< Romans 8 >

1 Nítorí náà, kò sí ìdálẹ́bi nísinsin yìí fún àwọn tí ó wà nínú Kristi Jesu, àwọn tí kò rìn nípa ti ara, bí kò ṣe nípa ti Ẹ̀mí.
ⲁ̅ϩⲁⲣⲁ ⲟⲩⲛ ϯⲛⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲛϩⲁⲡ ϭⲓ ⳿ⲉⲛⲏⲉⲧϧⲉⲛ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅.
2 Nítorí nípasẹ̀ òfin ti ẹ̀mí ìyè nínú Kristi Jesu ti sọ mí di òmìnira kúrò lọ́wọ́ òfin ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú.
ⲃ̅ⲡⲓⲛⲟⲙⲟⲥ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲱⲛϧ ϧⲉⲛ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲁϥⲁⲓⲧⲉⲛ ⳿ⲛⲣⲉⲙϩⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁ ⲡⲓⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲫⲛⲟⲃⲓ ⲛⲉⲙ ⳿ⲫⲙⲟⲩ.
3 Nítorí ohun tí òfin kò lè ṣe, bí ó ti jẹ aláìlera nítorí ara, Ọlọ́run rán ọmọ òun tìkára rẹ̀ ní àwòrán ara ẹ̀ṣẹ̀, ó sì di ẹ̀ṣẹ̀; àti bi ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀, ó sì dá ẹ̀ṣẹ̀ lẹ́bi nínú ara,
ⲅ̅ϯⲙⲉⲧⲁⲧϫⲟⲙ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲛⲟⲙⲟⲥ ⲑⲏ⳿ⲉⲛⲁϥϣⲱⲛⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ϯⲥⲁⲣⲝ ⲁ ⲫϯ ⲧⲁⲟⲩ⳿ⲟ ⳿ⲙⲡⲉϥϣⲏⲣⲓ ϧⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲓⲛⲓ ⳿ⲛⲥⲁⲣⲝ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲫⲛⲟⲃⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲑⲃⲉ ⳿ⲫⲛⲟⲃⲓ ⲁϥϩⲓ ⳿ⲫⲛⲟⲃⲓ ⳿ⲉ⳿ⲡϩⲁⲡ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲥⲁⲣⲝ.
4 kí a lè mú òdodo òfin ṣẹ, nínú wa, nítorí tí àwa yé gẹ́gẹ́ bí ohun ti ara, bí kò ṣe gẹ́gẹ́ bí ohun ti Ẹ̀mí.
ⲇ̅ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓ⳿ⲑⲙⲁⲓⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲛⲟⲙⲟⲥ ϫⲱⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧⲉⲛ ϧⲁ ⲛⲏⲉⲧⲉ⳿ⲛⲥⲉⲙⲟϣⲓ ⲁⲛ ⲕⲁⲧⲁ ⲥⲁⲣⲝ ⲁⲗⲗⲁ ⲕⲁⲧⲁ ⲡ͞ⲛⲁ̅.
5 Àwọn tí ń gbe nípa ti ara, wọn a máa ronú ohun ti ara; ṣùgbọ́n àwọn ti ń gbe nípa ti Ẹ̀mí, wọn a máa ronú ohun ti Ẹ̀mí.
ⲉ̅ⲛⲏⲉⲧϣⲟⲡ ⲅⲁⲣ ⲕⲁⲧⲁ ⲥⲁⲣⲝ ⲛⲁ⳿ⲧⲥⲁⲣⲝ ⲡⲉⲧⲟⲩⲙⲉⲩⲓ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲛⲉⲧⲙⲟϣⲓ ⲇⲉ ⲕⲁⲧⲁ ⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲛⲁ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲡⲉⲧⲟⲩⲙⲉⲩⲓ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ.
6 Nítorí èrò ti ara ikú ni; ṣùgbọ́n èrò ti ẹ̀mí ni ìyè àti àlàáfíà.
ⲋ̅⳿ⲫⲙⲉⲩⲓ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲥⲁⲣⲝ ⳿ⲫⲙⲟⲩ ⲡⲉ ⳿ⲫⲙⲉⲩⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲡⲱⲛϧ ⲡⲉ ⲛⲉⲙ ϯ ϩⲓⲣⲏⲛⲏ.
