< Romans 12 >

1 Nítorí náà mo fi ìyọ́nú Ọlọ́run bẹ̀ yín ará, kí ẹ̀yin kí ó fi ara yín fún Ọlọ́run ní ẹbọ ààyè mímọ́, ìtẹ́wọ́gbà, èyí ni iṣẹ́ ìsìn yín tí ó tọ̀nà.
ⲁ̅ϮϮϨⲞ ⲆⲈ ⲈⲢⲰⲦⲈⲚ ⲚⲀⲤⲚⲎⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲚⲒⲘⲈⲦϢⲈⲚϨⲎⲦ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲐⲢⲈⲦⲈⲚⲦⲀϨⲈ ⲚⲈⲦⲈⲚⲤⲰⲘⲀ ⲈⲢⲀⲦⲞⲨ ⲚⲞⲨϢⲞⲨϢⲰⲞⲨϢⲒ ⲈϤⲞⲚϦ ⲈϤⲞⲨⲀⲂ ⲈϤⲢⲀⲚⲀϤ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈⲦⲈⲚϢⲈⲘϢⲒ ⲚⲖⲞⲄⲒⲔⲞⲚ ⲈϤⲢⲀⲚⲀϤ.
2 Kí ẹ má sì da ara yín pọ̀ mọ́ ayé yìí; ṣùgbọ́n kí ẹ paradà láti di tuntun ní èrò inú yín, kí ẹ̀yin kí ó lè rí ìdí ìfẹ́ Ọlọ́run, tí ó dára, tí ó sì ṣe ìtẹ́wọ́gbà, ti ó sì pé. (aiōn g165)
ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚϢⲦⲈⲘⲈⲢϢⲪⲎⲢ ⲚⲤⲬⲎⲘⲀ ϪⲈ ⲚⲈⲘ ⲠⲀⲒⲈⲚⲈϨ ⲀⲖⲖⲀ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚϢⲈⲂⲦ ⲠⲈⲦⲈⲚⲤⲘⲞⲦ ϦⲈⲚⲞⲨⲘⲈⲦⲂⲈⲢⲒ ⲚⲦⲈⲠⲒⲔⲀϮ ⲈⲐⲢⲈⲦⲈⲚⲈⲢⲆⲞⲔⲒⲘⲀⲌⲒⲚ ϪⲈ ⲞⲨ ⲠⲈ ⲪⲞⲨⲰϢ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲠⲒⲀⲄⲀⲐⲞⲚ ⲈⲐⲢⲀⲚⲀϤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦϪⲎⲔ ⲈⲂⲞⲖ. (aiōn g165)
3 Ǹjẹ́ mo wí fún olúkúlùkù ènìyàn tí ó wà nínú yín, nípa oore-ọ̀fẹ́ tí a fi fún mi, kí ó má ṣe ro ara rẹ̀ ju bí ó ti yẹ ní rírò lọ; ṣùgbọ́n kí ó le rò níwọ́ntúnwọ́nsì, bí Ọlọ́run ti fi ìwọ̀n ìgbàgbọ́ fún olúkúlùkù.
ⲅ̅ϮϪⲰ ⲄⲀⲢ ⲘⲘⲞⲤ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲠⲒϨⲘⲞⲦ ⲈⲦⲦⲞⲒ ⲚⲎⲒ ⲚⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦϢⲞⲠ ϦⲈⲚⲐⲎⲚⲞⲨ ⲈϢⲦⲈⲘⲈⲢϨⲞⲨⲞ ⲘⲈⲨⲒ ⲤⲀⲂⲞⲖ ⲘⲠⲈⲦⲤϢⲈ ⲈⲘⲈⲨⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲀⲖⲖⲀ ⲈⲘⲈⲨⲒ ⲈϬⲒⲤⲂⲰ ⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲀ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲪⲰϢ ⲚⲀϤ ⲚⲞⲨϢⲒ ⲚⲚⲀϨϮ.
