< Revelation 1 >

1 Ìfihàn ti Jesu Kristi, tí Ọlọ́run fi fún un, láti fihàn fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ohun tí kò le ṣàìṣẹ ní lọ́ọ́lọ́ọ́; ó sì ránṣẹ́, ó sì fi í hàn láti ọwọ́ angẹli rẹ̀ wá fún Johanu, ìránṣẹ́ rẹ̀,
Aceasta este Revelația lui Isus Hristos, pe care i-a dat-o Dumnezeu ca să arate robilor Săi lucrurile care trebuie să se întâmple curând, pe care a trimis-o și a făcut-o cunoscută prin îngerul Său robului Său, Ioan,
2 ẹni tí ó jẹ́rìí ohun gbogbo tí ó rí, èyí ì ni ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, àti ẹ̀rí ti Jesu Kristi.
care a mărturisit cuvântul lui Dumnezeu și mărturia lui Isus Hristos, despre tot ce a văzut.
3 Ẹni ìbùkún ni ẹni tí ń kà, àti àwọn tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ yìí, tí ó sì ń pa nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí a kọ sínú rẹ̀ mọ́, nítorí ìgbà kù sí dẹ̀dẹ̀.
Ferice de cel ce citește și de cei ce ascultă cuvintele proorociei și păzesc cele scrise în ea, căci timpul este aproape.
4 Johanu, Sí àwọn ìjọ méje tí ń bẹ ní Asia: Oore-ọ̀fẹ́ fún yín, àti àlàáfíà, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ń bẹ, tí ó sì ti wà, tí ó sì ń bọ̀ wá; àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ẹ̀mí méje tí ń bẹ níwájú ìtẹ́ rẹ̀;
Ioan, către cele șapte adunări care sunt în Asia: Har vouă și pace de la Dumnezeu, care este, care era și care va veni, și de la cele șapte duhuri care sunt înaintea tronului Lui,
5 àti láti ọ̀dọ̀ Jesu Kristi, ẹlẹ́rìí olóòtítọ́, àkọ́bí nínú àwọn òkú, àti aláṣẹ àwọn ọba ayé. Ẹni tí ó fẹ́ wa, ẹni tí ó gbà wá kúrò lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wa nípa ẹ̀jẹ̀ rẹ̀,
și de la Isus Hristos, martorul credincios, întâiul născut dintre cei morți și conducătorul regilor pământului. Celui care ne iubește și ne-a spălat de păcatele noastre cu sângele său —
6 tí ó sì ti fi wá jẹ ọba àti àlùfáà láti sin Ọlọ́run àti Baba rẹ; tirẹ̀ ni ògo àti ìjọba láé àti láéláé. Àmín. (aiōn g165)
și ne-a făcut să fim un regat, preoți ai Dumnezeului și Tatălui său — lui să fie gloria și stăpânirea în vecii vecilor. Amin. (aiōn g165)
7 “Kíyèsi i, o ń bọ̀ nínú àwọsánmọ̀, gbogbo ojú ni yóò sì rí i, àti àwọn tí ó gún un ní ọ̀kọ̀ pẹ̀lú”; àti gbogbo orílẹ̀-èdè ayé ni “yóò sì máa pohùnréré ẹkún nítorí rẹ̀.”
Iată, El vine cu norii și orice ochi Îl va vedea, chiar și cei ce L-au străpuns. Toate semințiile pământului îl vor plânge. Chiar și așa, Amin.
8 “Èmi ni Alfa àti Omega,” ni Olúwa Ọlọ́run wí, “ẹni tí ó ń bẹ, tí ó ti wà, tí ó sì ń bọ̀ wá, alágbára.”
“Eu sunt Alfa și Omega, zice Domnul Dumnezeu, Cel ce este și Cel ce era și Cel ce va veni, Cel Atotputernic.”
9 Èmi, Johanu, arákùnrin yín àti alábápín pẹ̀lú yín nínú wàhálà àti ìjọba àti sùúrù tí ń bẹ nínú Jesu, wà ní erékúṣù tí a ń pè ní Patmo, nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, àti nítorí ẹ̀rí Jesu Kristi.
Eu, Ioan, fratele vostru și partenerul vostru în asuprire, în Împărăție și în perseverența în Hristos Isus, am fost pe insula numită Patmos, din cauza Cuvântului lui Dumnezeu și a mărturiei lui Isus Hristos.
