< Romans 11 >

1 Ǹjẹ́ mo ní, Ọlọ́run ha ta àwọn ènìyàn rẹ̀ nù bí? Kí a má ri. Nítorí Israẹli ni èmi pẹ̀lú, láti inú irú-ọmọ Abrahamu, ni ẹ̀yà Benjamini.
Czyżby więc Bóg odrzucił swój własny naród? Absolutnie nie! Przecież ja sam jestem Żydem, potomkiem Abrahama, pochodzącym z rodu Beniamina.
2 Ọlọ́run kò ta àwọn ènìyàn rẹ̀ nù ti ó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀. Tàbí ẹ̀yin kò mọ bí ìwé mímọ́ ti wí ní ti Elijah? Bí ó ti ń bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ Ọlọ́run fún Israẹli, wí pé:
Bóg nie porzucił wybranego przez siebie narodu. Czy nie pamiętacie, co Pismo mówi o Eliaszu? Prorok żalił się Bogu na Izraela:
3 “Olúwa, wọ́n ti pa àwọn wòlíì rẹ, wọn sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀; èmi nìkan ṣoṣo ni ó sì kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi.”
„Panie, pozabijali Twoich proroków i zburzyli Twoje ołtarze. Zostałem sam, a oni chcą zabić także mnie”.
4 Ṣùgbọ́n ìdáhùn wo ni Ọlọ́run fi fún un? “Mo ti ṣẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn kù sílẹ̀ fún ara mi, àwọn tí kò tẹ eékún ba fún Baali.”
Ale Bóg odpowiedział mu: „Nie jesteś sam! Zachowałem jeszcze siedem tysięcy ludzi, którzy nie pokłonili się bożkowi Baalowi”.
5 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni, ní àkókò yìí àṣẹ́kù àwọn ènìyàn kan wà nípa ìyànfẹ́ ti oore-ọ̀fẹ́.
Podobnie jest i dzisiaj. Została garstka wybranych przez Boga—dzięki Jego łasce.
6 Bí ó bá sì ṣe pé nípa ti oore-ọ̀fẹ́ ni, ǹjẹ́ kì í ṣe ti iṣẹ́ mọ́; bí bẹ́ẹ̀ kọ́ oore-ọ̀fẹ́ kì yóò jẹ́ oore-ọ̀fẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n bí ó ṣe pé nípa ti iṣẹ́ ni, ǹjẹ́ kì í ṣe ti oore-ọ̀fẹ́ mọ́; bí bẹ́ẹ̀ kọ́, iṣẹ́ kì í ṣe iṣẹ́ mọ́.
Jeśli więc dzięki łasce, to nie ze względu na dobre postępowanie, bo wtedy dar łaski przestałby być darem.
7 Kí ha ni? Ohun tí Israẹli ń wá kiri, òun náà ni kò rí; ṣùgbọ́n àwọn ẹni àyànfẹ́ ti rí i, a sì sé àyà àwọn ìyókù le.
Mamy więc taką sytuację: Izrael nie osiągnął tego, czego pragnął. Tylko wybrana garstka Żydów znalazła łaskę Boga—większość zaś stała się nieczuła.
8 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Ọlọ́run ti fún wọn ní ẹ̀mí oorun, àwọn ojú tí kò le ríran àti àwọn etí tí kò le gbọ́rọ̀, títí ó fi di òní olónìí yìí.”
Pismo mówi: „Bóg zesłał na nich otępienie, zamknął im oczy i uszy —i trwa to do dziś”.
9 Dafidi sì wí pé: “Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìdẹ̀kùn àti tàkúté, ohun ìkọ̀sẹ̀ àti ẹ̀san fún wọn.
Mówi o tym również król Dawid: „Zasiądą do posiłku, ale wpadną w pułapkę, i pogrążą się w niej, bo na to zasłużyli.
10 Jẹ́ kí ojú wọn ṣókùnkùn, kí wọn kí ó má le ríran, Kí wọn kí ó sì tẹ ẹ̀yìn wọn ba nígbà gbogbo.”
Ich oczy zaćmią się i niczego nie zobaczą, a ich grzbiet zegnie się pod ciężarem”.
11 Ǹjẹ́ mo ní, wọ́n ha kọsẹ̀ kí wọn kí ó lè ṣubú? Kí a má ri i, ṣùgbọ́n nípa ìṣubú wọn, ìgbàlà dé ọ̀dọ̀ àwọn Kèfèrí, láti mú Israẹli jowú.
Czy jednak Żydzi aż tak się potknęli, że zupełnie upadli? Absolutnie nie! Ich potknięcie sprawiło, że zbawienie stało się dostępne dla pogan, aby Izrael pozazdrościł im i również go zapragnął.
12 Ṣùgbọ́n bí ìṣubú wọn bá di ọrọ̀ ayé, àti bí ìfàsẹ́yìn wọn bá di ọrọ̀ àwọn Kèfèrí; mélòó mélòó ni kíkún ọrọ̀ wọn?
