⲈⲚⲒϢⲎⲢⲒ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲀⲖⲖⲀ ⲚⲒϢⲎⲢⲒ ⲚⲦⲈⲠⲒⲰϢ ⲈⲦⲞⲨⲚⲀⲞⲠⲞⲨ ⲈⲨϪⲢⲞϪ.
9 Nítorí ọ̀rọ̀ ìlérí ni èyí: “Ní ìwòyí àmọ́dún ni èmi yóò wá, Sara yóò sì ní ọmọ ọkùnrin.”
ⲑ̅ⲠⲀⲒⲤⲀϪⲒ ⲄⲀⲢ ⲪⲀ ⲞⲨⲰϢ ⲠⲈ ϪⲈ ⲔⲀⲦⲀ ⲠⲀⲒⲤⲎⲞⲨ ⲪⲀⲒ ⲈⲒⲈⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲢⲈ ⲞⲨϢⲎⲢⲒ ϢⲰⲠⲒ ⲚⲤⲀⲢⲢⲀ.
10 Kì í sì í ṣe kìkì èyí, ṣùgbọ́n nígbà tí Rebeka pẹ̀lú lóyún fún ẹnìkan, fún Isaaki baba wa.
ⲓ̅ⲞⲨ ⲘⲞⲚⲞⲚ ⲆⲈ ⲀⲖⲖⲀ ⲚⲈⲘ ⲦⲔⲈⲈⲢⲈⲂⲈⲔⲔⲀ ⲈⲀⲤϬⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲞⲨϢⲀⲒⲢⲒ ⲚⲞⲨⲰⲦ ⲚⲦⲈⲒⲤⲀⲀⲔ ⲠⲈⲚⲒⲰⲦ.
11 Nítorí nígbà tí kò tí ì bí àwọn ọmọ náà, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tí ì ṣe rere tàbí búburú—kí ìpinnu Ọlọ́run nípa ti ìyànfẹ́ kí ó lè dúró,
ⲓ̅ⲁ̅ⲈⲘⲠⲀⲚⲦⲞⲨⲘⲀⲤⲞⲨ ⲄⲀⲢ ⲞⲨⲆⲈ ⲘⲠⲀⲦⲞⲨⲒⲢⲒ ⲚⲞⲨϨⲰⲂ ⲈⲚⲀⲚⲈϤ ⲒⲈ ⲈϤϨⲰⲞⲨ ϨⲒⲚⲀ ϮⲘⲈⲦⲤⲰⲦⲠ ⲈⲦⲀ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲐⲀϢⲤ ⲒⲤϪⲈⲚ ϢⲞⲢⲠ ⲚⲦⲈⲤϢⲰⲠⲒ ⲈⲤⲤⲘⲞⲚⲦ.
12 kì í ṣe nípa ti iṣẹ́, bí kò ṣe ti ẹni tí ń peni—a ti sọ fún un pé, “Ẹ̀gbọ́n ni yóò máa sin àbúrò.”
ⲓ̅ⲃ̅ⲈⲚⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚϨⲀⲚϨⲂⲎⲞⲨⲒ ⲀⲚ ⲦⲈ ⲀⲖⲖⲀ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲈⲦⲐⲰϨⲈⲘ ⲀⲨϪⲞⲤ ⲚⲀⲤ ϪⲈ ⲈⲢⲈ ⲠⲒⲚⲒϢϮ ⲈⲢⲂⲰⲔ ⲘⲠⲒⲔⲞⲨϪⲒ.
13 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Jakọbu ni mo fẹ́ràn, ṣùgbọ́n Esau ni mo kórìíra.”
ⲓ̅ⲅ̅ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲤϦⲎⲞⲨⲦ ϪⲈ ⲒⲀⲔⲰⲂ ⲘⲈⲚ ⲀⲒⲘⲈⲚⲢⲒⲦϤ ⲎⲤⲀⲨ ⲆⲈ ⲀⲒⲘⲈⲤⲦⲰϤ.