10 Mo wà nínú Ẹ̀mí ní ọjọ́ Olúwa, mo sì gbọ́ ohùn ńlá kan lẹ́yìn mi, bí ìró ìpè,
Eram în Duhul Sfânt în ziua Domnului și am auzit în spatele meu un glas puternic, ca o trâmbiță
11 Ó ń wí pé, “Kọ́ ìwé rẹ̀, ohun tí ìwọ rí, kí ó sí fi ránṣẹ́ sí àwọn ìjọ méje; sí Efesu, àti sí Smirna, àti sí Pargamu, àti sí Tiatira, àti sí Sardi, àti sí Filadelfia, àti sí Laodikea.”
care spunea: “Ce vezi, scrie într-o carte și trimite la cele șapte adunări: la Efes, Smirna, Pergam, Tiatira, Sardes, Filadelfia și Laodiceea”.
12 Mo sì yí padà láti wo ohùn tí ń bá mi sọ̀rọ̀. Nígbà tí mo yípadà, mo rí ọ̀pá fìtílà wúrà méje,
M-am întors să văd vocea care vorbea cu mine. După ce m-am întors, am văzut șapte sfeșnice de aur.
13 àti láàrín àwọn ọ̀pá fìtílà náà, ẹnìkan tí ó dàbí “ọmọ ènìyàn,” tí a wọ̀ ní aṣọ tí ó kanlẹ̀ dé ẹsẹ̀, tí a sì fi àmùrè wúrà dì ní ẹ̀gbẹ́.
Și printre sfeșnice era unul ca un fiu de om, îmbrăcat cu o haină care-i ajungea până la picioare și cu o cingătoare de aur în jurul pieptului.
14 Orí rẹ̀ àti irun rẹ̀ funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú, ó funfun bí yìnyín; ojú rẹ̀ sì dàbí, ọwọ́ iná.
Capul și părul lui erau albe ca lâna albă, ca zăpada. Ochii lui erau ca o flacără de foc.
15 Ẹsẹ̀ rẹ̀ sì dàbí idẹ dáradára, bí ẹni pé a dà á nínú ìléru; ohùn rẹ̀ sì dàbí ìró omi púpọ̀.
Picioarele lui erau ca arama lustruită, ca și cum ar fi fost rafinată într-un cuptor. Glasul lui era ca un glas de ape multe.
16 Ó sì ní ìràwọ̀ méje ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀; àti láti ẹnu rẹ̀ wá ni idà olójú méjì mímú ti jáde. Ojú rẹ̀ sì dàbí oòrùn tí ó ń fi agbára rẹ̀ hàn.
Avea șapte stele în mâna dreaptă. Din gura lui ieșea o sabie ascuțită cu două tăișuri. Fața lui era ca soarele care strălucește la maxim.
17 Nígbà tí mo rí i, mo wólẹ̀ ní ẹsẹ̀ rẹ̀ bí ẹni tí ó kú. Ó sì fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ lé mi, ó ń wí fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Èmi ni ẹni ìṣáájú àti ẹni ìkẹyìn.
Când l-am văzut, am căzut la picioarele lui ca un mort. Și-a pus mâna dreaptă peste mine și mi-a zis: “Nu te teme. Eu sunt Cel dintâi și Cel de pe urmă,
18 Èmi ni ẹni tí ó ń bẹ láààyè, tí ó sì ti kú; sì kíyèsi i, èmi sì ń bẹ láààyè sí i títí láé! Mo sì ní kọ́kọ́rọ́ ikú àti ti ipò òkú lọ́wọ́. (aiōn g165, Hadēs g86)
și Cel viu. Am fost mort și iată că sunt viu în vecii vecilor. Amin. Eu am cheile Morții și ale Hadesului. (aiōn g165, Hadēs g86)
19 “Kọ̀wé nítorí náà ohun tí ìwọ ti rí, àti ti ohun tí ń bẹ, àti ti ohun tí yóò hù lẹ́yìn èyí;
Scrieți, așadar, lucrurile pe care le-ați văzut, lucrurile care sunt și lucrurile care se vor întâmpla în viitor.
20 ohun ìjìnlẹ̀ tí ìràwọ̀ méje náà tí ìwọ rí ní ọwọ́ ọ̀tún mi, àti ọ̀pá wúrà fìtílà méje náà. Ìràwọ̀ méje ni àwọn angẹli ìjọ méje náà: àti ọ̀pá fìtílà méje náà ní àwọn ìjọ méje.
Taina celor șapte stele pe care le-ai văzut în mâna Mea dreaptă și a celor șapte sfeșnice de aur este aceasta: Cele șapte stele sunt îngerii celor șapte adunări. Cele șapte sfeșnice sunt cele șapte adunări.

< Revelation 1 >