< Romans 14 >

1 Ẹ gba ẹni tí ó bá ṣe àìlera ní ìgbàgbọ́ mọ́ra, kí ẹ má ṣe tọpinpin ìṣeyèméjì rẹ̀.
ⲁ̅ⲠⲈⲦϢⲰⲚⲒ ϦⲈⲚⲪⲚⲀϨϮ ϢⲞⲠϤ ⲈⲢⲰⲦⲈⲚ ϦⲈⲚϨⲀⲚϨⲒⲞⲒ ⲀⲚ ⲚⲦⲈϨⲀⲚⲘⲞⲔⲘⲈⲔ.
2 Ẹnìkan gbàgbọ́ pé òun lè máa jẹ ohun gbogbo: ṣùgbọ́n ẹlòmíràn tí ó sì jẹ́ aláìlera ní ìgbàgbọ́ ń jẹ ewébẹ̀ nìkan.
ⲃ̅ⲞⲨⲞⲚ ⲠⲈⲐⲚⲀϨϮ ⲘⲈⲚ ⲈⲞⲨⲈⲘ ⲈⲚⲬⲀⲒ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲠⲈⲦϢⲰⲚⲒ ⲆⲈ ϢⲀϤⲞⲨⲈⲘ ⲞⲨⲞϮ.
3 Kí ẹni tí ń jẹ ohun gbogbo má ṣe kẹ́gàn ẹni tí kò jẹ; kí ẹni tí kò sì jẹ ohun gbogbo kí ó má ṣe dá ẹni tí ń jẹ lẹ́bi nítorí Ọlọ́run ti gbà á.
ⲅ̅ⲪⲎ ⲈⲐⲞⲨⲰⲘ ⲘⲠⲈⲚⲐⲢⲈϤϢⲈϢϤ ⲪⲎ ⲈⲦⲈⲚϤⲞⲨⲰⲘ ⲀⲚ ⲪⲎ ⲈⲦⲈⲚϤⲞⲨⲰⲘ ⲀⲚ ⲘⲠⲈⲚⲐⲢⲈϤϮ ϨⲀⲠ ⲈⲠⲈⲐⲞⲨⲰⲘ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲄⲀⲢ ⲀϤϢⲞⲠϤ ⲈⲢⲞϤ.
4 Ta ni ìwọ láti dá ọmọ ọ̀dọ̀ ẹlòmíràn lẹ́jọ́? Lójú olúwa tirẹ̀ ni òun dúró, tàbí ṣubú. Òun yóò sì dúró nítorí Ọlọ́run ní agbára láti mú kí òun dúró.
ⲇ̅ⲚⲐⲞⲔ ⲚⲒⲘ ⲚⲐⲞⲔ ⲪⲎ ⲈⲦϮϨⲀⲠ ⲈⲞⲨⲂⲰⲔ ⲚϢⲈⲘⲘⲞ ⲈϤⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦϤ ⲈⲠⲈϤϬⲞⲒⲤ ⲒⲈ ⲈϤⲚⲀϨⲈⲒ ⲈϤⲞϨⲒ ⲆⲈ ⲈⲢⲀⲦϤ ⲞⲨⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲘⲠϬⲞⲒⲤ ⲈⲦⲀϨⲞϤ ⲈⲢⲀⲦϤ.
5 Ẹnìkan bu ọlá fún ọjọ́ kan ju òmíràn; ẹlòmíràn bu ọlá fún ọjọ́ gbogbo bákan náà. Kí olúkúlùkù kí ó dá ara rẹ̀ lójú ní inú ara rẹ̀.
ⲉ̅ⲞⲨⲞⲚ ⲠⲈϮϨⲀⲠ ⲄⲀⲢ ⲘⲈⲚ ⲚⲈϨⲞⲞⲨ ϦⲀⲦϨⲎ ⲚⲈϨⲞⲞⲨ ⲞⲨⲞⲚ ⲠⲈⲦϮϨⲀⲠ ⲆⲈ ⲚⲈϨⲞⲞⲨ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲘⲀⲢⲈϤⲐⲰⲦ ⲚϨⲎⲦ ϦⲈⲚⲠⲈϤϨⲎⲦ ⲘⲘⲒⲚ ⲘⲘⲞϤ.
6 Ẹni tí ó bá ya ọjọ́ kan sí ọ̀tọ̀, ó ń yà á sọ́tọ̀ fún Olúwa. Ẹni tí ó ń jẹ ẹran, ó ń jẹ ẹran fún Olúwa, nítorí pé òun náà dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run; ẹni tí kò bá sì jẹ ẹran, kò jẹ ẹran fún Olúwa, òun náà dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run.