Pomyślcie więc: Jeśli ich potknięcie przyniosło światu korzyść i jeśli ich poniżenie obdarzyło pogan bogactwem, to jak wielkie szczęście przyniesie światu ich powstanie!
13 Ẹ̀yin tí i ṣe Kèfèrí ni èmi sá à ń bá sọ̀rọ̀, níwọ̀n bí èmi ti jẹ́ aposteli àwọn Kèfèrí, mo gbé oyè mi ga
Teraz kilka słów do was, wierzących pogan. Ciągle podkreślam, że jestem apostołem posłanym do pogan.
14 bí ó le ṣe kí èmi kí ó lè mú àwọn ará mi jowú, àti kí èmi kí ó lè gba díẹ̀ là nínú wọn.
Mam nadzieję, że wzbudzę w ten sposób zazdrość moich rodaków i doprowadzę do zbawienia przynajmniej niektórych z nich.
15 Nítorí bí títanù wọn bá jẹ́ ìlàjà ayé, gbígbà wọn yóò ha ti rí, bí kò sí ìyè kúrò nínú òkú?
Jeśli bowiem ich odrzucenie przyniosło światu pojednanie z Bogiem, to ich ponowne przyjęcie będzie przejściem ze śmierci do życia.
16 Ǹjẹ́ bí àkọ́so bá jẹ́ mímọ́, bẹ́ẹ̀ ni àkópọ̀ yóò jẹ́ mímọ́; bí gbòǹgbò bá sì jẹ́ mímọ́, bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ẹ̀ka rẹ̀ náà.
Skoro zaczyn ciasta jest święty, to i całe ciasto! Jeśli święte są korzenie, to i gałęzie drzewa!
17 Ṣùgbọ́n bí a bá ya nínú àwọn ẹ̀ka kúrò, tí a sì lọ́ ìwọ, tí í ṣe igi òróró igbó sára wọn, tí ìwọ sì ń bá wọn pín nínú gbòǹgbò àti ọ̀rá igi olifi náà,
Niektóre gałązki z oliwnego drzewa Abrahama zostały odcięte, abyś ty, jako poganin, będący gałązką z dzikiego drzewa, został wszczepiony w szlachetną oliwkę i obficie czerpał soki z jej korzenia.
18 má ṣe ṣe féfé sí àwọn ẹ̀ka igi náà. Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá ṣe féfé, ìwọ kọ́ ni ó rù gbòǹgbò, ṣùgbọ́n gbòǹgbò ni ó rù ìwọ.
Ale nie pogardzaj odciętymi gałęziami i nie wywyższaj się! To nie ty przecież utrzymujesz korzeń, ale korzeń ciebie.
19 Ǹjẹ́ ìwọ ó wí pé, “A ti fa àwọn ẹ̀ka náà ya, nítorí kí a lè lọ́ mi sínú rẹ̀.”
Pewnie powiesz: „Inne gałęzie zostały wycięte, abym ja mógł zostać wszczepiony w ich miejsce”.
20 Ó dára; nítorí àìgbàgbọ́ ni a ṣe fà wọn ya kúrò, ìwọ sì dúró nípa ìgbàgbọ́ rẹ. Má ṣe gbé ara rẹ ga, ṣùgbọ́n bẹ̀rù.
Masz rację! Z powodu niewiary tamte gałęzie zostały usunięte, a ty dzięki wierze zająłeś ich miejsce. Ale nie wywyższaj się i nie bądź zbyt pewny siebie!
21 Nítorí bí Ọlọ́run kò bá dá ẹ̀ka-ìyẹ́ka sí, kíyèsára kí ó má ṣe ṣe àìdá ìwọ náà sí.
Jeśli bowiem Bóg nie oszczędził naturalnych gałęzi, to może wyciąć także ciebie.
22 Nítorí náà wo oore àti ìkáàánú Ọlọ́run; lórí àwọn tí ó ṣubú, ìkáàánú; ṣùgbọ́n lórí ìwọ, oore, bi ìwọ bá dúró nínú oore rẹ̀; kí a má bá ké ìwọ náà kúrò.
Zwróć uwagę na dobroć i surowość Boga: był surowy dla wyciętych gałęzi, a jest dobry dla ciebie—o ile trwasz w tej dobroci, bo i ciebie może spotkać podobny los.
23 Àti àwọn pẹ̀lú, bí wọn kò bá jókòó sínú àìgbàgbọ́, a ó lọ́ wọn sínú rẹ̀, nítorí Ọlọ́run le tún wọn lọ́ sínú rẹ̀.
Żydzi zaś, jeśli porzucą swoją niewiarę, zostaną ponownie wszczepieni. Bóg jest w stanie tego dokonać!
