< Revelation 9 >

1 Angẹli karùn-ún sì fún ìpè tirẹ̀, mo sì rí, ìràwọ̀ kan bọ́ sílẹ̀ láti ọ̀run wá, a sì fi kọ́kọ́rọ́ ihò ọ̀gbun fún un. (Abyssos g12)
And the fifth angel sounded; and I saw a Star fall from the heaven to the earth; and there was given to him the key of the bottomless pit. (Abyssos g12)
2 Ó sì ṣí ihò ọ̀gbun náà, èéfín sì rú jáde láti inú ihò náà wá, bí èéfín ìléru ńlá, oòrùn àti ojú sánmọ̀ sì ṣókùnkùn nítorí èéfín ihò náà. (Abyssos g12)
And he opened the bottomless pit, and smoke ascended from the pit, as the smoke of a great furnace: and the sun and the air were darkened by the smoke of the pit. (Abyssos g12)
3 Àwọn eṣú sì jáde ti inú èéfín náà wá sórí ilẹ̀, a sì fi agbára fún wọn gẹ́gẹ́ bí agbára àkéekèe ilẹ̀.
And out of the smoke there came locusts upon the earth; and power was given to them, as scorpions of the earth have power.
4 A sì fún wọn pé ki wọn má ṣe pa koríko ilẹ̀ lára tàbí ohun tútù kan, tàbí igikígi kan; bí kò ṣe àwọn ènìyàn tí kò ni èdìdì Ọlọ́run ní iwájú wọn.
And it was said to them that they should not injure the grass of the earth, nor any green thing, nor any tree; but the men who had not the seal of God in their foreheads.
5 A sì pàṣẹ fún wọn pé, kí wọn má ṣe pa wọ́n, ṣùgbọ́n kí a dá wọn ni oró ni oṣù márùn-ún, oró wọn sì dàbí oró àkéekèe, nígbà tí o bá ta ènìyàn.
And it was not given to them to kill them, but to torment them five months: and their torment was like that of a scorpion when it stings a man.
6 Ní ọjọ́ wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn yóò sì máa wá ikú, wọn kì yóò sì rí i; wọn yóò sì fẹ́ láti kú, ikú yóò sì sá kúrò lọ́dọ̀ wọn.
And in these days men shall seek death, and shall not find it: and they shall desire to die, and death shall fly from them.
7 Ìrísí àwọn eṣú náà sì dàbí àwọn ẹṣin tí a múra sílẹ̀ fún ogun; àti ní orí wọn ni ohun tí o dàbí àwọn adé wúrà wà, ojú wọn sì dàbí ojú ènìyàn;
And the resemblance of the locusts was like horses prepared for war; and on their heads were, as it were, crowns of gold; and and their faces were like the faces of men:
8 wọ́n sì ní irun bí obìnrin, eyín wọn sì dàbí ti kìnnìún.
and they had tresses, like the tresses of women; and their teeth were like the teeth of lions.
9 Wọ́n sì ní ìgbàyà tí ó dàbí ìgbàyà irin; ìró ìyẹ́ wọn sì dàbí ìró kẹ̀kẹ́-ẹṣin púpọ̀ tí ń súré lọ sí ogun.
And they had breastplates like breastplates of iron; and the noise of their wings was like the noise of chariots, and many horses rushing to war.
10 Wọ́n sì ni ìrù àti oró bí tí àkéekèe, àti ní ìrù wọn ni agbára wọn wà láti pa ènìyàn lára fún oṣù márùn-ún.
And they had tails like scorpions, and their stings were in their tails; and their power was to hurt men five months.
11 Wọ́n ní angẹli ọ̀gbun náà bí ọba lórí wọn, orúkọ rẹ̀ ní èdè Heberu ní Abaddoni, àti ni èdè Giriki orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Apollioni (èyí ni Apanirun). (Abyssos g12)
For they had a king over them, the angel of the bottomless pit, whose name, in the Hebrew language, is Abaddon; and in the Greek, he has the name Apollyon. (Abyssos g12)
12 Ègbé kan tí kọjá, kíyèsi i, ègbé méjì ń bọ̀ síbẹ̀ lẹ́yìn èyí.