14 Ǹjẹ́ àwa yóò ha ti wí? Àìṣòdodo ha wà lọ́dọ̀ Ọlọ́run bí? Kí a má ri!
ⲓ̅ⲇ̅ⲞⲨ ϪⲈ ⲠⲈⲦⲈⲚⲚⲀϪⲞϤ ⲘⲎ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲘⲈⲦϬ ⲒⲚϪⲞⲚⲤ ϦⲀⲦⲈⲚ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲚⲚⲈⲤϢⲰⲠⲒ.
15 Nítorí ó wí fún Mose pé, “Èmi ó ṣàánú fún ẹni tí èmi yóò ṣàánú fún, èmi yóò sì ṣe ìyọ́nú fún ẹni tí èmi yóò ṣe ìyọ́nú fún.”
ⲓ̅ⲉ̅ϤϪⲰ ⲄⲀⲢ ⲘⲘⲞⲤ ⲘⲘⲰⲨⲤⲎⲤ ϪⲈ ϮⲚⲀⲚⲀⲒ ⲘⲪⲎ ⲈϮⲚⲀⲚⲀⲒ ⲚⲀϤ ⲞⲨⲞϨ ϮⲚⲀϢⲈⲚϨⲎ ⲦϦⲀ ⲪⲎ ⲈϮⲚⲀϢⲈⲚϨⲎⲦ ϦⲀⲢⲞϤ.
16 Ǹjẹ́ bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe ti ẹni tí ó fẹ́, kì í sì í ṣe ti ẹni tí ń sáré, bí kò ṣe ti Ọlọ́run tí ń ṣàánú.
ⲓ̅ⲋ̅ϨⲀⲢⲀ ⲞⲨⲚ ⲪⲀ ⲠⲈⲐⲞⲨⲰϢ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲞⲨⲆⲈ ⲘⲪⲀ ⲠⲈⲦϬⲞϪⲒ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲀⲖⲖⲀ ⲪⲀ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲐⲚⲀⲒ ⲠⲈ.
17 Nítorí ìwé mímọ́ wí fún Farao pé, “Nítorí èyí náà ni mo ṣe gbé ọ dìde, kí èmi kí ó le fi agbára mi hàn lára rẹ, àti kí a bá à le máa ròyìn orúkọ mi ká gbogbo ayé.”
ⲓ̅ⲍ̅ⲤϪⲰ ⲄⲀⲢ ⲘⲘⲞⲤ ⲚϪⲈϮⲄⲢⲀⲪⲎ ⲘⲪⲀⲢⲀⲰ ϪⲈ ⲈⲐⲂⲈ ⲪⲀⲒ ⲀⲒⲦⲞⲨⲚⲞⲤⲔ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲀⲞⲨⲰⲚϨ ⲚⲦⲀϪⲞⲘ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϦⲢⲎⲒ ⲚϦⲎⲦⲔ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲤⲈⲪⲒⲢⲒ ⲈⲠⲀⲢⲀⲚ ϨⲒϪⲈⲚ ⲠⲔⲀϨⲒ ⲦⲎⲢϤ.
18 Nítorí náà ni ó ṣe ń ṣàánú fún ẹni tí ó wù ú, ẹni tí ó wù ú a sì mú ní ọkàn le.
ⲓ̅ⲏ̅ϨⲀⲢⲀ ⲞⲨⲚ ⲠⲈⲦⲈϤⲞⲨⲀϢϤ ϢⲀϤⲚⲀⲒ ⲚⲀϤ ⲪⲎ ⲆⲈ ⲈⲦⲀϤⲞⲨⲀϢϤ ⲀⲚ ϢⲀϤⲈⲐⲢⲈϤⲈⲚϢⲰⲦ.
19 Ìwọ ó sì wí fún mi pé, “Kín ni ó ha tún bá ni wí sí? Nítorí ta ni ó ń de ìfẹ́ rẹ lọ́nà?”