7 Nítorí èrò ti ara ọ̀tá ni sí Ọlọ́run, nítorí kì í tẹríba fún òfin Ọlọ́run, òun kò tilẹ̀ le ṣe e.
ⲍ̅ϫⲉ ⳿ⲫⲙⲉⲩⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲥⲁⲣⲝ ⲟⲩⲙⲉⲧϫⲁϫⲓ ⲡⲉ ⳿ⲉⲫϯ ⳿ⲙⲡⲁϥϭⲛⲉ ϫⲱϥ ⲅⲁⲣ ⳿ⲙⲡⲓⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
8 Ìdí nìyìí tí àwọn tí ó wà lábẹ́ àkóso ara ẹ̀ṣẹ̀, kò le è tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn.
ⲏ̅ⲛⲏ ⲇⲉ ⲉⲧϧⲉⲛ ⳿ⲧⲥⲁⲣⲝ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲣⲁⲛⲁϥ ⳿ⲙⲫϯ.
9 Ṣùgbọ́n ẹyin kò sí nínú ti ara, bí kò ṣe nínú ti Ẹ̀mí, bí ó bá ṣe pé Ẹ̀mí Ọlọ́run ń gbé inú yín. Ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni kò bá ní Ẹ̀mí Kristi, òun kò sí nínú ẹni tirẹ̀.
ⲑ̅⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲇⲉ ⲛⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲭⲏ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲥⲁⲣⲝ ⲁⲛ ⲁⲗⲗⲁ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲓⲥϫⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ϣⲟⲡ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲫⲏ ⲇⲉ ⲉⲧⲉ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ϣⲟⲡ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⲁⲛ ⲫⲁⲓ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲫⲱϥ ⲁⲛ ⲡⲉ.
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Kristi ń gbé inú yín síbẹ̀síbẹ̀, ara yín jẹ́ òkú nítorí ẹ̀ṣẹ̀; ṣùgbọ́n ẹ̀mí mímọ́ tí ń gbé inú yín yóò fún yín ní ìyè, nítorí ó ti fún un yín ní òdodo.
ⲓ̅ⲓⲥϫⲉ ⲇⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲡⲓⲥⲱⲙⲁ ⲙⲉⲛ ⳿ϥⲙⲱⲟⲩⲧ ⲉⲑⲃⲉ ⳿ⲫⲛⲟⲃⲓ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲇⲉ ⲟⲩⲱⲛϧ ⲡⲉ ⲉⲑⲃⲉ ϯⲙⲉⲑⲙⲏⲓ.
11 Àti pé, bí ẹ̀mí Ọlọ́run, ẹni tí ó jí Jesu kúrò nínú òkú bá ń gbé inú yín, ẹni tí ó jí Kristi Jesu dìde kúrò nínú òkú, yóò fi ẹ̀mí rẹ̀ tí ń gbé inú yín sọ ara kíkú yín di ààyè pẹ̀lú.
ⲓ̅ⲁ̅ⲓⲥϫⲉ ⲇⲉ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫⲏⲉⲧⲁϥⲧⲟⲩⲛⲟⲥ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲏⲉⲑⲙⲱⲟⲩⲧ ⳿ϥϣⲟⲡ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲓⲉ ⲫⲏⲉⲧⲁϥⲧⲟⲩⲛⲟⲥ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲏⲉⲑⲙⲱⲟⲩⲧ ⲉϥ⳿ⲉⲧⲁⲛϧⲉ ⲛⲉⲧⲉⲛⲕⲉⲥⲱⲙⲁ ⲉⲧⲉϣⲁⲩⲙⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲡⲉϥⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲉⲧϣⲟⲡ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
12 Nítorí náà ará a ni ojúṣe láti ṣe, ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa nǹkan tí ara, tí a ó fi máa gbé nípa ti ara.
ⲓ̅ⲃ̅ϩⲁⲣⲁ ⲟⲩⲛ ⲛⲁ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲉⲣⲟⲛ ϧⲉⲛ ⲥⲁⲣⲝ ⲁⲛ ⲉⲑⲣⲉⲛⲱⲛϧ ⲕⲁⲧⲁ ⲥⲁⲣⲝ.
