< Revelation 1 >

1 Ìfihàn ti Jesu Kristi, tí Ọlọ́run fi fún un, láti fihàn fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ohun tí kò le ṣàìṣẹ ní lọ́ọ́lọ́ọ́; ó sì ránṣẹ́, ó sì fi í hàn láti ọwọ́ angẹli rẹ̀ wá fún Johanu, ìránṣẹ́ rẹ̀,
ⲁ̅
2 ẹni tí ó jẹ́rìí ohun gbogbo tí ó rí, èyí ì ni ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, àti ẹ̀rí ti Jesu Kristi.
ⲃ̅
3 Ẹni ìbùkún ni ẹni tí ń kà, àti àwọn tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ yìí, tí ó sì ń pa nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí a kọ sínú rẹ̀ mọ́, nítorí ìgbà kù sí dẹ̀dẹ̀.
ⲅ̅ϩⲱⲛ ⲉϩⲟⲩⲛ
4 Johanu, Sí àwọn ìjọ méje tí ń bẹ ní Asia: Oore-ọ̀fẹ́ fún yín, àti àlàáfíà, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ń bẹ, tí ó sì ti wà, tí ó sì ń bọ̀ wá; àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ẹ̀mí méje tí ń bẹ níwájú ìtẹ́ rẹ̀;
ⲇ̅ⲓⲱϩⲁⲛⲛⲏⲥ ⲉϥⲥϩⲁⲓ [ⲛⲛ]ⲥⲁϣϥⲉ ⲛⲉⲕⲕⲗⲏⲥⲓⲁ ⲉⲧϩⲛⲧⲁⲥⲓⲁ [ⲧⲉ]ⲭⲁⲣⲓⲥ ⲛⲏⲧⲛ ⲙⲛϯⲣⲏⲛⲏ ⲉⲃⲟⲗ [ϩⲓⲧⲛ]ⲡⲉⲧϥϣⲟⲟⲡ ⲡⲉⲧⲉⲛⲉϥϣⲟⲟⲡ [ⲡⲉⲧ]ⲛⲏⲩ ⲁⲩⲱ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲛⲡⲥⲁϣϥ ⲙⲡⲛⲁ [ ⲙ]ⲡⲉⲙⲧⲟ ⲉⲃⲟⲗ ⲡⲉⲑⲣⲟ[ⲛⲟⲥ]
5 àti láti ọ̀dọ̀ Jesu Kristi, ẹlẹ́rìí olóòtítọ́, àkọ́bí nínú àwọn òkú, àti aláṣẹ àwọn ọba ayé. Ẹni tí ó fẹ́ wa, ẹni tí ó gbà wá kúrò lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wa nípa ẹ̀jẹ̀ rẹ̀,
ⲉ̅[ⲁⲩⲱ ⲉⲃⲟⲗ ϩ]ⲓⲧⲛⲓ̅ⲥ̅ ⲡⲉⲭ̅ⲥ̅ ⲡ[ⲙ]ⲛⲧⲣⲉ [ⲡⲡⲓⲥⲧⲟⲥ ⲡ]ϣⲣⲡ ⲙⲙⲓⲥⲉ ⲉⲃⲟⲗ [ϩⲛⲛⲉⲧⲙⲟⲟⲩⲧ ⲡⲁⲣ]ⲭⲱⲛ ⲛⲛⲉⲣⲣⲱ[ⲟⲩ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲙⲡⲕⲁϩ] ⲡⲉⲛⲧ[ⲁϥⲙⲉⲣⲓ]ⲧⲛ ⲁⲩⲱ
6 tí ó sì ti fi wá jẹ ọba àti àlùfáà láti sin Ọlọ́run àti Baba rẹ; tirẹ̀ ni ògo àti ìjọba láé àti láéláé. Àmín. (aiōn g165)
ⲋ̅
7 “Kíyèsi i, o ń bọ̀ nínú àwọsánmọ̀, gbogbo ojú ni yóò sì rí i, àti àwọn tí ó gún un ní ọ̀kọ̀ pẹ̀lú”; àti gbogbo orílẹ̀-èdè ayé ni “yóò sì máa pohùnréré ẹkún nítorí rẹ̀.”