24 Nítorí bí a bá ti ké ìwọ kúrò lára igi òróró igbó nípa ẹ̀dá rẹ̀, tí a sì lọ́ ìwọ sínú igi òróró rere lòdì sí ti ẹ̀dá; mélòó mélòó ni a ó lọ́ àwọn wọ̀nyí, tí í ṣe ẹ̀ka-ìyẹ́ka sára igi òróró wọn?
Skoro ty, jako gałązka wycięta z dzikiego drzewa, wbrew naturze zostałeś wszczepiony w szlachetną oliwkę, to tym bardziej oni mogą zostać z powrotem wszczepieni w swoje własne drzewo.
25 Ará, èmi kò ṣá fẹ́ kí ẹ̀yin kí ó wà ní òpè ní ti ohun ìjìnlẹ̀ yìí, kí ẹ̀yin má ba á ṣe ọlọ́gbọ́n ní ojú ara yín, pé ìfọ́jú bá Israẹli ní apá kan, títí kíkún àwọn Kèfèrí yóò fi dé.
Przyjaciele, bardzo chcę, abyście znali tę tajemnicę i myśleli o sobie w rozsądny sposób. Wiedzcie więc o tym, że Izrael będzie okazywać upór tylko do czasu, gdy do Chrystusa przyjdą już wszyscy poganie, którzy mają Go znaleźć.
26 Bẹ́ẹ̀ ni a ó sì gba gbogbo Israẹli là, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Ní Sioni ni Olùgbàlà yóò ti jáde wá, yóò sì yìí àìwà-bí-Ọlọ́run kúrò lọ́dọ̀ Jakọbu.
A wtedy cały Izrael zostanie zbawiony. Bóg mówi o tym w Piśmie: „Z Syjonu przyjdzie Zbawiciel, który odwróci Izraela od bezbożności.
27 Èyí sì ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú wọn. Nígbà tí èmi yóò mú ẹ̀ṣẹ̀ wọn kúrò.”
I dotrzymam zawartego przymierza, oczyszczając ich z grzechów”.
28 Nípa ti ìyìnrere, ọ̀tá ni wọ́n nítorí yín; bí ó sì ṣe ti ìyànfẹ́ ni, olùfẹ́ ni wọ́n nítorí ti àwọn baba.
Jeśli chodzi o dobrą nowinę, Żydzi są teraz wrogami Boga—ale to dla waszego dobra. Jeśli jednak chodzi o dawne Boże wybranie—są Jego ukochanym ludem, ze względu na przodków.
29 Nítorí àìlábámọ̀ ni ẹ̀bùn àti ìpè Ọlọ́run.
Bóg bowiem nie odbiera ludziom swoich darów i powołania.
30 Nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin kò ti gba Ọlọ́run gbọ́ rí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí tí ẹ̀yin rí àánú gbà nípa àìgbàgbọ́ wọn.
Wy niegdyś buntowaliście się przeciw Niemu, ale teraz, z powodu uporu ze strony Żydów, doznaliście Jego miłości.
31 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni àwọn wọ̀nyí tí ó ṣe àìgbọ́ràn nísinsin yìí, kí àwọn pẹ̀lú bá le rí àánú gbà nípa àánú tí a fihàn yín.
Oni, teraz zbuntowani z powodu okazanej wam miłości, również doznają Bożej łaski.
32 Nítorí Ọlọ́run sé gbogbo wọn mọ́ pọ̀ sínú àìgbàgbọ́, kí ó le ṣàánú fún gbogbo wọn. (eleēsē g1653)
Bóg pozwolił na to, żeby wszyscy się zbuntowali, aby wszystkim okazać swoją miłość. (eleēsē g1653)
33 A! Ìjìnlẹ̀ ọ̀rọ̀ àti ọgbọ́n àti ìmọ̀ Ọlọ́run! Àwámárídìí ìdájọ́ rẹ̀ ti rí, ọ̀nà rẹ̀ sì jù àwárí lọ!
Jak niezgłębiona jest mądrość, wiedza i bogactwo Boga! Jak niedościgłe Jego decyzje i sposoby działania!
34 “Nítorí ta ni ó mọ ọkàn Olúwa? Tàbí ta ni í ṣe ìgbìmọ̀ rẹ̀?”
Kto ogarnie myśli Pana? Kto może zostać Jego doradcą?
35 “Tàbí ta ni ó kọ́ fi fún un, tí a kò sì san padà fún un?”
I kto Go czymś obdarował, aby oczekiwać czegoś w zamian?
36 Nítorí láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti nípa rẹ̀, àti fún un ni ohun gbogbo; ẹni tí ògo wà fún láéláé! Àmín. (aiōn g165)
Wszystko przecież pochodzi od Niego, dzięki Niemu istnieje i do Niego zmierza. Jemu niech będzie wieczna chwała! Amen! (aiōn g165)

< Romans 11 >