13 Nítorí pé bí ẹ̀yin bá ń tẹ̀lé, ẹ̀ṣẹ̀ ti ara ẹ̀yin yóò sọnù, ẹ ó sì ṣègbé, ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ ń gbé nípa ti ara, ẹ̀yin yóò kú, ṣùgbọ́n bí ẹ̀yín bá ń gbé nípa ti Ẹ̀mí, ẹ ó pa iṣẹ́ ti ara run, ẹ̀yin yóò yè.
ⲓ̅ⲅ̅ⲓⲥϫⲉ ⲅⲁⲣ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲟⲛϧ ⲕⲁⲧⲁ ⲥⲁⲣⲝ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲙⲟⲩ ⲓⲥϫⲉ ⲇⲉ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲛⲓ⳿ϩⲃⲏⲟⲩⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲥⲱⲙⲁ ⲧⲉⲧⲉⲛϧⲱⲧⲉⲃ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲱⲛϧ.
14 Nítorí pé, iye àwọn tí Ẹ̀mí Ọlọ́run bá ń darí ni ọmọ Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲇ̅ⲛⲏ ⲅⲁⲣ ⲉⲑⲙⲟϣⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲛⲁⲓ ⲛⲉ ⲛⲓϣⲏⲣⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
15 Nítorí ẹ̀yin kò tún gba ẹ̀mí ẹrú láti máa bẹ̀rù mọ́; ṣùgbọ́n ẹ̀yin gba ẹ̀mí ìsọdọmọ, nípa èyí tí àwa fi ń ké pé “Ábbà, Baba.”
ⲓ̅ⲉ̅ⲛⲁⲣⲉⲧⲉⲛϭⲓ ⲅⲁⲣ ⲁⲛ ⳿ⲛⲟⲩⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩⲙⲉⲧⲃⲱⲕ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⲟⲛ ⲉⲩϩⲟϯ ⲁⲗⲗⲁ ⲁⲣⲉⲧⲉⲛϭ ⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩⲙⲉⲧϣⲏⲣⲓ ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲉⲛⲱϣ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ϫⲉ ⲁⲃⲃⲁ ⳿ⲫⲓⲱⲧ.
16 Nítorí Ẹ̀mí mímọ́ ń sọ̀rọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú ọkàn wa, ó sì ń sọ fún wa pé, nítòótọ́, àwa jẹ́ ọmọ Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ϥⲉⲣⲙⲉⲑⲣⲉ ⲛⲉⲙ ⲡⲉⲛⲡ͞ⲛⲁ̅ ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ϩⲁⲛϣⲏⲣⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
17 Níwọ́n ìgbà tí a jẹ́ ọmọ rẹ̀, ǹjẹ́ ajogún ni àwa, ajogún Ọlọ́run, àti àjùmọ̀jogún pẹ̀lú Kristi, bí ó bá ṣe àwa jìyà, kí a sì le ṣe wá lógo pẹ̀lú rẹ̀.
ⲓ̅ⲍ̅ⲓⲥϫⲉ ⲇⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ϩⲁⲛϣⲏⲣⲓ ⲓⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ϩⲁⲛ⳿ⲕⲗⲏⲣⲟⲛⲟⲙⲟⲥ ⲟⲛ ϩⲁⲛ⳿ⲕⲗⲏⲣⲟⲛⲟⲙⲟⲥ ⲙⲉⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ϩⲁⲛ⳿ϣⲫⲏⲣ ⳿ⲛ⳿ⲕⲗⲏⲣⲟⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲓⲥϫⲉ ⲧⲉⲛϭⲓ⳿ⲙⲕⲁϩ ⲛⲉⲙⲁϥ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲛ ϭⲓⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙⲁϥ ⲟⲛ.