ⲋ̅ⲪⲎ ⲈⲐⲘⲈⲨⲒ ⲈⲠⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲀϤⲘⲈⲨⲒ ⲈⲠϬⲞⲒⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈⲐⲞⲨⲰⲘ ⲀϤⲞⲨⲰⲘ ⲘⲠϬⲞⲒⲤ ϤϢⲈⲠϨⲘⲞⲦ ⲄⲀⲢ ⲚⲦⲈⲚ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲞⲨⲞϨ ⲪⲎ ⲈⲦⲈⲚϤⲞⲨⲰⲘ ⲀⲚ ϤⲞⲨⲰⲘ ⲀⲚ ⲘⲠϬⲞⲒⲤ ⲞⲨⲞϨ ϤϢⲈⲠϨⲘⲞⲦ ⲚⲦⲈⲚ ⲪⲚⲞⲨϮ.
7 Nítorí kò sí ẹnìkan tí ó wà láààyè fún ara rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí ó kú fún ara rẹ̀.
ⲍ̅ⲘⲘⲞⲚ ϨⲖⲒ ⲄⲀⲢ ⲘⲘⲞⲚ ⲚⲀⲰⲚϦ ⲚⲀϤ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲘⲞⲚ ϨⲖⲒ ⲚⲀⲘⲞⲨ ⲚⲀϤ.
8 Bí a bá wà láààyè, a wà láààyè fún Olúwa; bí a bá sì kú, a kú fún Olúwa. Nítorí náà, bí a wà láààyè, tàbí bí a kú, ti Olúwa ni àwa i ṣe.
ⲏ̅ⲈϢⲰⲠ ⲄⲀⲢ ⲈⲚⲚⲀⲰⲚϦ ⲈⲚⲚⲀⲰⲚϦ ⲘⲠϬ ⲤⲈϢⲰⲠ ⲆⲈ ⲈⲚⲚⲀⲘⲞⲨ ⲈⲚⲚⲀⲘⲞⲨ ⲘⲠϬⲞⲒⲤ ⲒⲦⲈ ⲞⲨⲚ ⲈⲚⲚⲀⲰⲚϦ ⲒⲦⲈ ⲈⲚⲚⲀⲘⲞⲨ ⲀⲚⲞⲚ ⲚⲀ ⲠϬⲞⲒⲤ.
9 Nítorí ìdí èyí náà ni Kristi ṣe kú, tí ó sì tún yè, kí ó bá le jẹ́ Olúwa òkú àti alààyè.
ⲑ̅ⲈⲐⲂⲈ ⲪⲀⲒ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲀϤⲘⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲰⲚϦ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϤⲈⲢϬⲞⲒⲤ ⲈⲚⲎ ⲈⲐⲘⲰⲞⲨⲦ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲦⲞⲚϦ.
10 Èéṣe nígbà náà tí ìwọ fi ń dá arákùnrin tàbí arábìnrin rẹ lẹ́jọ́? Tàbí èéṣe tí ìwọ fi ń gàn wọn? Nítorí gbogbo wa ni yóò dúró níwájú ìtẹ́ ìdájọ́ Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲚⲐⲞⲔ ⲆⲈ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲔϮϨⲀⲠ ⲈⲠⲈⲔⲤⲞⲚ ⲘⲘⲞⲚ ⲚⲐⲞⲔ ϨⲰⲔ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲔϢⲰϢ ⲘⲠⲈⲔⲤⲞⲚ ⲀⲚⲞⲚ ⲄⲀⲢ ⲦⲎⲢⲈⲚ ⲤⲈⲚⲀⲦⲀϨⲞⲚ ⲈⲢⲀⲦⲈⲚ ⲚⲀϨⲢⲈⲚ ⲠⲒⲂⲎⲘⲀ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
11 A ti kọ ìwé rẹ̀ pé: “‘Níwọ́n ìgbà tí mo wà láààyè,’ ni Olúwa wí, ‘gbogbo eékún ni yóò wólẹ̀ fún mi; gbogbo ahọ́n ni yóò jẹ́wọ́ fún Ọlọ́run.’”
ⲓ̅ⲁ̅ⲤⲤϦⲎⲞⲨⲦ ⲄⲀⲢ ϪⲈ ϮⲞⲚϦ ⲀⲚⲞⲔ ⲠⲈϪⲈ ⲠϬⲞⲒⲤ ϪⲈ ⲔⲈⲖⲒ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲨⲈⲔⲰⲖϪ ⲚⲎⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲈⲖⲀⲤ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲞⲨⲰⲚϨ ⲈⲂⲞⲖ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ.
12 Ǹjẹ́ nítorí náà, olúkúlùkù wa ni yóò jíyìn ara rẹ̀ fún Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲃ̅ϨⲀⲢⲀ ⲞⲨⲚ ⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲘⲘⲞⲚ ϤⲚⲀϮⲖⲞⲄⲞⲤ ⲈϪⲰϤ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ.
