< Romans 2 >
1 Nítorí náà, aláìríwí ni ẹnikẹ́ni tí ó wù kí ó jẹ́ tí ń dá ni lẹ́jọ́, nítorí nínú ohun tí ìwọ ń ṣe ìdájọ́ ẹlòmíràn, ìwọ ń dá ara rẹ lẹ́bi; nítorí ìwọ tí ń dájọ́ ń ṣe ohun kan náà nínú èyí tí ìwọ ń dá ni lẹ́jọ́.
Przetoż jesteś bez wymówki, o człowiecze! który osądzasz; bo w czem drugiego osądzasz, samego siebie osądzasz, ponieważ toż czynisz, który drugiego osądzasz.
2 Ṣùgbọ́n àwa mọ̀ pé ìdájọ́ Ọlọ́run jẹ́ òtítọ́ si gbogbo àwọn tí ó ń ṣe irú ohun báwọ̀nyí.
Lecz wiemy, iż sąd Boży jest według prawdy przeciwko tym, którzy takowe rzeczy czynią.
3 Nítorí bí ìwọ tí ń ṣe ènìyàn lásán bá ń ṣe ìdájọ́ àwọn tí ń ṣe irú ohun báwọ̀nyí, tí ìwọ tìkára rẹ ń ṣe bẹ́ẹ̀, ìwọ ro èyí pé ìwọ o yọ nínú ìdájọ́ Ọlọ́run bí?
Czy mniemasz, o człowiecze! który osądzasz tych, co takowe rzeczy czynią, a sam je czynisz, że ty ujdziesz sądu Bożego?
4 Tàbí ìwọ ń gàn ọrọ̀ oore àti ìpamọ́ra àti sùúrù rẹ̀? Ìwọ kò ha mọ̀ pé oore Ọlọ́run ni ó ń fà ọ́ lọ sì ìrònúpìwàdà?
Czy bogactwy dobrotliwości jego i cierpliwości, i nieskwapliwości pogardzasz, nie wiedząc, iż cię dobrotliwość Boża do pokuty prowadzi?
5 Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí líle àti àìronúpìwàdà ọkàn rẹ̀, ìwọ ń to ìbínú jọ fún ara rẹ de ọjọ́ ìbínú àti ìfihàn ìdájọ́ òdodo Ọlọ́run.
Ale podług zatwardziałości twojej i serca niepokutującego skarbisz sobie samemu gniew na dzień gniewu i objawienia sprawiedliwego sądu Bożego.
6 Ọlọ́run yóò san án fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀.
Który odda każdemu podług uczynków jego;
7 Àwọn ẹni tí ń fi sùúrù nínú rere ṣíṣe, wá ògo àti ọlá àti àìdíbàjẹ́ ni yóò fi ìyè àìnípẹ̀kun fún. (aiōnios )
Tym, którzy przez wytrwanie w uczynku dobrym szukają sławy i czci i nieskazitelności, odda żywot wieczny; (aiōnios )
8 Ṣùgbọ́n fún àwọn onímọ̀-tara-ẹni-nìkan, tí wọn kò sì gba òtítọ́ gbọ́, ṣùgbọ́n tí wọn ń tẹ̀lé ọ̀nà búburú, wọn yóò ní ìrírí ìrunú àti ìbínú rẹ̀.
A zaś swarliwym i prawdzie nieposłusznym, lecz posłusznym niesprawiedliwości, odda zapalczywość i gniew;
9 Ìpọ́njú àti ìrora, yóò wà lórí olúkúlùkù ọkàn ènìyàn tí ń hùwà ibi: ti Júù ṣáájú, àti àwọn Helleni pẹ̀lú;
Utrapienie i ucisk duszy każdego człowieka, który złość popełnia, Żyda najprzód, potem i Greka;
10 ṣùgbọ́n ògo, àti ọlá, àti àlàáfíà, fún olúkúlùkù ẹni tí ń hùwà rere, fún Júù, ṣáájú àti fún àwọn Helleni pẹ̀lú.
A chwałę i cześć, i pokój wszelkiemu czyniącemu dobre, Żydowi najprzód, potem i Grekowi.
11 Nítorí Ọlọ́run kì í ṣe ojúsàájú ènìyàn.
Albowiem nie masz względu na osoby u Boga.
12 Gbogbo àwọn tí ó ṣẹ̀ ní àìlófin wọn ó sì ṣègbé láìlófin, àti iye àwọn tí ó ṣẹ̀ lábẹ́ òfin, àwọn ni a ó fi òfin dá lẹ́jọ́.
A którzykolwiek bez zakonu zgrzeszyli, bez zakonu też poginą; a którzykolwiek w zakonie zgrzeszyli, przez zakon sądzeni będą.
13 Nítorí kì í ṣe àwọn olùgbọ́ òfin ni ẹni ìdáláre lọ́dọ̀ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n àwọn olùṣe òfin ni a ó dá láre.
(Gdyż nie słuchacze zakonu sprawiedliwymi są u Boga; ale czyniciele zakonu usprawiedliwieni będą.)
14 Nítorí nígbà tí àwọn aláìkọlà, tí kò ní òfin, bá ṣe ohun tí ó wà nínú òfin nípa ìwà ẹ̀dá, àwọn wọ̀nyí, jẹ́ òfin fún ara wọn bí wọn kò tilẹ̀ ní òfin.
