< Romans 12 >
1 Nítorí náà mo fi ìyọ́nú Ọlọ́run bẹ̀ yín ará, kí ẹ̀yin kí ó fi ara yín fún Ọlọ́run ní ẹbọ ààyè mímọ́, ìtẹ́wọ́gbà, èyí ni iṣẹ́ ìsìn yín tí ó tọ̀nà.
Kérlek azért titeket, atyámfiai, Isten irgalmasságára, hogy szánjátok oda testeteket élő, szent és Istennek kedves áldozatul, mint a ti okos istentiszteleteteket.
2 Kí ẹ má sì da ara yín pọ̀ mọ́ ayé yìí; ṣùgbọ́n kí ẹ paradà láti di tuntun ní èrò inú yín, kí ẹ̀yin kí ó lè rí ìdí ìfẹ́ Ọlọ́run, tí ó dára, tí ó sì ṣe ìtẹ́wọ́gbà, ti ó sì pé. (aiōn )
És ne szabjátok magatokat e világhoz, hanem változzatok meg értelmetek megújulásával, hogy megítélhessétek, mi az Isten jó, neki tetsző és tökéletes akarata. (aiōn )
3 Ǹjẹ́ mo wí fún olúkúlùkù ènìyàn tí ó wà nínú yín, nípa oore-ọ̀fẹ́ tí a fi fún mi, kí ó má ṣe ro ara rẹ̀ ju bí ó ti yẹ ní rírò lọ; ṣùgbọ́n kí ó le rò níwọ́ntúnwọ́nsì, bí Ọlọ́run ti fi ìwọ̀n ìgbàgbọ́ fún olúkúlùkù.
A nekem adott kegyelem által mondom mindenkinek közöttetek, hogy ne gondoljon magáról többet, mint amit kell, hanem józanon gondolkodjék, amint Isten adta kinek-kinek a hit mértékét.
4 Nítorí gẹ́gẹ́ bí àwa ti ní ẹ̀yà púpọ̀ nínú ara kan, tí gbogbo ẹ̀yà kò sì ní iṣẹ́ kan náà,
Mert ahogyan egy testnek sok tagja van, de nem minden tagnak ugyanaz a feladata,
5 bẹ́ẹ̀ ni àwa, tí a jẹ́ púpọ̀, a jẹ́ ara kan nínú Kristi, àti olúkúlùkù ẹ̀yà ara ọmọnìkejì rẹ̀.
úgy sokan egy test vagyunk a Krisztusban, egyenként pedig egymásnak tagjai vagyunk.
6 Ǹjẹ́ bí àwa sì ti ń rí ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ẹ̀bùn gbà gẹ́gẹ́ bí oore-ọ̀fẹ́ tí a fi fún wa, bí ó ṣe ìsọtẹ́lẹ̀ ni, kí a máa sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀n ìgbàgbọ́;
Mivel pedig különböző ajándékaink vannak a nekünk adott kegyelem szerint, így is szolgálunk: ha írásmagyarázás, a hit szabályai szerint teljesítsük;
7 tàbí iṣẹ́ ìránṣẹ́, kí a kọjú sí iṣẹ́ ìránṣẹ́ wa tàbí ẹni tí ń kọ́ni, kí ó kọjú sí kíkọ́.
ha más szolgálat adatott, akkor abban a szolgálatban munkálkodjunk: a tanító a tanításban,
8 Tàbí ẹni tí ó ń gbani níyànjú, sí ìgbìyànjú; ẹni tí ń fi fún ni kí ó máa fi inú kan ṣe é; ẹni tí ń ṣe olórí, kí ó máa ṣe é ní ojú méjèèjì; ẹni tí ń ṣàánú, kí ó máa fi inú dídùn ṣe é.
az intő az intésben, az adakozó szelídségben, az elöljáró szorgalommal, a könyörülő vidámsággal tegye.
9 Kí ìfẹ́ kí ó wà ní àìṣẹ̀tàn. Ẹ máa takété sí ohun tí í ṣe búburú; ẹ fi ara mọ́ ohun tí í ṣe rere.
A szeretet képmutatás nélkül való legyen. Iszonyodjatok a gonosztól, ragaszkodjatok a jóhoz.
