< Romans 2 >

1 Nítorí náà, aláìríwí ni ẹnikẹ́ni tí ó wù kí ó jẹ́ tí ń dá ni lẹ́jọ́, nítorí nínú ohun tí ìwọ ń ṣe ìdájọ́ ẹlòmíràn, ìwọ ń dá ara rẹ lẹ́bi; nítorí ìwọ tí ń dájọ́ ń ṣe ohun kan náà nínú èyí tí ìwọ ń dá ni lẹ́jọ́.
Selv om Gud en dag vil straffe menneskene, har du ingen rett til å dømme andre, hvem du enn er. Om du dømmer en annen for det han gjør, da dømmer du jo samtidig deg selv, etter som du handler på samme måten som han. Det finnes ingen unnskyldning for deg som dømmer!
2 Ṣùgbọ́n àwa mọ̀ pé ìdájọ́ Ọlọ́run jẹ́ òtítọ́ si gbogbo àwọn tí ó ń ṣe irú ohun báwọ̀nyí.
Vi vet at Gud har rett når han dømmer dem som lever på denne måten.
3 Nítorí bí ìwọ tí ń ṣe ènìyàn lásán bá ń ṣe ìdájọ́ àwọn tí ń ṣe irú ohun báwọ̀nyí, tí ìwọ tìkára rẹ ń ṣe bẹ́ẹ̀, ìwọ ro èyí pé ìwọ o yọ nínú ìdájọ́ Ọlọ́run bí?
Men du som dømmer dine medmennesker, du tror vel ikke at Gud bare skal dømme de andre, og ha overbærenhet med deg når du handler på samme måten?
4 Tàbí ìwọ ń gàn ọrọ̀ oore àti ìpamọ́ra àti sùúrù rẹ̀? Ìwọ kò ha mọ̀ pé oore Ọlọ́run ni ó ń fà ọ́ lọ sì ìrònúpìwàdà?
Du skal ikke undervurdere Gud, når han på grunn av sin godhet og sin tålmodighet ikke straffer deg! Innser du ikke at han ved sin godhet vil få deg til å vende om til ham?
5 Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí líle àti àìronúpìwàdà ọkàn rẹ̀, ìwọ ń to ìbínú jọ fún ara rẹ de ọjọ́ ìbínú àti ìfihàn ìdájọ́ òdodo Ọlọ́run.
Dersom du gjenstridig nekter å vende om til Gud, da gjør du din straff verre på dommens dag, for på den dagen skal det vise seg at Gud dømmer alle rettferdig.
6 Ọlọ́run yóò san án fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀.
Da skal hver og en få lønn etter sine gjerninger.
7 Àwọn ẹni tí ń fi sùúrù nínú rere ṣíṣe, wá ògo àti ọlá àti àìdíbàjẹ́ ni yóò fi ìyè àìnípẹ̀kun fún. (aiōnios g166)
Gud skal gi evig liv til dem som uten å bli trette fortsetter å gjøre det gode og søker herlighet, ære og udødelighet sammen med Gud. (aiōnios g166)
8 Ṣùgbọ́n fún àwọn onímọ̀-tara-ẹni-nìkan, tí wọn kò sì gba òtítọ́ gbọ́, ṣùgbọ́n tí wọn ń tẹ̀lé ọ̀nà búburú, wọn yóò ní ìrírí ìrunú àti ìbínú rẹ̀.
Men han skal i sitt sinne straffe dem som bare tenker på seg selv, og som i stedet for å gjøre det som er rett, lever i ondskap.
9 Ìpọ́njú àti ìrora, yóò wà lórí olúkúlùkù ọkàn ènìyàn tí ń hùwà ibi: ti Júù ṣáájú, àti àwọn Helleni pẹ̀lú;
Nød og angst skal ramme hvert mennesker som gjør det onde. Dette gjelder jødene, som først fikk høre Guds budskap, men også alle andre folk.