13 Nítorí náà, ẹ má ṣe tún jẹ́ kí a máa dá ara wa lẹ́jọ́ mọ́. Ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀, ẹ pinu nínú ọkàn yín láti má ṣe fi ohun ìkọ̀sẹ̀ tàbí òkúta ìdìgbòlù kankan sí ọ̀nà arákùnrin tàbí arábìnrin yín.
ⲓ̅ⲅ̅ⲘⲠⲈⲚⲐⲢⲈⲚϮϨⲀⲠ ⲞⲨⲚ ϪⲈ ⲈⲚⲈⲚⲈⲢⲎⲞⲨ ⲀⲖⲖⲀ ⲪⲀⲒ ⲘⲀⲖⲖⲞⲚ ⲘⲀϨⲀⲠ ⲈⲢⲞϤ ⲈϢⲦⲈⲘⲬ ⲀⲞⲨϬⲢⲞⲠ ⲒⲈ ⲞⲨⲤⲔⲀⲚⲆⲀⲖⲞⲚ ⲘⲠⲈⲔⲤⲞⲚ.
14 Mo mọ̀ dájú gbangba bí ẹni tí ó wà nínú Jesu Olúwa pé, kò sí ohun tó ṣe àìmọ́ fún ara rẹ̀. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ka ohunkóhun sí àìmọ́, òun ni ó ṣe àìmọ́ fún.
ⲓ̅ⲇ̅ϮⲈⲘⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲀϨⲎⲦ ⲐⲎⲦ ϦⲈⲚⲠϬⲞⲒⲤ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϪⲈ ⲘⲘⲞⲚ ϨⲖⲒ ⲈϤϬⲀϦⲈⲘ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦϤ ⲈⲂⲎⲖ ⲈⲪⲎ ⲈⲐⲘⲈⲨⲒ ⲈⲞⲨⲈⲚⲬⲀⲒ ϪⲈ ϤϬⲀϦⲈⲘ ϤϬⲀϦⲈⲘ ⲚⲦⲞⲦϤ ⲘⲪⲎ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ.
15 Bí inú arákùnrin tàbí arábìnrin rẹ ba bàjẹ́ nítorí oúnjẹ rẹ, ìwọ kò rìn nínú ìfẹ́ mọ́. Má ṣe fi oúnjẹ rẹ sọ ẹni tí Kristi kú fún di ẹni ègbé.
ⲓ̅ⲉ̅ⲒⲤϪⲈ ⲄⲀⲢ ⲈⲐⲂⲈ ⲞⲨϦⲢⲈ ⲀⲢⲈ ⲠⲈⲔⲤⲞⲚ ⲚⲀⲈⲢⲤⲔⲀⲚⲆⲀⲖⲒⲌⲈⲤⲐⲈ ⲒⲈ ⲔⲘⲞϢⲒ ⲀⲚ ϪⲈ ⲔⲀⲦⲀ ⲞⲨⲀⲄⲀⲠⲎ ⲘⲠⲈⲢⲦⲀⲔⲈ ⲪⲎ ⲈⲦⲀ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲘⲞⲨ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲰϤ ϦⲈⲚⲦⲈⲔϦⲢⲈ.
16 Nítorí náà, ẹ má ṣe jẹ́ kí a máa sọ̀rọ̀ ohun tí ẹ mọ̀ sí rere ní búburú.
ⲓ̅ⲋ̅ⲘⲠⲈⲚⲐⲢⲞⲨϪⲈⲞⲨⲀ ⲞⲨⲚ ⲈⲠⲈⲦⲈⲚⲠⲈⲐⲚⲀⲚⲈϤ.
17 Nítorí ìjọba ọ̀run kì í ṣe jíjẹ àti mímu, bí kò ṣe nípa ti òdodo, àlàáfíà àti ayọ̀ nínú Ẹ̀mí Mímọ́,
ⲓ̅ⲍ̅ϮⲘⲈⲦⲞⲨⲢⲞ ⲄⲀⲢ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲚⲀⲤϦⲈⲚ ⲞⲨⲰⲘ ⲀⲚ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲤⲰ ⲀⲖⲖⲀ ⲀⲤϦⲈⲚ ⲞⲨⲘⲈⲐⲘⲎ ⲒⲚⲈⲘ ⲞⲨϨⲒⲢⲎⲚⲎ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲢⲀϢⲒ ϦⲈⲚⲞⲨⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈϤⲞⲨⲀⲂ.
18 nítorí ẹni tí ó bá sin Kristi nínú nǹkan wọ̀nyí ni ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ Ọlọ́run, tí ó sì ní ìyìn lọ́dọ̀ ènìyàn.