10 Ní ti ìfẹ́ ará, ẹ máa fi ìyọ́nú fẹ́ràn ara yín; ní ti ọlá, ẹ máa fi ẹnìkejì yín ṣáájú.
Atyafiúi szeretettel egymás iránt gyöngédek, a tiszteletadásban egymást megelőzők legyetek.
11 Ní ti iṣẹ́ ṣíṣe, ẹ má ṣe ọ̀lẹ; ẹ máa ní ìgbóná ọkàn; ẹ máa sìn Olúwa.
Az igyekezetben ne legyetek restek, lélekben buzgók legyetek, az Úrnak szolgáljatok,
12 Ẹ máa yọ̀ ni ìrètí; ẹ máa mú sùúrù nínú ìpọ́njú; ẹ máa dúró gbọingbọin nínú àdúrà.
A reménységben örvendezők, a háborúságban tűrők, a könyörgésben állhatatosak,
13 Ẹ máa pèsè fún àìní àwọn ènìyàn mímọ́; ẹ fi ara yín fún àlejò ṣíṣe.
a szentek szükségeire adakozók legyetek, a vendégszeretetet gyakoroljátok.
14 Ẹ máa súre fún àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí yín; ẹ máa súre, ẹ má sì ṣépè.
Áldjátok azokat, akik titeket üldöznek, áldjátok, és ne átkozzátok.
15 Àwọn tí ń yọ̀, ẹ máa bá wọn yọ̀, àwọn tí ń sọkún, ẹ máa bá wọn sọkún.
Örüljetek az örülőkkel, és sírjatok a sírókkal.
16 Ẹ máa wà ní inú kan náà sí ara yín. Ẹ má ṣe gbéraga, ṣùgbọ́n ẹ má tẹ̀lé àwọn onírẹ̀lẹ̀. Ẹ má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n ní ojú ara yín.
Egymással egyetértésben éljetek, ne kevélykedjetek, hanem az alázatosokhoz tartsátok magatokat. Ne legyetek bölcsek önmagatok szemében.
17 Ẹ má ṣe fi búburú san búburú fún ẹnikẹ́ni. Ẹ má pèsè ohun tí ó tọ́ níwájú gbogbo ènìyàn.
Senkinek gonoszért gonosszal ne fizessetek. A tisztességre gondotok legyen minden ember előtt.
18 Bí ó bá sé é ṣe, bí ó ti wà ní ipa tiyín, ẹ má wà ní àlàáfíà pẹ̀lú gbogbo ènìyàn.
Ha lehetséges, amennyire rajtatok áll, minden emberrel békességben éljetek.
19 Olùfẹ́ mi ọ̀wọ́n, ẹ má ṣe gbẹ̀san ara yín, ṣùgbọ́n ẹ fi ààyè sílẹ̀ fún ìbínú Ọlọ́run; nítorí a ti kọ ọ́ pé, Olúwa wí pé, “Tèmi ni ẹ̀san, èmi ó gbẹ̀san.”
Magatokért bosszút ne álljatok, szeretteim, hanem adjatok helyt az ő haragjának, mert meg van írva: „Enyém az igazságszolgáltatás, én megfizetek! – ezt mondja az Úr.“
20 Ní òdìkejì ẹ̀wẹ̀, “Bí ebi bá ń pa ọ̀tá rẹ, fún un ní oúnjẹ; bí òùngbẹ bá ń gbẹ ẹ́, fún un ní omi mu. Ní ṣíṣe èyí, ìwọ ó kó ẹ̀yín iná lé e ní orí.”
Azért, ha éhezik a te ellenséged, adj ennie, ha szomjazik, adj innia, mert ha ezt teszed, parazsat gyűjtesz a fejére.
21 Má ṣe jẹ́ kí búburú ṣẹ́gun rẹ, ṣùgbọ́n fi rere ṣẹ́gun búburú.
Ne győzzön le téged a gonosz, hanem a gonoszt jóval győzd meg.