18 Síbẹ̀síbẹ̀, ìyà tí a ń jẹ nísinsin yìí kò jámọ́ nǹkan nígbà tí a bá fiwé ògo tí yóò fún wa ní ìkẹyìn.
ⲓ̅ⲏ̅ϯⲙⲉⲩⲓ ⲅⲁⲣ ϫⲉ ⲥⲉ⳿ⲙ⳿ⲡϣⲁ ⲁⲛ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓ⳿ⲙⲕⲁⲩϩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲁⲓⲥⲏⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲛⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲓⲱⲟⲩ ⲉⲑⲛⲁϭⲱⲣⲡ ⲛⲁⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
19 Nítorí ẹ̀dá ń dúró ní ìfojúsọ́nà de ìfihàn àwọn ọmọ Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲑ̅⳿ⲡϫⲓⲛⲥⲟⲙⲥ ⲅⲁⲣ ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲥⲱⲛⲧ ⲁϥⲥⲟⲙⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲁ⳿ⲧϩⲏ ⳿ⲙⲡⲓϭⲱⲣⲡ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓϣⲏⲣⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
20 Nítorí a tẹrí ẹ̀dá ba fún asán, kì í ṣe bí òun ti fẹ́, ṣùgbọ́n nípa ìfẹ́ ẹni tí ó tẹ orí rẹ̀ ba ní ìrètí.
ⲕ̅ⲡⲓⲥⲱⲛⲧ ⲅⲁⲣ ⲁϥϭⲛⲉϫⲱϥ ⳿ⲛϯⲙⲉⲧⲉⲫⲗⲏⲟⲩ ⳿ⲛ⳿ϥⲟⲩⲱϣ ⲁⲛ ⲁⲗⲗⲁ ⲉⲑⲃⲉ ⲫⲏⲉⲧⲁϥ⳿ⲑⲣⲉϥϭⲛⲉϫⲱϥ ϧⲉⲛ ⲟⲩϩⲉⲗⲡⲓⲥ.
21 Nítorí a ó sọ ẹ̀dá tìkára rẹ̀ di òmìnira kúrò nínú ẹrú ìdíbàjẹ́, sí òmìnira ògo àwọn ọmọ Ọlọ́run.
ⲕ̅ⲁ̅ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲟϥ ϩⲱϥ ⲡⲓⲥⲱⲛⲧ ⳿ϥⲛⲁⲉⲣⲣⲉⲙϩⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁ ϯⲙⲉⲧⲃⲱⲕ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲧⲁⲕⲟ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲉ ϯⲙⲉⲧⲣⲉⲙϩⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓϣⲏⲣⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
22 Nítorí àwa mọ̀ pé gbogbo ẹ̀dá ni ó jùmọ̀ ń kérora tí ó sì ń rọbí pọ̀ títí di ìsinsin yìí.
ⲕ̅ⲃ̅ⲧⲉⲛⲥⲱⲟⲩⲛ ⲙⲉⲛ ⲅⲁⲣ ϫⲉ ⲡⲓⲥⲱⲛⲧ ⲧⲏⲣϥ ϥⲓ⳿ⲁϩⲟⲙ ⲛⲉⲙⲁⲛ ⲟⲩⲟϩ ⳿ϥϯⲛⲁⲕϩⲓ ⲛⲉⲙⲁⲛ ϣⲁ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉϯⲛⲟⲩ.
23 Kì í ṣe àwọn nìkan, ṣùgbọ́n àwa tìkára wa pẹ̀lú, a ni àkóso ẹ̀mí, àní àwa tìkára wa ń kérora nínú ara wa, àwa ń dúró de ìsọdọmọ àní ìdáǹdè ara wa.
ⲕ̅ⲅ̅ⲟⲩ ⲙⲟⲛⲟⲛ ⲇⲉ ⲁⲗⲗⲁ ⲛⲉⲙ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ϩⲱⲛ ⳿ⲉϯⲁⲡⲁⲣⲭⲏ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲛⲧⲟⲧⲉⲛ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ⲧⲉⲛϥⲓ⳿ⲁϩⲟⲙ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧⲉⲛ ⲉⲛϫⲟⲩϣⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲁ⳿ⲧϩⲏ ⳿ⲛϯⲙⲉⲧϣⲏⲣⲓ ⲡⲓⲥⲱϯ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲛⲥⲱⲙⲁ.
24 Nítorí nípa ìrètí ni a fi gbà wá là, ṣùgbọ́n ìrètí tí a bá rí kì í ṣe ìrètí nítorí ta ni ń retí ohun tí ó bá rí?
ⲕ̅ⲇ̅ⲉⲧⲁⲛⲛⲟϩⲉⲙ ⲅⲁⲣ ϧⲉⲛ ⲟⲩϩⲉⲗⲡⲓⲥ ⲟⲩϩⲉⲗⲡⲓⲥ ⲇⲉ ⲉⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟⲥ ⳿ⲛⲟⲩϩⲉⲗⲡⲓⲥ ⲁⲛ ⲧⲉ ⲫⲏ ⲅⲁⲣ ⳿ⲉϣⲁⲣⲉ ⲟⲩⲁⲓ ⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϣⲁϥⲉⲣϩⲩⲡⲟⲙⲟⲛⲓⲛ ⳿ⲉⲣⲟϥ.
