< Romans 5 >
1 Nítorí náà, níwọ̀n ìgbà tí a ti dá wa láre nípa ìgbàgbọ́, àwa ní àlàáfíà lọ́dọ̀ Ọlọ́run nípasẹ̀ Olúwa wa Jesu Kristi.
Deci, fiind îndreptățiți prin credință, avem pace cu Dumnezeu, prin Domnul nostru Isus Hristos,
2 Nípasẹ̀ ẹni tí àwa sì ti rí ọ̀nà gbà nípa ìgbàgbọ́ sí inú oore-ọ̀fẹ́ yìí nínú èyí tí àwa gbé dúró. Àwa sì ń yọ̀ nínú ìrètí ògo Ọlọ́run.
prin care, de asemenea, avem acces prin credință la acest har în care stăm. Ne bucurăm în speranța gloriei lui Dumnezeu.
3 Kì í sì ṣe bẹ́ẹ̀ nìkan, ṣùgbọ́n àwa tún ń ṣògo nínú ìjìyà pẹ̀lú, bí a ti mọ̀ pé ìjìyà ń ṣiṣẹ́ sùúrù;
Și nu numai atât, ci ne bucurăm și în suferințele noastre, știind că suferința produce perseverență;
4 àti pé sùúrù ń ṣiṣẹ́ ìwà rere; àti pé ìwà rere ń ṣiṣẹ́ ìrètí.
iar perseverența, caracter dovedit; iar caracterul dovedit, speranță;
5 Ìrètí kì í sì í dójúti ni nítorí a ti dá ìfẹ́ Ọlọ́run sí wa lọ́kàn láti ọwọ́ Ẹ̀mí Mímọ́ tí a fi fún wa.
iar speranța nu ne dezamăgește, pentru că dragostea lui Dumnezeu a fost revărsată în inimile noastre prin Duhul Sfânt care ne-a fost dat.
6 Nítorí ìgbà tí àwa jẹ́ aláìlera, ní àkókò tí ó yẹ, Kristi kú fún àwa aláìwà-bí-Ọlọ́run.
Căci, pe când eram noi încă slabi, Hristos a murit la vremea potrivită pentru cei nelegiuiți.
7 Nítorí ó ṣọ̀wọ́n kí ẹnìkan tó kú fún olódodo, ṣùgbọ́n fún ènìyàn rere bóyá ẹlòmíràn tilẹ̀ lè dábàá láti kú.
Căci cu greu va muri cineva pentru un om neprihănit. Totuși, poate că pentru un om bun cineva chiar va îndrăzni să moară.
8 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run fi ìfẹ́ òun pàápàá sí wa hàn nínú èyí pé, nígbà tí àwa jẹ́ ẹlẹ́ṣẹ̀, Kristi kú fún wa.
Dar Dumnezeu Își recomandă dragostea față de noi, prin faptul că, pe când eram încă păcătoși, Hristos a murit pentru noi.
9 Mélòó mélòó sì ni tí a dá wa láre nísinsin yìí nípa ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ ni a ó gbà wá là kúrò nínú ìbínú nípasẹ̀ rẹ̀.
Cu atât mai mult, fiind acum îndreptățiți prin sângele Lui, vom fi mântuiți prin El de mânia lui Dumnezeu.
10 Ǹjẹ́, nígbà tí àwa wà ní ọ̀tá, a mú wa, ba Ọlọ́run làjà nípa ikú Ọmọ rẹ̀, mélòó mélòó, nígbà tí a là wá ní ìjà tan, ni a ó gbà wá là nípa ìyè rẹ̀.
Căci dacă, pe când eram vrăjmași, am fost împăcați cu Dumnezeu prin moartea Fiului Său, cu atât mai mult, fiind împăcați, vom fi mântuiți prin viața lui.
11 Kì sì í ṣe bẹ́ẹ̀ nìkan, ṣùgbọ́n àwa ń ṣògo nínú Ọlọ́run nípa Olúwa wa Jesu Kristi, nípasẹ̀ ẹni tí àwa ti rí ìlàjà gbà nísinsin yìí.
Și nu numai atât, ci ne și bucurăm în Dumnezeu prin Domnul nostru Isus Hristos, prin care am primit acum împăcarea.
12 Nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ṣẹ̀ ti tipa ọ̀dọ̀ ènìyàn kan wọ ayé, àti ikú nípa ẹ̀ṣẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ikú sì kọjá sórí ènìyàn gbogbo, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí gbogbo ènìyàn ti dẹ́ṣẹ̀.
Așadar, după cum păcatul a intrat în lume printr-un singur om și moartea prin păcat, tot așa și moartea a trecut la toți oamenii, pentru că toți au păcătuit.