Bo ponieważ poganie nie mający zakonu, z przyrodzenia czynią, co jest w zakonie, ci, zakonu nie mając, sami sobie są zakonem;
15 Àwọn ẹni tí ó fihàn pé, a kọ̀wé iṣẹ́ òfin sí wọn lọ́kàn, tí ẹ̀rí ọkàn wọn pẹ̀lú sì tún ń jẹ́ wọn lẹ́rìí, àti pé, èrò ọkàn wọn tí ó jẹ́ ọ̀nà ìfinisùn, sì ń gbè wọ́n lẹ́yìn ní ìsinsin yìí.
Którzy ukazują skutek zakonu, napisany na sercach swych, z poświadczaniem sumienia ich i myśli wespół siebie oskarżających albo też wymawiających,
16 Èyí yóò farahàn ní ọjọ́ náà nígbà tí Ọlọ́run yóò tipasẹ̀ Jesu Kristi ṣe ìdájọ́ àwọn àṣírí ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ìyìnrere mi.
W dzień, gdy sądzić będzie Bóg skryte rzeczy ludzkie według Ewangielii mojej przez Jezusa Chrystusa.
17 Ṣùgbọ́n bí a bá ń pe ìwọ ní Júù, tí o sì sinmi lé òfin, tí o sì ń ṣògo nínú ìbálòpọ̀ rẹ̀ sí Ọlọ́run,
Oto się ty nazywasz Żydem i polegasz na zakonie, a chlubisz się Bogiem.
18 tí o sì mọ ìfẹ́ rẹ̀, tí o sì fọwọ́sí ohun tí ó dára jùlọ, nítorí tí a ti kọ́ ọ ní òfin;
I znasz wolę jego i rozeznajesz rzeczy różne od niej, wyćwiczony będąc z zakonu;
19 tí o sì dá ara rẹ lójú pé ìwọ ni amọ̀nà àwọn afọ́jú, ìmọ́lẹ̀ fún àwọn tí ó wà ni òkùnkùn,
I masz za to, żeś jest wodzem ślepych, światłością tych, którzy są w ciemności;
20 Olùkọ́ àwọn aláìmòye, olùkọ́ àwọn ọmọdé, ẹni tí ó ní ètò ìmọ̀ àti òtítọ́ òfin lọ́wọ́.
Mistrzem bezrozumnych, nauczycielem niemowlątek, mając kształt znajomości i prawdy w zakonie.
21 Ǹjẹ́ ìwọ tí o ń kọ́ ẹlòmíràn, ìwọ kò kọ́ ara rẹ? Ìwọ tí ó ń wàásù kí ènìyàn má jalè, ìwọ ha ń jalè bí?
Który tedy uczysz drugiego, siebie samego nie uczysz? Który opowiadasz, żeby nie kradziono, kradniesz?
22 Ìwọ tí o wí pé, kí ènìyàn má ṣe panṣágà, ìwọ ń ṣe panṣágà bí? Ìwọ tí o kórìíra òrìṣà, ìwọ ń ja tẹmpili ní olè bí?
Który mówisz, żeby nie cudzołożono, cudzołożysz? który się brzydzisz bałwany, święte rzeczy kradniesz?
23 Ìwọ ti ń ṣògo nínú òfin, ìwọ ha ń bu Ọlọ́run ni ọlá kù nípa rírú òfin?
Który się chlubisz zakonem, przez przestępstwo zakonu Boga lżysz?
24 Nítorí gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́, “Orúkọ Ọlọ́run sá à di ìsọ̀rọ̀-òdì sí láàrín àwọn aláìkọlà nítorí yín.”
Albowiem imię Boże dla was bluźnione bywa między pogany, jako napisano.
25 Nítorí ìkọlà ní èrè nítòótọ́, bí ìwọ bá pa òfin mọ́; ṣùgbọ́n bí ìwọ bá jẹ́ arúfin, ìkọlà rẹ di àìkọlà.
Boć obrzezanie jest pożyteczne, jeźlibyś pełnił zakon; ale jeźlibyś był przestępcą zakonu, twoje obrzezanie stało się nieobrzezką.
26 Nítorí náà bí àwọn aláìkọlà bá pa ìlànà òfin mọ́, a kì yóò ha kà wọ́n sí àwọn tí a kọ nílà bí?
Jeźliby tedy nieobrzezka przestrzegała praw zakonnych, azaż jego nieobrzezka nie będzie przyczyną za obrzezkę?
27 Aláìkọlà nípa àdánidá, bí ó bá pa òfin mọ́, yóò dá ẹ̀bi fún ìwọ tí ó jẹ́ arúfin nípa ti àkọsílẹ̀ òfin àti ìkọlà.
I osądzi nieobrzezka z przyrodzenia zakon pełniąca ciebie, który przez literę i obrzezkę jesteś przestępcą zakonu.
28 Kì í ṣe èyí tí ó farahàn ní òde ni Júù, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe èyí tí ó farahàn ní ara ni ìkọlà.
Albowiem nie ten jest Żydem, który jest Żydem na jawie, ani to jest obrzezka, która jest na jawie na ciele;
29 Ṣùgbọ́n Júù ti inú ni Júù, àti ìkọlà sì ni ti ọkàn nínú ẹ̀mí tí kì í ṣe ti àkọsílẹ̀, ìyìn ẹni tí kò sí lọ́dọ̀ ènìyàn, bí kò ṣe lọ́dọ̀ Ọlọ́run.
Ale który jest w skrytości Żydem i obrzezka serca, która jest w duchu, nie w literze, której chwała nie jest z ludzi, ale z Boga.