< Romans 3 >

1 Ǹjẹ́ àǹfààní wo ní Júù ní? Tàbí kín ni èrè ilà kíkọ?
Quel est donc l’avantage du juif, ou quelle est l'utilité de la circoncision?
2 Púpọ̀ lọ́nà gbogbo; pàtàkì jùlọ ni pé àwọn ni a fi ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lé lọ́wọ́.
— Cet avantage est grand à tous égards: d'abord, parce que les oracles de Dieu leur ont été confiés?
3 Ǹjẹ́ kí ha ni bí àwọn kan jẹ́ aláìgbàgbọ́? Àìgbàgbọ́ wọn yóò ha sọ òtítọ́ Ọlọ́run di asán bí?
Car, qu'est-ce à dire? Si quelques-uns n'ont pas cru, leur incrédulité annulera-t-elle la fidélité de Dieu?
4 Kí a má rí! Kí Ọlọ́run jẹ́ olóòtítọ́, àti olúkúlùkù ènìyàn jẹ́ èké; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Kí a lè dá ọ láre nínú ọ̀rọ̀ rẹ, ṣùgbọ́n kí ìwọ lè borí nígbà tí ìwọ bá wá sí ìdájọ́.”
— Loin de nous cette pensée! mais plutôt que Dieu soit reconnu pour vrai — et tout homme pour menteur — «de sorte, comme il est écrit, que tu sois reconnu juste dans tes paroles, et que tu triomphes, quand on te juge.»
5 Ṣùgbọ́n bí àìṣòdodo wa bá fi òdodo Ọlọ́run hàn, kín ni àwa ó wí? Ọlọ́run ha jẹ́ àìṣòdodo bí, nígbà tí ó bá ń fi ìbínú rẹ̀ hàn? (Mo fi ṣe àkàwé bí ènìyàn.)
Mais si notre incrédulité fait éclater la justice de Dieu, que dirons-nous? Dieu n'est-il pas injuste en nous punissant? (Je parle comme font les hommes.) —
6 Kí a má rí i. Bí bẹ́ẹ̀ bá ni, Ọlọ́run yóò ha ṣe lè dájọ́ aráyé?
Non, certes; autrement, comment Dieu jugerait-il le monde?
7 Nítorí bí òtítọ́ Ọlọ́run bá di púpọ̀ sí ìyìn rẹ̀ nítorí èké mi, èéṣe tí a fi ń dá mi lẹ́jọ́ bí ẹlẹ́ṣẹ̀?
Car, dirait-on, si la véracité de Dieu a été rehaussée, à sa gloire, par mon mensonge, pourquoi, moi aussi, suis-je encore jugé comme pécheur?
8 Èéṣe tí a kò fi ṣe búburú kí rere lè jáde wá? Bí àwọn kan tí ń fi ẹnu àtẹ́ sọ wí pé a ń sọ bẹ́ẹ̀; ti àwọn kan sì ń tẹnumọ́ ọn pé a sọ; àwọn ẹni tí ìdálẹ́bi wọn tọ́.
et même (comme quelques personnes, qui nous calomnient, nous accusent de le dire) ne ferons-nous pas le mal, pour qu'il en arrive du bien? — La condamnation de ces gens est juste.
9 Ǹjẹ́ kí ha ni? Àwa ha sàn ju wọn lọ bí? Kò rí bẹ́ẹ̀ rárá, nítorí a fihàn ṣáájú pé àti àwọn Júù àti àwọn Giriki, gbogbo wọn ni ó wà lábẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
Quoi donc? Avons-nous quelque supériorité? — Non, aucune; car nous avons prouvé que tous, tant Juifs que Grecs, sont sous l'empire du péché,
10 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Kò sí ẹni tí í ṣe olódodo, kò sí ẹnìkan,
ainsi qu'il est écrit: «Il n'y a point de juste, pas même un seul;
11 kò sí ẹni tí òye yé, kò sí ẹni tí ó ń wá Ọlọ́run.
il n'y a point d'homme qui ait de l’intelligence; il n'y en a point qui cherche Dieu.
12 Gbogbo wọn ni ó ti yapa, wọ́n jùmọ̀ di aláìlérè; kò sí ẹni tí ń ṣe rere, kò tilẹ̀ sí ẹnìkan.”
Tous se sont dévoyés, ils se sont tous ensemble corrompus. Il n'y en a point qui fasse le bien, pas même un seul.
13 “Ibojì tí ó ṣí sílẹ̀ ní ọ̀fun wọn: ahọ́n wọn n sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.” “Oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ lábẹ́ ètè wọn.”
Leur gosier est un sépulcre béant, leur langue est trompeuse; le venin de l'aspic est sur leurs lèvres;
14 “Ẹnu ẹni tí ó kún fún èpè àti fún oró kíkorò.”
leur bouche est pleine de malédiction et d'amertume.
15 “Ẹsẹ̀ wọn yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀,
Ils ont pied léger pour répandre le sang;
16 ìparun àti ìpọ́njú wà lọ́nà wọn.
la désolation et la misère sont dans leurs voies.