25 Ṣùgbọ́n bí àwa bá ń retí èyí tí àwa kò rí, ǹjẹ́ àwa ń fi sùúrù dúró dè é.
ⲕ̅ⲉ̅ⲓⲥϫⲉ ⲇⲉ ⲫⲏⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲁⲛ ⲧⲉⲛⲉⲣϩⲉⲗⲡⲓⲥ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲟⲩϩⲩⲡⲟⲙⲟⲛⲏ ⲧⲉⲛϫⲟⲩϣⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲁϫⲱϥ.
26 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ẹ̀mí pẹ̀lú sì ń ran àìlera wa lọ́wọ́: nítorí a kò mọ bí a ti ń gbàdúrà gẹ́gẹ́ bí ó ti yẹ, ṣùgbọ́n ẹ̀mí tìkára rẹ̀ ń fi ìrora tí a kò le fi ẹnu sọ bẹ̀bẹ̀ fún wa.
ⲕ̅ⲋ̅ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲇⲉ ⲟⲛ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲁϥϯⲧⲟⲧⲥ ⳿ⲛⲧⲉⲛⲙⲉⲧϫⲱⲃ ⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛⲧⲱⲃϩ ⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲁⲓϥ ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧ⳿ⲥϣⲉ ⳿ⲛⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ϥⲉⲣϩⲟⲩ⳿ⲟ ⲥⲉⲙⲓ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲱⲛ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛϥⲓ⳿ⲁϩⲟⲙ ⳿ⲛⲁⲧⲥⲁϫⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ.
27 Ẹni tí ó sì ń wá inú ọkàn wò, ó mọ ohun ti ẹ̀mí, nítorí tí ó ń bẹ̀bẹ̀ fún àwọn ènìyàn mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Ọlọ́run.
ⲕ̅ⲍ̅ⲫⲏ ⲇⲉ ⲉⲧϧⲟⲧϧⲉⲧ ⳿ⲛⲛⲓϩⲏⲧ ⳿ϥⲥⲱⲟⲩⲛ ϫⲉ ⲟⲩ ⲡⲉ ⳿ⲫⲙⲉⲩⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ϫⲉ ⲁϥⲥⲉⲙⲓ ⳿ⲉⲫϯ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲫⲏⲉⲑⲟⲩⲁⲃ.
28 Àwa sì mọ̀ pé ohun gbogbo ni ó ń ṣiṣẹ́ pọ̀ sí rere fún àwọn tí ó fẹ́ Ọlọ́run, àní fún àwọn ẹni tí a pè gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ̀.
ⲕ̅ⲏ̅ⲧⲉⲛⲥⲱⲟⲩⲛ ⲇⲉ ϫⲉ ⲛⲏⲉⲧⲉⲣⲁⲅⲁⲡⲁⲛ ⳿ⲙⲫϯ ϣⲁϥⲉⲣϩⲱⲃ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ ϧⲉⲛ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲑⲛⲁⲛⲉⲩ ⲛⲏⲉⲧⲁϥⲑⲁϩⲙⲟⲩ ⲕⲁⲧⲁ ⲡⲉϥϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛⲑⲱϣ.
29 Nítorí àwọn ẹni tí ó mọ̀ tẹ́lẹ̀, ni ó sì yàn tẹ́lẹ̀ láti rí bí àwòrán ọmọ rẹ̀, kí òun lè jẹ́ àkọ́bí láàrín àwọn arákùnrin púpọ̀.
ⲕ̅ⲑ̅ϫⲉ ⲛⲏⲉⲧⲁϥⲉⲣϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛⲥⲟⲩⲱⲛⲟⲩ ⲛⲁⲓ ⲟⲛ ⲁϥⲉⲣϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛⲑⲁϣⲟⲩ ⳿ⲛ⳿ϣⲫⲏⲣ ⳿ⲛ⳿ⲥⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲧϩⲓⲕⲱⲛ ⳿ⲙⲡⲉϥϣⲏⲣⲓ ⲉⲑⲣⲉϥϣⲱⲡⲓ ⲉϥⲟⲓ ⳿ⲛϣⲟⲣⲡ ⳿ⲙⲙⲓⲥⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛⲥⲟⲡ.