ⲍ̅ⲉⲓⲥϩⲏⲏⲧⲉ ⲉϥⲛⲏⲩ ϩⲓϫⲛⲛⲉⲕⲗⲟⲟⲗⲉ ⲛⲧⲡⲉ ⲛⲧⲉⲃⲁⲗ ⲛⲓⲙ ⲛⲁⲩ ⲉⲣⲟϥ ⲛⲥⲉⲛⲉϩⲡⲉ ⲉϩⲣⲁⲓ ⲉϫⲱϥ ⲛϭⲓⲛⲉⲫⲩⲗⲏ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲙⲡⲕⲁϩ ϩⲁⲙⲏⲛ
8 “Èmi ni Alfa àti Omega,” ni Olúwa Ọlọ́run wí, “ẹni tí ó ń bẹ, tí ó ti wà, tí ó sì ń bọ̀ wá, alágbára.”
ⲏ̅ⲡⲉⲧϣⲟⲟⲡ ⲡⲉⲧⲉⲛⲉϥϣⲟⲟⲡ ⲡⲉⲧⲛⲏⲩ ⲡⲡⲁⲛⲧⲟⲕⲣⲁⲧⲱⲣ
9 Èmi, Johanu, arákùnrin yín àti alábápín pẹ̀lú yín nínú wàhálà àti ìjọba àti sùúrù tí ń bẹ nínú Jesu, wà ní erékúṣù tí a ń pè ní Patmo, nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, àti nítorí ẹ̀rí Jesu Kristi.
ⲑ̅ⲁⲛⲟⲕ ϩⲱ ⲓⲱϩⲁⲛⲛⲏⲥ ⲡⲉⲧⲛⲥⲟⲛ ⲁⲩⲱ ⲡⲉⲧⲛϣⲃⲏⲣⲕⲟⲓⲛⲟⲛⲟⲥ ϩⲛⲧⲉⲑⲗⲓⲯⲓⲥ ⲁⲩⲱ ⲧⲙⲛⲧⲉⲣⲟ ⲙⲛⲑⲩⲡⲟⲙⲟⲛⲏ ⲙⲡⲛ̅ϫⲟⲉⲓⲥ ⲓ̅ⲥ̅ ⲡⲉⲭ̅ⲥ̅ ⲁⲓϣⲱⲡⲉ ϩⲛⲧⲛⲏⲥⲟⲥ ⲉⲧⲟⲩⲙⲟⲩⲧⲉ ⲉⲣⲟⲥ ϫⲉ ⲡⲁⲧⲙⲟⲥ ⲉⲧⲃⲉⲡϣⲁϫⲉ ⲙⲡⲛⲟⲩⲧⲉ ⲁⲩⲱ ⲉⲧⲃⲉⲧⲙⲛⲧⲙⲛⲧⲣⲉ ⲛⲓ̅ⲥ̅ ⲡⲉⲭ̅ⲥ̅
10 Mo wà nínú Ẹ̀mí ní ọjọ́ Olúwa, mo sì gbọ́ ohùn ńlá kan lẹ́yìn mi, bí ìró ìpè,
ⲓ̅ⲁⲓϣⲱⲡⲉ ϩⲙⲡⲉⲡ̅ⲛ̅ⲁ̅ ⲙⲡⲉϩⲟⲟⲩ ⲛⲧⲕⲩⲣⲓⲁⲕⲏ ⲁⲩⲱ ⲁⲓⲥⲱⲧⲙ ⲉⲩⲥⲙⲏ ϩⲓⲡⲁϩⲟⲩ ⲙⲙⲟⲓ ⲛⲑⲉ ⲛⲟⲩⲥⲁⲗⲡⲓⲅⲝ
11 Ó ń wí pé, “Kọ́ ìwé rẹ̀, ohun tí ìwọ rí, kí ó sí fi ránṣẹ́ sí àwọn ìjọ méje; sí Efesu, àti sí Smirna, àti sí Pargamu, àti sí Tiatira, àti sí Sardi, àti sí Filadelfia, àti sí Laodikea.”
