< Revelation 9 >

1 Angẹli karùn-ún sì fún ìpè tirẹ̀, mo sì rí, ìràwọ̀ kan bọ́ sílẹ̀ láti ọ̀run wá, a sì fi kọ́kọ́rọ́ ihò ọ̀gbun fún un. (Abyssos g12)
The fifth angel blew his trumpet. Then I saw [an evil angel. He was like] a star that had fallen from the sky to the earth. He was given {[Someone] gave him} the key to the shaft [that descended] ([to] the underworld/[to] the deep dark pit). (Abyssos g12)
2 Ó sì ṣí ihò ọ̀gbun náà, èéfín sì rú jáde láti inú ihò náà wá, bí èéfín ìléru ńlá, oòrùn àti ojú sánmọ̀ sì ṣókùnkùn nítorí èéfín ihò náà. (Abyssos g12)
When he opened that shaft, smoke arose from it like smoke from a huge burning furnace. The smoke prevented [anyone from seeing] the sky and the light of the sun. (Abyssos g12)
3 Àwọn eṣú sì jáde ti inú èéfín náà wá sórí ilẹ̀, a sì fi agbára fún wọn gẹ́gẹ́ bí agbára àkéekèe ilẹ̀.
Locusts came out of the smoke onto the earth. [They were given] {[God] gave them} power [to sting people], like scorpions [sting people].
4 A sì fún wọn pé ki wọn má ṣe pa koríko ilẹ̀ lára tàbí ohun tútù kan, tàbí igikígi kan; bí kò ṣe àwọn ènìyàn tí kò ni èdìdì Ọlọ́run ní iwájú wọn.
[God] told the locusts that they should not harm grass, nor any plants, nor any tree. [God said that they should harm only] those people who did not have a mark on the forehead [to show that they belonged to God].
5 A sì pàṣẹ fún wọn pé, kí wọn má ṣe pa wọ́n, ṣùgbọ́n kí a dá wọn ni oró ni oṣù márùn-ún, oró wọn sì dàbí oró àkéekèe, nígbà tí o bá ta ènìyàn.
[God] did not allow the locusts to kill those people. Instead, [he] allowed them to continue torturing people for five months. When they tortured people, the pain those people felt was like the pain a scorpion causes when it stings someone.
6 Ní ọjọ́ wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn yóò sì máa wá ikú, wọn kì yóò sì rí i; wọn yóò sì fẹ́ láti kú, ikú yóò sì sá kúrò lọ́dọ̀ wọn.
During the time [when the locusts torture rebellious people, the pain will be so bad that] people will want to find a way to die, but they will not be able to [PRS].
7 Ìrísí àwọn eṣú náà sì dàbí àwọn ẹṣin tí a múra sílẹ̀ fún ogun; àti ní orí wọn ni ohun tí o dàbí àwọn adé wúrà wà, ojú wọn sì dàbí ojú ènìyàn;
The locusts looked like horses that are ready for battle. They had on their heads what looked like golden crowns. Their faces were like the faces of people.
8 wọ́n sì ní irun bí obìnrin, eyín wọn sì dàbí ti kìnnìún.
They had [long] hair like the [long] hair of women. Their teeth were [strong], like lions’ teeth.
9 Wọ́n sì ní ìgbàyà tí ó dàbí ìgbàyà irin; ìró ìyẹ́ wọn sì dàbí ìró kẹ̀kẹ́-ẹṣin púpọ̀ tí ń súré lọ sí ogun.
They wore metal breastplates. [When they were flying], their wings made a noise like the roar when many horses [pull chariots as they are] rushing into battle.
10 Wọ́n sì ni ìrù àti oró bí tí àkéekèe, àti ní ìrù wọn ni agbára wọn wà láti pa ènìyàn lára fún oṣù márùn-ún.
They had tails like scorpions have. With their tails they stung [people] for five months.
11 Wọ́n ní angẹli ọ̀gbun náà bí ọba lórí wọn, orúkọ rẹ̀ ní èdè Heberu ní Abaddoni, àti ni èdè Giriki orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Apollioni (èyí ni Apanirun). (Abyssos g12)
The king who ruled over them was the angel of the underworld. His name in the Hebrew language is Abaddon. In the Greek language it is Apollyon. [Both of] those names [mean ‘Destroyer’]. (Abyssos g12)
12 Ègbé kan tí kọjá, kíyèsi i, ègbé méjì ń bọ̀ síbẹ̀ lẹ́yìn èyí.