One woe is gone, and behold other two woes, besides it, yet coming.
13 Angẹli kẹfà si fọn ìpè rẹ̀, mo sì gbọ́ ohùn kan láti ibi ìwo mẹ́rin pẹpẹ wúrà wá, tí ń bẹ níwájú Ọlọ́run.
And the sixth angel sounded; and I heard a voice from the four horns of the golden altar which was before God,
14 Òun wí fún angẹli kẹfà náà tí o ni ìpè náà pé, “Tú àwọn angẹli mẹ́rin náà sílẹ̀ tí a dè lẹ́bàá odò ńlá Eufurate!”
saying to the sixth angel, who had the trumpet, Loose the four angels who are bound by the great river Euphrates.
15 A sì tú àwọn angẹli mẹ́rin náà sílẹ̀, tí a ti pèsè tẹ́lẹ̀ fún wákàtí náà, àti ọjọ́ náà, àti oṣù náà, àti ọdún náà, láti pa ìdámẹ́ta ènìyàn.
And the four angels were loosed, who were prepared for an hour, and a day, and a month, and a year, to kill a third part of men.
16 Iye ogún àwọn ẹlẹ́ṣin sì jẹ́ àádọ́ta ọ̀kẹ́ lọ́nà igba, mo sì gbọ́ iye wọn.
And the number of the horsemen was two myriads of myriads: I heard the number of them.
17 Báyìí ni mo sì rí àwọn ẹṣin náà ní ojúran, àti àwọn tí o gùn wọ́n, wọ́n ni ìgbàyà aláwọ̀ iná, àti ti jakinti, àti ti sulfuru, orí àwọn ẹṣin náà sì dàbí orí àwọn kìnnìún; àti láti ẹnu wọn ni iná, àti èéfín, àti sulfuru tí ń jáde.
And I saw the horses, and those who sat upon them, thus in their appearance; having breastplates of fire, and hyacinth, and brimstone: and the heads of the horses were like the heads of lions, and out of their mouths went fire, and smoke, and brimstone.
18 Nípa ìyọnu mẹ́ta wọ̀nyí ni a tí pa ìdámẹ́ta ènìyàn, nípa iná, àti nípa èéfín, àti nípa sulfuru tí o ń tí ẹnu wọn jáde.
With these three--by the fire, by the smoke, and by the brimstone--that went out of their mouths, they slew a third part of men.
19 Nítorí pé agbára àwọn ẹṣin náà ń bẹ ní ẹnu wọn àti ní ìrù wọn: nítorí pé ìrù wọn dàbí ejò, wọn sì ní orí, àwọn wọ̀nyí ni wọn sì fi ń pa ni lára.
And their powers are in their mouths, and in their tails; and their tails are like serpents, having heads, and with them they injure.
20 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ìyókù tí a kò sì ti ipa ìyọnu wọ̀nyí pa, kò sì ronúpìwàdà iṣẹ́ ọwọ́ wọn, kí wọn má ṣe sin àwọn ẹ̀mí èṣù àti ère wúrà, àti ti fàdákà, àti ti idẹ, àti òkúta, àti ti igi mọ́: àwọn tí kò lè ríran, tàbí kí wọn gbọ́rọ̀, tàbí kí wọn rìn.
Yet the remainder of men, who died not by these plagues, did not reform from the works of their hands, that they might not worship demons, and idols of gold, and silver, and brass, and stone, and wood; which can neither see, nor hear, nor walk.
21 Bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ronúpìwàdà ìwà ìpànìyàn wọn, tàbí oṣó wọn tàbí àgbèrè wọn, tàbí olè wọn.
And they reformed not from their murders, and their magical incantations; nor from their fornication, nor their thefts.

< Revelation 9 >