4 Nítorí gẹ́gẹ́ bí àwa ti ní ẹ̀yà púpọ̀ nínú ara kan, tí gbogbo ẹ̀yà kò sì ní iṣẹ́ kan náà,
ⲇ̅ⲘⲪⲢⲎϮ ⲄⲀⲢ ⲈⲦⲈ ⲚϨⲢⲎⲒ ϦⲈⲚⲞⲨⲤⲰⲘⲀ ⲚⲞⲨⲰⲦ ⲞⲨⲞⲚⲦⲀⲚ ⲚⲞⲨⲘⲎϢ ⲘⲘⲈⲖⲞⲤ ⲘⲘⲀⲨ ⲚⲒⲘⲈⲖⲞⲤ ⲆⲈ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲚⲞⲨϨⲰⲂ ⲚⲞⲨⲰⲦ ⲀⲚ ⲠⲈⲦⲈⲚⲦⲰⲞⲨ
5 bẹ́ẹ̀ ni àwa, tí a jẹ́ púpọ̀, a jẹ́ ara kan nínú Kristi, àti olúkúlùkù ẹ̀yà ara ọmọnìkejì rẹ̀.
ⲉ̅ⲠⲀⲒⲢⲎϮ ⲀⲚⲞⲚ ϨⲰⲚ ϦⲀ ⲚⲒⲘⲎϢ ⲀⲚⲞⲚ ⲞⲨⲤⲰⲘⲀ ⲚⲞⲨⲰⲦ ϦⲈⲚⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲘⲘⲞⲚ ⲀⲚⲞⲚ ϨⲀⲚⲘⲈⲖⲞⲤ ⲚⲦⲈⲚⲈⲚⲈⲢⲎ ⲞⲨ.
6 Ǹjẹ́ bí àwa sì ti ń rí ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ẹ̀bùn gbà gẹ́gẹ́ bí oore-ọ̀fẹ́ tí a fi fún wa, bí ó ṣe ìsọtẹ́lẹ̀ ni, kí a máa sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀n ìgbàgbọ́;
ⲋ̅ⲈⲞⲨⲞⲚⲦⲀⲚ ⲆⲈ ⲘⲘⲀⲨ ⲚϨⲀⲚϨⲘⲞⲦ ⲈⲨϢⲈⲂⲒⲎⲞⲨⲦ ⲔⲀⲦⲀ ⲠϢⲒ ⲘⲠⲒϨⲘⲞⲦ ⲈⲦⲦⲞⲒ ⲚⲀⲚ ⲒⲦⲈ ⲞⲨⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲒⲀ ⲔⲀⲦⲀ ⲠⲒⲐⲞⲚⲦⲈⲚ ⲚⲦⲈⲪⲚⲀϨϮ.
7 tàbí iṣẹ́ ìránṣẹ́, kí a kọjú sí iṣẹ́ ìránṣẹ́ wa tàbí ẹni tí ń kọ́ni, kí ó kọjú sí kíkọ́.
ⲍ̅ⲒⲦⲈ ⲞⲨⲆⲒⲀⲔⲞⲚⲒⲀ ϦⲈⲚϮⲆⲒⲀⲔⲞⲚⲒⲀ ⲒⲦⲈ ⲠⲈⲦϮⲤⲂⲰ ϦⲈⲚϮⲘⲈⲦⲢⲈϤϮⲤⲂⲰ.
8 Tàbí ẹni tí ó ń gbani níyànjú, sí ìgbìyànjú; ẹni tí ń fi fún ni kí ó máa fi inú kan ṣe é; ẹni tí ń ṣe olórí, kí ó máa ṣe é ní ojú méjèèjì; ẹni tí ń ṣàánú, kí ó máa fi inú dídùn ṣe é.
ⲏ̅ⲒⲦⲈ ⲠⲈⲦϮⲚⲞⲘϮ ϦⲈⲚϮⲘⲈⲦⲐⲀⲦϨⲎⲦ ⲪⲎ ⲈⲦϮ ϦⲈⲚⲞⲨⲘⲈⲦϨⲀⲠⲖⲞⲨⲤ ⲪⲎ ⲈⲦⲬⲎ ϦⲀϪⲰⲞⲨ ϦⲈⲚⲞⲨⲤⲠⲞⲨⲆⲎ ⲪⲎ ⲈⲐⲚⲀⲒ ϦⲈⲚⲞⲨⲢⲀϢⲒ.
9 Kí ìfẹ́ kí ó wà ní àìṣẹ̀tàn. Ẹ máa takété sí ohun tí í ṣe búburú; ẹ fi ara mọ́ ohun tí í ṣe rere.
ⲑ̅ϮⲀⲄⲀⲠⲎ ⲘⲘⲞⲚ ⲘⲈⲦϢⲞⲂⲒ ⲚϦⲎⲦⲤ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲪⲎⲦ ⲤⲀⲂⲞⲖ ⲘⲠⲒⲠⲈⲦϨⲰⲞⲨ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲦⲞⲘⲒ ⲘⲘⲰⲦⲈⲚ ⲈⲠⲒⲀⲄⲀⲐⲞⲚ.