13 Nítorí kí òfin tó dé, ẹ̀ṣẹ̀ ti wà láyé; ṣùgbọ́n a kò ka ẹ̀ṣẹ̀ sí ni lọ́rùn nígbà tí òfin kò sí.
Căci, până la apariția Legii, păcatul era în lume; dar păcatul nu este acuzat când nu există Legea.
14 Ṣùgbọ́n ikú jẹ ọba láti ìgbà Adamu wá títí fi di ìgbà ti Mose, àti lórí àwọn tí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò dàbí irú ìrékọjá Adamu, ẹni tí í ṣe àpẹẹrẹ ẹni tí ń bọ̀.
Cu toate acestea, moartea a domnit de la Adam până la Moise, chiar și peste cei ale căror păcate nu au fost ca neascultarea lui Adam, care este o prefigurare a celui ce avea să vină.
15 Ṣùgbọ́n ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ kò dàbí ẹ̀ṣẹ̀. Nítorí bí nípa ẹ̀ṣẹ̀. Nítorí bí o bá jẹ pé ẹnìkan ẹni púpọ̀ kú, mélòó mélòó ni oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run, àti ẹ̀bùn nínú oore-ọ̀fẹ́ ọkùnrin kan, Jesu Kristi, di púpọ̀ fún ẹni púpọ̀.
Dar darul gratuit nu este ca și fărădelegea. Căci, dacă prin greșeala unuia singur au murit cei mulți, cu atât mai mult harul lui Dumnezeu și darul prin harul unui singur om, Isus Hristos, a abundat pentru cei mulți.
16 Kì í ṣe nípa ẹnìkan tí ó sẹ̀ ni ẹ̀bùn náà, nítorí ìdájọ́ ti ipasẹ̀ ẹnìkan wá fún ìdálẹ́bi, ṣùgbọ́n ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ ti inú ẹ̀ṣẹ̀ púpọ̀ wá fún ìdáláre.
Darul nu este ca prin unul singur care a păcătuit; căci judecata a venit prin unul singur spre osândă, dar darul gratuit a urmat multor fărădelegi spre îndreptățire.
17 Ǹjẹ́ bí o bá jẹ pé nípa ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin kan, ikú jẹ ọba nípasẹ̀ ẹnìkan náà; mélòó mélòó ni àwọn tí ń gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore-ọ̀fẹ́ àti ẹ̀bùn òdodo yóò jẹ ọba nínú ìyè nípasẹ̀ ẹnìkan, Jesu Kristi.
Căci, dacă prin fărădelegea unuia singur a domnit moartea prin unul singur, cu atât mai mult cei care primesc abundența harului și a darului neprihănirii vor domni în viață prin unul singur, Isus Hristos.
18 Ǹjẹ́ bí o bá jẹ pé nípa ẹ̀ṣẹ̀ ẹnìkan ìdájọ́ dé bá gbogbo ènìyàn sí ìdálẹ́bi; gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni nípa ìwà òdodo ẹnìkan, ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ dé sórí gbogbo ènìyàn fún ìdáláre sí ìyè.
Astfel, după cum, printr-o singură fărădelege, toți oamenii au fost condamnați, tot așa, printr-o singură faptă de dreptate, toți oamenii au fost îndreptățiți pentru viață.
19 Nítorí gẹ́gẹ́ bí nípa àìgbọ́ràn ọkùnrin kan, ènìyàn púpọ̀ di ẹlẹ́ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni nípa ìgbọ́ràn ẹnìkan, a ó sọ ènìyàn púpọ̀ di olódodo.
Căci, după cum prin neascultarea unui singur om, mulți au fost făcuți păcătoși, tot așa, prin ascultarea unuia singur, mulți vor fi făcuți neprihăniți.
20 Ṣùgbọ́n òfin bọ́ sí inú rẹ̀, kí ẹ̀ṣẹ̀ lè di púpọ̀, ṣùgbọ́n ni ibi ti ẹ̀ṣẹ̀ di púpọ̀, oore-ọ̀fẹ́ di púpọ̀ rékọjá.
Legea a venit pentru ca fărădelegea să abunde; dar acolo unde a abundat păcatul, harul a abundat și mai mult,
21 Pé, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ṣẹ̀ ti jẹ ọba nípa ikú bẹ́ẹ̀ ni kí oore-ọ̀fẹ́ sì lè jẹ ọba nípa òdodo títí ìyè àìnípẹ̀kun nípasẹ̀ Jesu Kristi Olúwa wa. (aiōnios )
pentru ca, după cum păcatul a domnit în moarte, tot așa harul să domnească prin dreptate pentru viața veșnică, prin Isus Hristos, Domnul nostru. (aiōnios )