< Revelation 6 >

1 Èmi sì rí i nígbà tí Ọ̀dọ́-àgùntàn náà ṣí ọkàn nínú èdìdì wọ̀nyí, mo sì gbọ́ ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin náà ń wí bí sísán àrá pé, “Wá, wò ó!”
And I watched (when *NK(o)*) opened the Lamb one of the (seven *NO*) seals and I heard one of the four living creatures saying like (a voice *N(k)O*) of thunder; Come (and *K*) (do heed. *K(o)*)
2 Mo sì wò ó, kíyèsi i, ẹṣin funfun kan: ẹni tí ó sì jókòó lórí i rẹ̀ ní ọfà kan; a sì fi adé kan fún un: ó sì jáde lọ láti ìṣẹ́gun dé ìṣẹ́gun.
And I looked and behold a horse white and the [one] sitting on (it *N(k)O*) having a bow. and was given to him a crown, and he went forth overcoming and that he may conquer.
3 Nígbà tí ó sì ṣí èdìdì kejì, mo gbọ́ ohùn ẹ̀dá alààyè wí pé, “Wá, wò ó!”
And when He opened the seal second I heard the second living creature saying; do come (and do heed. *K*)
4 Ẹṣin mìíràn tí ó pupa sì jáde, a sì fi agbára fún ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀, láti gba àlàáfíà kúrò lórí ilẹ̀ ayé, àti pé kí wọn kí ó máa pa ara wọn, a sì fi idà ńlá kan lé e lọ́wọ́.
And went forth another horse bright red. and to the [one] sitting on (it *N(k)O*) was granted to him to take the peace (from *N(k)O*) the earth, and that one another (they will slay. *N(k)O*) and was given to him a sword great.
5 Nígbà tí ó sì di èdìdì kẹta, mo gbọ́ ohùn ẹ̀dá alààyè kẹta wí pé, “Wá wò ó”. Mo sì wò ó, sì kíyèsi i, ẹṣin dúdú kan; ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀ ní ìwọ̀n aláwẹ́ méjì ní ọwọ́ rẹ̀.
And when He opened the seal third I heard the third living creature saying; do come (and do heed. *K*) And (I saw *NK(O)*) and behold a horse black and the [one] sitting on (it *N(k)O*) having a pair of scales in the hand of him.
6 Mo sì gbọ́ bí ẹni pé ohùn kan ní àárín àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rẹ̀ẹ̀rin nì ti ń wí pé, òsùwọ̀n alikama kan fún owó idẹ kan, àti òsùwọ̀n ọkà barle mẹ́ta fún owó idẹ kan, sì kíyèsi i, kí ó má sì ṣe pa òróró àti ọtí wáìnì lára.
And I heard ([something] like *NO*) a voice in [the] midst of the four living creatures saying; A choenix of wheat for a denarius and three choenixes (of barley *N(k)O*) for a denarius, and the oil and the wine not you may injure.
7 Nígbà tí ó sì ṣí èdìdì kẹrin, mo gbọ́ ohùn ẹ̀dá alààyè kan wí pé, “Wá wò ó!”
And when He opened the seal fourth, I heard [the] voice of the fourth living creature (saying; *N(k)O*) Come (and *K*) (do heed. *K(o)*)
8 Mo sì wò ó, kíyèsi, ẹṣin ràndànràndàn kan, orúkọ ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀ ni ikú, àti ipò òkú sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn. A sì fi agbára fún wọn lórí ìdámẹ́rin ayé, láti fi idà, àti ebi, àti ikú, àti ẹranko lu orí ilẹ̀ ayé pa. (Hadēs g86)
And I looked and behold a horse pale and the [one] sitting on it [the] name of him [was] Death. and Hades (was following *N(k)O*) with (him. *NK(o)*) and was given (to them *NK(O)*) authority over the fourth of the earth to kill with sword and with famine and with plague and by the beasts of the earth. (Hadēs g86)
9 Nígbà tí ó sì ṣí èdìdì karùn-ún, mo rí lábẹ́ pẹpẹ, ọkàn àwọn tí a ti pa nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, àti nítorí ẹ̀rí tí wọ́n dìímú,
And when He opened the fifth seal, I saw under the altar the souls of those slain because of the word of God and because of the testimony (of the lamb *O*) which they were upholding.