ⲓ̅ⲑ̅ⲬⲚⲀϪⲞⲤ ⲞⲨⲚ ⲚⲎⲒ ϪⲈ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ϤϪⲈⲘ ⲀⲢⲒⲔⲒ ⲚⲒⲘ ⲄⲀⲢ ⲈϤϮ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈϨⲢⲈⲚ ⲠⲈϤⲤⲞϬ ⲚⲒ.
20 Bẹ́ẹ̀ kọ́, ìwọ ènìyàn, tà ni ìwọ tí ń dá Ọlọ́run lóhùn? “Ohun tí a mọ, a ha máa wí fún ẹni tí ó mọ ọ́n pé, ‘Èéṣe tí ìwọ fi mọ mi báyìí?’”
ⲕ̅ⲘⲈⲚⲞⲨⲚⲄⲈ ⲰⲪⲢⲰⲘⲒ ⲚⲐⲞⲔ ⲚⲒⲘ ⲚⲐⲞⲔ ⲪⲎ ⲈⲦⲈⲢⲞⲨⲰ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈϨⲢⲈⲚ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲘⲎ ⲈⲢⲈϢ ⲠⲒⲘⲞⲚⲔ ϪⲞⲤ ⲘⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲘⲞⲚⲔϤ ϪⲈ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲀⲔⲐⲀⲘⲒⲞⲒ ⲘⲠⲀⲒⲢⲎϮ.
21 Amọ̀kòkò kò ha ni agbára lórí amọ̀, nínú ìṣù kan náà láti ṣe apá kan nínú ohun èlò sí ọlá, àti apá kan nínú ohun èlò sí àìlọ́lá?
ⲕ̅ⲁ̅ϢⲀⲚ ⲘⲘⲞⲚ ⲚⲦⲈⲠⲒⲔⲈⲢⲀⲘⲈⲨⲤ ⲘⲠⲈⲢϢⲒϢⲒ ⲘⲠⲈϤⲞⲘⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲀⲒⲞⲨⲰϢⲈⲘ ⲢⲰ ⲈⲐⲀⲘⲒⲞ ⲚⲞⲨⲤⲔⲈⲨⲞⲤ ⲞⲨⲀⲒ ⲘⲈⲚ ⲈⲠⲦⲀⲒⲞ ⲔⲈⲞⲨⲀⲒ ⲆⲈ ⲈⲨϢⲰϢ.
22 Ǹjẹ́ bí Ọlọ́run bá fẹ́ fi ìbínú rẹ̀ hàn ń kọ́? Tí ó sì fẹ́ sọ agbára rẹ̀ di mí mọ̀, tí ó sì mú sùúrù púpọ̀ fún àwọn ohun èlò ìbínú tí a ṣe fún ìparun.
ⲕ̅ⲃ̅ⲒⲤϪⲈ ⲆⲈ ⲀϤⲞⲨⲰϢ ⲚϪⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲈϤⲞⲨⲰⲚϨ ⲘⲠⲈϤϪⲰⲚⲦ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲘⲞⲚ ⲈⲦⲈϤϪⲞⲘ ⲀϤⲒⲚⲒ ϦⲈⲚⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲘⲘⲈⲦⲢⲈϤⲰⲞⲨ ⲚϨⲎⲦ ⲚϨⲀⲚⲤⲔⲈⲨⲞⲤ ⲚⲦⲈⲠϪⲰⲚⲦ ⲈⲨⲤⲈⲂⲦⲰⲦ ⲈⲠⲦⲀⲔⲞ.
23 Àti kí ó lè sọ ọ̀rọ̀ ògo rẹ̀ di mí mọ̀ lára àwọn ohun èlò àánú tí ó ti pèsè ṣáájú fún ògo.