10 ṣùgbọ́n ògo, àti ọlá, àti àlàáfíà, fún olúkúlùkù ẹni tí ń hùwà rere, fún Júù, ṣáájú àti fún àwọn Helleni pẹ̀lú.
På samme måten skal herlighet, ære og fred bli gitt til hver og en som gjør det gode. Det skal bli gitt til jødene, som først fikk høre Guds budskap, men også til alle andre folk.
11 Nítorí Ọlọ́run kì í ṣe ojúsàájú ènìyàn.
Gud behandler alle likt.
12 Gbogbo àwọn tí ó ṣẹ̀ ní àìlófin wọn ó sì ṣègbé láìlófin, àti iye àwọn tí ó ṣẹ̀ lábẹ́ òfin, àwọn ni a ó fi òfin dá lẹ́jọ́.
Gud skal straffe alle folk for syndene deres, også om de ikke kjenner til Moseloven som Gud ga til jødene. Men han skal også straffe jødene for syndene deres, etter som de har fått loven.
13 Nítorí kì í ṣe àwọn olùgbọ́ òfin ni ẹni ìdáláre lọ́dọ̀ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n àwọn olùṣe òfin ni a ó dá láre.
Det rekker nemlig ikke å bare kjenne teoretisk til loven for å bli skyldfri innfor Gud. Vi må også følge den.
14 Nítorí nígbà tí àwọn aláìkọlà, tí kò ní òfin, bá ṣe ohun tí ó wà nínú òfin nípa ìwà ẹ̀dá, àwọn wọ̀nyí, jẹ́ òfin fún ara wọn bí wọn kò tilẹ̀ ní òfin.
Bare jødene har fått Guds lov skriftlig. Men når andre folk, uten å kjenne til loven, likevel lyder det som står i den, da forstår vi at de vet forskjell på godt og ondt.
15 Àwọn ẹni tí ó fihàn pé, a kọ̀wé iṣẹ́ òfin sí wọn lọ́kàn, tí ẹ̀rí ọkàn wọn pẹ̀lú sì tún ń jẹ́ wọn lẹ́rìí, àti pé, èrò ọkàn wọn tí ó jẹ́ ọ̀nà ìfinisùn, sì ń gbè wọ́n lẹ́yìn ní ìsinsin yìí.
De viser ved handlingene sine at loven er skrevet i hjertene deres. Deres samvittighet reagerer alt etter om de handler rett eller galt.
16 Èyí yóò farahàn ní ọjọ́ náà nígbà tí Ọlọ́run yóò tipasẹ̀ Jesu Kristi ṣe ìdájọ́ àwọn àṣírí ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ìyìnrere mi.
At det er slik, vil vise seg den dagen da Jesus Kristus på Guds befaling skal dømme oss alle etter våre innerste tanker og motiv. Dette er det budskapet jeg har fått fra Gud.
17 Ṣùgbọ́n bí a bá ń pe ìwọ ní Júù, tí o sì sinmi lé òfin, tí o sì ń ṣògo nínú ìbálòpọ̀ rẹ̀ sí Ọlọ́run,
Dere som er jøder, stoler på den loven dere har fått fra Gud. Dere er stolte over det spesielle forholdet dere har til ham.
18 tí o sì mọ ìfẹ́ rẹ̀, tí o sì fọwọ́sí ohun tí ó dára jùlọ, nítorí tí a ti kọ́ ọ ní òfin;
Dere sier at dere kjenner Guds vilje og vet hvordan alle bør handle, etter som dere har fått lære dere det som står i Moseloven.
19 tí o sì dá ara rẹ lójú pé ìwọ ni amọ̀nà àwọn afọ́jú, ìmọ́lẹ̀ fún àwọn tí ó wà ni òkùnkùn,
Dere sier at dere kan peke ut Guds vei for de blinde og være et lys for dem som lever i åndelig mørke.