ⲓ̅ⲏ̅ⲪⲎ ⲄⲀⲢ ⲈⲦⲞⲒ ⲘⲂⲰⲔ ϦⲈⲚⲚⲀⲒ ⲈⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ϤⲢⲀⲚⲀϤ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲞⲨⲞϨ ϤⲤⲞⲨⲦⲰⲚ ⲠⲈ ϦⲈⲚⲚⲒⲢⲰⲘⲒ.
19 Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí a ṣa gbogbo ipá wa láti máa lépa àlàáfíà, àti ohun tí àwa yóò fi gbé ara wa ró.
ⲓ̅ⲑ̅ϨⲀⲢⲀ ⲞⲨⲚ ⲘⲀⲢⲈⲚϬⲞϪⲒ ⲚⲤⲀⲚⲀ ϮϨⲒⲢⲎⲚⲎ ⲚⲈⲘ ⲚⲀ ⲠⲒⲔⲰⲦ ⲈⲚⲈⲚⲈⲢⲎⲞⲨ.
20 Má ṣe bi iṣẹ́ Ọlọ́run ṣubú nítorí oúnjẹ. Gbogbo oúnjẹ ni ó mọ́, ṣùgbọ́n ohun búburú ni fún ẹni náà tí ó jẹ ohunkóhun tí ó le mú ẹlòmíràn kọsẹ̀.
ⲕ̅ⲘⲠⲈⲢⲂⲈⲖ ⲠⲒϨⲰⲂ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲂⲞⲖ ⲈⲐⲂⲈ ⲞⲨϦⲢⲈ ⲤⲈⲞⲨⲀⲂ ⲘⲈⲚ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲀⲖⲖⲀ ⲞⲨⲠⲈⲦϨⲰⲞⲨ ⲠⲈ ⲘⲠⲒⲢⲰⲘⲒ ⲪⲎ ⲈⲐⲚⲀⲞⲨⲰⲘ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲞⲨϬⲢⲞⲠ.
21 Ó dára kí a má tilẹ̀ jẹ ẹran tàbí mu wáìnì tàbí ṣe ohunkóhun tí yóò mú arákùnrin tàbí arábìnrin rẹ ṣubú.
ⲕ̅ⲁ̅ⲚⲀⲚⲈⲤ ⲈϢⲦⲈⲘⲞⲨⲈⲘ ⲀϤ ⲞⲨⲆⲈ ⲈϢⲦⲈⲘⲤⲈ ⲎⲢⲠ ⲚⲈⲘ ⲪⲎ ⲈⲦⲈ ⲠⲈⲔⲤⲞⲚ ⲚⲀϬⲒϬⲢⲞⲠ ⲚϦⲎⲦϤ.
22 Nítorí náà, ohun tí ìwọ bá gbàgbọ́ nípa gbogbo nǹkan wọ̀nyí, pa á mọ́ ní àárín ìwọ àti Ọlọ́run. Alábùkún fún ni ẹni náà tí kò dá ara rẹ̀ lẹ́bi nínú ohun tí ó yàn.
ⲕ̅ⲃ̅ⲚⲐⲞⲔ ⲞⲨⲞⲚⲦⲀⲔ ⲚⲞⲨⲚⲀϨϮ ⲘⲘⲀⲨ ⲬⲀϤ ⲚϦⲎⲦⲔ ⲘⲠⲈⲘⲐⲞ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲰⲞⲨⲚⲒⲀⲦϤ ⲘⲪⲎ ⲈⲦⲈⲚϤⲚⲀϮϨⲀⲠ ⲈⲢⲞϤ ⲀⲚ ϦⲈⲚⲪⲎ ⲈⲦⲈϤⲚⲀⲈⲢⲆⲞⲔⲒⲘⲀⲌⲒⲚ ⲘⲘⲞϤ.
23 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó ṣe iyèméjì, ó jẹ̀bi bí ó ba jẹ ẹ́, nítorí jíjẹ ẹ́ rẹ̀ kò ti inú ìgbàgbọ́ wá; bẹ́ẹ̀ sì ni, ohun gbogbo tí kò bá ti inú ìgbàgbọ́ wá, ẹ̀ṣẹ̀ ni.
ⲕ̅ⲅ̅ⲪⲎ ⲆⲈ ⲈⲦⲞⲒ ⲚϨⲎⲦ ⲂⲈϢⲰⲠ ⲀϤϢⲀⲚⲞⲨⲰⲘ ⲀϤϨⲒⲦϤ ⲈⲠϨⲀⲠ ϪⲈ ⲚⲞⲨⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲞⲨⲚⲀϨϮ ⲀⲚ ⲠⲈ ϨⲰⲂ ⲆⲈ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦⲈⲚⲞⲨⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲞⲨⲚⲀϨϮ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲞⲨⲚⲞⲂⲒ ⲠⲈ.

< Romans 14 >