ⲕ̅ⲅ̅ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϤⲞⲨⲰⲚϨ ⲚϮⲘⲈⲦⲢⲀⲘⲀⲞ ⲚⲦⲈⲠⲈϤⲰⲞⲨ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲈⲚ ϨⲀⲚⲤⲔⲈⲨⲞⲤ ⲚⲚⲀⲒ ⲈⲦⲈ ⲚⲎ ⲚⲈⲈⲦⲀϤⲈⲢϢⲞⲢⲠ ⲚⲤⲈⲂⲦⲰⲦⲞⲨ ⲈⲨⲰⲞⲨ.
24 Àní àwa, tí ó ti pè, kì í ṣe nínú àwọn Júù nìkan, ṣùgbọ́n nínú àwọn Kèfèrí pẹ̀lú?
ⲕ̅ⲇ̅ⲈⲦⲈ ⲀⲚⲞⲚ ⲠⲈ ϦⲀ ⲚⲎ ⲈⲦⲀϤⲐⲀϨⲘⲞⲨ ⲞⲨ ⲘⲞⲚⲞⲚ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲀⲖⲖⲀ ⲚⲈⲘ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲒⲔⲈⲈⲐⲚⲞⲤ.
25 Bí ó ti wí pẹ̀lú ní Hosea pé, “Èmi ó pe àwọn tí kì í ṣe ènìyàn mi, ní ‘ènìyàn mi’, àti ẹni tí kí í ṣe àyànfẹ́ ní ‘àyànfẹ́.’”
ⲕ̅ⲉ̅ⲘⲪⲢⲎϮ ⲞⲚ ⲈⲦⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲤⲒⲈ ϪⲈ ϮⲚⲀⲘⲞⲨϮ ⲈⲪⲎ ⲈⲦⲈ ⲠⲀⲖⲀⲞⲤ ⲀⲚ ⲠⲈ ϪⲈ ⲠⲀⲖⲀⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲐⲎ ⲈⲦⲈ ⲘⲠⲞⲨⲘⲈⲚⲢⲒⲦⲤ ϪⲈ ⲀⲨⲘⲈⲚⲢⲒⲦⲤ.
26 Yóò sì ṣe, “Ní ibi ti a gbé ti sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó gbé pè wọ́n ní ‘ọmọ Ọlọ́run alààyè.’”
ⲕ̅ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲤⲈϢⲰⲠⲒ ϦⲈⲚⲠⲒⲘⲀ ⲈⲦⲀⲨϪⲞⲤ ⲚⲰⲞⲨ ⲘⲘⲞϤ ϪⲈ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲠⲀⲖⲀⲞⲤ ⲀⲚ ⲘⲠⲒⲘⲀ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲈⲨⲈⲘⲞⲨϮ ⲈⲢⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲚⲈⲚϢⲎ ⲢⲒ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲦⲞⲚϦ.
27 Isaiah sì kígbe nítorí Israẹli pé: “Bí iye àwọn ọmọ Israẹli bá rí bí iyanrìn Òkun, apá kan ni ó gbàlà.
ⲕ̅ⲍ̅ⲎⲤⲀⲎⲀⲤ ⲆⲈ ⲈϤⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲒⲤⲖ ϪⲈ ⲈϢⲰⲠ ⲈⲢⲈ ⲦⲎⲠⲒ ⲚⲦⲈⲚⲈⲚϢⲎⲢⲒ ⲘⲠⲒⲤⲖ ⲈⲤⲞⲒ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲘⲠⲒϢⲰ ⲚⲦⲈⲪⲒⲞⲘ ⲠⲤⲰϪⲠ ⲈϤⲈⲚⲞϨⲈⲘ.
28 Nítorí Olúwa yóò mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ lórí ilẹ̀ ayé, yóò parí rẹ̀, yóò sì ké e kúrò ní òdodo.”
ⲕ̅ⲏ̅ⲞⲨⲤⲀϪⲒ ⲄⲀⲢ ⲈϤϪⲰⲔ ⲘⲘⲞϤ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲈϤϢⲰⲦ ⲘⲘⲞϤ ⲈⲂⲞⲖ ⲪⲎ ⲈⲦⲈ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲚⲀⲀⲒϤ ϨⲒϪⲈⲚ ⲠⲔⲀϨⲒ.