30 Àti pé lẹ́yìn tí òun ti pè wá wá sọ́dọ̀ ara rẹ̀, ó sọ wá di aláìjẹ̀bi lẹ́yìn èyí, ó fi rere Kristi kún inú ọkàn wa. Lékè gbogbo rẹ̀, ó fún wa ní ìdúró rere pẹ̀lú rẹ̀, ó sì pinu ògo rẹ̀ fún wa.
ⲗ̅ⲛⲏ ⲇⲉ ⲉⲧⲁϥⲉⲣϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛⲑⲁϣⲟⲩ ⲛⲁⲓ ⲟⲛ ⲛⲏⲉⲧⲁϥⲑⲁϩⲙⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲏⲉⲧⲁϥⲑⲁϩⲙⲟⲩ ⲛⲁⲓ ⲟⲛ ⲁϥ⳿ⲑⲙⲁⲓⲱⲟⲩ ⲛⲏ ⲇⲉ ⲉⲧⲁϥ⳿ⲑⲙⲁⲓⲱⲟⲩ ⲛⲁⲓ ⲟⲛ ⲁϥϯⲱⲟⲩ ⲛⲱⲟⲩ.
31 Kí ni àwa yóò wí nísinsin yìí sí nǹkan ìyanu wọ̀nyí? Bí Ọlọ́run bá wà pẹ̀lú wa, ta ni yóò kọjú ìjà sí wa?
ⲗ̅ⲁ̅ⲟⲩ ϫⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛⲛⲁϫⲟϥ ⲟⲩⲃⲉ ⲛⲁⲓ ⲓⲥϫⲉ ⲫϯ ⲡⲉⲧϯ ⳿ⲉϫⲱⲛ ⲛⲓⲙ ⲉⲑⲛⲁϣϯ ⲟⲩⲃⲏⲛ.
32 Níwọ̀n ìgbà tí Ọlọ́run ti fi Ọmọ rẹ̀ fún wa, ǹjẹ́ ó ha tún le ṣòro fún un láti fún wa ní ohunkóhun bí?
ⲗ̅ⲃ̅ⲫⲏⲉⲧⲉ⳿ⲙⲡⲉϥϯⲁⲥⲟ ⳿ⲉⲡⲉϥϣⲏⲣⲓ ⳿ⲙⲙⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲁⲗⲗⲁ ⲁϥⲧⲏⲓϥ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲱⲛ ⲧⲏⲣⲉⲛ ⲡⲱⲥ ϫⲉ ⳿ⲛⲛⲉϥϯ ⳿ⲛⲉⲛⲭⲁⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲛⲁⲛ ⳿ⲛ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲛⲉⲙⲁϥ.
33 Ta ni ẹni náà tí ó lè dá wa lẹ́bi, àwa ẹni tí Ọlọ́run ti yàn fún ara rẹ̀. Ǹjẹ́ Ọlọ́run yóò dá wa lẹ́bi? Bẹ́ẹ̀ kọ́! Òun ni ẹni tí ó dáríjì wá, tí ó sì fi wá sípò tí ó dára lọ́dọ̀ rẹ̀.
ⲗ̅ⲅ̅ⲛⲓⲙ ⲉⲑⲛⲁ⳿ϣⲥⲉⲙⲓ ⳿ⲉⲛⲓⲥⲱⲧⲡ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲫϯ ⲡⲉⲧ⳿ⲑⲙⲁⲓⲟ.
34 Ta ni ẹni náà tí yóò dá wa lẹ́bi? Kò sí. Kristi Jesu tí ó kú, kí a sá à kúkú wí pé tí a ti jí dìde kúrò nínú òkú, ẹni tí ó sì wà ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run, tó sì ń bẹ̀bẹ̀ fún wa?
