< Romans 4 >

1 Ǹjẹ́ kín ni àwa ó ha wí nípa Abrahamu, baba wa ti o ṣàwárí èyí? Májẹ̀mú láéláé jẹ́rìí sí i wí pé, a gba Abrahamu là nípa ìgbàgbọ́.
Vad skola vi då säga om Abraham, vår stamfader efter köttet?
2 Nítorí bí a bá dá Abrahamu láre nípa iṣẹ́, ó ní ohun ìṣògo; ṣùgbọ́n kì í ṣe níwájú Ọlọ́run.
Om Abraham blev rättfärdig av gärningar, så har han ju något att berömma sig av. Dock icke inför Gud.
3 Ìwé Mímọ́ ha ti wí? “Abrahamu gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.”
Ty vad säger skriften? »Abraham trodde Gud, och det räknades honom till rättfärdighet.»
4 Ǹjẹ́ fún ẹni tí ó ṣiṣẹ́, a kò ka èrè náà sí oore-ọ̀fẹ́ bí kò ṣe sí ẹ̀tọ́ rẹ̀.
Den som håller sig till gärningar, honom bliver lönen tillräknad icke på grund av nåd, utan på grund av förtjänst.
5 Ṣùgbọ́n fún ẹni tí kò ṣiṣẹ́, tí ó sì ń gba ẹni tí ó ń dá ènìyàn búburú láre gbọ́, a ka ìgbàgbọ́ rẹ̀ sí òdodo.
Men den som icke håller sig till gärningar, utan tror på honom som gör den ogudaktige rättfärdig, honom räknas hans tro till rättfärdighet.
6 Gẹ́gẹ́ bí Dafidi pẹ̀lú ti pe olúwa rẹ̀ náà ní ẹni ìbùkún, ẹni tí Ọlọ́run ka òdodo fún láìsí ti iṣẹ́.
Så prisar ock David den människa salig, som Gud tillräknar rättfärdighet, utan gärningar:
7 Wí pé, “Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí a dárí ìrékọjá wọn jì, tí a sì bo ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀.
»Saliga äro de vilkas överträdelser äro förlåtna, och vilkas synder äro överskylda.
8 Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà ẹni tí Olúwa kò ka ẹ̀ṣẹ̀ sí lọ́rùn.”
Salig är den man som Herren icke tillräknar synd.»
9 Ìbùkún yìí ha jẹ́ ti àwọn akọlà nìkan, tàbí ti àwọn aláìkọlà pẹ̀lú? Nítorí tí a wí pé, Abrahamu gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.
Gäller nu detta ordet »salig» de omskurna allenast eller ock de oomskurna? Vi säga ju att »tron räknades Abraham till rättfärdighet».
10 Báwo ni a ṣe kà á sí i? Nígbà tí ó wà ní ìkọlà tàbí ní àìkọlà? Kì í ṣe ni ìkọlà, ṣùgbọ́n ní àìkọlà ni.
Huru blev den honom då tillräknad? Skedde det sedan han hade blivit omskuren, eller medan han ännu var oomskuren? Det skedde icke sedan han hade blivit omskuren, utan medan han ännu var oomskuren.
11 Ó sì gbé àmì ìkọlà àti èdìdì òdodo ìgbàgbọ́ tí ó ní nígbà tí ó wà ní àìkọlà kí ó lè ṣe baba gbogbo àwọn tí ó gbàgbọ́, bí a kò tilẹ̀ kọ wọ́n ní ilà kí a lè ka òdodo sí wọn pẹ̀lú.
Och han undfick omskärelsens tecken såsom ett insegel på den rättfärdighet genom tron, som han hade, medan han ännu var oomskuren. Ty så skulle han bliva en fader för alla oomskurna som tro, och så skulle rättfärdighet tillräknas dem.
12 Àti baba àwọn tí ìkọlà tí kì í ṣe pé a kàn kọlà fún nìkan, ṣùgbọ́n tiwọn ń tẹ̀lé àpẹẹrẹ ìgbàgbọ́ tí baba wa Abrahamu ní, kí a tó kọ ọ́ nílà.
Han skulle ock bliva en fader för omskurna, nämligen för sådana som icke allenast äro omskurna, utan ock vandra i spåren av den tro som vår fader Abraham hade, medan han ännu var oomskuren.
13 Ìlérí fún Abrahamu àti fún irú-ọmọ rẹ̀, ni pé, wọn ó jogún ayé, kì í ṣe nípa òfin bí kò ṣe nípa òdodo ti ìgbàgbọ́.
Det var nämligen icke genom lag som Abraham och hans säd undfick det löftet att han skulle få världen till arvedel; det var genom rättfärdighet av tro.