10 Wọ́n kígbe ní ohùn rara, wí pé, “Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa Olódùmarè, ẹni mímọ́ àti olóòtítọ́ ìwọ kì yóò ṣe ìdájọ́ kí o sì gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ wa mọ́ lára àwọn tí ń gbé orí ilẹ̀ ayé?”
And (they were crying *N(k)O*) in a voice loud saying; Until when, O Lord holy and (*k*) true, not do You judge and you avenge the blood of us (from *N(k)O*) those dwelling upon the earth?
11 A sì fi aṣọ funfun fún gbogbo wọn; a sì wí fún wọn pé, kí wọn kí ó sinmi fún ìgbà díẹ̀ ná, títí iye àwọn ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ wọn àti arákùnrin wọn tí a o pa bí wọn, yóò fi dé.
And (were given *N(k)O*) to them (each *N(k)O*) (a robe *N(K)O*) (white *N(k)O*) and it was said to them that (they will rest *N(k)O*) yet a time little until (when *k*) (may be fulfilled *N(k)(o)*) also the fellow servants of them and the brothers of them, (and *O*) those being about to be killed as also [had been] they.
12 Nígbà tí ó sì ṣí èdìdì kẹfà mo sì rí i, sì kíyèsi i, ìṣẹ̀lẹ̀ ńlá kan ṣẹ̀; oòrùn sì dúdú bí aṣọ ọ̀fọ̀ onírun, òṣùpá sì dàbí ẹ̀jẹ̀;
And I saw when He opened the seal sixth, and (behold *K*) an earthquake great there was, and the sun became black as sackcloth of hair, and the moon (whole *NO*) became like blood,
13 àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run sì ṣubú sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí igi ọ̀pọ̀tọ́ tí ń rẹ̀ àìgbó èso rẹ̀ dànù, nígbà tí ẹ̀fúùfù ńlá bá mì í.
and the stars of heaven fell to the earth as a fig tree (casts *NK(o)*) the unripe figs of it by a wind great being shaken,
14 A sì ká ọ̀run kúrò bí ìwé tí a ká, àti olúkúlùkù òkè àti erékùṣù ní a sì ṣí kúrò ní ipò wọn.
And heaven departed like a scroll being rolled up, and every mountain and island out of the places of them were moved,
15 Àwọn ọba ayé àti àwọn ọlọ́lá àti àwọn olórí ogun, àti àwọn ọlọ́rọ̀ àti àwọn alágbára, àti olúkúlùkù ẹrú, àti olúkúlùkù òmìnira, sì fi ara wọn pamọ́ nínú ihò ilẹ̀, àti nínú àpáta orí òkè;
And the kings of the earth and the great ones and the commanders and the rich and the (powerful *N(k)O*) and every slave and (everyone *K*) free hid themselves in the caves and among the rocks of the mountains
16 wọ́n sì ń wí fún àwọn òkè àti àwọn àpáta náà pé, “Ẹ wó lù wá, kí ẹ sì fi wá pamọ́ kúrò lójú ẹni tí ó jókòó lórí ìtẹ́, àti kúrò nínú ìbínú Ọ̀dọ́-Àgùntàn náà.
And they say to the mountains and to the rocks; do fall on us and do hide us from [the] face of the [One] sitting on the throne and from the wrath of the Lamb,
17 Nítorí ọjọ́ ńlá ìbínú wọn dé; ta ni ó sì le dúró?”
because has come the day great of the wrath (of them, *N(K)O*) and who is able to stand?

< Revelation 6 >