That was the end of the first terrible event. [Be aware that] two tragic events are still to come.
13 Angẹli kẹfà si fọn ìpè rẹ̀, mo sì gbọ́ ohùn kan láti ibi ìwo mẹ́rin pẹpẹ wúrà wá, tí ń bẹ níwájú Ọlọ́run.
The sixth angel blew his trumpet. Then I heard a voice from the four corners of the golden altar that is in God’s presence.
14 Òun wí fún angẹli kẹfà náà tí o ni ìpè náà pé, “Tú àwọn angẹli mẹ́rin náà sílẹ̀ tí a dè lẹ́bàá odò ńlá Eufurate!”
It was saying to the sixth angel, the one who had the trumpet, “Release the four angels whom [I] have bound at the great river Euphrates!”
15 A sì tú àwọn angẹli mẹ́rin náà sílẹ̀, tí a ti pèsè tẹ́lẹ̀ fún wákàtí náà, àti ọjọ́ náà, àti oṣù náà, àti ọdún náà, láti pa ìdámẹ́ta ènìyàn.
The four angels were released, those who had been {[He] released the four angels, whom [God] had} kept ready for that [exact] hour of that day, of that month, of that year. They were released {[He] released them} in order that they might enable [their soldiers to] kill a third of the [rebellious] people.
16 Iye ogún àwọn ẹlẹ́ṣin sì jẹ́ àádọ́ta ọ̀kẹ́ lọ́nà igba, mo sì gbọ́ iye wọn.
The number of the soldiers riding on horses who did that was 200 million. I heard [someone say] how many there were.
17 Báyìí ni mo sì rí àwọn ẹṣin náà ní ojúran, àti àwọn tí o gùn wọ́n, wọ́n ni ìgbàyà aláwọ̀ iná, àti ti jakinti, àti ti sulfuru, orí àwọn ẹṣin náà sì dàbí orí àwọn kìnnìún; àti láti ẹnu wọn ni iná, àti èéfín, àti sulfuru tí ń jáde.
In the vision I saw what the horses and the [beings] that rode them looked like. They [wore] breastplates that were [red] like fire, [dusky blue] like smoke, and [yellow] like sulfur. The heads of the horses were like the heads of lions. From their mouths came fire, smoke, and [fumes of burning] sulfur.
18 Nípa ìyọnu mẹ́ta wọ̀nyí ni a tí pa ìdámẹ́ta ènìyàn, nípa iná, àti nípa èéfín, àti nípa sulfuru tí o ń tí ẹnu wọn jáde.
Those three things—the fire, the smoke, and the [burning] sulfur from [the horses’] mouths—killed a third of the [rebellious] people.
19 Nítorí pé agbára àwọn ẹṣin náà ń bẹ ní ẹnu wọn àti ní ìrù wọn: nítorí pé ìrù wọn dàbí ejò, wọn sì ní orí, àwọn wọ̀nyí ni wọn sì fi ń pa ni lára.
The horses had power with their mouths and with their tails. Their tails have heads like snakes by which they harm people.
20 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ìyókù tí a kò sì ti ipa ìyọnu wọ̀nyí pa, kò sì ronúpìwàdà iṣẹ́ ọwọ́ wọn, kí wọn má ṣe sin àwọn ẹ̀mí èṣù àti ère wúrà, àti ti fàdákà, àti ti idẹ, àti òkúta, àti ti igi mọ́: àwọn tí kò lè ríran, tàbí kí wọn gbọ́rọ̀, tàbí kí wọn rìn.
The rest of the [rebellious] people, those who were not killed by these plagues of [fire and smoke and burning sulfur], did not turn from their sinful behavior. [They did not stop worshipping] the idols that they had made with their own hands. They did not stop worshipping demons and idols [that were made] of gold, of silver, of bronze, of stone, and of wood, [even though they are idols] that can neither see nor hear nor walk.
21 Bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ronúpìwàdà ìwà ìpànìyàn wọn, tàbí oṣó wọn tàbí àgbèrè wọn, tàbí olè wọn.
They did not stop murdering people, or practicing sorcery, or acting in sexually immoral ways, or stealing [things].

< Revelation 9 >