17 Ọ̀nà àlàáfíà ni wọn kò sì mọ̀,”
Ils ne connaissent point le chemin de la paix.
18 “Ìbẹ̀rù Ọlọ́run kò sí níwájú wọn.”
Ils n'ont point la crainte de Dieu devant les yeux.»
19 Àwa sì mọ̀ pé ohunkóhun tí òfin bá wí, ó ń wí fún àwọn tí ó wà lábẹ́ òfin: kí gbogbo ẹnu bá à lè dákẹ́ àti kí a lè mú gbogbo aráyé wá sábẹ́ ìdájọ́ Ọlọ́run.
Or nous savons que tout ce que la loi dit, elle l'adresse à ceux qui sont sous la loi, afin que toute bouche soit fermée, et que le monde entier soit sous le coup de la justice de Dieu;
20 Nítorí pé nípa iṣẹ́ òfin, a kì yóò dá ẹnikẹ́ni láre níwájú rẹ̀: nítorí nípa òfin ni ìmọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ ti wá.
attendu que nul ne sera justifié devant lui par les oeuvres de la loi, car la loi ne fait que donner la connaissance du péché.
21 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, a ti fi òdodo Ọlọ́run hàn láìsí òfin, tí a ti ń jẹ́rìí sí nípa òfin àti nípa àwọn wòlíì,
Mais voici, la justice qui vient de Dieu a été manifestée indépendamment de toute loi (la Loi et les Prophètes lui rendent témoignage),
22 àní òdodo Ọlọ́run nípa ìgbàgbọ́ nínú Jesu Kristi, sí gbogbo ènìyàn àti gbogbo àwọn tí ó gbàgbọ́, nítorí tí kò sí ìyàtọ̀ láàrín Júù àti Helleni.
la justice, dis-je, qui vient de Dieu par la foi en Jésus-Christ, pour tous et sur tous ceux qui ont la foi, indistinctement,
23 Gbogbo ènìyàn ni ó ṣá ti ṣẹ̀, tí wọ́n sì kùnà ògo Ọlọ́run,
car tous ont péché et sont privés de la gloire de Dieu.
24 àwọn ẹni tí a ń dá láre lọ́fẹ̀ẹ́ nípa oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀, nípa ìdáǹdè tí ó wà nínú Kristi Jesu.
Puisque nous sommes justifiés gratuitement, par la grâce de Dieu, au moyen du pardon qui est en Jésus-Christ
25 Ẹni tí Ọlọ́run ti gbé kalẹ̀ láti jẹ́ ètùtù nípa ìgbàgbọ́ nípa ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, láti fi òdodo rẹ̀ hàn nítorí ìdáríjì àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti kọjá, nínú ìpamọ́ra Ọlọ́run,
— qui devait être, d'après le conseil de Dieu, une victime propitiatoire, par la foi en son sang, pour faire voir la justice qui vient de Lui, parce qu'il avait passé aux hommes leurs péchés commis précédemment, au temps de sa patience,
26 láti fi òdodo rẹ̀ hàn ní ìgbà ìsinsin yìí: kí ó lè jẹ́ olódodo àti olùdáláre ẹni tí ó gba Jesu gbọ́.
pour faire voir, dis-je, à cette époque-ci, la justice qui vient de Lui, en sorte qu'il est tout ensemble juste et justifiant celui qui a la foi —
27 Ọ̀nà ìṣògo dà? A ti mú un kúrò. Nípa òfin wo? Nípa iṣẹ́? Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n nípa òfin ìgbàgbọ́.
y a-t-il donc là sujet de se glorifier? Toute glorification est exclue. Par quel principe? celui des oeuvres? — Non, mais par le principe de la foi;
28 Nítorí náà, a parí rẹ̀ sí pé nípa ìgbàgbọ́ ni a ń dá ènìyàn láre láìsí iṣẹ́ òfin.
car nous estimons que l'homme est justifié par la foi, indépendamment des oeuvres de la loi.
29 Ọlọ́run àwọn Júù nìkan ha ni bí? Kì í ha ṣe ti àwọn aláìkọlà pẹ̀lú? Bẹ́ẹ̀ ni, ti àwọn aláìkọlà pẹ̀lú.
Dieu est-il seulement le Dieu des Juifs? N'est-il pas aussi le Dieu des Gentils? — Oui, il est aussi le Dieu des Gentils,
30 Bí ó ti jẹ́ pé Ọlọ́run kan ni, yóò dá àwọn akọlà láre nípa ìgbàgbọ́ àti àwọn aláìkọlà nípa ìgbàgbọ́ wọn.
puisqu'il y a un seul Dieu, qui justifiera par la foi le circoncis et l'incirconcis.
31 Àwa ha ń sọ òfin dasán nípa ìgbàgbọ́ bí? Kí a má rí i, ṣùgbọ́n a ń fi òfin múlẹ̀.
Annulons-nous donc la Loi par la foi?— Loin de là; nous la confirmons au contraire.

< Romans 3 >