< Romans 10 >
1 Ẹ̀yin arákùnrin àti arábìnrin, ìfẹ́ ọkàn àti àdúrà mi sí Ọlọ́run fún àwọn ènìyàn Israẹli ni kí wọ́n le ní ìgbàlà.
Fraților, dorința inimii mele și rugăciunea mea către Dumnezeu este pentru Israel, ca să fie mântuit.
2 Nítorí mo gba ẹ̀rí wọn jẹ́ wí pé, wọ́n ní ìtara fún Ọlọ́run, ṣùgbọ́n kì í ṣe gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀.
Căci mărturisesc despre ei că au un zel pentru Dumnezeu, dar nu potrivit cu cunoștința.
3 Nítorí bí wọn kò tí mọ òdodo Ọlọ́run, tí wọ́n si ń wá ọ̀nà láti gbé òdodo ara wọn kalẹ̀, wọn kò tẹríba fún òdodo Ọlọ́run.
Pentru că, ignorând dreptatea lui Dumnezeu și căutând să își stabilească propria dreptate, nu s-au supus dreptății lui Dumnezeu.
4 Nítorí Kristi ni òpin òfin sí òdodo fún olúkúlùkù ẹni tí ó gbà á gbọ́.
Căci Hristos este împlinirea Legii, ca neprihănire pentru oricine crede.
5 Mose ṣá kọ èyí nípa òdodo tí í ṣe ti òfin pé, “Ẹni tí ó ba ṣe, yóò yè nípa wọn.”
Căci Moise scrie despre dreptatea Legii: “Cel ce le împlinește va trăi prin ele.”
6 Ṣùgbọ́n òdodo tí í ṣe ìgbàgbọ́ wí pé, “Má ṣe wí ni ọkàn rẹ̀ pé, ‘Ta ni yóò gòkè lọ si ọ̀run?’” (èyí ni, láti mú Kristi sọ̀kalẹ̀),
Dar neprihănirea care vine din credință spune următoarele: “Nu spuneți în inima voastră: “Cine se va sui în cer?”. (adică să-l coboare pe Cristos);
7 “tàbí, ‘Ta ni yóò sọ̀kalẹ̀ lọ si ọ̀gbun?’” (èyí ni, láti mú Kristi gòkè ti inú òkú wá). (Abyssos )
sau: “Cine se va coborî în abis?” (adică să-l coboare pe Cristos); sau: “Cine se va coborî în abis?”. (adică să-l aducă pe Hristos din morți).” (Abyssos )
8 Ṣùgbọ́n kí ni ó wí? “Ọ̀rọ̀ náà wà létí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ní ẹnu rẹ̀, àti ní ọkàn rẹ̀,” èyí nì ni ọ̀rọ̀ ìgbàgbọ́, tí àwa ń wàásù pé:
Dar ce spune? “Cuvântul este aproape de tine, în gura ta și în inima ta”, adică cuvântul credinței pe care îl predicăm:
9 Bí ìwọ bá fi ẹnu rẹ̀ jẹ́wọ́ “Jesu ní Olúwa,” tí ìwọ si gbàgbọ́ ní ọkàn rẹ pé, Ọlọ́run jí i dìde kúrò nínú òku, a ó gbà ọ́ là.
că, dacă vei mărturisi cu gura ta că Isus este Domnul și dacă vei crede în inima ta că Dumnezeu l-a înviat din morți, vei fi mântuit.
10 Nítorí ọkàn ni a fi ìgbàgbọ́ sí òdodo; ẹnu ni a sì ń fi ìjẹ́wọ́ sí ìgbàlà.
Căci cu inima se crede, ceea ce duce la neprihănire, iar cu gura se face mărturisirea, ceea ce duce la mântuire.
11 Nítorí Ìwé Mímọ́ wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà a gbọ́ ojú kò yóò tì í.”
Căci Scriptura spune: “Oricine crede în el nu va fi dezamăgit”.
