< Revelation 6 >

1 Èmi sì rí i nígbà tí Ọ̀dọ́-àgùntàn náà ṣí ọkàn nínú èdìdì wọ̀nyí, mo sì gbọ́ ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin náà ń wí bí sísán àrá pé, “Wá, wò ó!”
Ningĩ nĩndonire ũcio Gatũrũme akĩmethũra gatembe ka mbere ga tũtembe tũrĩa mũgwanja twa mũhũra. Ngĩcooka ngĩigua kĩũmbe kĩmwe gĩa ciũmbe iria inya irĩ muoyo gĩkiuga na mũgambo wagambaga ta marurumĩ atĩrĩ, “Ũka!”
2 Mo sì wò ó, kíyèsi i, ẹṣin funfun kan: ẹni tí ó sì jókòó lórí i rẹ̀ ní ọfà kan; a sì fi adé kan fún un: ó sì jáde lọ láti ìṣẹ́gun dé ìṣẹ́gun.
Na niĩ ngĩrora, ngĩona mbarathi njerũ hau mbere yakwa! Ũrĩa wamĩhaicĩte aanyiitĩte ũta, nake akĩheo thũmbĩ, akiumĩra atariĩ ta mũtoorania werekeire o gũtoorania.
3 Nígbà tí ó sì ṣí èdìdì kejì, mo gbọ́ ohùn ẹ̀dá alààyè wí pé, “Wá, wò ó!”
Rĩrĩa Gatũrũme aamethũrire gatembe ga keerĩ, ngĩigua kĩũmbe kĩrĩa kĩrĩ muoyo gĩa keerĩ kĩoiga atĩrĩ, “Ũka!”
4 Ẹṣin mìíràn tí ó pupa sì jáde, a sì fi agbára fún ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀, láti gba àlàáfíà kúrò lórí ilẹ̀ ayé, àti pé kí wọn kí ó máa pa ara wọn, a sì fi idà ńlá kan lé e lọ́wọ́.
Ningĩ gũkiumĩra mbarathi ĩngĩ, nayo yarĩ ndune mũno. Ũrĩa wamĩhaicĩte nĩaheetwo ũhoti wa kũniina thayũ kuuma thĩ, na atũme andũ mooragane. Nake akĩheo rũhiũ rwa njora rũnene.
5 Nígbà tí ó sì di èdìdì kẹta, mo gbọ́ ohùn ẹ̀dá alààyè kẹta wí pé, “Wá wò ó”. Mo sì wò ó, sì kíyèsi i, ẹṣin dúdú kan; ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀ ní ìwọ̀n aláwẹ́ méjì ní ọwọ́ rẹ̀.
Ningĩ rĩrĩa Gatũrũme aamethũrire gatembe ga gatatũ, ngĩigua kĩũmbe kĩrĩa kĩrĩ muoyo gĩa gatatũ kĩoiga atĩrĩ, “Ũka!” Na niĩ ngĩrora, ngĩona mbarathi njirũ hau mbere yakwa! Ũrĩa wamĩhaicĩte aanyiitĩte ratiri na guoko gwake.
6 Mo sì gbọ́ bí ẹni pé ohùn kan ní àárín àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rẹ̀ẹ̀rin nì ti ń wí pé, òsùwọ̀n alikama kan fún owó idẹ kan, àti òsùwọ̀n ọkà barle mẹ́ta fún owó idẹ kan, sì kíyèsi i, kí ó má sì ṣe pa òróró àti ọtí wáìnì lára.
Ningĩ ngĩigua kĩndũ kĩarurumire ta mũgambo ũkuuma gatagatĩ-inĩ ga ciũmbe icio inya irĩ muoyo, ũkiuga atĩrĩ, “Kĩbaba kĩa ngano kiumage mũcaara wa mũthenya ũmwe, na ibaba ithatũ cia ngano ya cairi ciumage mũcara wa mũthenya ũmwe, no ndũgathũkie maguta kana ũthũkie ndibei!”
7 Nígbà tí ó sì ṣí èdìdì kẹrin, mo gbọ́ ohùn ẹ̀dá alààyè kan wí pé, “Wá wò ó!”
Ningĩ rĩrĩa Gatũrũme aamethũrire gatembe ga kana-rĩ, ngĩigua mũgambo wa kĩũmbe kĩrĩa kĩrĩ muoyo gĩa kana woiga atĩrĩ, “Ũka!”
8 Mo sì wò ó, kíyèsi, ẹṣin ràndànràndàn kan, orúkọ ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀ ni ikú, àti ipò òkú sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn. A sì fi agbára fún wọn lórí ìdámẹ́rin ayé, láti fi idà, àti ebi, àti ikú, àti ẹranko lu orí ilẹ̀ ayé pa. (Hadēs g86)
Na niĩ ngĩrora, ngĩona mbarathi theũku hau mbere yakwa! Ũrĩa wamĩhaicĩte-rĩ, eetagwo Gĩkuũ, nake Jehanamu aamumĩte thuutha, amũkuhĩrĩirie. Nao makĩheo ũhoti wa gwatha gĩcunjĩ kĩa inya gĩa thĩ, nĩguo mooragane na rũhiũ rwa njora, na ngʼaragu, na mũthiro, o na ningĩ nyamũ iria ndĩani cia gĩthaka. (Hadēs g86)
9 Nígbà tí ó sì ṣí èdìdì karùn-ún, mo rí lábẹ́ pẹpẹ, ọkàn àwọn tí a ti pa nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, àti nítorí ẹ̀rí tí wọ́n dìímú,
Ningĩ aamethũra gatembe ga gatano-rĩ, ngĩona hau rungu rwa kĩgongona maroho ma andũ arĩa mooragĩtwo nĩ ũndũ wa kiugo kĩa Ngai, na nĩ ũndũ wa ũira ũrĩa maagwatĩirie.