20 Olùkọ́ àwọn aláìmòye, olùkọ́ àwọn ọmọdé, ẹni tí ó ní ètò ìmọ̀ àti òtítọ́ òfin lọ́wọ́.
Dere vil veilede uforstandige og undervise de umodne. Deres tro på loven har gitt dere den fullkomne kunnskapen om det som er rett og galt.
21 Ǹjẹ́ ìwọ tí o ń kọ́ ẹlòmíràn, ìwọ kò kọ́ ara rẹ? Ìwọ tí ó ń wàásù kí ènìyàn má jalè, ìwọ ha ń jalè bí?
Ja, dere underviser andre, men ikke dere selv! Dere sier til andre at de ikke skal stjele, men dere er selv tyver.
22 Ìwọ tí o wí pé, kí ènìyàn má ṣe panṣágà, ìwọ ń ṣe panṣágà bí? Ìwọ tí o kórìíra òrìṣà, ìwọ ń ja tẹmpili ní olè bí?
Dere sier at det er galt å være utro i ekteskapet, men dere er selv utro. Dere sier at de ikke skal tilbe avguder, men dere plyndrer avgudstemplene for å tjene penger.
23 Ìwọ ti ń ṣògo nínú òfin, ìwọ ha ń bu Ọlọ́run ni ọlá kù nípa rírú òfin?
Dere er stolte over å ha Moseloven, men bringer skam over Gud ved å bryte den.
24 Nítorí gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́, “Orúkọ Ọlọ́run sá à di ìsọ̀rọ̀-òdì sí láàrín àwọn aláìkọlà nítorí yín.”
Det står i Skriften:”Andre folk håner Gud på grunn av dere.”
25 Nítorí ìkọlà ní èrè nítòótọ́, bí ìwọ bá pa òfin mọ́; ṣùgbọ́n bí ìwọ bá jẹ́ arúfin, ìkọlà rẹ di àìkọlà.
Dere jøder som tror dere holder paktene med Gud ved å omskjære sønnene deres, dere har bare nytte av denne seremonien dersom dere samtidig lyder hele Moseloven. Dersom dere ikke gjør det, da er dere ikke noe bedre enn andre folk, som ikke omskjærer sønnene sine.
26 Nítorí náà bí àwọn aláìkọlà bá pa ìlànà òfin mọ́, a kì yóò ha kà wọ́n sí àwọn tí a kọ nílà bí?
Om noen fra et annet folk lyder loven, skulle ikke da den personen få det privilegiet å tilhøre Guds eget folk?
27 Aláìkọlà nípa àdánidá, bí ó bá pa òfin mọ́, yóò dá ẹ̀bi fún ìwọ tí ó jẹ́ arúfin nípa ti àkọsílẹ̀ òfin àti ìkọlà.
Jo, og på dommens dag skal de som ikke er omskåret rent fysisk, men likevel følger loven, anklage dere jøder, dere som omskjærer sønnene deres og har fått loven, men ikke følger den.
28 Kì í ṣe èyí tí ó farahàn ní òde ni Júù, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe èyí tí ó farahàn ní ara ni ìkọlà.
Alle som kaller seg jøder, tilhører altså ikke Guds eget folk. Det har ikke noe med den fysiske omskjærelsen å gjøre.
29 Ṣùgbọ́n Júù ti inú ni Júù, àti ìkọlà sì ni ti ọkàn nínú ẹ̀mí tí kì í ṣe ti àkọsílẹ̀, ìyìn ẹni tí kò sí lọ́dọ̀ ènìyàn, bí kò ṣe lọ́dọ̀ Ọlọ́run.
Nei, den som vil tilhøre Guds eget folk, må ha et rett forhold til Gud. Det virkelige tegnet på dem som tilhører Guds folk, altså den virkelige omskjærelsen, er ikke det bokstavelige, fysiske inngrepet som Moseloven beskriver, men det handler om at Guds Ånd får forvandle hjertet. Og den som har gjennomgått en slik forvandling, blir æret av Gud, ikke av mennesker.

< Romans 2 >