10 Ní ti ìfẹ́ ará, ẹ máa fi ìyọ́nú fẹ́ràn ara yín; ní ti ọlá, ẹ máa fi ẹnìkejì yín ṣáájú.
ⲓ̅ϦⲈⲚ ϮⲘⲈⲦⲘⲀⲒⲤⲞⲚ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲬⲎ ϦⲈⲚⲞⲨⲘⲈⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲚⲈⲦⲈⲚⲈⲢⲎⲞⲨ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲈⲢϢⲞⲢⲠ ⲚⲬⲀ ⲚⲈⲦⲈⲚⲈⲢⲎⲞⲨ ⲚⲦⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ ϦⲈⲚⲞⲨⲦⲀⲒⲞ.
11 Ní ti iṣẹ́ ṣíṣe, ẹ má ṣe ọ̀lẹ; ẹ máa ní ìgbóná ọkàn; ẹ máa sìn Olúwa.
ⲓ̅ⲁ̅ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲞⲒ ⲚϬⲚⲀⲨ ⲀⲚ ϦⲈⲚϮⲤⲠⲞⲨⲆⲎ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚϦⲎⲘ ϦⲈⲚⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲞⲒ ⲘⲂⲰⲔ ⲘⲠϬⲞⲒⲤ.
12 Ẹ máa yọ̀ ni ìrètí; ẹ máa mú sùúrù nínú ìpọ́njú; ẹ máa dúró gbọingbọin nínú àdúrà.
ⲓ̅ⲃ̅ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲢⲀϢⲒ ϦⲈⲚϮϨⲈⲖⲠⲒⲤ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲈⲢϨⲨⲠⲞⲘⲈⲚⲒⲚ ϦⲈⲚⲚⲒϨⲞϪϨⲈϪ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲘⲎ ⲚⲈϮⲠⲢⲞⲤⲈⲨⲬⲎ.
13 Ẹ máa pèsè fún àìní àwọn ènìyàn mímọ́; ẹ fi ara yín fún àlejò ṣíṣe.
ⲓ̅ⲅ̅ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲞⲒ ⲚϢⲪⲎⲢ ⲈⲚⲒⲬⲢⲒⲀ ⲚⲦⲈⲚⲒⲀⲄⲒⲞⲤ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚϬⲞϪⲒ ⲚⲤⲀⲦⲘⲈⲦⲘⲀⲒϢⲈⲘⲘⲞ.
14 Ẹ máa súre fún àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí yín; ẹ máa súre, ẹ má sì ṣépè.
ⲓ̅ⲇ̅ⲤⲘⲞⲨ ⲈⲚⲎ ⲈⲦϬⲞϪⲒ ⲚⲤⲀⲐⲎⲚⲞⲨ ⲤⲘⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈⲢⲤⲀϨⲞⲨⲒ.
15 Àwọn tí ń yọ̀, ẹ máa bá wọn yọ̀, àwọn tí ń sọkún, ẹ máa bá wọn sọkún.
ⲓ̅ⲉ̅ⲢⲀϢⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲦⲢⲀϢⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲢⲒⲘⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲦⲢⲒⲘⲒ.
16 Ẹ máa wà ní inú kan náà sí ara yín. Ẹ má ṣe gbéraga, ṣùgbọ́n ẹ má tẹ̀lé àwọn onírẹ̀lẹ̀. Ẹ má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n ní ojú ara yín.
ⲓ̅ⲋ̅ⲞⲨⲘⲈⲨⲒ ⲚⲞⲨⲰⲦ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲢⲀ ⲘⲘⲞϤ ⲈⲚⲈⲦⲈⲚⲈⲢⲎⲞⲨ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚⲘⲈⲨⲒ ⲀⲚ ⲈⲚⲒⲘⲈⲦϬⲀⲤⲒϨⲎ ⲦⲀⲖⲖⲀ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲘⲞϢⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲦⲐⲈⲂⲒⲎ ⲞⲨⲦ ⲘⲠⲈⲢϢⲰⲠⲒ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲞⲒ ⲚⲤⲀⲂⲈ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ.