10 Wọ́n kígbe ní ohùn rara, wí pé, “Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa Olódùmarè, ẹni mímọ́ àti olóòtítọ́ ìwọ kì yóò ṣe ìdájọ́ kí o sì gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ wa mọ́ lára àwọn tí ń gbé orí ilẹ̀ ayé?”
Nao magĩkaya na mũgambo mũnene, makĩũria atĩrĩ, “Mwathani Jehova, Wee mũtheru na wa ma, ũgũikara nginya rĩ ũtatuĩrĩire atũũri a thĩ ciira nĩguo ũrĩhĩrie thakame iitũ?”
11 A sì fi aṣọ funfun fún gbogbo wọn; a sì wí fún wọn pé, kí wọn kí ó sinmi fún ìgbà díẹ̀ ná, títí iye àwọn ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ wọn àti arákùnrin wọn tí a o pa bí wọn, yóò fi dé.
Nao makĩheo o mũndũ nguo ndaaya ya rangi mwerũ, na makĩĩrwo meterere hanini, nginya mũigana wa ndungata iria maarutithanagia wĩra nacio ũhinge, na nĩo ariũ na aarĩ a Ithe witũ arĩa maarĩ mooragwo o ta ũrĩa o mooragirwo.
12 Nígbà tí ó sì ṣí èdìdì kẹfà mo sì rí i, sì kíyèsi i, ìṣẹ̀lẹ̀ ńlá kan ṣẹ̀; oòrùn sì dúdú bí aṣọ ọ̀fọ̀ onírun, òṣùpá sì dàbí ẹ̀jẹ̀;
Ningĩ ngĩrora na ngĩona aamethũra gatembe ga gatandatũ. Nakuo gũkĩgĩa na gĩthingithia kĩnene. Narĩo riũa rĩkĩgarũrũka, rĩkĩira ta nguo ya ikũnia ĩtumĩtwo na guoya wa mbũri, naguo mweri wothe ũkĩgarũrũka, ũgĩtunĩha ta thakame,
13 àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run sì ṣubú sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí igi ọ̀pọ̀tọ́ tí ń rẹ̀ àìgbó èso rẹ̀ dànù, nígbà tí ẹ̀fúùfù ńlá bá mì í.
nacio njata cia igũrũ ikĩgũa thĩ, o ta ũrĩa ngũyũ iria thaatu ciitĩkaga kuuma mũkũyũ-inĩ rĩrĩa wainainio nĩ rũhuho rũnene.
14 A sì ká ọ̀run kúrò bí ìwé tí a ká, àti olúkúlùkù òkè àti erékùṣù ní a sì ṣí kúrò ní ipò wọn.
Narĩo igũrũ rĩkĩeherio o ta ũrĩa ibuku rĩa gĩkũnjo rĩkũnjagwo, nacio irĩma ciothe na icigĩrĩra ikĩeherio ikiuma kũndũ gwacio.
15 Àwọn ọba ayé àti àwọn ọlọ́lá àti àwọn olórí ogun, àti àwọn ọlọ́rọ̀ àti àwọn alágbára, àti olúkúlùkù ẹrú, àti olúkúlùkù òmìnira, sì fi ara wọn pamọ́ nínú ihò ilẹ̀, àti nínú àpáta orí òkè;
Nao athamaki a thĩ, na anene, na anene a thigari, na itonga, na andũ arĩa marĩ hinya, na ngombo ciothe, na andũ arĩa othe eyathi, makĩĩhitha ngurunga-inĩ, na gatagatĩ ka ndwaro cia mahiga ma irĩma.
16 wọ́n sì ń wí fún àwọn òkè àti àwọn àpáta náà pé, “Ẹ wó lù wá, kí ẹ sì fi wá pamọ́ kúrò lójú ẹni tí ó jókòó lórí ìtẹ́, àti kúrò nínú ìbínú Ọ̀dọ́-Àgùntàn náà.
Nao nĩmeeraga irĩma na ndwaro cia mahiga atĩrĩ, “Tũgwĩrei, mũtũhithe twehere ũthiũ-inĩ wa ũcio ũrĩa ũikarĩire gĩtĩ kĩa ũnene, na kuuma kũrĩ mangʼũrĩ ma Gatũrũme!
17 Nítorí ọjọ́ ńlá ìbínú wọn dé; ta ni ó sì le dúró?”
Nĩgũkorwo mũthenya ũrĩa mũnene wa mangʼũrĩ mao nĩmũkinyu, nake nũũ ũngĩhota kũwĩtiiria?”

< Revelation 6 >