ⲗ̅ⲇ̅ⲛⲓⲙ ⲉⲑⲛⲁ⳿ϣϩⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲙ⳿ⲡϩⲁⲡ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲡⲉ ⲉⲧⲁϥⲙⲟⲩ ⲙⲁⲗⲗⲟⲛ ⲇⲉ ⲁϥⲧⲱⲛϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲏⲉⲑⲙⲱⲟⲩⲧ ⲫⲏⲉⲧⲭⲏ ⲥⲁⲟⲩ⳿ⲓⲛⲁⲙ ⳿ⲙⲫϯ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲉⲧⲥⲉⲙⲓ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲱⲛ.
35 Ta ni yóò ha yà wá kúrò nínú ìfẹ́ Kristi? Ìpọ́njú ni, tàbí wàhálà tàbí inúnibíni tàbí ìyàn, tàbí ìhòhò, tàbí ewu tàbí idà?
ⲗ̅ⲉ̅ⲛⲓⲙ ⲉⲑⲛⲁ⳿ϣⲫⲟⲣϫⲧⲉⲛ ⲥⲁⲃⲟⲗ ⳿ⲛϯ ⲁⲅⲁⲡⲏ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲟⲩϩⲟϫϩⲉϫ ⲡⲉ ⲓⲉ ⲟⲩⲧⲁⲧϩⲟ ⲓⲉ ⲟⲩⲇⲓⲱⲅⲙⲟⲥ ⲓⲉ ⲟⲩ⳿ϩⲕⲟ ⲓⲉ ⲟⲩⲃⲱϣ ⲓⲉ ⲟⲩⲕⲩⲛⲇⲓⲛⲟⲥ ⲓⲉ ⲟⲩⲥⲏϥⲓ.
36 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Nítorí rẹ̀ ni a ṣe ń pa wá kú ní gbogbo ọjọ́; À ń kà wá sí bí àgùntàn fún pípa.”
ⲗ̅ⲋ̅ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧ⳿ⲥϧⲏⲟⲩⲧ ϫⲉ ⲉⲑⲃⲏⲧⲕ ⲥⲉϧⲱⲧⲉⲃ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲧⲏⲣϥ ⲁⲩⲟⲡⲧⲉⲛ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛϩⲁⲛ⳿ⲉⲥⲱⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ⲡϧⲟⲗϧⲉⲗ.
37 Ṣùgbọ́n nínú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, àwa ju ẹni tí ó ṣẹ́gun lọ nípasẹ̀ Kristi ẹni tí ó fẹ́ wa.
ⲗ̅ⲍ̅ⲁⲗⲗⲁ ϧⲉⲛ ⲛⲁⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲧⲉⲛⲉⲣϩⲟⲩ⳿ⲟ ϭⲣⲟ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲫⲏⲉⲧⲁϥⲙⲉⲛⲣⲓⲧⲉⲛ.
38 Nítorí pé ó dá mi lójú gbangba pé, kì í ṣe ikú tàbí ìyè, kì í ṣe àwọn angẹli tàbí ẹ̀mí èṣù, kì í ṣe ohun ìgbà ìsinsin yìí tàbí ohun tí ó ń bọ̀, tàbí àwọn agbára,
ⲗ̅ⲏ̅⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲅⲁⲣ ⲡⲁϩⲏⲧ ⲑⲏⲧ ϫⲉ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲫⲙⲟⲩ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲡⲱⲛϧ ⲟⲩⲇⲉ ⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⲟⲩⲇⲉ ⲁⲣⲭⲏ ⲟⲩⲇⲉ ⲛⲉⲧϣⲟⲡ ⲟⲩⲇⲉ ⲛⲉⲧⲛⲁϣⲱⲡⲓ ⲟⲩⲇⲉ ϫⲟⲙ.
39 tàbí òkè, tàbí ọ̀gbun, tàbí ohunkóhun nínú ìṣẹ̀dá ni yóò le yà wá kúrò nínú ìfẹ́ Ọlọ́run tí ó ń bẹ nínú Kristi Jesu, Olúwa wa.
ⲗ̅ⲑ̅ⲟⲩⲇⲉ ϭⲓⲥⲓ ⲟⲩⲇⲉ ϣⲱⲕ ⲟⲩⲇⲉ ⲕⲉⲥⲱⲛⲧ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲫⲟⲣϫⲧⲉⲛ ⲥⲁⲃⲟⲗ ⳿ⲛϯⲁⲅⲁⲡⲏ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲑⲏ ⲉⲧϧⲉⲛ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲡⲉⲛ⳪

< Romans 8 >