29 Àti bí Isaiah ti wí tẹ́lẹ̀: “Bí kò ṣe bí Olúwa àwọn Ọmọ-ogun ti fi irú-ọmọ sílẹ̀ fún wa, àwa ìbá ti dàbí Sodomu, a bá sì ti sọ wá dàbí Gomorra.”
ⲕ̅ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲞⲚ ⲈⲦⲀϤϪⲞⲤ ⲚϪⲈⲎⲤⲀⲎⲀⲤ ϪⲈ ⲈⲚⲈⲘⲠⲈ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲤⲀⲂⲀⲰⲐ ⲤⲰϪⲠ ⲚⲞⲨϪⲢⲞϪ ⲚⲀⲚ ⲚⲀⲚⲚⲀⲈⲢ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲚⲤⲞⲆⲞⲘⲀ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲚⲚⲀⲒⲚⲒ ⲚⲄⲞⲘⲞⲢⲢⲀ.
30 Ǹjẹ́ kí ni àwa ó ha wí? Pé àwọn Kèfèrí, tí kò lépa òdodo, ọwọ́ wọn tẹ òdodo, ṣùgbọ́n òdodo tí ó ti inú ìgbàlà wá ni.
ⲗ̅ⲞⲨ ϪⲈ ⲠⲈⲦⲈⲚⲚⲀϪⲞϤ ϪⲈ ⲚⲒⲈⲐⲚⲞⲤ ⲈⲦⲈ ⲘⲠⲞⲨϬⲞϪⲒ ⲚⲤⲀϮⲘⲈⲐⲘⲎⲒ ⲀⲨⲦⲀϨⲈ ϮⲘⲈⲐⲘⲎ ⲒϮⲘⲈⲐⲘⲎⲒ ⲆⲈ ϮⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲪⲚⲀϨϮ.
31 Ṣùgbọ́n Israẹli ti ń lépa òfin òdodo, ọwọ́ wọn kò tẹ òfin òdodo.
ⲗ̅ⲁ̅ⲠⲒⲤⲖ ⲆⲈ ⲈϤϬⲞϪⲒ ⲚⲤⲀⲠⲒⲚⲞⲘⲞⲤ ⲚⲦⲈϮⲘⲈⲐⲘⲎⲒ ⲘⲠⲈϤⲪⲞϨ ⲈⲠⲒⲚⲞⲘⲞⲤ.
32 Nítorí kí ni? Nítorí wọn kò wá a nípa ìgbàgbọ́, ṣùgbọ́n bí ẹni pé nípa iṣẹ́ òfin. Nítorí wọn kọsẹ̀ lára òkúta ìkọ̀sẹ̀ ni.
ⲗ̅ⲃ̅ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ϪⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲪⲚⲀϨϮ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲀⲖⲖⲀ ϨⲰⲤ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚϨⲀⲚϨⲂⲎⲞⲨⲒ ⲀⲨϬⲒϬⲢⲞⲠ ⲈⲠⲒⲰⲚⲒ ⲚϬⲢⲞⲠ ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲤϦⲎⲞⲨⲦ
33 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Kíyèsi, mo gbé òkúta ìkọ̀sẹ̀ kalẹ̀ ní Sioni àti àpáta tí ó mú wọn ṣubú, ẹnikẹ́ni ti ó bá sì gbà a gbọ́, ojú kì yóò tì í.”
ⲗ̅ⲅ̅ϪⲈ ϨⲎⲠⲠⲈ ϮⲚⲀⲬⲰ ϦⲈⲚⲤⲒⲰⲚ ⲚⲞⲨⲰⲚⲒ ⲚϬⲢⲞⲠ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲠⲈⲦⲢⲀ ⲚⲤⲔⲀⲚⲆⲀⲖⲞⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲪⲎ ⲈⲐⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞϤ ⲚⲚⲈϤϬⲒϢⲒⲠⲒ.

< Romans 9 >