14 Nítorí bí àwọn tí ń ṣe ti òfin bá jẹ ajogún, ìgbàgbọ́ di asán, ìlérí sì di aláìlágbára.
Ty om de som låta det bero på lag skola få arvedelen, så är tron till intet nyttig, och löftet är gjort om intet.
15 Nítorí òfin ń ṣiṣẹ́ ìbínú, ṣùgbọ́n ní ibi tí òfin kò bá sí, ìrúfin kò sí níbẹ̀.
Vad lagen kommer åstad är ju vredesdom; men där ingen lag finnes, där finnes icke heller någon överträdelse.
16 Nítorí náà ni ó ṣe gbé e ka orí ìgbàgbọ́, kí ìlérí náà bá a lè sinmi lé oore-ọ̀fẹ́, kí a sì lè mú un dá gbogbo irú-ọmọ lójú, kì í ṣe fún àwọn tí ń pa òfin mọ́ nìkan, ṣùgbọ́n bí kò ṣe pẹ̀lú fún àwọn ti ó pín nínú ìgbàgbọ́ Abrahamu, ẹni tí í ṣe baba gbogbo wa pátápátá,
Därför måste det bero på tro, för att det skulle vara av nåd, så att löftet kunde bliva beståndande för all hans säd, icke blott för dem som hörde till lagens folk, utan ock för dem som allenast hade Abrahams tro. Han är ju allas vår fader,
17 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Mo ti fi ọ́ ṣe baba orílẹ̀-èdè púpọ̀.” Níwájú Ọlọ́run ẹni tí òun gbàgbọ́, ẹni tí ó sọ òkú di ààyè, tí ó sì pè àwọn ohun tí kò sí bí ẹni pé wọ́n wà.
enligt detta skriftens ord: »Jag har bestämt dig till att bliva en fader till många folk»; han är detta inför den Gud som han trodde, inför honom som gör de döda levande och kallar på de ting som icke äro till, likasom voro de till.
18 Nígbà tí ìrètí kò sí mọ́, Abrahamu gbàgbọ́ nínú ìrètí bẹ́ẹ̀ ni ó sì di baba orílẹ̀-èdè púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí èyí tí a wí fún un pé, “Báyìí ni irú-ọmọ rẹ̀ yóò rí.”
Och där ingen förhoppning fanns, där hoppades han ändå och trodde; och han kunde så bliva »en fader till många folk», efter vad som var förutsagt: »Så skall din säd bliva.»
19 Ẹni tí kò rẹ̀wẹ̀sì nínú ìgbàgbọ́, nígbà tí ó mọ pe ara òun tìkára rẹ̀ tí ó ti kú tan, nítorí ó tó bí ẹni ìwọ̀n ọgọ́rùn-ún ọdún, àti nígbà tí ó ro ti yíyàgàn inú Sara.
Och han försvagades icke i sin tro, när han betänkte huru hans egen kropp var såsom död -- han var ju omkring hundra år gammal -- och huru jämväl Saras moderliv var såsom dött.
20 Kò fi àìgbàgbọ́ ṣiyèméjì nípa ìlérí Ọlọ́run; ṣùgbọ́n ó lágbára sí i nínú ìgbàgbọ́ bí ó ti fi ògo fún Ọlọ́run,
Han tvivlade icke på Guds löfte i otro, utan blev fastmer starkare i sin tro; ty han ärade Gud
21 pẹ̀lú ìdánilójú kíkún pé, Ọlọ́run lè ṣe ohun tí ó ti ṣe ìlérí rẹ̀.
och var fullt viss om att vad Gud hade lovat, det var han också mäktig att hålla.
22 Nítorí náà ni a sì ṣe kà á sí òdodo fún un.
Därför räknades det honom ock till rättfärdighet.
23 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ náà, “A kà á sí òdodo fún un,” ni a kọ kì í ṣe nítorí tirẹ̀ nìkan.
Men att det så tillräknades honom, det är skrivet icke såsom gällde det allenast honom,
24 Ṣùgbọ́n nítorí tiwa pẹ̀lú. A ó sì kà á sí fún wa, bí àwa bá gba ẹni tí ó gbé Jesu Olúwa wa dìde kúrò nínú òkú gbọ́.
utan det skulle gälla också oss; ty det skall tillräknas jämväl oss, oss som tro på honom som från de döda uppväckte Jesus, vår Herre,
25 Ẹni tí a pa fún ẹ̀ṣẹ̀ wa, tí a sì jí dìde nítorí ìdáláre wa.
vilken utgavs för våra synders skull och uppväcktes för vår rättfärdiggörelses skull.

< Romans 4 >