ⲓ̅ⲁ̅ⲉⲥϫⲱ ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲛⲉⲧⲉⲕⲛⲁⲩ ⲉⲣⲟⲟⲩ ⲙⲛⲛⲉⲧⲉⲕⲛⲁⲛⲁⲩ ⲉⲣⲟⲟⲩ ⲥϩⲁⲓⲥⲟⲩ ⲉⲩϫⲱⲱⲙⲉ ⲛⲅϫⲟⲟⲩⲥⲟⲩ ⲉⲧⲥⲁϣϥⲉ ⲛⲉⲕⲕⲗⲏⲥⲓⲁ ⲉⲧϩⲛⲉⲫⲉⲥⲟⲥ ⲁⲩⲱ ⲥⲙⲩⲣⲛⲁ ⲙⲛⲡⲣ̅ⲅⲁⲙⲟⲥ ⲁⲩⲱ ⲑⲉⲁⲧⲓⲣⲁ ⲙⲛⲥⲁⲣⲇⲓⲥ ⲙⲛⲫⲓⲗⲁⲇⲉⲗⲫⲓⲁ ⲙⲛⲗⲁⲟⲇⲟⲕⲓⲁ
12 Mo sì yí padà láti wo ohùn tí ń bá mi sọ̀rọ̀. Nígbà tí mo yípadà, mo rí ọ̀pá fìtílà wúrà méje,
ⲓ̅ⲃ̅ⲁⲩⲱ ⲁⲓⲕⲧⲟⲓ ⲉⲛⲁⲩ ⲉⲧⲉⲥⲙⲏ ⲙⲡⲉⲧϣⲁϫⲉ ⲛⲙⲙⲁⲓ ⲛⲧⲉⲣⲉⲓⲕⲧⲟⲓ ⲇⲉ ⲁⲓⲛⲁⲩ ⲉⲥⲁϣϥⲉ ⲛⲗⲩⲭⲛⲓⲁ ⲛⲛⲟⲩⲃ
13 àti láàrín àwọn ọ̀pá fìtílà náà, ẹnìkan tí ó dàbí “ọmọ ènìyàn,” tí a wọ̀ ní aṣọ tí ó kanlẹ̀ dé ẹsẹ̀, tí a sì fi àmùrè wúrà dì ní ẹ̀gbẹ́.
ⲓ̅ⲅ̅ⲉⲣⲉⲡⲉⲓⲛⲉ ⲛⲟⲩϣⲏⲣⲉ ⲛⲣⲱⲙⲉ ϩⲛⲧⲙⲏⲏⲧⲉ ⲛⲉⲛⲗⲩⲭⲛⲓⲁ ⲉϥϭⲟⲟⲗⲉ ⲛⲟⲩϣⲛⲧⲟ ⲉϥⲙⲏⲣ ⲉⲡⲉⲥⲏⲧ ⲉⲛⲉϥⲉⲕⲉⲓⲃⲉ ⲛⲟⲩⲙⲟϫϩ ⲛⲛⲟⲩⲃ
14 Orí rẹ̀ àti irun rẹ̀ funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú, ó funfun bí yìnyín; ojú rẹ̀ sì dàbí, ọwọ́ iná.
ⲓ̅ⲇ̅ⲉⲣⲉⲧⲉϥⲁⲡⲉ ⲟⲩⲟⲃϣ ⲙⲛⲡⲉϥϥⲱ ⲛⲑⲉ ⲛⲟⲩⲥⲟⲣⲧ ⲛⲟⲩⲟⲃϣ̅ ⲁⲩⲱ ⲛⲑⲉ ⲛⲟⲩⲭⲓⲱⲛ ⲉⲣⲉⲛⲉϥⲃⲁⲗ ⲟ ⲛⲑⲉ ⲛⲟⲩϣⲁϩ ⲛⲕⲱϩⲧ
15 Ẹsẹ̀ rẹ̀ sì dàbí idẹ dáradára, bí ẹni pé a dà á nínú ìléru; ohùn rẹ̀ sì dàbí ìró omi púpọ̀.
ⲓ̅ⲉ̅ⲉⲣⲉⲛⲉϥⲟⲩⲣⲏⲏⲧⲉ ⲉⲓⲛⲉ ⲛⲟⲩϩⲟⲙⲛⲧ ⲛⲃⲁⲣⲱⲧ ⲉϥⲡⲟⲥⲉ ϩⲛⲟⲩϩⲣⲱ ⲉⲣⲉⲧⲉϥⲥⲙⲏ ⲟ ⲛⲑⲉ ⲙⲡⲉϩⲣⲟⲟⲩ ⲛϩⲉⲛⲙⲟⲟⲩ ⲉⲛⲁϣⲱⲟⲩ
16 Ó sì ní ìràwọ̀ méje ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀; àti láti ẹnu rẹ̀ wá ni idà olójú méjì mímú ti jáde. Ojú rẹ̀ sì dàbí oòrùn tí ó ń fi agbára rẹ̀ hàn.
ⲓ̅ⲋ̅ⲉⲟⲩⲛⲥⲁϣϥ ⲛⲥⲓⲟⲩ ϩⲛⲧⲉϥϭⲓϫ ⲛⲟⲩⲛⲁⲙ ⲉⲣⲉⲟⲩⲥⲏϥⲉ ⲛⲏⲩ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲛⲧⲉϥⲧⲁⲡⲣⲟ ⲉⲥⲧⲏⲙ ⲙⲫⲟ ⲥⲛⲁⲩ ⲉⲣⲉⲡⲉϥϩⲟ ⲟ ⲛⲑⲉ ⲙⲡⲣⲏ ⲉⲧⲣⲟⲩⲟⲉⲓⲛ ϩⲛⲧⲉϥϭⲟⲙ.