12 Nítorí kò si ìyàtọ̀ nínú Júù àti Helleni: nítorí Olúwa kan náà ni Olúwa gbogbo wọn, o si pọ̀ ni ọrọ̀ fún gbogbo àwọn ti ń ké pe e.
Căci nu este nici o deosebire între iudei și greci, căci același Domn este Domnul tuturor și este bogat pentru toți cei ce-L cheamă.
13 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá à ti pe orúkọ Olúwa ni a ó gbàlà.”
Căci: “Oricine va invoca numele Domnului va fi mântuit”.
14 Ǹjẹ́ wọn ó ha ti ṣe ké pe ẹni tí wọn kò gbàgbọ́? Wọn ó ha sì ti ṣe gba ẹni tí wọn kò gbúròó rẹ̀ rí gbọ́? Wọn o ha sì ti ṣe gbọ́ láìsí oníwàásù?
Cum îl vor invoca, așadar, pe cel în care nu au crezut? Cum vor crede în cel pe care nu l-au auzit? Cum vor auzi fără un predicator?
15 Wọ́n ó ha sì ti ṣe wàásù, bí kò ṣe pé a rán wọn? Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Ẹsẹ̀ àwọn tí ń wàásù ìyìnrere àlàáfíà ti dára tó, àwọn tí ń wàásù ìròyìn ayọ̀ ohun rere!”
Și cum vor propovădui ei dacă nu vor fi trimiși? După cum este scris: “Cât de frumoase sunt picioarele celor care propovăduiesc vestea bună a păcii, care aduceți vești bune!”
16 Ṣùgbọ́n kì í ṣe gbogbo wọn ni ó gbọ́ ti ìyìnrere. Nítorí Isaiah wí pé, “Olúwa, ta ni ó gba ìyìn wa gbọ́?”
Dar nu toți au ascultat vestea cea bună. Căci Isaia spune: “Doamne, cine a crezut în vestea noastră?”.
17 Ǹjẹ́ nípa gbígbọ́ ni ìgbàgbọ́ ti í wá, àti gbígbọ́ nípa ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
Așadar, credința vine prin auz, iar auzul prin cuvântul lui Dumnezeu.
18 Ṣùgbọ́n mo ní, wọn kò ha gbọ́ bí? Bẹ́ẹ̀ ni nítòótọ́: “Ohùn wọn jáde lọ sí gbogbo ilẹ̀, àti ọ̀rọ̀ wọn sí òpin ilẹ̀ ayé.”
Dar eu zic: nu au auzit ei? Ba da, cu siguranță că da, “Sunetul lor s-a răspândit pe tot pământul, cuvintele lor până la marginile lumii.”
19 Ṣùgbọ́n mo wí pé, Israẹli kò ha mọ̀ bí? Mose ni ó kọ́ wí pé, “Èmi ó fi àwọn tí kì í ṣe ènìyàn mú yín jowú. Àti àwọn aláìmòye ènìyàn ni èmi ó fi bí yín nínú.”
Dar eu întreb: nu știa Israel? Mai întâi Moise spune, “Vă voi provoca la gelozie cu ceea ce nu este neam. Te voi înfuria cu un neam lipsit de înțelegere.”
20 Ṣùgbọ́n Isaiah tilẹ̀ láyà, ó wí pé, “Àwọn tí kò wá mi rí mi; Àwọn tí kò béèrè mi ni a fi mí hàn fún.”
Isaia este foarte îndrăzneț și spune, “Am fost găsit de cei care nu m-au căutat. Am fost dezvăluit celor care nu m-au cerut.”
21 Ṣùgbọ́n nípa ti Israẹli ni ó wí pé, “Ní gbogbo ọjọ́ ni mo na ọwọ́ mi sí àwọn aláìgbọ́ràn àti aláríwísí ènìyàn.”
Dar despre Israel spune: “Toată ziua mi-am întins mâinile spre un popor neascultător și răzvrătit.”