17 Ẹ má ṣe fi búburú san búburú fún ẹnikẹ́ni. Ẹ má pèsè ohun tí ó tọ́ níwájú gbogbo ènìyàn.
ⲓ̅ⲍ̅ⲚⲦⲈⲦⲈⲚϮ ⲚⲞⲨⲠⲈⲦϨⲰⲞⲨ ⲀⲚ ⲚϨⲖⲒ ⲚⲦϢⲈⲂⲒⲰ ⲚⲠⲞⲨⲠⲈⲦϨⲰⲞⲨ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚϤⲒ ⲘⲪⲢⲰⲞⲨϢ ⲚϨⲀⲚⲠⲈⲐⲚⲀⲚⲈⲨ ⲘⲠⲈⲘⲐⲞ ⲚⲢⲰⲘⲒ ⲚⲒⲂⲈⲚ.
18 Bí ó bá sé é ṣe, bí ó ti wà ní ipa tiyín, ẹ má wà ní àlàáfíà pẹ̀lú gbogbo ènìyàn.
ⲓ̅ⲏ̅ⲒⲤϪⲈ ⲞⲨⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲘⲘⲰⲦⲈⲚ ⲀⲢⲒⲀⲨⲦⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲈⲈⲢϨⲒⲢⲎⲚⲎ ⲚⲈⲘ ⲢⲰⲘⲒ ⲚⲒⲂⲈⲚ
19 Olùfẹ́ mi ọ̀wọ́n, ẹ má ṣe gbẹ̀san ara yín, ṣùgbọ́n ẹ fi ààyè sílẹ̀ fún ìbínú Ọlọ́run; nítorí a ti kọ ọ́ pé, Olúwa wí pé, “Tèmi ni ẹ̀san, èmi ó gbẹ̀san.”
ⲓ̅ⲑ̅ⲚⲦⲈⲦⲈⲚϬⲒ ⲘⲠⲈⲦⲈⲚⲘⲠϢⲒϢ ⲀⲚ ⲚⲀⲘⲈⲚⲢⲀϮ ⲀⲖⲖⲀ ⲘⲀⲘⲀ ⲘⲠϪⲰⲚⲦ ⲤⲤϦⲎⲞⲨⲦ ⲄⲀⲢ ϪⲈ ⲚϬⲒⲘⲠϢⲒϢ ⲪⲰⲒ ⲀⲚⲞⲔ ⲠⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲈⲐⲚⲀϮϢⲈⲂⲒⲰ ⲠⲈϪⲈ ⲠϬⲞⲒⲤ.
20 Ní òdìkejì ẹ̀wẹ̀, “Bí ebi bá ń pa ọ̀tá rẹ, fún un ní oúnjẹ; bí òùngbẹ bá ń gbẹ ẹ́, fún un ní omi mu. Ní ṣíṣe èyí, ìwọ ó kó ẹ̀yín iná lé e ní orí.”
ⲕ̅ⲀⲖⲖⲀ ⲈϢⲰⲠ ⲀⲢⲈϢⲀⲚ ⲠⲈⲔϪⲀϪⲒ ϨⲔⲞ ⲘⲀⲦⲈⲘⲘⲞϤ ⲀϤϢⲀⲚⲒⲂⲒ ⲘⲀⲦⲤⲞϤ ⲪⲀⲒ ⲄⲀⲢ ⲈⲔⲢⲀ ⲘⲘⲞϤ ⲈⲔⲈⲐⲰⲞⲨϮ ⲚϨⲀⲚϪⲈⲂⲤ ⲚⲬⲢⲰⲘ ϨⲒϪⲈⲚ ⲦⲈϤⲀⲪⲈ.
21 Má ṣe jẹ́ kí búburú ṣẹ́gun rẹ, ṣùgbọ́n fi rere ṣẹ́gun búburú.
ⲕ̅ⲁ̅ⲘⲠⲈⲚⲐⲢⲈ ⲠⲒⲠⲈⲦϨⲰⲞⲨ ϬⲢⲞ ⲈⲢⲰⲦⲈⲚ ⲀⲖⲖⲀ ϦⲈⲚⲠⲒⲠⲈⲐⲚⲀⲚⲈϤ ϬⲢⲞ ⲈⲠⲒⲠⲈⲦϨⲰⲞⲨ.

< Romans 12 >