17 Nígbà tí mo rí i, mo wólẹ̀ ní ẹsẹ̀ rẹ̀ bí ẹni tí ó kú. Ó sì fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ lé mi, ó ń wí fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Èmi ni ẹni ìṣáájú àti ẹni ìkẹyìn.
ⲓ̅ⲍ̅ⲛⲧⲉⲣⲉⲓⲛⲁⲩ ⲇⲉ ⲉⲣⲟϥ ⲁⲓϩⲉ ϩⲁⲛⲉϥⲟⲩⲣⲏⲏⲧⲉ ⲛⲑⲉ ⲛⲛⲉⲧⲙⲟⲟⲩⲧ ⲁⲩⲱ ⲁϥⲧⲁⲗⲉⲧⲉϥϭⲓϫ ⲛⲟⲩⲛⲁⲙ ⲉϩⲣⲁⲓ ⲉϫⲱⲓ ⲉϥϫⲱ ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲙⲡⲣⲣϩⲟⲧⲉ ⲁⲛⲟⲕ ⲡⲉ ⲡϣⲟⲣⲡ ⲁⲩⲱ ⲡϩⲁⲉ
18 Èmi ni ẹni tí ó ń bẹ láààyè, tí ó sì ti kú; sì kíyèsi i, èmi sì ń bẹ láààyè sí i títí láé! Mo sì ní kọ́kọ́rọ́ ikú àti ti ipò òkú lọ́wọ́. (aiōn g165, Hadēs g86)
ⲓ̅ⲏ̅ⲡⲉⲧⲟⲛϩ ⲁⲩⲱ ⲁⲓⲙⲟⲩ ⲁⲩⲱ ⲉⲓⲥϩⲏⲏⲧⲉ ϯⲟⲛϩ ϣⲁⲉⲛⲉϩ ⲛⲉⲛⲉϩ ⲁⲩⲱ ⲉⲣⲉⲛϣⲟϣⲧ ⲛⲧⲟⲟⲧ ⲙⲡⲙⲟⲩ ⲙⲛⲁⲙⲛⲧⲉ (aiōn g165, Hadēs g86)
19 “Kọ̀wé nítorí náà ohun tí ìwọ ti rí, àti ti ohun tí ń bẹ, àti ti ohun tí yóò hù lẹ́yìn èyí;
ⲓ̅ⲑ̅ⲥϩⲁⲓ ϭⲉ ⲛⲛⲉⲛⲧⲁⲕⲛⲁⲩ ⲉⲣⲟⲟⲩ ⲙⲛⲛⲉⲧϣⲟⲟⲡ ⲁⲩⲱ ⲛⲉⲧⲛⲁϣⲱⲡⲉ ⲙⲛⲛⲥⲁⲛⲁⲓ
20 ohun ìjìnlẹ̀ tí ìràwọ̀ méje náà tí ìwọ rí ní ọwọ́ ọ̀tún mi, àti ọ̀pá wúrà fìtílà méje náà. Ìràwọ̀ méje ni àwọn angẹli ìjọ méje náà: àti ọ̀pá fìtílà méje náà ní àwọn ìjọ méje.
ⲕ̅ⲡⲙⲏⲥⲧⲩⲣⲓⲟⲛ ⲙⲡⲥⲁϣϥ ⲛⲥⲓⲟⲩ ⲛⲧⲁⲕⲛⲁⲩ ⲉⲣⲟⲟⲩ ϩⲛⲧⲁⲟⲩⲛⲁⲙ ⲙⲛⲧⲥⲁϣϥⲉ ⲛⲗⲩⲭⲛⲓⲁ ⲛⲛⲟⲩⲃ ⲡⲥⲁϣϥ ⲛⲥⲓⲟⲩ ⲡⲥⲁϣϥ ⲛⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⲛⲉⲛⲧⲥⲁϣϥⲉ ⲛⲉⲕⲕⲗⲏⲥⲓⲁ ⲁⲩⲱ ⲧⲥⲁϣϥⲉ ⲛⲗⲩⲭⲛⲓⲁ ⲧⲥⲁϣϥⲉ ⲛⲉⲕⲕⲗⲏⲥⲓⲁ ⲛⲉ

< Revelation 1 >